< Ezekiel 16 >

1 Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé:
La parole de Yahvé me fut adressée, en ces termes:
2 “Ọmọ ènìyàn, mú kí Jerusalẹmu mọ gbogbo ìwà ìríra rẹ̀.
Fils d'homme, fais connaître à Jérusalem ses abominations;
3 Sọ pé, ‘Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí sí Jerusalẹmu, ìran rẹ àti ilẹ̀ ìbí rẹ wà ní ilẹ̀ Kenaani; ará Amori ni baba rẹ̀, ìyá rẹ̀ sì jẹ́ ará Hiti.
et dis: « Le Seigneur Yahvé dit à Jérusalem: « Ton origine et ta naissance sont du pays des Cananéens. Ton père était un Amoréen, et ta mère était une Héthienne.
4 Ní ọjọ́ tí a bí ọ, a kò gé okùn ìwọ́ rẹ, bẹ́ẹ̀ ni a kò sì fi omi wẹ̀ ọ́ láti mú kí o mọ́, a kò fi iyọ̀ pa ọ́ lára rárá, bẹ́ẹ̀ ni a kò fi aṣọ wé ọ.
Quant à ta naissance, le jour où tu es née, ton nombril n'a pas été coupé. On ne t'a pas lavée dans l'eau pour te purifier. On ne t'a pas salé du tout, ni enveloppé dans des couvertures.
5 Kò sí ẹni tó ṣàánú tàbí kẹ́dùn rẹ dé bi à ti ṣe nǹkan kan nínú ìwọ̀nyí fún ọ, ṣùgbọ́n lọ́jọ́ ìbí rẹ, ìta la jù ọ́ sí torí wọ́n kórìíra rẹ.
Aucun œil n'a eu pitié de toi, pour te faire l'une de ces choses, pour avoir pitié de toi; mais on t'a jeté en plein champ, parce que tu étais en horreur le jour où tu es né.
6 “‘Nígbà tí mo sì kọjá tí mo rí ọ tó ń jàgùdù nínú ẹ̀jẹ̀ rẹ, mo sọ fún ọ pé, “Yè!” Nítòótọ́, nígbà tí ìwọ wà nínú ẹ̀jẹ̀ rẹ pé, “Yè.”
« Quand j'ai passé près de toi et que je t'ai vu te vautrer dans ton sang, je t'ai dit: « Si tu es dans ton sang, vis.
7 Mo mú ọ dàgbà bí ohun ọ̀gbìn inú oko. O ga sókè, o sì dàgbà, o wá di arẹwà jùlọ, ọmú rẹ yọ, irun rẹ gùn, ìwọ tí o wà ní ìhòhò láìfi nǹkan kan bora.
Je t'ai fait multiplier comme les plantes des champs, tu as grandi et tu es devenue grande, et tu as atteint une grande beauté. Tes seins se sont formés, et tes cheveux ont poussé; pourtant tu étais nue et dénudée.
8 “‘Nígbà tí mo tún kọjá, tí mo rí ọ, mo rí i pé àsìkò àti nífẹ̀ẹ́ rẹ ti tó, mo fi ìṣẹ́tí aṣọ mi bo ìhòhò rẹ. Mo búra fún ọ, èmi sì bá ọ dá májẹ̀mú ìwọ sì di tèmi, ni Olúwa Olódùmarè wí.
"''Quand je passais devant toi et que je te regardais, voici que ton temps était le temps de l'amour; j'ai étendu sur toi mon vêtement et j'ai couvert ta nudité. Oui, je me suis engagé envers toi et j'ai conclu une alliance avec toi, dit le Seigneur Yahvé, et tu es devenu mien.
9 “‘Nígbà náà ni mo fi omi wẹ ẹ̀jẹ̀ kúrò ní ara rẹ, mo fi ìpara pa ọ́ lára.
"''Puis je t'ai lavé avec de l'eau. Oui, j'ai lavé à fond ton sang, et je t'ai oint d'huile.
10 Mo fi aṣọ oníṣẹ́-ọnà sí ọ lára láti wọ̀ ọ́, mo wọ bàtà aláwọ fún ọ. Mo fi aṣọ funfun gbòò àti aṣọ olówó iyebíye ṣe ọ́ lọ́ṣọ̀ọ́.
Je t'ai aussi revêtu d'un ouvrage brodé et je t'ai mis des sandales de cuir. Je t'ai habillé de lin fin et je t'ai couvert de soie.
11 Mo fi ohun ọ̀ṣọ́ ṣe ọ́ lọ́ṣọ̀ọ́, mo fi ẹ̀gbà ọwọ́ sí ọ ní ọwọ́, mo fi ìlẹ̀kẹ̀ ọrùn sí ọ ní ọrùn,
Je t'ai paré d'ornements, j'ai mis des bracelets à tes mains, et j'ai mis une chaîne à ton cou.
12 mo sì tún fi òrùka sí ọ ní imú, mo fi yẹtí sí ọ ní etí, mo sì fi adé tó rẹwà dé ọ ní orí.
J'ai mis un anneau à ton nez, des boucles d'oreille à tes oreilles, et une belle couronne sur ta tête.
13 Báyìí ni mo ṣe ọ́ lọ́ṣọ̀ọ́ pẹ̀lú wúrà àti fàdákà; tí aṣọ rẹ jẹ́ funfun gbòò, aṣọ olówó iyebíye àti aṣọ tí a ṣiṣẹ́ ọnà sí. Ìyẹ̀fun kíkúnná, oyin àti òróró ni oúnjẹ rẹ. Ó di arẹwà títí ó fi dé ipò ayaba.
Tu étais ainsi paré d'or et d'argent. Tes vêtements étaient de lin fin, de soie et de broderie. Tu mangeais de la farine fine, du miel et de l'huile. Tu étais d'une grande beauté, et tu as prospéré jusqu'à devenir une famille royale.
14 Òkìkí rẹ sì kàn káàkiri orílẹ̀-èdè nítorí ẹwà rẹ, nítorí dídán tí mo fi ṣe ẹwà rẹ ní àṣepé, ni Olúwa Olódùmarè wí.
Ta renommée s'est répandue parmi les nations à cause de ta beauté, car elle était parfaite, grâce à la majesté dont je t'avais revêtue, dit le Seigneur Yahvé.
15 “‘Ṣùgbọ́n, ìwọ gbẹ́kẹ̀lé ẹwà rẹ, ìwọ sì di alágbèrè nítorí òkìkí rẹ. Ìwọ sì fọ́n ojúrere rẹ káàkiri sí orí ẹni yówù tó ń kọjá lọ, ẹwà rẹ sì di tìrẹ.
"''Mais tu t'es confiée à ta beauté, tu t'es prostituée à cause de ta renommée, et tu as déversé ta prostitution sur tous les passants. C'était à lui.
16 Ìwọ mú lára àwọn aṣọ rẹ, láti rán aṣọ aláràbarà fún ibi gíga òrìṣà tí ìwọ ti ń ṣe àgbèrè. Èyí kò yẹ kí ó rí bẹ́ẹ̀, tàbí kó tilẹ̀ ṣẹlẹ̀ rárá.
Tu as pris une partie de tes vêtements, tu t'es fait des hauts lieux ornés de couleurs variées, et tu t'es prostituée dessus. Cela ne doit pas arriver, et cela n'arrivera pas.
17 Ìwọ tún mú àwọn ohun ọ̀ṣọ́ dáradára tí mo fi wúrà àti fàdákà ṣe fún ọ láti fi yá ère ọkùnrin tí ó ń bá ọ ṣe àgbèrè papọ̀.
Vous avez aussi pris vos beaux bijoux, de mon or et de mon argent, que je vous avais donnés, et vous vous êtes fait des images d'hommes, et vous vous êtes prostitués avec elles.
18 Ìwọ sì wọ aṣọ iṣẹ́ ọnà abẹ́rẹ́ rẹ fún wọn, o sì tún gbé òróró àti tùràrí mi sílẹ̀ níwájú wọn.
Tu as pris tes vêtements brodés, tu les as couverts, et tu as mis devant eux mon huile et mon encens.
19 Ìwọ tún gbé oúnjẹ tí mo fún ọ—ìyẹ̀fun dáradára, òróró àti oyin—fún wọn gẹ́gẹ́ bí ẹbọ sísun olóòórùn dídùn; ohun tó ṣẹlẹ̀ nìyìí, ni Olúwa Olódùmarè wí.
Et le pain que je t'ai donné, la fleur de farine, l'huile et le miel, dont je t'ai nourri, tu l'as mis devant eux comme un parfum agréable, et il en a été ainsi, dit le Seigneur Yahvé.
20 “‘Àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin tí o bí fún mi lo ti fi rú ẹbọ bí oúnjẹ fún àwọn òrìṣà. Ṣé ìwà àgbèrè rẹ kò ha tó bí?
"« Tu as pris tes fils et tes filles, que tu m'avais enfantés, et tu les as sacrifiés pour qu'ils soient dévorés. Votre prostitution a-t-elle été peu de chose,
21 Tí ìwọ ti pa àwọn ọmọ mí, ìwọ sì fà wọ́n fún ère gẹ́gẹ́ bí ẹbọ sísun.
pour que vous fassiez mourir mes enfants et que vous les livriez, en les faisant passer par le feu pour eux?
22 Nínú gbogbo iṣẹ́ ìríra àti ìwà àgbèrè rẹ, ìwọ kò rántí ìgbà èwe rẹ, nígbà tí ìwọ wà ní ìhòhò, tó ń jàgùdù nínú ẹ̀jẹ̀.’
Dans toutes tes abominations et tes prostitutions, tu ne t'es pas souvenu des jours de ta jeunesse, quand tu étais nu et dénudé, et que tu te vautrais dans ton sang.
23 “Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, ‘Ègbé! Ègbé ni fún ọ. Lẹ́yìn gbogbo ìwà búburú rẹ,
"« Il est arrivé, après toutes vos méchancetés, malheur à vous, dit le Seigneur Yahvé,
24 ìwọ kọ́lé amọ̀ fún ara rẹ, ìwọ sì kọ́ ojúbọ gíga sí gbogbo òpin ojú pópó.
que vous vous êtes bâti une voûte, et que vous vous êtes fait une place élevée dans toutes les rues.
25 Ní gbogbo ìkóríta ni ìwọ lọ kọ ojúbọ gíga sí, tí ìwọ sọ ẹwà rẹ di ìkórìíra, ìwọ sọ àgbèrè rẹ di púpọ̀ nípa fífi ara rẹ sílẹ̀ fún gbogbo ẹni tó ń kọjá lọ.
Tu t'es bâti une place élevée à la tête de chaque chemin, et tu as fait de ta beauté une abomination; tu as ouvert tes pieds à tous les passants, et tu as multiplié tes prostitutions.
26 Ìwọ ti ṣe àgbèrè pẹ̀lú ará Ejibiti tí í ṣe aládùúgbò rẹ láti mú mi bínú ìwọ sì ti sọ àgbèrè rẹ di púpọ̀.
Tu t'es aussi livrée à l'impudicité avec les Égyptiens, tes voisins, grands par la chair, et tu as multiplié tes prostitutions, pour m'irriter.
27 Nítorí náà ni mo fi na ọwọ́ mi lé ọ lórí, mo sì ti bu oúnjẹ rẹ̀ kù; èmi yóò sì mú ìfẹ́ àwọn to kórìíra rẹ ṣẹ́ lé ọ lórí, àwọn ọmọbìnrin Filistini ti ìwàkiwà rẹ tì lójú.
Voici donc que j'ai étendu ma main sur toi, que j'ai diminué ta part, et que je t'ai livrée à la volonté de celles qui te haïssent, les filles des Philistins, qui ont honte de ton impudicité.
28 Nítorí àìnítẹ́lọ́rùn rẹ, ìwọ ti ṣe àgbèrè pẹ̀lú ara Asiria; ìwọ ti bá wọn ṣe àgbèrè, síbẹ̀síbẹ̀, kò sì lè tẹ́ ọ lọ́rùn.
Tu t'es aussi prostituée avec les Assyriens, parce que tu étais insatiable; oui, tu t'es prostituée avec eux, et pourtant tu n'étais pas satisfaite.
29 Ìwọ si ti sọ àgbèrè rẹ di púpọ̀ láti ilẹ̀ Kenaani dé ilẹ̀ Kaldea; síbẹ̀ èyí kò sì tẹ́ ọ lọ́rùn níhìn-ín yìí.’
Tu as en outre multiplié tes prostitutions jusqu'au pays des marchands, jusqu'en Chaldée; et pourtant tu n'as pas été satisfaite de cela.
30 “Olúwa Olódùmarè wí pé, ‘Báwo ni ọkàn rẹ ṣe jẹ aláìlera tó tí o ń ṣe gbogbo nǹkan wọ̀nyí, bí iṣẹ́ àwọn agídí alágbèrè!
"« Que ton cœur est faible, dit le Seigneur Yahvé, puisque tu fais toutes ces choses, qui sont l'œuvre d'une prostituée impudente,
31 Ni ti pé ìwọ kọ́ ilé gíga rẹ ni gbogbo ìkóríta, tí ìwọ sì ṣe gbogbo ibi gíga rẹ ni gbogbo ìta, ìwọ kò sì wa dàbí panṣágà obìnrin, ní ti pé ìwọ gan ọ̀yà.
en ce que tu bâtis ta voûte à la tête de chaque chemin, et que tu fais ta place élevée dans chaque rue, et que tu n'as pas été comme une prostituée, en ce que tu méprises le salaire.
32 “‘Ìwọ alágbèrè aya! Ìwọ fẹ́ràn ọkùnrin àjèjì ju ọkọ rẹ lọ!
"« Femme adultère, qui prend des étrangers au lieu de son mari!
33 Àwọn ọkùnrin máa ń sanwó fún àwọn panṣágà ni ṣùgbọ́n ìwọ lo tún ń sanwó fun wọn, tí ó tún ń fún àwọn olólùfẹ́ rẹ lẹ́bùn àti owó ẹ̀yìn kí wọn bá à le máa wá ọ wá láti gbogbo agbègbè fún àgbèrè ṣíṣe.
Les gens font des cadeaux à toutes les prostituées; mais toi, tu fais des cadeaux à tous tes amants, et tu les corromps, afin qu'ils viennent de tous côtés pour te prostituer.
34 Nínú àgbèrè rẹ ìwọ yàtọ̀ sí àwọn alágbèrè obìnrin yòókù; nínú àgbèrè rẹ tí ẹnìkan kò tẹ̀lé ọ láti ṣe àgbèrè; àti ní ti pé ìwọ ń tọrẹ tí a kò sì tọrẹ fún ọ, nítorí náà ìwọ yàtọ̀.
Tu es différente des autres femmes dans ta prostitution, en ce que personne ne te suit pour se prostituer; et comme tu donnes un salaire, et qu'on ne te donne pas de salaire, tu es donc différente. »''
35 “‘Nítorí náà, ìwọ alágbèrè, gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa!
C'est pourquoi, prostituée, écoute la parole de Yahvé:
36 Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, “Nítorí pé ìwọ tú ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ rẹ jáde, ìwọ sì fi ìhòhò rẹ hàn, nípa ṣíṣe àgbèrè pẹ̀lú àwọn olólùfẹ́ rẹ, àti nítorí gbogbo òrìṣà ìríra tí o fi ẹ̀jẹ̀ àwọn ọmọ rẹ ṣe ìrúbọ fún,
Le Seigneur Yahvé dit: Parce que ta souillure s'est répandue et que ta nudité a été découverte par tes prostitutions avec tes amants, à cause de toutes les idoles de tes abominations et du sang de tes enfants que tu leur as donné,
37 nítorí náà, Èmi yóò ṣa gbogbo àwọn olólùfẹ́ rẹ jọ, àwọn ẹni ti ìwọ ti bá jayé àti gbogbo àwọn tí ìwọ ti fẹ́ àti àwọn tí ìwọ kórìíra. Èmi yóò sa gbogbo wọn káàkiri jọ, láti mú wọn lòdì sí ọ, èmi yóò sí aṣọ rẹ, níwájú wọn, wọn yóò sì rí ìhòhò rẹ.
voici, je rassemblerai tous tes amants avec lesquels tu as pris plaisir, tous ceux que tu as aimés et tous ceux que tu as haïs. Je les rassemblerai même contre toi de toutes parts, et je leur découvrirai ta nudité, afin qu'ils voient toute ta nudité.
38 Èmi yóò sì dá ọ lẹ́jọ́, gẹ́gẹ́ bí a ti dá obìnrin tó ba ìgbéyàwó jẹ́, tí wọn sì ta ẹ̀jẹ̀ sílẹ̀; Èmi yóò sì mú ẹ̀jẹ̀ ìbínú àti owú mi wá sórí rẹ.
Je te jugerai comme on juge les femmes qui rompent le mariage et versent le sang, et je ferai retomber sur toi le sang de la colère et de la jalousie.
39 Nígbà náà ni èmi yóò fà ọ lé àwọn olólùfẹ́ rẹ lọ́wọ́, wọn yóò sì wó gbogbo òkìtì rẹ pẹ̀lú àwọn ojúbọ rẹ palẹ̀. Wọn yóò tú aṣọ kúrò lára rẹ̀, gbogbo ọ̀ṣọ́ rẹ ni wọn yóò gbà, wọn yóò sì fi ọ sílẹ̀ ní ìhòhò àti ní àìwọṣọ.
Je te livrerai aussi entre leurs mains; ils jetteront tes voûtes et briseront tes hauts lieux. Ils te dépouilleront de tes vêtements et prendront tes beaux bijoux. Ils te laisseront nu et dénudé.
40 Wọn yóò pe àjọ ènìyàn jọ lé ọ lórí, àwọn tí yóò sọ ọ́ ní òkúta, tiwọn yóò sì fi idà wọn gé ọ sí wẹ́wẹ́.
Ils amèneront contre toi une troupe, ils te lapideront, ils te transperceront de leurs épées.
41 Wọn yóò jo gbogbo ilé rẹ palẹ̀ wọn yóò sì fi ìyà jẹ ọ́ ní ojú àwọn obìnrin. Èmi yóò fi òpin sí àgbèrè ṣíṣe rẹ. Ìwọ kò sì ní san owó fún àwọn olólùfẹ́ rẹ mọ́.
Ils brûleront vos maisons par le feu, et ils exerceront sur vous des jugements en présence de nombreuses femmes. Je te ferai cesser de te prostituer, et tu ne donneras plus de salaire.
42 Nígbà náà ni ìbínú mi sí o yóò rọ̀, owú ìbínú mi yóò sì kúrò lọ́dọ̀ rẹ; inú mi yóò rọ̀, èmi kò sì ní bínú mọ́.”
Je ferai en sorte que ma colère contre toi s'apaise, et que ma jalousie s'éloigne de toi. Je me tairai, et je ne me mettrai plus en colère.
43 “‘Nítorí pé ìwọ kò rántí ọjọ́ èwe rẹ ṣùgbọ́n ìwọ ń rí mi fín pẹ̀lú gbogbo nǹkan wọ̀nyí, ó dájú pé, Èmi yóò mú gbogbo ohun tí ìwọ ti ṣe wa sí orí rẹ, ni Olúwa Olódùmarè wí, ìwọ kì yóò sì ṣe ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ yìí ni orí gbogbo ohun ìríra rẹ mọ́?
"« Parce que tu ne t'es pas souvenu des jours de ta jeunesse, mais que tu t'es déchaîné contre moi en toutes ces choses, voici que je fais retomber ta voie sur ta tête, dit le Seigneur Yahvé: « et tu ne commettras plus cette infamie avec toutes tes abominations.
44 “‘Gbogbo àwọn to ń pòwe, ni yóò máa pòwe yìí mọ́ ọ pé: “Bí ìyá ṣe rí, bẹ́ẹ̀ ni ọmọ rẹ̀ obìnrin.”
« Voici, tous ceux qui se servent de proverbes se serviront de ce proverbe contre toi, en disant: « Telle est la mère, telle est la fille ».
45 Ìwọ ni ọmọ ìyá rẹ ti ó kọ ọkọ rẹ̀, àti àwọn ọmọ rẹ̀; ìwọ ni arábìnrin àwọn arábìnrin rẹ tí ó kọ àwọn ọkọ wọn àti àwọn ọmọ wọn: ara Hiti ni ìyá rẹ, ara Amori sì ni baba rẹ.
Tu es la fille de ta mère, qui a en horreur son mari et ses enfants, et tu es la sœur de tes sœurs, qui ont en horreur leurs maris et leurs enfants. Ta mère était une Hittite, et ton père un Amoréen.
46 Ẹ̀gbọ́n rẹ obìnrin ni Samaria, òun àti àwọn ọmọbìnrin rẹ̀ n gbé ni apá àríwá rẹ, àti àbúrò rẹ obìnrin ní ń gbé ọwọ́ òsì rẹ̀, àti àbúrò rẹ obìnrin ti ń gbé ọwọ́ ọ̀tún rẹ ni Sodomu àti àwọn ọmọ rẹ obìnrin.
Ta sœur aînée est Samarie, qui habite à ta gauche, elle et ses filles; et ta sœur cadette, qui habite à ta droite, est Sodome avec ses filles.
47 Kì í sẹ pé ìwọ rìn ni ọ̀nà wọn nìkan, tàbí ṣe àfiwé ìwà ìríra wọn ṣùgbọ́n ní àárín àkókò kúkúrú díẹ̀, ìwọ bàjẹ́ jù wọ́n lọ
Tu n'as pas marché dans leurs voies, tu n'as pas commis leurs abominations; mais bientôt tu t'es corrompue plus qu'eux dans toutes tes voies.
48 Olúwa Olódùmarè wí pé, “Bí mo ṣe wà láààyè, Sodomu tí í ṣe ẹ̀gbọ́n rẹ obìnrin àti àwọn ọmọbìnrin rẹ̀ kò ṣe to ohun tí ìwọ àti ọmọbìnrin rẹ ṣe.”
Je suis vivant, dit le Seigneur Yahvé, Sodome, ta sœur, n'a pas fait, elle et ses filles, ce que tu as fait, toi et tes filles.
49 “‘Wò ó, ẹ̀ṣẹ̀ tí Sodomu ẹ̀gbọ́n rẹ̀ obìnrin ṣẹ̀ nìyìí. Òun àti àwọn ọmọbìnrin rẹ gbéraga, wọ́n jẹ́ alájẹjù àti aláìbìkítà; wọn kò ran tálákà àti aláìní lọ́wọ́.
"''Voici ce qu'était l'iniquité de ta sœur Sodome: l'orgueil, l'abondance du pain et l'aisance prospère étaient chez elle et chez ses filles. Elle n'a pas non plus fortifié la main des pauvres et des nécessiteux.
50 Nítorí náà, mo mu wọn kúrò níwájú mi lójú mi gẹ́gẹ́ bi ìwọ ti rò ó, nítorí ìgbéraga àti àwọn ohun ìríra tí wọ́n ṣe.
Ils se sont montrés arrogants et ont commis des abominations devant moi. C'est pourquoi je les ai fait disparaître quand je l'ai vu.
51 Samaria kò ṣe ìdajì ẹ̀ṣẹ̀ rẹ. Ìwọ ṣe àwọn ohun ìríra ju tirẹ̀ lọ, ìwọ sì jẹ kí àwọn arábìnrin rẹ dàbí olódodo pẹ̀lú gbogbo ìwọ̀nyí tí ìwọ ti ṣe.
Samarie n'a pas commis la moitié de tes péchés; mais toi, tu as multiplié tes abominations plus qu'elles, et tu as justifié tes sœurs par toutes les abominations que tu as commises.
52 Gba ìtìjú rẹ, nítorí ìwọ ti jẹ́ kí arábìnrin rẹ gba ìdáláre. Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ rẹ ti burú ju tí wọn lọ, wọn dàbí olódodo ju ìwọ lọ. Nítorí náà rú ìtìjú rẹ, kí o sì gba ẹ̀gàn rẹ pẹ̀lú nítorí ìwọ ti jẹ́ kí àwọn arábìnrin rẹ dàbí olódodo.
Tu portes toi-même ta propre honte, en ce que tu as jugé tes sœurs; par les péchés que tu as commis plus abominablement qu'elles, elles sont plus justes que toi. Oui, toi aussi, sois confondue, et porte ta honte, en ce que tu as justifié tes sœurs.
53 “‘Bi o tilẹ̀ jẹ pe èmi yóò mú ìgbèkùn wọn padà, ìgbèkùn Sodomu àti àwọn ọmọ rẹ̀ obìnrin, pẹ̀lú Samaria àti àwọn ọmọ rẹ̀ obìnrin, nígbà náà ni èmi yóò tún mú ìgbèkùn àwọn òǹdè rẹ wá láàrín wọn,
"« Je renverserai leur captivité, la captivité de Sodome et de ses filles, la captivité de Samarie et de ses filles, et la captivité de vos captifs au milieu d'eux;
54 kí ó bá à le rú ìtìjú rẹ, àti ẹ̀gàn gbogbo ohun tí ìwọ ṣe láti tù wọ́n nínú.
afin que vous portiez votre propre honte, et que vous ayez honte de tout ce que vous avez fait, puisque vous leur êtes une consolation.
55 Nígbà tí àwọn arábìnrin rẹ, Sodomu àti àwọn ọmọbìnrin rẹ; Samaria àti àwọn ọmọbìnrin rẹ ba padà si ipò tí wọn wà tẹ́lẹ̀, ìgbà náà ni ìwọ náà yóò padà sí ipò àtijọ́ rẹ.
Tes sœurs, Sodome et ses filles, retourneront dans leur ancien domaine; Samarie et ses filles retourneront dans leur ancien domaine; et toi et tes filles, vous retournerez dans votre ancien domaine.
56 Ìwọ ko tilẹ̀ ní dárúkọ arábìnrin rẹ Sodomu ni ọjọ́ ìgbéraga rẹ,
Car ta sœur Sodome n'a pas été mentionnée par ta bouche au jour de ton orgueil,
57 kó tó di pé àṣírí ìwà búburú rẹ tú síta, báyìí ìwọ di ẹni ẹ̀gàn lọ́dọ̀ àwọn ọmọbìnrin Edomu, Siria àti gbogbo agbègbè rẹ, àti lọ́dọ̀ àwọn ọmọbìnrin Filistini àti lọ́dọ̀ àwọn tó yí ọ ká, tiwọn si ń kẹ́gàn rẹ.
avant que ta méchanceté ne soit découverte, comme au temps de l'opprobre des filles de Syrie, et de toutes celles qui l'entourent, les filles des Philistins, qui te méprisent tout autour.
58 Èmi yóò gba ẹ̀san ìwà ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ àti àwọn iṣẹ́ ìríra rẹ ní Olúwa wí.’
Tu as porté tes débauches et tes abominations, dit Yahvé.
59 “Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, ‘Èmi yóò hùwà sí ọ gẹ́gẹ́ bi ó ṣe tọ́ sí ọ, nítorí ó ti kẹ́gàn ẹ̀jẹ́ nípa dídà májẹ̀mú.
"'Car le Seigneur Yahvé dit: « Je vous traiterai aussi comme vous avez fait, vous qui avez méprisé le serment en rompant l'alliance.
60 Síbẹ̀ èmi yóò rántí májẹ̀mú tí mo bá ọ ṣe nígbà èwe rẹ, èmi yóò sì bá ọ dá májẹ̀mú láéláé.
Mais je me souviendrai de mon alliance avec toi aux jours de ta jeunesse, et j'établirai avec toi une alliance éternelle.
61 Nígbà náà ni ìwọ yóò rántí àwọn ọ̀nà rẹ ojú yóò sì tì ọ́ nígbà tí mo bá gba àwọn ẹ̀gbọ́n àti àbúrò rẹ obìnrin padà. Fún ọ gẹ́gẹ́ bí ọmọbìnrin, ṣùgbọ́n kì í ṣe lórí májẹ̀mú tí mo bá ọ dá.
Alors tu te souviendras de tes voies et tu auras honte quand tu recevras tes sœurs, tes aînées et tes cadettes; et je te les donnerai pour filles, mais non par ton alliance.
62 Èmi yóò gbé májẹ̀mú mi kalẹ̀ pẹ̀lú rẹ, ìwọ yóò sì mọ pé èmi ni Olúwa.
J'établirai mon alliance avec vous. Alors vous saurez que je suis Yahvé;
63 Nígbà tí mo bá sì ti ṣe ètùtù fún gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ rẹ tan, Èmi yóò sì rántí, ojú yóò tì ọ́, ìwọ kò sì ní le ya ẹnu rẹ mọ́ nítorí ìtìjú rẹ, ni Olúwa Olódùmarè wí.’”
afin que vous vous souveniez et que vous soyez confus, et que vous n'ouvriez plus la bouche à cause de votre honte, quand je vous aurai pardonné tout ce que vous avez fait, dit le Seigneur Yahvé.'"

< Ezekiel 16 >