< Ezekiel 14 >

1 Díẹ̀ nínú àwọn àgbàgbà Israẹli wá sọ́dọ̀ mi, wọ́n sì jókòó níwájú mi.
İsrail ileri gelenlerinden kimisi gelip yanıma oturdu.
2 Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá,
O sırada RAB bana şöyle seslendi:
3 “Ọmọ ènìyàn, àwọn ọkùnrin wọ̀nyí ti gbé òrìṣà kalẹ̀ sínú ọkàn wọn, wọ́n sì gbé àwọn ohun tó lè mú wọn ṣubú sínú ẹ̀ṣẹ̀ síwájú wọn; Èmi yóò ha jẹ́ kí wọ́n béèrè lọ́wọ́ mi rárá bí?
“İnsanoğlu, bu adamların yüreği putlara bağlı. Diktikleri putların kendilerini günaha sokmasına olanak veriyorlar. Öyleyse onların bana danışmasına izin vermeli miyim?
4 Nítorí náà, sọ fún wọn pé, ‘Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Bí ẹnikẹ́ni ní ilé Israẹli tó gbé òrìṣà sí ọkàn rẹ̀, tó tún gbé ohun ìkọ̀sẹ̀ síwájú rẹ̀, tí ó sì wá sọ́dọ̀ wòlíì, Èmi Olúwa fúnra mi ni yóò dá ẹni tí ó wa lóhùn gẹ́gẹ́ bí ìwà ìbọ̀rìṣà rẹ.
Bunun için onlarla konuş ve de ki, ‘Egemen RAB şöyle diyor: Yüreğini puta bağlayan, diktiği putun kendisini günaha sokmasına olanak veren, sonra da peygambere danışmaya gelen her İsrailli'ye putlarının çokluğuna göre ben RAB kendim karşılık vereceğim.
5 Èmi yóò ṣe èyí láti gba ọkàn àwọn ará Israẹli tó ti tẹ̀lé òrìṣà wọn lọ padà sí ọ̀dọ̀ mi.’
Bunu, putları yüzünden bana sırt çeviren İsrail halkının yüreğini yeniden kendime çekmek için yapacağım.’
6 “Nítorí náà sọ fún ilé Israẹli, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: Ẹ ronúpìwàdà! Ẹ yípadà kúrò lọ́dọ̀ òrìṣà yín, kí ẹ̀yin sì kọ gbogbo ìwà ìríra yín sílẹ̀!
“Bu yüzden İsrail halkına de ki, ‘Egemen RAB şöyle diyor: Geri dönün! Putlarınızdan vazgeçin, iğrenç uygulamalarınızı bırakın!
7 “‘Bí ẹnikẹ́ni ní ilé Israẹli tàbí àlejò tó ń gbé ní ilẹ̀ Israẹli, bá ya ara rẹ̀ kúrò lọ́dọ̀ mi, tó gbé òrìṣà rẹ̀ sí ọkàn rẹ̀, tó tún gbé ohun tó mú ni ṣubú sínú ẹ̀ṣẹ̀ síwájú rẹ, lẹ́yìn èyí tó tún lọ sọ́dọ̀ wòlíì láti béèrè nǹkan lọ́wọ́ mi! Èmi Olúwa fúnra ara mi ní èmi yóò dá a lóhùn.
“‘İsrail halkından biri ya da İsrail'de yaşayan bir yabancı benden ayrılır, yüreğini putlara bağlar, diktiği putların kendisini günaha sokmasına olanak verir, sonra da bana danışmak üzere bir peygambere giderse, ben RAB kendim ona karşılık vereceğim.
8 Èmi yóò lòdì si irú ọkùnrin bẹ́ẹ̀ lọ́nà òdì, Èmi yóò sì fi i ṣe àmì àti òwe. Èmi yóò sì gé e kúrò láàrín àwọn ènìyàn mi. Nígbà náà, ẹ̀yin yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa.
O kişiye karşı çıkacağım. Onu bir belirti, bir alay konusu yapıp halkımın arasından atacağım. O zaman benim RAB olduğumu anlayacaksınız.
9 “‘Bí wọ́n bá sì tan wòlíì náà láti sọtẹ́lẹ̀, Èmi Olúwa ló tan wòlíì náà, Èmi yóò nawọ́ sí i, èmi yóò sì pa á run kúrò láàrín àwọn ènìyàn mi Israẹli.
“‘Bir peygamber ayartılır da bir söz söylerse, onu ayartan benim. Elimi ona karşı uzatacağım, onu halkım İsrail'in arasından çıkarıp yok edeceğim.
10 Wọn yóò ru ẹ̀bi ẹ̀ṣẹ̀ wọn—ìjìyà kan náà là ó fún wòlíì àti ẹni tó lọ béèrè lọ́dọ̀ rẹ̀.
Suçlarının cezasını çekecekler. Peygamber de ona danışan da aynı şekilde cezalandırılacak.
11 Kí ilé Israẹli má ba à ṣáko kúrò lọ́dọ̀ mi mọ, kí wọ́n má ba à fi gbogbo ìrékọjá ba ara wọn jẹ́ mọ́. Ṣùgbọ́n kí wọ́n le jẹ́ ènìyàn mi, kí Èmi náà sì le jẹ́ Ọlọ́run wọn, ni Olúwa Olódùmarè wí.’”
Böylece İsrail halkı bir daha benden ayrılmayacak, günahlarıyla kendilerini kirletmeyecekler. Onlar halkım olacaklar, ben de onların Tanrısı olacağım. Egemen RAB böyle diyor.’”
12 Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé:
RAB bana şöyle seslendi:
13 “Ọmọ ènìyàn bí orílẹ̀-èdè kan bá dẹ́ṣẹ̀ sí mi nípa ìwà àìṣòdodo, èmi yóò nawọ́ mi jáde sí wọn, láti gé ìpèsè oúnjẹ wọn, èmi yóò rán ìyàn sí wọn, èmi yóò sì pa ènìyàn àti ẹranko inú rẹ̀,
“İnsanoğlu, eğer bir ülke bana sadakatsizlik eder, günah işlerse, ben de o ülkeye karşı elimi uzatır, onu her türlü yiyecekten yoksun bırakır, üzerine kıtlık gönderir, insanları ve hayvanları yok edersem;
14 bí àwọn ọkùnrin mẹ́ta yìí. Noa, Daniẹli àti Jobu tilẹ̀ wà nínú rẹ, kìkì ẹ̀mí ara wọn nìkan ni wọ́n lé fi òdodo wọn gbàlà, Olúwa Olódùmarè wí.
şu üç adam –Nuh, Daniel, Eyüp– orada olsalar bile, doğruluklarıyla ancak kendi canlarını kurtarabilirler. Egemen RAB böyle diyor.
15 “Tàbí bí mo bá jẹ́ kí ẹranko búburú gba orílẹ̀-èdè náà kọjá, tí wọn sì bà á jẹ́ tó bẹ́ẹ̀ tí ó di ahoro, tí kò sí ẹni tó le gba ibẹ̀ kọjá torí ẹranko búburú yìí,
“Ya da ülkeye yabanıl hayvanlar gönderirsem ve ülkeyi kimsesiz bırakırlarsa, ülke viraneye döner, hayvanlar yüzünden kimse içinden geçemezse;
16 bí àwọn ọkùnrin mẹ́ta wọ̀nyí tilẹ̀ wà nínú rẹ̀, Olúwa Olódùmarè wí pé, wọn kì yóò gba ọmọkùnrin tàbí ọmọbìnrin là: àwọn nìkan ni a ó gbàlà, ṣùgbọ́n ilẹ̀ náà yóò di ahoro.
Varlığım hakkı için diyor Egemen RAB, bu üç kişi o ülkede yaşasa bile, ne oğullarını ne de kızlarını kurtarabilirler. Ancak kendi canlarını kurtarabilirler. Ülke ise viraneye döner.
17 “Tàbí tí mo bá mú idà kọjá láàrín orílẹ̀-èdè náà tí mo wí pé, ‘Ẹ jẹ́ kí idà kọjá láàrín ilẹ̀ náà,’ tí mo sì tú ìbínú gbígbóná lé wọn lórí nípa ìtàjẹ̀ sílẹ̀, tí mo pa ènìyàn àti ẹranko inú rẹ.
“Ya da o ülkeye kılıç gönderir, ‘Kılıç ülkeyi yarsın’ der, oradaki insanları ve hayvanları yok edersem;
18 Bí àwọn ọkùnrin mẹ́ta yìí tilẹ̀ wà nínú rẹ̀, Olúwa Olódùmarè wí pé, bí mo ti wà, wọn ki yóò gba ọmọkùnrin tàbí ọmọbìnrin là, ṣùgbọ́n àwọn tìkára wọn nìkan ni a ó gbàlà.
varlığım hakkı için diyor Egemen RAB, bu üç kişi orada olsa bile, ne oğullarını ne de kızlarını kurtarabilirler. Ancak kendi canlarını kurtarabilirler.
19 “Tàbí bí mo rán àjàkálẹ̀-ààrùn si ilẹ̀ náà, ti mo si da ìrunú mi lé e lórí pẹ̀lú ẹ̀jẹ̀, láti gé ènìyàn àti ẹranko kúrò nínú rẹ̀,
“O ülkeye salgın hastalık gönderir, kan dökerek öfkemi yağdırır, oradaki insanları ve hayvanları yok edersem;
20 bó tilẹ̀ jẹ́ pé Noa, Daniẹli àti Jobu wà nínú rẹ, bí mo ti wà láààyè ni Olúwa Olódùmarè wí, wọn kò le gba ọmọkùnrin tàbí ọmọbìnrin wọn lá. Ara wọn nìkan ni ìwà òdodo wọn lè gbàlà.
varlığım hakkı için diyor Egemen RAB, Nuh, Daniel ve Eyüp orada olsa bile, ne oğullarını ne de kızlarını kurtarabilirler. Doğruluklarıyla ancak kendi canlarını kurtarabilirler.
21 “Nítorí báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, báwo ni yóò ti burú tó nígbà tí mo bá rán ìdájọ́ kíkan mi mẹ́rin sórí Jerusalẹmu, èyí ni idà àti ìyàn, ẹranko búburú àti àjàkálẹ̀-ààrùn láti pa àwọn ènìyàn àti ẹranko inú rẹ̀!
“Egemen RAB şöyle diyor: Yeruşalim'deki insanları ve hayvanları yok etmek için üzerine dört ağır yargımı –kılıcı, kıtlığı, yabanıl hayvanları, salgın hastalığı– gönderdiğimde daha neler neler olacak!
22 Síbẹ̀, yóò ṣẹ́kù àwọn díẹ̀, àwọn ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin tí a ó kó jáde nínú rẹ̀. Wọn yóò wá bá yin, ẹ̀yin yóò rí ìwà àti ìṣe wọn, nígbà náà ni ẹ̀yin yóò rí ìtùnú nípa àjálù tí mo mú wá sórí Jerusalẹmu—àní gbogbo àjálù ní mo ti mú wá sórí rẹ̀.
Orada sağ bırakılacak kimi oğullarınız, kızlarınız olacak, çıkıp yanınıza gelecekler. Onların davranışlarını ve yaptıklarını görünce, Yeruşalim'in başına getirdiğim yıkımdan ve her tür felaketten avuntu bulacaksınız.
23 Nígbà tí ẹ̀yin bá rí ìwà àti ìṣe wọn, a ó tù yín nínú, nítorí pé ẹ̀yin yóò mọ̀ pé èmi kò ṣe nǹkan kan láìnídìí, ni Olúwa Olódùmarè wí.”
Onların davranışlarını ve yaptıklarını görünce avutulacak, Yeruşalim'in başına getirdiklerimin amaçsız olmadığını anlayacaksınız. Egemen RAB böyle diyor.”

< Ezekiel 14 >