< Ezekiel 14 >

1 Díẹ̀ nínú àwọn àgbàgbà Israẹli wá sọ́dọ̀ mi, wọ́n sì jókòó níwájú mi.
Og det kom til mig nogen av Israels eldste, og de satte sig foran mig.
2 Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá,
Da kom Herrens ord til mig, og det lød så:
3 “Ọmọ ènìyàn, àwọn ọkùnrin wọ̀nyí ti gbé òrìṣà kalẹ̀ sínú ọkàn wọn, wọ́n sì gbé àwọn ohun tó lè mú wọn ṣubú sínú ẹ̀ṣẹ̀ síwájú wọn; Èmi yóò ha jẹ́ kí wọ́n béèrè lọ́wọ́ mi rárá bí?
Menneskesønn! Disse menn har gitt sine motbydelige avguder rum i sitt hjerte, og det som er dem et anstøt til misgjerning, har de satt for sine øine; skulde jeg la mig spørre av dem?
4 Nítorí náà, sọ fún wọn pé, ‘Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Bí ẹnikẹ́ni ní ilé Israẹli tó gbé òrìṣà sí ọkàn rẹ̀, tó tún gbé ohun ìkọ̀sẹ̀ síwájú rẹ̀, tí ó sì wá sọ́dọ̀ wòlíì, Èmi Olúwa fúnra mi ni yóò dá ẹni tí ó wa lóhùn gẹ́gẹ́ bí ìwà ìbọ̀rìṣà rẹ.
Tal derfor med dem og si til dem: Så sier Herren, Israels Gud: Hver den av Israels hus som gir sine motbydelige avguder rum i sitt hjerte og setter det som er ham et anstøt til misgjerning, for sine øine og så kommer til profeten, ham vil jeg, Herren, selv svare for hans mange motbydelige avguders skyld,
5 Èmi yóò ṣe èyí láti gba ọkàn àwọn ará Israẹli tó ti tẹ̀lé òrìṣà wọn lọ padà sí ọ̀dọ̀ mi.’
for å gripe Israels hus i deres hjerte, fordi de alle har veket bort fra mig ved sine motbydelige avguder.
6 “Nítorí náà sọ fún ilé Israẹli, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: Ẹ ronúpìwàdà! Ẹ yípadà kúrò lọ́dọ̀ òrìṣà yín, kí ẹ̀yin sì kọ gbogbo ìwà ìríra yín sílẹ̀!
Si derfor til Israels hus: Så sier Herren, Israels Gud: Vend om og vend eder bort fra alle eders motbydelige avguder og vend eders åsyn bort fra alle eders vederstyggeligheter!
7 “‘Bí ẹnikẹ́ni ní ilé Israẹli tàbí àlejò tó ń gbé ní ilẹ̀ Israẹli, bá ya ara rẹ̀ kúrò lọ́dọ̀ mi, tó gbé òrìṣà rẹ̀ sí ọkàn rẹ̀, tó tún gbé ohun tó mú ni ṣubú sínú ẹ̀ṣẹ̀ síwájú rẹ, lẹ́yìn èyí tó tún lọ sọ́dọ̀ wòlíì láti béèrè nǹkan lọ́wọ́ mi! Èmi Olúwa fúnra ara mi ní èmi yóò dá a lóhùn.
For hver den av Israels hus og av de fremmede som bor i Israel, som skiller sig fra mig og gir sine motbydelige avguder rum i sitt hjerte og setter det som er ham et anstøt til misgjerning, for sine øine og så kommer til profeten for å spørre mig for sig, ham vil jeg, Herren, selv svare på min vis.
8 Èmi yóò lòdì si irú ọkùnrin bẹ́ẹ̀ lọ́nà òdì, Èmi yóò sì fi i ṣe àmì àti òwe. Èmi yóò sì gé e kúrò láàrín àwọn ènìyàn mi. Nígbà náà, ẹ̀yin yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa.
Jeg vil sette mitt åsyn mot den mann og ødelegge ham, så han blir til et tegn og til et ordsprog, og jeg vil utrydde ham av mitt folk, og I skal kjenne at jeg er Herren.
9 “‘Bí wọ́n bá sì tan wòlíì náà láti sọtẹ́lẹ̀, Èmi Olúwa ló tan wòlíì náà, Èmi yóò nawọ́ sí i, èmi yóò sì pa á run kúrò láàrín àwọn ènìyàn mi Israẹli.
Og om profeten lar sig forlokke og taler et ord, da er det jeg, Herren, som har forlokket denne profet, og jeg vil rekke ut min hånd mot ham og utslette ham av mitt folk Israel.
10 Wọn yóò ru ẹ̀bi ẹ̀ṣẹ̀ wọn—ìjìyà kan náà là ó fún wòlíì àti ẹni tó lọ béèrè lọ́dọ̀ rẹ̀.
Og de skal lide for sin misgjerning; som det er med spørgerens misgjerning, så skal det være med profetens misgjerning,
11 Kí ilé Israẹli má ba à ṣáko kúrò lọ́dọ̀ mi mọ, kí wọ́n má ba à fi gbogbo ìrékọjá ba ara wọn jẹ́ mọ́. Ṣùgbọ́n kí wọ́n le jẹ́ ènìyàn mi, kí Èmi náà sì le jẹ́ Ọlọ́run wọn, ni Olúwa Olódùmarè wí.’”
forat Israels hus ikke mere skal forville sig bort fra mig og ikke mere gjøre sig uren med alle sine overtredelser, men være mitt folk, og jeg deres Gud, sier Herren, Israels Gud.
12 Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé:
Og Herrens ord kom til mig, og det lød så:
13 “Ọmọ ènìyàn bí orílẹ̀-èdè kan bá dẹ́ṣẹ̀ sí mi nípa ìwà àìṣòdodo, èmi yóò nawọ́ mi jáde sí wọn, láti gé ìpèsè oúnjẹ wọn, èmi yóò rán ìyàn sí wọn, èmi yóò sì pa ènìyàn àti ẹranko inú rẹ̀,
Menneskesønn! Når et land synder mot mig og gjør sig skyldig i troløshet, og jeg rekker ut min hånd mot det og sønderbryter brødets stav for det og sender hungersnød over det og utrydder både mennesker og fe av det,
14 bí àwọn ọkùnrin mẹ́ta yìí. Noa, Daniẹli àti Jobu tilẹ̀ wà nínú rẹ, kìkì ẹ̀mí ara wọn nìkan ni wọ́n lé fi òdodo wọn gbàlà, Olúwa Olódùmarè wí.
og om da disse tre menn, Noah, Daniel og Job, var der i landet, da skulde de ved sin rettferdighet bare kunne berge sitt eget liv, sier Herren, Israels Gud.
15 “Tàbí bí mo bá jẹ́ kí ẹranko búburú gba orílẹ̀-èdè náà kọjá, tí wọn sì bà á jẹ́ tó bẹ́ẹ̀ tí ó di ahoro, tí kò sí ẹni tó le gba ibẹ̀ kọjá torí ẹranko búburú yìí,
Om jeg lot ville dyr fare gjennem landet, og de gjorde det folketomt, og det blev til en ørken, så ingen kunde dra gjennem det for de ville dyrs skyld,
16 bí àwọn ọkùnrin mẹ́ta wọ̀nyí tilẹ̀ wà nínú rẹ̀, Olúwa Olódùmarè wí pé, wọn kì yóò gba ọmọkùnrin tàbí ọmọbìnrin là: àwọn nìkan ni a ó gbàlà, ṣùgbọ́n ilẹ̀ náà yóò di ahoro.
da skulde, så sant jeg lever, sier Herren, Israels Gud, disse tre menn, om de var der, hverken kunne berge sønner eller døtre; bare de selv skulde bli berget, men landet skulde bli en ørken.
17 “Tàbí tí mo bá mú idà kọjá láàrín orílẹ̀-èdè náà tí mo wí pé, ‘Ẹ jẹ́ kí idà kọjá láàrín ilẹ̀ náà,’ tí mo sì tú ìbínú gbígbóná lé wọn lórí nípa ìtàjẹ̀ sílẹ̀, tí mo pa ènìyàn àti ẹranko inú rẹ.
Eller om jeg lot sverd komme over det land og sa: Sverd skal fare gjennem landet, og jeg utryddet både mennesker og fe av det,
18 Bí àwọn ọkùnrin mẹ́ta yìí tilẹ̀ wà nínú rẹ̀, Olúwa Olódùmarè wí pé, bí mo ti wà, wọn ki yóò gba ọmọkùnrin tàbí ọmọbìnrin là, ṣùgbọ́n àwọn tìkára wọn nìkan ni a ó gbàlà.
og disse tre menn var der i landet, da skulde de, så sant jeg lever, sier Herren, Israels Gud, ikke kunne berge sønner eller døtre, bare de selv skulde bli berget.
19 “Tàbí bí mo rán àjàkálẹ̀-ààrùn si ilẹ̀ náà, ti mo si da ìrunú mi lé e lórí pẹ̀lú ẹ̀jẹ̀, láti gé ènìyàn àti ẹranko kúrò nínú rẹ̀,
Eller om jeg sendte pest i det land og utøste min harme over det med blod for å utrydde både mennesker og fe av det,
20 bó tilẹ̀ jẹ́ pé Noa, Daniẹli àti Jobu wà nínú rẹ, bí mo ti wà láààyè ni Olúwa Olódùmarè wí, wọn kò le gba ọmọkùnrin tàbí ọmọbìnrin wọn lá. Ara wọn nìkan ni ìwà òdodo wọn lè gbàlà.
og Noah, Daniel og Job var der i landet, da skulde de, så sant jeg lever, sier Herren, Israels Gud, hverken kunne berge sønn eller datter; bare sitt eget liv skulde de berge ved sin rettferdighet.
21 “Nítorí báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, báwo ni yóò ti burú tó nígbà tí mo bá rán ìdájọ́ kíkan mi mẹ́rin sórí Jerusalẹmu, èyí ni idà àti ìyàn, ẹranko búburú àti àjàkálẹ̀-ààrùn láti pa àwọn ènìyàn àti ẹranko inú rẹ̀!
For så sier Herren, Israels Gud: Enn når jeg sender mine fire onde straffedommer, sverd, hungersnød og ville dyr og pest, over Jerusalem for å utrydde både mennesker og fe av det!
22 Síbẹ̀, yóò ṣẹ́kù àwọn díẹ̀, àwọn ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin tí a ó kó jáde nínú rẹ̀. Wọn yóò wá bá yin, ẹ̀yin yóò rí ìwà àti ìṣe wọn, nígbà náà ni ẹ̀yin yóò rí ìtùnú nípa àjálù tí mo mú wá sórí Jerusalẹmu—àní gbogbo àjálù ní mo ti mú wá sórí rẹ̀.
Allikevel skal nogen undkomme og bli igjen der, nogen sønner og døtre, som blir bortført, og de skal da komme ut til eder, og I skal se deres ferd og deres gjerninger, og I skal trøste eder over den ulykke jeg lot komme over Jerusalem, over alt det jeg lot komme over det.
23 Nígbà tí ẹ̀yin bá rí ìwà àti ìṣe wọn, a ó tù yín nínú, nítorí pé ẹ̀yin yóò mọ̀ pé èmi kò ṣe nǹkan kan láìnídìí, ni Olúwa Olódùmarè wí.”
Og de skal trøste eder når I ser deres ferd og deres gjerninger, og I skal kjenne at jeg ikke uten årsak har gjort noget av alt det jeg har gjort mot det, sier Herren, Israels Gud.

< Ezekiel 14 >