< Ezekiel 14 >

1 Díẹ̀ nínú àwọn àgbàgbà Israẹli wá sọ́dọ̀ mi, wọ́n sì jókòó níwájú mi.
And men of the eldris of Israel camen to me, and saten bifor me.
2 Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá,
And the word of the Lord was maad to me, and he seide, Sone of man,
3 “Ọmọ ènìyàn, àwọn ọkùnrin wọ̀nyí ti gbé òrìṣà kalẹ̀ sínú ọkàn wọn, wọ́n sì gbé àwọn ohun tó lè mú wọn ṣubú sínú ẹ̀ṣẹ̀ síwájú wọn; Èmi yóò ha jẹ́ kí wọ́n béèrè lọ́wọ́ mi rárá bí?
these men han set her vnclennesses in her hertis, and han set stidfastli the sclaundre of her wickidnesse ayens her face. Whether Y `that am axid, schal answere to hem?
4 Nítorí náà, sọ fún wọn pé, ‘Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Bí ẹnikẹ́ni ní ilé Israẹli tó gbé òrìṣà sí ọkàn rẹ̀, tó tún gbé ohun ìkọ̀sẹ̀ síwájú rẹ̀, tí ó sì wá sọ́dọ̀ wòlíì, Èmi Olúwa fúnra mi ni yóò dá ẹni tí ó wa lóhùn gẹ́gẹ́ bí ìwà ìbọ̀rìṣà rẹ.
For this thing speke thou to hem, and thou schalt seie to hem, These thingis seith the Lord God, A man, a man of the hous of Israel, that settith hise vnclennessis in his herte, and settith stidfastli the sclaundre of his wickidnesse ayens his face, and cometh to the profete, and axith me bi hym, Y the Lord schal answere to hym in the multitude of hise vnclennessis;
5 Èmi yóò ṣe èyí láti gba ọkàn àwọn ará Israẹli tó ti tẹ̀lé òrìṣà wọn lọ padà sí ọ̀dọ̀ mi.’
that the hous of Israel be takun in her herte, bi which thei yeden awei fro me in alle her idols.
6 “Nítorí náà sọ fún ilé Israẹli, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: Ẹ ronúpìwàdà! Ẹ yípadà kúrò lọ́dọ̀ òrìṣà yín, kí ẹ̀yin sì kọ gbogbo ìwà ìríra yín sílẹ̀!
Therfor seie thou to the hous of Israel, The Lord God seith these thingis, Be ye conuertid, and go ye awei fro youre idols, and turne awei youre faces fro alle youre filthis.
7 “‘Bí ẹnikẹ́ni ní ilé Israẹli tàbí àlejò tó ń gbé ní ilẹ̀ Israẹli, bá ya ara rẹ̀ kúrò lọ́dọ̀ mi, tó gbé òrìṣà rẹ̀ sí ọkàn rẹ̀, tó tún gbé ohun tó mú ni ṣubú sínú ẹ̀ṣẹ̀ síwájú rẹ, lẹ́yìn èyí tó tún lọ sọ́dọ̀ wòlíì láti béèrè nǹkan lọ́wọ́ mi! Èmi Olúwa fúnra ara mi ní èmi yóò dá a lóhùn.
For whi a man, a man of the hous of Israel, and of conuersis, who euer is a comelyng in Israel, if he is alienyd fro me, and settith hise idols in his herte, and settith stidfastli the sclaundir of his wickidnesse ayens his face, and he cometh to the profete, to axe me bi hym, Y the Lord schal answere hym bi my silf.
8 Èmi yóò lòdì si irú ọkùnrin bẹ́ẹ̀ lọ́nà òdì, Èmi yóò sì fi i ṣe àmì àti òwe. Èmi yóò sì gé e kúrò láàrín àwọn ènìyàn mi. Nígbà náà, ẹ̀yin yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa.
And Y schal sette my face on that man, and Y schal make hym in to ensaumple, and in to a prouerbe, and Y schal leese hym fro the myddis of my puple; and ye schulen wite, that Y am the Lord.
9 “‘Bí wọ́n bá sì tan wòlíì náà láti sọtẹ́lẹ̀, Èmi Olúwa ló tan wòlíì náà, Èmi yóò nawọ́ sí i, èmi yóò sì pa á run kúrò láàrín àwọn ènìyàn mi Israẹli.
And whanne a profete errith, and spekith a word, Y the Lord schal disseyue that profete; and Y schal stretche forth myn hond on hym, and Y schal do hym awei fro the myddis of my puple Israel.
10 Wọn yóò ru ẹ̀bi ẹ̀ṣẹ̀ wọn—ìjìyà kan náà là ó fún wòlíì àti ẹni tó lọ béèrè lọ́dọ̀ rẹ̀.
And thei schulen bere her wickidnesse; bi the wickidnesse of the axere, so the wickidnesse of the profete schal be;
11 Kí ilé Israẹli má ba à ṣáko kúrò lọ́dọ̀ mi mọ, kí wọ́n má ba à fi gbogbo ìrékọjá ba ara wọn jẹ́ mọ́. Ṣùgbọ́n kí wọ́n le jẹ́ ènìyàn mi, kí Èmi náà sì le jẹ́ Ọlọ́run wọn, ni Olúwa Olódùmarè wí.’”
that the hous of Israel erre no more fro me, nether be defoulid in alle her trespassyngis; but that it be in to a puple to me, and Y be in to a God to hem, seith the Lord of oostis.
12 Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé:
And the word of the Lord was maad to me, and he seide,
13 “Ọmọ ènìyàn bí orílẹ̀-èdè kan bá dẹ́ṣẹ̀ sí mi nípa ìwà àìṣòdodo, èmi yóò nawọ́ mi jáde sí wọn, láti gé ìpèsè oúnjẹ wọn, èmi yóò rán ìyàn sí wọn, èmi yóò sì pa ènìyàn àti ẹranko inú rẹ̀,
Sone of man, whanne the lond synneth ayens me, that it trespassynge do trespas, Y schal stretche forth myn hond on it, and Y schal al to-breke the yerde of breed therof; and Y schal sende hungur in to it, and Y schal sle of it man and beeste.
14 bí àwọn ọkùnrin mẹ́ta yìí. Noa, Daniẹli àti Jobu tilẹ̀ wà nínú rẹ, kìkì ẹ̀mí ara wọn nìkan ni wọ́n lé fi òdodo wọn gbàlà, Olúwa Olódùmarè wí.
And if these thre men Noe, Danyel, and Job, ben in the myddis therof, thei bi her riytfulnesse schulen delyuere her soulis, seith the Lord of oostis.
15 “Tàbí bí mo bá jẹ́ kí ẹranko búburú gba orílẹ̀-èdè náà kọjá, tí wọn sì bà á jẹ́ tó bẹ́ẹ̀ tí ó di ahoro, tí kò sí ẹni tó le gba ibẹ̀ kọjá torí ẹranko búburú yìí,
That if also Y brynge in worste beestis on the lond, that Y distrie it, and if it is with out weie, for that no passer is for the beestis,
16 bí àwọn ọkùnrin mẹ́ta wọ̀nyí tilẹ̀ wà nínú rẹ̀, Olúwa Olódùmarè wí pé, wọn kì yóò gba ọmọkùnrin tàbí ọmọbìnrin là: àwọn nìkan ni a ó gbàlà, ṣùgbọ́n ilẹ̀ náà yóò di ahoro.
and these thre men, that `ben bifore seid, ben therynne, Y lyue, seith the Lord God, for thei schulen nethir delyuere sones, nether douytris, but thei aloone schulen be deliuered; forsothe the lond schal be maad desolat.
17 “Tàbí tí mo bá mú idà kọjá láàrín orílẹ̀-èdè náà tí mo wí pé, ‘Ẹ jẹ́ kí idà kọjá láàrín ilẹ̀ náà,’ tí mo sì tú ìbínú gbígbóná lé wọn lórí nípa ìtàjẹ̀ sílẹ̀, tí mo pa ènìyàn àti ẹranko inú rẹ.
Ethir if Y brynge in swerd on that lond, and Y seie to the swerd, Passe thou thorouy the lond, and Y sle of it man and beeste,
18 Bí àwọn ọkùnrin mẹ́ta yìí tilẹ̀ wà nínú rẹ̀, Olúwa Olódùmarè wí pé, bí mo ti wà, wọn ki yóò gba ọmọkùnrin tàbí ọmọbìnrin là, ṣùgbọ́n àwọn tìkára wọn nìkan ni a ó gbàlà.
and these thre men ben in the myddis therof, Y lyue, seith the Lord God, that thei schulen not delyuere sones nether douytris, but thei aloone schulen be delyuered.
19 “Tàbí bí mo rán àjàkálẹ̀-ààrùn si ilẹ̀ náà, ti mo si da ìrunú mi lé e lórí pẹ̀lú ẹ̀jẹ̀, láti gé ènìyàn àti ẹranko kúrò nínú rẹ̀,
Forsothe if Y brynge in also pestilence on that lond, and Y schede out myn indignacioun on it in blood, that Y do awei fro it man and beeste,
20 bó tilẹ̀ jẹ́ pé Noa, Daniẹli àti Jobu wà nínú rẹ, bí mo ti wà láààyè ni Olúwa Olódùmarè wí, wọn kò le gba ọmọkùnrin tàbí ọmọbìnrin wọn lá. Ara wọn nìkan ni ìwà òdodo wọn lè gbàlà.
and Noe, and Danyel, and Joob, ben in the myddis therof, Y lyue, seith the Lord God, for thei schulen not delyuere a sone and a douyter, but thei bi her riytfulnesse schulen delyuere her soulis.
21 “Nítorí báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, báwo ni yóò ti burú tó nígbà tí mo bá rán ìdájọ́ kíkan mi mẹ́rin sórí Jerusalẹmu, èyí ni idà àti ìyàn, ẹranko búburú àti àjàkálẹ̀-ààrùn láti pa àwọn ènìyàn àti ẹranko inú rẹ̀!
For the Lord God seith these thingis, That thouy Y sende in my foure worste domes, swerd, and hungur, and yuele beestis, and pestilence, in to Jerusalem, that Y sle of it man and beeste,
22 Síbẹ̀, yóò ṣẹ́kù àwọn díẹ̀, àwọn ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin tí a ó kó jáde nínú rẹ̀. Wọn yóò wá bá yin, ẹ̀yin yóò rí ìwà àti ìṣe wọn, nígbà náà ni ẹ̀yin yóò rí ìtùnú nípa àjálù tí mo mú wá sórí Jerusalẹmu—àní gbogbo àjálù ní mo ti mú wá sórí rẹ̀.
netheles saluacioun of hem that leden out sones and douytris, schal be left ther ynne. Lo! thei schulen go out to you, and ye schulen se the weie of hem, and the fyndyngis of hem; and ye schulen be coumfortid on the yuel, which Y brouyte in on Jerusalem, in alle thingis whiche Y bar in on it.
23 Nígbà tí ẹ̀yin bá rí ìwà àti ìṣe wọn, a ó tù yín nínú, nítorí pé ẹ̀yin yóò mọ̀ pé èmi kò ṣe nǹkan kan láìnídìí, ni Olúwa Olódùmarè wí.”
And thei schulen coumforte you, whanne ye schulen se the weie of hem and the fyndyngis of hem; and ye schulen knowe, that not in veyn Y dide alle thingis, what euer thingis Y dide there ynne, seith the Lord almyyti.

< Ezekiel 14 >