< Ezekiel 14 >

1 Díẹ̀ nínú àwọn àgbàgbà Israẹli wá sọ́dọ̀ mi, wọ́n sì jókòó níwájú mi.
Тогава дойдоха при мене някои от Израилевите старейшини та седнаха пред мене.
2 Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá,
И Господното слово дойде към мене и рече:
3 “Ọmọ ènìyàn, àwọn ọkùnrin wọ̀nyí ti gbé òrìṣà kalẹ̀ sínú ọkàn wọn, wọ́n sì gbé àwọn ohun tó lè mú wọn ṣubú sínú ẹ̀ṣẹ̀ síwájú wọn; Èmi yóò ha jẹ́ kí wọ́n béèrè lọ́wọ́ mi rárá bí?
Сине човешки, тия мъже прегърнаха идолите си в сърцата си, и туриха беззаконието си като препънка пред лицето си; бива ли да се допитват тия до Мене?
4 Nítorí náà, sọ fún wọn pé, ‘Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Bí ẹnikẹ́ni ní ilé Israẹli tó gbé òrìṣà sí ọkàn rẹ̀, tó tún gbé ohun ìkọ̀sẹ̀ síwájú rẹ̀, tí ó sì wá sọ́dọ̀ wòlíì, Èmi Olúwa fúnra mi ni yóò dá ẹni tí ó wa lóhùn gẹ́gẹ́ bí ìwà ìbọ̀rìṣà rẹ.
Затова, говори им като им речеш: Така казва Господ Иеова: На всекиго от Израилевия дом, който прегърне идолите си в сърцето си, и тури беззаконието си като препънка пред лицето си, и дойде при пророка, Аз Господ ще му отговоря както подобава според многото му идоли,
5 Èmi yóò ṣe èyí láti gba ọkàn àwọn ará Israẹli tó ti tẹ̀lé òrìṣà wọn lọ padà sí ọ̀dọ̀ mi.’
за да хвана Израилевия дом за самото им сърце, понеже те всички станаха чужди за Мене чрез идолите си.
6 “Nítorí náà sọ fún ilé Israẹli, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: Ẹ ronúpìwàdà! Ẹ yípadà kúrò lọ́dọ̀ òrìṣà yín, kí ẹ̀yin sì kọ gbogbo ìwà ìríra yín sílẹ̀!
Затова, кажи на Израилевия дом: Така казва Господ Иеова: Покайте се, отвърнете се от идолите си, да! отвърнете лицата си от всичките си мерзости.
7 “‘Bí ẹnikẹ́ni ní ilé Israẹli tàbí àlejò tó ń gbé ní ilẹ̀ Israẹli, bá ya ara rẹ̀ kúrò lọ́dọ̀ mi, tó gbé òrìṣà rẹ̀ sí ọkàn rẹ̀, tó tún gbé ohun tó mú ni ṣubú sínú ẹ̀ṣẹ̀ síwájú rẹ, lẹ́yìn èyí tó tún lọ sọ́dọ̀ wòlíì láti béèrè nǹkan lọ́wọ́ mi! Èmi Olúwa fúnra ara mi ní èmi yóò dá a lóhùn.
Защото на всекиго от Израилевия дом, или от чужденците, които пришелствуват в Израиля, който стане чужд за Мене като прегърне идолите си в сърцето си, и тури беззаконието си като препънка пред лицето си, и дойде при пророка, за да се допита до Мене чрез него, Аз Господ ще му отговоря непосредствено от Себе Си;
8 Èmi yóò lòdì si irú ọkùnrin bẹ́ẹ̀ lọ́nà òdì, Èmi yóò sì fi i ṣe àmì àti òwe. Èmi yóò sì gé e kúrò láàrín àwọn ènìyàn mi. Nígbà náà, ẹ̀yin yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa.
защото ще насоча лицето Си против такъв човек, ще го направя за учудване, за знамение и поговорка, и ще го отсека отсред людете Си; и ще познаете, че Аз съм Господ.
9 “‘Bí wọ́n bá sì tan wòlíì náà láti sọtẹ́lẹ̀, Èmi Olúwa ló tan wòlíì náà, Èmi yóò nawọ́ sí i, èmi yóò sì pa á run kúrò láàrín àwọn ènìyàn mi Israẹli.
И ако би се подмамил пророкът да проговори дума, Аз Господ подмамих този пророк; и ще простра ръката Си върху него, та ще го изтребя отсред людете Си Израиля.
10 Wọn yóò ru ẹ̀bi ẹ̀ṣẹ̀ wọn—ìjìyà kan náà là ó fún wòlíì àti ẹni tó lọ béèrè lọ́dọ̀ rẹ̀.
И ще понесат наказанието на беззаконието си, (наказанието на пророка ще бъде като наказанието на онзи, който би се допитвал чрез него),
11 Kí ilé Israẹli má ba à ṣáko kúrò lọ́dọ̀ mi mọ, kí wọ́n má ba à fi gbogbo ìrékọjá ba ara wọn jẹ́ mọ́. Ṣùgbọ́n kí wọ́n le jẹ́ ènìyàn mi, kí Èmi náà sì le jẹ́ Ọlọ́run wọn, ni Olúwa Olódùmarè wí.’”
за да не блуждае вече Израилевият дом от Мене, нито да се оскверняват вече с всичките си престъпления, но да бъдат Мои люде, и Аз да бъде техен Бог, казва Господ Иеова.
12 Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé:
И Господното слово дойде към мене и рече:
13 “Ọmọ ènìyàn bí orílẹ̀-èdè kan bá dẹ́ṣẹ̀ sí mi nípa ìwà àìṣòdodo, èmi yóò nawọ́ mi jáde sí wọn, láti gé ìpèsè oúnjẹ wọn, èmi yóò rán ìyàn sí wọn, èmi yóò sì pa ènìyàn àti ẹranko inú rẹ̀,
Сине човешки, когато някоя земя Ми съгреши с коварство, и Аз простра ръката Си върху нея, и строша подпорката й от хляба, и пратя глад върху нея, и отсека от нея и човек и животно,
14 bí àwọn ọkùnrin mẹ́ta yìí. Noa, Daniẹli àti Jobu tilẹ̀ wà nínú rẹ, kìkì ẹ̀mí ara wọn nìkan ni wọ́n lé fi òdodo wọn gbàlà, Olúwa Olódùmarè wí.
та ако тия трима мъже, Ное, Даниил и Иов, бяха всред нея, те щяха да избавят само своите си души чрез правдата си, казва Господ Иеова.
15 “Tàbí bí mo bá jẹ́ kí ẹranko búburú gba orílẹ̀-èdè náà kọjá, tí wọn sì bà á jẹ́ tó bẹ́ẹ̀ tí ó di ahoro, tí kò sí ẹni tó le gba ibẹ̀ kọjá torí ẹranko búburú yìí,
Ако бих докарал против земята люти зверове, и те я обезлюдяха, та да запустее, тъй че да не може някой да мине през нея от зверовете,
16 bí àwọn ọkùnrin mẹ́ta wọ̀nyí tilẹ̀ wà nínú rẹ̀, Olúwa Olódùmarè wí pé, wọn kì yóò gba ọmọkùnrin tàbí ọmọbìnrin là: àwọn nìkan ni a ó gbàlà, ṣùgbọ́n ilẹ̀ náà yóò di ahoro.
пак, и тримата тия мъже ако бяха всред нея, заклевам се в живота Си, казва Господ Иеова, те не щяха да избавят нито синове нито дъщери, само сами те щяха да се избавят, а земята щеше да запустее.
17 “Tàbí tí mo bá mú idà kọjá láàrín orílẹ̀-èdè náà tí mo wí pé, ‘Ẹ jẹ́ kí idà kọjá láàrín ilẹ̀ náà,’ tí mo sì tú ìbínú gbígbóná lé wọn lórí nípa ìtàjẹ̀ sílẹ̀, tí mo pa ènìyàn àti ẹranko inú rẹ.
Или ако изнесях меч върху оная земя, и речех: Мечо, мини през земята, та да отсека от нея и човек и животно,
18 Bí àwọn ọkùnrin mẹ́ta yìí tilẹ̀ wà nínú rẹ̀, Olúwa Olódùmarè wí pé, bí mo ti wà, wọn ki yóò gba ọmọkùnrin tàbí ọmọbìnrin là, ṣùgbọ́n àwọn tìkára wọn nìkan ni a ó gbàlà.
то и тримата тия мъже ако бяха всред нея, заклевам се в живота Си, казва Господ Иеова, те не щяха да избавят ни синове ни дъщери, но само те щяха да се избавят.
19 “Tàbí bí mo rán àjàkálẹ̀-ààrùn si ilẹ̀ náà, ti mo si da ìrunú mi lé e lórí pẹ̀lú ẹ̀jẹ̀, láti gé ènìyàn àti ẹranko kúrò nínú rẹ̀,
Или ако нанесях мор върху оная земя, и излеех яростта Си върху нея с кръв, та да отсека от нея и човек и животно,
20 bó tilẹ̀ jẹ́ pé Noa, Daniẹli àti Jobu wà nínú rẹ, bí mo ti wà láààyè ni Olúwa Olódùmarè wí, wọn kò le gba ọmọkùnrin tàbí ọmọbìnrin wọn lá. Ara wọn nìkan ni ìwà òdodo wọn lè gbàlà.
пак, заклевам се в живота Си, казва Господ Иеова, ако бяха всред нея Ное, Даниил и Иов, те не щяха да избавят нито син нито дъщеря, но щяха да избавят само своите си души чрез правдата си;
21 “Nítorí báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, báwo ni yóò ti burú tó nígbà tí mo bá rán ìdájọ́ kíkan mi mẹ́rin sórí Jerusalẹmu, èyí ni idà àti ìyàn, ẹranko búburú àti àjàkálẹ̀-ààrùn láti pa àwọn ènìyàn àti ẹranko inú rẹ̀!
прочее (така казва Господ Иеова), колко повече когато изпратя четирите Си тежки съдби върху Ерусалим, меча, глада, лютите зверове, и мора, та да отсека от него и човек и животно!
22 Síbẹ̀, yóò ṣẹ́kù àwọn díẹ̀, àwọn ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin tí a ó kó jáde nínú rẹ̀. Wọn yóò wá bá yin, ẹ̀yin yóò rí ìwà àti ìṣe wọn, nígbà náà ni ẹ̀yin yóò rí ìtùnú nípa àjálù tí mo mú wá sórí Jerusalẹmu—àní gbogbo àjálù ní mo ti mú wá sórí rẹ̀.
Но, ето, ще останат в него избавилите се, синове и дъщери, които ще се изнесат; ето, те ще излязат при вас, и ще видите постъпките им и делата им; и ще се утешите относно злото, което нанесох върху Ерусалим, да! относно всичко що нанесох върху него.
23 Nígbà tí ẹ̀yin bá rí ìwà àti ìṣe wọn, a ó tù yín nínú, nítorí pé ẹ̀yin yóò mọ̀ pé èmi kò ṣe nǹkan kan láìnídìí, ni Olúwa Olódùmarè wí.”
Те ще ви утешат, когато видите постъпките им и делата им; и ще познаете, че Аз не съм сторил без причина всичко това що съм сторил в него, казва Господ Иеова.

< Ezekiel 14 >