< Ezekiel 13 >

1 Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé:
Perwerdigarning sözi manga kélip mundaq déyildi: —
2 “Ọmọ ènìyàn sọtẹ́lẹ̀ lòdì sí àwọn wòlíì Israẹli tó ń sọtẹ́lẹ̀, kí o sì sọ fún àwọn tí ń sọtẹ́lẹ̀ láti inú èrò ọkàn wọn, ‘Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa!
«I insan oghli, sen Israilning bésharet bergüchi peyghemberliri, yeni öz tesewwuri bilen bésharet bergüchilerni eyiblep bésharet bérip: «Perwerdigarning sözini anglanglar!» — dégin.
3 Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Ègbé ni fún àwọn aṣiwèrè wòlíì tó ń tẹ̀lé ẹ̀mí ara wọn tí wọn kò sì rí nǹkan kan!
Reb Perwerdigar mundaq deydu: — Öz rohigha egiship mangidighan, héch wehiyni körmigen hamaqet peyghemberlerning haligha way!
4 Israẹli àwọn wòlíì rẹ dàbí kọ̀lọ̀kọ̀lọ̀ nínú pápá.
I Israil, séning peyghemberliring xuddi xarabiler arisida yürüwatqan tülkilerdek boldi.
5 Ẹ̀yin kò gòkè láti mọ odi tí ó ya ní ilé Israẹli kí wọ́n ba lè dúró gbọin ní ojú ogun ní ọjọ́ Olúwa.
Siler bösülgen jaylargha chiqmighansiler, uning Perwerdigarning künide bolidighan jengde puxta turushi üchün Israil jemetining buzulghan témini héch yasimidinglar.
6 Ìran àti àfọ̀ṣẹ wọn jẹ́ èké. Wọ́n wí pé, “Olúwa wí,” nígbà tí Olúwa kò rán wọn, síbẹ̀ wọ́n fẹ́ kí Olúwa mú ọ̀rọ̀ wọn ṣẹ.
«Perwerdigar mundaq deydu» dégüchiler bolsa peqet saxta bir körünüshni we yalghan palni körgenlerdin ibarettur; Perwerdigar ularni ewetmigen; biraq ular öz sözining emelge ashurulushini ümid qilidu.
7 Ẹ̀yin kò ha ti rí ìran asán, ẹ̀yin kò ha ti fọ àfọ̀ṣẹ èké, nígbà tí ẹ̀yin sọ pé, “Olúwa wí,” bẹ́ẹ̀ sì ni Èmi kò sọ̀rọ̀?
Siler «Perwerdigar mundaq deydu» dégininglarda, Men héch söz qilmighan tursam, siler saxta bir «alamet körünüsh»ni körgen, yalghan palni éytqan emesmu?
8 “‘Nítorí náà, báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, Nítorí ọ̀rọ̀ asán àti ìran èké yín, mo lòdì sí yín: ni Olúwa Olódùmarè wí.
Shunga Reb Perwerdigar mundaq deydu: «Siler oydurma sözligininglar, yalghan «alamet körünüsh»lerni körgininglar tüpeylidin, emdi mana, Men silerge qarshimen, — deydu Reb Perwerdigar,
9 Ọwọ́ mi yóò sì wà lórí àwọn wòlíì tó ń ríran asán, tó sì ń sọ àfọ̀ṣẹ èké. Wọn kò ní sí nínú ìjọ àwọn ènìyàn mi, a ó sì yọ orúkọ wọn kúrò nínú àkọsílẹ̀ ilé Israẹli, bẹ́ẹ̀ ni wọn kò sì ní wọ ilẹ̀ Israẹli mọ́. Nígbà náà ni ẹ̀yin yóò sì mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa Olódùmarè.
— Méning qolum saxta «alamet körünüsh»ni körgen we yalghan palni éytqan peyghemberler bilen qarshilishidu; ular öz xelqimning kéngishide olturmaydu, ular Israil jemetining nesebnamiside xatirilenmeydu; ular Israilning zéminigha héch kirgüzülmeydu; shuning bilen siler Méning Reb Perwerdigar ikenlikimni tonup yétisiler.
10 “‘Wọ́n ti mú àwọn ènìyàn mi ṣìnà, wọ́n ní, “Àlàáfíà,” nígbà tí kò sí àlàáfíà, nítorí pé bí àwọn ènìyàn bá mọ odi fẹ́lẹ́fẹ́lẹ́, wọn a fi amọ̀ àìpò rẹ́ ẹ, wọn ó sì fi ẹfun kùn ún,
Berheq, ular tinch-amanliq bolmighandimu «tinch-amanliq!» dep jar sélip, xelqimni éziqturghanliqi üchün, birsi népiz ara tamni qopursa, ular kélip peqet uni hak suwaq bilen aqartip qoyghanliqi üchün —
11 nítorí náà, sọ fún àwọn tí ń fi amọ̀ àìpò rẹ́ ẹ àti àwọn tó fi ẹfun kùn ún pé, odi náà yóò wó, ìkún omi òjò yóò dé, Èmi yóò sì rán òkúta yìnyín sọ̀kalẹ̀, ìjì líle yóò ya á lulẹ̀.
Tamni hak suwaq bilen aqartiwatqanlargha: «Bu tam yiqilidu!» dégin! Kelkündek bir yamghur yaghidu! I yoghan möldürler, siler chüshisiler! Dehshetlik bir shamal chiqidu;
12 Nígbà tí odi náà bá sì wó, ǹjẹ́ àwọn ènìyàn wọn kò níbi yín pé, “Rírẹ́ tí ẹ rẹ́ ẹ dà, ibo sì ni ẹfun tí ẹ fi kùn ún wà?”
we mana, tam örülüp chüshkende, xeq silerdin: «Siler bu tamni suwighan hak suwaq qéni!» dep sorimamdu?
13 “‘Nítorí náà, báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, Nínú ìbínú gbígbóná mi, èmi yóò tu afẹ́fẹ́ líle lé e lórí nínú ìrunú mi, àti nínú ìbínú mi, òjò yóò sì rọ̀ púpọ̀ nínú ìbínú mi, àti yìnyín ńlá nínú ìrunú mi láti pa wọ́n run.
Shunga Reb Perwerdigar mundaq deydu: «Öz qehrim bilen dehshetlik bir shamal partlitip chiqirimen; Méning achchiqimdin kelkündek bir yamghur we hemmini halak qilidighan qehrlik möldürler yaghidu.
14 Èmi yóò wó ògiri tí ẹ fi amọ̀ àìpò rẹ́, èyí tí ẹ fi ẹfun kùn lulẹ̀ dé bi pé ìpìlẹ̀ rẹ yóò hàn jáde. Nígbà ti odi náà wó palẹ̀, a ó sì run yín sínú rẹ̀, ẹ̀yin yóò sì mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.
Shuning bilen Men siler hak suwaq bilen aqartqan tamni ghulitip, uning ulini ashkare qilip, uni yer bilen yeksan qilimen; u ghulap chüshkende, siler uning arisida halak bolisiler; we Méning Perwerdigar ikenlikimni tonup yétisiler.
15 Báyìí ni Èmi yóò ṣe lo ìbínú mi lórí odi yìí àti àwọn to fi amọ̀ àìpò rẹ́ ẹ, tí wọ́n sì fi ẹfun kùn ún. Èmi yóò sì sọ fún yín pé, “Kò sí odi mọ́, bẹ́ẹ̀ ni àwọn tó rẹ́ ẹ náà kò sí mọ́.
Shundaq qilip Men qehrimni tam hem uni hak suwaq bilen aqartqanlarning üstige chüshürüp pighandin chiqimen; we: «Tam yoq boldi, shundaqla uni hak suwaq bilen aqartqanlar, yeni Yérusalém toghruluq bésharet bergüchi, héch tinch-amanliq bolmighandimu u toghruluq tinch-amanliqni körsetken «alamet körünüsh»ni körgen Israilning peyghemberlirimu yoq boldi» — deymen».
16 Àwọn wòlíì Israẹli tí ń sọtẹ́lẹ̀ sí Jerusalẹmu, tí wọn ríran àlàáfíà sí i nígbà ti kò sì àlàáfíà, báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí.”’
17 “Nísinsin yìí, ọmọ ènìyàn, dojúkọ àwọn ọmọbìnrin ènìyàn rẹ tí wọ́n ń sọtẹ́lẹ̀ láti inú èrò ọkàn wọn, sọtẹ́lẹ̀ sí wọn
«Emdi sen, i insan oghli, öz tesewwuri boyiche bésharet bergüchi öz xelqingning qizlirigha yüzüngni qaritip, ularni eyiblep bésharet bérip mundaq dégin: —
18 wí pé, ‘Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí. Ègbé ni fún ẹ̀yin obìnrin tí ẹ ń rán ìfúnpá òògùn sí ìgbọ̀nwọ́ àwọn ènìyàn, tí ẹ ń ṣe ìbòjú oríṣìíríṣìí fún orí oníkálùkù ènìyàn láti ṣọdẹ ọkàn wọn. Ẹ̀yin yóò wa dẹkùn fún ọkàn àwọn ènìyàn mi bí? Ẹ̀yin yóò sì gba ọkàn ti ó tọ̀ yín wá là bí?
Reb Perwerdigar mundaq deydu: «Öz béghishlirining herbirige [séhirlik] bilezüklerni qadap, janlarni tuzaqqa élish üchün herqandaq égiz-pakar ademlerning béshigha perenchini yasighanlargha way! Emdi siler öz xelqimning janlirini tuzaqqa chüshürüp, janliringlarni saq qaldurimiz dewatamsiler?
19 Nítorí ẹ̀kúnwọ́ ọkà barle àti òkèlè oúnjẹ. Ẹ ti pa àwọn tí kò yẹ kí ẹ pa, ẹ sì fi àwọn tí kò yẹ kó wà láààyè sílẹ̀ nípa irọ́ tí ẹ ń pa fún àwọn ènìyàn mi, èyí tí àwọn náà ń fetí sí.
Nechche tutam arpa, nechche chishlem nanni dep siler Manga kupurluq qilip, yalghan sözge qulaq salidighan Méning xelqimge yalghanchiliqinglar arqiliq ölmeske tégishliklirini öltürüp, tirik qalmasliqqa tégishliklirini hayat qaldurmaqchimusiler?
20 “‘Nítorí náà, báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí. Mo lòdì sí ìfúnpá òògùn tí ẹ fi ń ṣọdẹ ọkàn ènìyàn káàkiri bí ẹyẹ, Èmi yóò ya á kúrò lápá yín, Èmi yóò sì dá ọkàn àwọn ènìyàn tí ẹ ń ṣọdẹ sílẹ̀.
Shunga Reb Perwerdigar mundaq deydu: «Mana, Men silerning qushlarni tuzaqqa chüshürgendek kishilerni tuzaqqa chüshürgüchi séhirlik «téngiq»liringlargha qarshimen, Men ularni bilikinglardin yirtip tashlaymen; shuning bilen siler qushlarni tuzaqqa chüshürgendek tutqan kishilerni erkinlikke uchuriwétimen.
21 Èmi yóò ya àwọn ìbòjú yín, láti gba àwọn ènìyàn mi lọ́wọ́ yín, wọn kò sì ní jẹ́ ìjẹ fún yín mọ́. Nígbà náà ni ẹ̀yin yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.
Men silerning perenjiliringlarnimu yirtip tashliwétip, xelqimni qolunglardin qutquzimen; ular yene qolunglarda olja bolup turmaydu; shuning bilen siler Méning Perwerdigar ikenlikimni tonup yétisiler.
22 Nítorí pé ẹ̀yin ti ba ọkàn àwọn olódodo jẹ́ pẹ̀lú irọ́ yín, nígbà tí Èmi kò mú ìbànújẹ́ bá wọn, àti nítorí ẹ̀yin ti mú ọkàn àwọn ènìyàn búburú le, kí wọ́n má ba à kúrò nínú ọ̀nà ibi wọn dé bi tí wọn yóò fi gba ẹ̀mí wọn là,
Siler yalghanchiliq bilen, Özüm azar bermigen heqqaniy ademlerning könglige azar bergenlikinglar üchün, shundaqla rezil ademlerning hayatini saqlap qutquzushqa ularni rezil yolidin yandurmay, eksiche ularning qolini kücheytkininglar üchün,
23 nítorí èyí, ẹ̀yin kò ní í ríran èké, ẹ̀yin kò sì ní fọ àfọ̀ṣẹ mọ́. Èmi yóò gba àwọn ènìyàn mi lọ́wọ́ yín. Ẹ̀yin yóò sì mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.’”
siler quruq «alamet közünüsh»lerni ikkinchi bolup körmeysiler, yaki yalghan palchiliq qilmaysiler; Men Öz xelqimni qolunglardin qutquzimen; shuning bilen siler Méning Perwerdigar ikenlikimni tonup yétisiler».

< Ezekiel 13 >