< Ezekiel 13 >

1 Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé:
Och HERRENS ord kom till mig; han sade:
2 “Ọmọ ènìyàn sọtẹ́lẹ̀ lòdì sí àwọn wòlíì Israẹli tó ń sọtẹ́lẹ̀, kí o sì sọ fún àwọn tí ń sọtẹ́lẹ̀ láti inú èrò ọkàn wọn, ‘Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa!
Du människobarn, profetera mot Israels profeterande profeter; säg till dem som profetera efter sina egna hjärtans ingivelser: Hören HERRENS ord.
3 Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Ègbé ni fún àwọn aṣiwèrè wòlíì tó ń tẹ̀lé ẹ̀mí ara wọn tí wọn kò sì rí nǹkan kan!
Så säger Herren, HERREN: Ve eder, I dåraktiga profeter, som följen eder egen ande och syner som I icke haven sett! --
4 Israẹli àwọn wòlíì rẹ dàbí kọ̀lọ̀kọ̀lọ̀ nínú pápá.
Lika rävar på öde platser äro dina profeter, Israel.
5 Ẹ̀yin kò gòkè láti mọ odi tí ó ya ní ilé Israẹli kí wọ́n ba lè dúró gbọin ní ojú ogun ní ọjọ́ Olúwa.
I haven icke trätt fram i gapet eller fört upp någon mur omkring Israels hus, så att det har kunnat bestå i striden på HERRENS dag.
6 Ìran àti àfọ̀ṣẹ wọn jẹ́ èké. Wọ́n wí pé, “Olúwa wí,” nígbà tí Olúwa kò rán wọn, síbẹ̀ wọ́n fẹ́ kí Olúwa mú ọ̀rọ̀ wọn ṣẹ.
Nej, deras syner voro falskhet och deras spådomar lögn, fastän de sade "Så har HERREN sagt." HERREN hade ju icke sänt dem, men de hoppades att deras tal ändå skulle gå i fullbordan.
7 Ẹ̀yin kò ha ti rí ìran asán, ẹ̀yin kò ha ti fọ àfọ̀ṣẹ èké, nígbà tí ẹ̀yin sọ pé, “Olúwa wí,” bẹ́ẹ̀ sì ni Èmi kò sọ̀rọ̀?
Ja, förvisso var det falska syner som I skådaden och lögnaktiga spådomar som I uttaladen, fastän I saden: "Så har HERREN sagt." Jag hade ju icke talat något sådant.
8 “‘Nítorí náà, báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, Nítorí ọ̀rọ̀ asán àti ìran èké yín, mo lòdì sí yín: ni Olúwa Olódùmarè wí.
Därför säger Herren, HERREN så: Eftersom edert tal är falskhet och edra syner äro lögn, se, därför skall jag komma över eder, säger Herren, HERREN.
9 Ọwọ́ mi yóò sì wà lórí àwọn wòlíì tó ń ríran asán, tó sì ń sọ àfọ̀ṣẹ èké. Wọn kò ní sí nínú ìjọ àwọn ènìyàn mi, a ó sì yọ orúkọ wọn kúrò nínú àkọsílẹ̀ ilé Israẹli, bẹ́ẹ̀ ni wọn kò sì ní wọ ilẹ̀ Israẹli mọ́. Nígbà náà ni ẹ̀yin yóò sì mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa Olódùmarè.
Och min hand skall drabba profeterna som skåda falska syner och spå lögnaktiga spådomar. De skola icke få en plats i mitt folks församling och skola icke bliva upptagna i förteckningen på Israels hus, ej heller skola de få komma till Israels land; och I skolen förnimma att jag är Herren, HERREN.
10 “‘Wọ́n ti mú àwọn ènìyàn mi ṣìnà, wọ́n ní, “Àlàáfíà,” nígbà tí kò sí àlàáfíà, nítorí pé bí àwọn ènìyàn bá mọ odi fẹ́lẹ́fẹ́lẹ́, wọn a fi amọ̀ àìpò rẹ́ ẹ, wọn ó sì fi ẹfun kùn ún,
Eftersom, ja, eftersom de förde mitt folk vilse, i det att de sade: "Allt står väl till", och dock stod icke allt väl till, och eftersom de, när folket bygger upp en mur, vitmena den,
11 nítorí náà, sọ fún àwọn tí ń fi amọ̀ àìpò rẹ́ ẹ àti àwọn tó fi ẹfun kùn ún pé, odi náà yóò wó, ìkún omi òjò yóò dé, Èmi yóò sì rán òkúta yìnyín sọ̀kalẹ̀, ìjì líle yóò ya á lulẹ̀.
därför må du säga till dessa vitmenare att den måste falla. Ett slagregn skall komma -- ja, I skolen fara ned, I hagelstenar, och du skall bryta ned den, du stormvind!
12 Nígbà tí odi náà bá sì wó, ǹjẹ́ àwọn ènìyàn wọn kò níbi yín pé, “Rírẹ́ tí ẹ rẹ́ ẹ dà, ibo sì ni ẹfun tí ẹ fi kùn ún wà?”
Och när så väggen faller, då skall man förvisso säga till eder: "Var är nu vitmeningen som I ströken på?"
13 “‘Nítorí náà, báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, Nínú ìbínú gbígbóná mi, èmi yóò tu afẹ́fẹ́ líle lé e lórí nínú ìrunú mi, àti nínú ìbínú mi, òjò yóò sì rọ̀ púpọ̀ nínú ìbínú mi, àti yìnyín ńlá nínú ìrunú mi láti pa wọ́n run.
Därför säger Herren, HERREN så; Jag skall i min förtörnelse låta en stormvind bryta lös, ett slagregn skall komma genom min vrede, och hagelstenar genom min förtörnelse, så att det bliver en ände därpå.
14 Èmi yóò wó ògiri tí ẹ fi amọ̀ àìpò rẹ́, èyí tí ẹ fi ẹfun kùn lulẹ̀ dé bi pé ìpìlẹ̀ rẹ yóò hàn jáde. Nígbà ti odi náà wó palẹ̀, a ó sì run yín sínú rẹ̀, ẹ̀yin yóò sì mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.
Och jag skall förstöra väggen som I beströken med vitmening, jag skall slå den till jorden, så att dess grundval bliver blottad. Och när den faller, skolen I förgås därinne; och I skolen förnimma att jag är HERREN.
15 Báyìí ni Èmi yóò ṣe lo ìbínú mi lórí odi yìí àti àwọn to fi amọ̀ àìpò rẹ́ ẹ, tí wọ́n sì fi ẹfun kùn ún. Èmi yóò sì sọ fún yín pé, “Kò sí odi mọ́, bẹ́ẹ̀ ni àwọn tó rẹ́ ẹ náà kò sí mọ́.
Och jag skall uttömma min förtörnelse på väggen och på dem som hava bestrukit den med vitmening; och så skall jag säga till eder: Det är ute med väggen, det är ute med dess vitmenare,
16 Àwọn wòlíì Israẹli tí ń sọtẹ́lẹ̀ sí Jerusalẹmu, tí wọn ríran àlàáfíà sí i nígbà ti kò sì àlàáfíà, báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí.”’
med Israels profeter, som profeterade om Jerusalem och skådade syner, det till behag, om att allt stod väl till, och dock stod icke allt väl till, säger Herren, HERREN.
17 “Nísinsin yìí, ọmọ ènìyàn, dojúkọ àwọn ọmọbìnrin ènìyàn rẹ tí wọ́n ń sọtẹ́lẹ̀ láti inú èrò ọkàn wọn, sọtẹ́lẹ̀ sí wọn
Och du, människobarn, vänd ditt ansikte mot dina landsmaninnor som profetera efter sina egna hjärtans ingivelser; profetera mot dem
18 wí pé, ‘Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí. Ègbé ni fún ẹ̀yin obìnrin tí ẹ ń rán ìfúnpá òògùn sí ìgbọ̀nwọ́ àwọn ènìyàn, tí ẹ ń ṣe ìbòjú oríṣìíríṣìí fún orí oníkálùkù ènìyàn láti ṣọdẹ ọkàn wọn. Ẹ̀yin yóò wa dẹkùn fún ọkàn àwọn ènìyàn mi bí? Ẹ̀yin yóò sì gba ọkàn ti ó tọ̀ yín wá là bí?
och säg: Så säger Herren, HERREN: Ve eder som syn bindlar till alla handleder och gören slöjor till alla huvuden, både ungas och gamlas, för att så fånga själar! Skullen I få fånga själar bland mitt folk och döma somliga själar till liv, eder till vinning,
19 Nítorí ẹ̀kúnwọ́ ọkà barle àti òkèlè oúnjẹ. Ẹ ti pa àwọn tí kò yẹ kí ẹ pa, ẹ sì fi àwọn tí kò yẹ kó wà láààyè sílẹ̀ nípa irọ́ tí ẹ ń pa fún àwọn ènìyàn mi, èyí tí àwọn náà ń fetí sí.
I som för några nävar korn och några bitar bröd ohelgen mig hos mitt folk, därmed att I dömen till döden själar som icke skola dö, och dömen till liv själar som icke skola leva, i det att I ljugen för mitt folk, som gärna hör lögn?
20 “‘Nítorí náà, báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí. Mo lòdì sí ìfúnpá òògùn tí ẹ fi ń ṣọdẹ ọkàn ènìyàn káàkiri bí ẹyẹ, Èmi yóò ya á kúrò lápá yín, Èmi yóò sì dá ọkàn àwọn ènìyàn tí ẹ ń ṣọdẹ sílẹ̀.
Nej, och därför säger Herren, HERREN så: Se, jag skall väl nå edra bindlar, i vilka I fången själarna såsom fåglar, och skall slita dem från edra armar; och jag skall giva själarna fria, de själar som I haven fångat såsom fåglar.
21 Èmi yóò ya àwọn ìbòjú yín, láti gba àwọn ènìyàn mi lọ́wọ́ yín, wọn kò sì ní jẹ́ ìjẹ fún yín mọ́. Nígbà náà ni ẹ̀yin yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.
Och jag skall slita sönder edra slöjor och rädda mitt folk ur eder hand, och de skola icke mer vara ett byte i eder hand; och I skolen förnimma att jag är HERREN.
22 Nítorí pé ẹ̀yin ti ba ọkàn àwọn olódodo jẹ́ pẹ̀lú irọ́ yín, nígbà tí Èmi kò mú ìbànújẹ́ bá wọn, àti nítorí ẹ̀yin ti mú ọkàn àwọn ènìyàn búburú le, kí wọ́n má ba à kúrò nínú ọ̀nà ibi wọn dé bi tí wọn yóò fi gba ẹ̀mí wọn là,
Eftersom I genom lögnaktigt tal haven gjort den rättfärdige försagd i hjärtat, honom som jag ingalunda ville plåga, men däremot haven styrkt den ogudaktiges mod, så att han icke vänder om från sin onda väg och räddar sitt liv,
23 nítorí èyí, ẹ̀yin kò ní í ríran èké, ẹ̀yin kò sì ní fọ àfọ̀ṣẹ mọ́. Èmi yóò gba àwọn ènìyàn mi lọ́wọ́ yín. Ẹ̀yin yóò sì mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.’”
därför skolen I icke få fortsätta att skåda falska syner och att öva spådom; utan jag skall rädda mitt folk ur eder hand, och I skolen förnimma att jag är HERREN.

< Ezekiel 13 >