< Ezekiel 13 >
1 Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé:
Și cuvântul DOMNULUI a venit la mine, spunând:
2 “Ọmọ ènìyàn sọtẹ́lẹ̀ lòdì sí àwọn wòlíì Israẹli tó ń sọtẹ́lẹ̀, kí o sì sọ fún àwọn tí ń sọtẹ́lẹ̀ láti inú èrò ọkàn wọn, ‘Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa!
Fiu al omului, profețește împotriva profeților lui Israel care profețesc, și spune celor care profețesc din propriile lor inimi: Ascultați cuvântul DOMNULUI;
3 Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Ègbé ni fún àwọn aṣiwèrè wòlíì tó ń tẹ̀lé ẹ̀mí ara wọn tí wọn kò sì rí nǹkan kan!
Astfel spune Domnul DUMNEZEU: Vai profeților proști care urmează propriul lor duh și nu au văzut nimic!
4 Israẹli àwọn wòlíì rẹ dàbí kọ̀lọ̀kọ̀lọ̀ nínú pápá.
Israele, profeții tăi sunt ca vulpile în pustiuri.
5 Ẹ̀yin kò gòkè láti mọ odi tí ó ya ní ilé Israẹli kí wọ́n ba lè dúró gbọin ní ojú ogun ní ọjọ́ Olúwa.
Voi nu ați urcat în spărturi, nici nu ați ridicat îngrăditura pentru casa lui Israel, pentru a sta în picioare în bătălie în ziua DOMNULUI.
6 Ìran àti àfọ̀ṣẹ wọn jẹ́ èké. Wọ́n wí pé, “Olúwa wí,” nígbà tí Olúwa kò rán wọn, síbẹ̀ wọ́n fẹ́ kí Olúwa mú ọ̀rọ̀ wọn ṣẹ.
Ei au văzut deșertăciune și ghicire mincinoasă, spunând: DOMNUL spune; și DOMNUL nu i-a trimis; și au făcut pe [alții] să spere că vor întări cuvântul.
7 Ẹ̀yin kò ha ti rí ìran asán, ẹ̀yin kò ha ti fọ àfọ̀ṣẹ èké, nígbà tí ẹ̀yin sọ pé, “Olúwa wí,” bẹ́ẹ̀ sì ni Èmi kò sọ̀rọ̀?
Nu ați văzut voi o viziune deșartă și nu ați vorbit o ghicire mincinoasă, prin aceea când spuneți: DOMNUL spune [aceasta]; deși eu nu am vorbit?
8 “‘Nítorí náà, báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, Nítorí ọ̀rọ̀ asán àti ìran èké yín, mo lòdì sí yín: ni Olúwa Olódùmarè wí.
De aceea astfel spune Domnul DUMNEZEU: Pentru că ați vorbit deșertăciune și ați văzut minciuni, de aceea, iată, eu [sunt] împotriva voastră, spune Domnul DUMNEZEU.
9 Ọwọ́ mi yóò sì wà lórí àwọn wòlíì tó ń ríran asán, tó sì ń sọ àfọ̀ṣẹ èké. Wọn kò ní sí nínú ìjọ àwọn ènìyàn mi, a ó sì yọ orúkọ wọn kúrò nínú àkọsílẹ̀ ilé Israẹli, bẹ́ẹ̀ ni wọn kò sì ní wọ ilẹ̀ Israẹli mọ́. Nígbà náà ni ẹ̀yin yóò sì mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa Olódùmarè.
Și mâna mea va fi asupra profeților care văd deșertăciune și care ghicesc minciuni; ei nu vor fi în adunarea poporului meu, nici nu vor fi scriși în scrierea casei lui Israel, nici nu vor intra în țara lui Israel; și voi veți cunoaște că eu [sunt] Domnul DUMNEZEU.
10 “‘Wọ́n ti mú àwọn ènìyàn mi ṣìnà, wọ́n ní, “Àlàáfíà,” nígbà tí kò sí àlàáfíà, nítorí pé bí àwọn ènìyàn bá mọ odi fẹ́lẹ́fẹ́lẹ́, wọn a fi amọ̀ àìpò rẹ́ ẹ, wọn ó sì fi ẹfun kùn ún,
Pentru că, da pentru că au amăgit pe poporul meu, spunând: Pace; și nu [era] pace; și unul construiește un zid și, iată, alții îl tencuiesc cu [mortar] nestins;
11 nítorí náà, sọ fún àwọn tí ń fi amọ̀ àìpò rẹ́ ẹ àti àwọn tó fi ẹfun kùn ún pé, odi náà yóò wó, ìkún omi òjò yóò dé, Èmi yóò sì rán òkúta yìnyín sọ̀kalẹ̀, ìjì líle yóò ya á lulẹ̀.
Spune celor ce [îl] tencuiesc cu [mortar] nestins că va cădea; va fi o ploaie torențială; și voi, pietre mari de grindină, veți cădea; și un vânt furtunos [îl] va rupe.
12 Nígbà tí odi náà bá sì wó, ǹjẹ́ àwọn ènìyàn wọn kò níbi yín pé, “Rírẹ́ tí ẹ rẹ́ ẹ dà, ibo sì ni ẹfun tí ẹ fi kùn ún wà?”
Iată, după ce zidul va fi căzut, nu vi se va spune: Unde [este] tencuiala cu care [l-]ați tencuit?
13 “‘Nítorí náà, báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, Nínú ìbínú gbígbóná mi, èmi yóò tu afẹ́fẹ́ líle lé e lórí nínú ìrunú mi, àti nínú ìbínú mi, òjò yóò sì rọ̀ púpọ̀ nínú ìbínú mi, àti yìnyín ńlá nínú ìrunú mi láti pa wọ́n run.
De aceea, astfel spune Domnul DUMNEZEU: [Îl] voi rupe cu un vânt furtunos în furia mea; și va fi o ploaie torențială în mânia mea și pietre mari de grindină în furia [mea], pentru a-[l] mistui.
14 Èmi yóò wó ògiri tí ẹ fi amọ̀ àìpò rẹ́, èyí tí ẹ fi ẹfun kùn lulẹ̀ dé bi pé ìpìlẹ̀ rẹ yóò hàn jáde. Nígbà ti odi náà wó palẹ̀, a ó sì run yín sínú rẹ̀, ẹ̀yin yóò sì mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.
Astfel voi dărâma zidul pe care voi l-ați tencuit cu [mortar] nestins și îl voi doborî la pământ, astfel încât temelia acestuia va fi descoperită și el va cădea și voi veți fi mistuiți în mijlocul lui; și veți cunoaște că eu [sunt] DOMNUL.
15 Báyìí ni Èmi yóò ṣe lo ìbínú mi lórí odi yìí àti àwọn to fi amọ̀ àìpò rẹ́ ẹ, tí wọ́n sì fi ẹfun kùn ún. Èmi yóò sì sọ fún yín pé, “Kò sí odi mọ́, bẹ́ẹ̀ ni àwọn tó rẹ́ ẹ náà kò sí mọ́.
Astfel îmi voi împlini furia asupra zidului și asupra celor ce l-au tencuit cu [mortar] nestins și vă voi spune: Zidul nu [mai este], nici cei care l-au tencuit;
16 Àwọn wòlíì Israẹli tí ń sọtẹ́lẹ̀ sí Jerusalẹmu, tí wọn ríran àlàáfíà sí i nígbà ti kò sì àlàáfíà, báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí.”’
[Adică, ] profeții lui Israel care profețesc referitor la Ierusalim și care văd viziuni de pace pentru el, dar nu [este] pace, spune Domnul DUMNEZEU.
17 “Nísinsin yìí, ọmọ ènìyàn, dojúkọ àwọn ọmọbìnrin ènìyàn rẹ tí wọ́n ń sọtẹ́lẹ̀ láti inú èrò ọkàn wọn, sọtẹ́lẹ̀ sí wọn
De asemenea, tu fiu al omului, îndreaptă-ți fața împotriva fiicelor poporului tău, care profețesc din propria lor inimă; și profețește împotriva lor,
18 wí pé, ‘Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí. Ègbé ni fún ẹ̀yin obìnrin tí ẹ ń rán ìfúnpá òògùn sí ìgbọ̀nwọ́ àwọn ènìyàn, tí ẹ ń ṣe ìbòjú oríṣìíríṣìí fún orí oníkálùkù ènìyàn láti ṣọdẹ ọkàn wọn. Ẹ̀yin yóò wa dẹkùn fún ọkàn àwọn ènìyàn mi bí? Ẹ̀yin yóò sì gba ọkàn ti ó tọ̀ yín wá là bí?
Și spune: Astfel spune Domnul DUMNEZEU: Vai de [femeile] care cos pernițe pentru toți subțiorii și fac voaluri pentru cap de orice mărime pentru a vâna suflete! Veți vâna voi sufletele poporului meu și veți lăsa în viață [pe cei care vin] la voi?
19 Nítorí ẹ̀kúnwọ́ ọkà barle àti òkèlè oúnjẹ. Ẹ ti pa àwọn tí kò yẹ kí ẹ pa, ẹ sì fi àwọn tí kò yẹ kó wà láààyè sílẹ̀ nípa irọ́ tí ẹ ń pa fún àwọn ènìyàn mi, èyí tí àwọn náà ń fetí sí.
Și mă veți întina voi printre poporul meu pentru [câteva] mâini pline de orz și pentru bucăți de pâine, ca să ucideți sufletele care nu ar trebui să moară și să lăsați în viață sufletele care nu ar trebui să trăiască, mințind pe poporul meu care ascultă minciunile [voastre]?
20 “‘Nítorí náà, báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí. Mo lòdì sí ìfúnpá òògùn tí ẹ fi ń ṣọdẹ ọkàn ènìyàn káàkiri bí ẹyẹ, Èmi yóò ya á kúrò lápá yín, Èmi yóò sì dá ọkàn àwọn ènìyàn tí ẹ ń ṣọdẹ sílẹ̀.
De aceea, astfel spune Domnul DUMNEZEU: Iată, eu [sunt] împotriva pernițelor voastre cu care vânați acolo sufletele pentru a [le] face să zboare, și le voi rupe de la brațele voastre și voi lăsa sufletele să plece, sufletele pe care voi le vânați pentru a [le] face să zboare.
21 Èmi yóò ya àwọn ìbòjú yín, láti gba àwọn ènìyàn mi lọ́wọ́ yín, wọn kò sì ní jẹ́ ìjẹ fún yín mọ́. Nígbà náà ni ẹ̀yin yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.
Voalurile voastre le voi rupe de asemenea și voi elibera pe poporul meu din mâna voastră și ei nu vor mai fi în mâna voastră pentru a fi vânați; și veți cunoaște că eu [sunt] DOMNUL.
22 Nítorí pé ẹ̀yin ti ba ọkàn àwọn olódodo jẹ́ pẹ̀lú irọ́ yín, nígbà tí Èmi kò mú ìbànújẹ́ bá wọn, àti nítorí ẹ̀yin ti mú ọkàn àwọn ènìyàn búburú le, kí wọ́n má ba à kúrò nínú ọ̀nà ibi wọn dé bi tí wọn yóò fi gba ẹ̀mí wọn là,
Deoarece cu minciuni ați întristat inima celui drept, pe care eu nu l-am întristat; și ați întărit mâinile celui stricat, ca să nu se întoarcă de la calea lui stricată, promițându-i viața;
23 nítorí èyí, ẹ̀yin kò ní í ríran èké, ẹ̀yin kò sì ní fọ àfọ̀ṣẹ mọ́. Èmi yóò gba àwọn ènìyàn mi lọ́wọ́ yín. Ẹ̀yin yóò sì mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.’”
De aceea nu veți mai vedea deșertăciune, nici nu veți ghici ghiciri, căci voi elibera pe poporul meu din mâna voastră; și veți cunoaște că eu [sunt] DOMNUL.