< Ezekiel 13 >

1 Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé:
Niheo amako ty tsara’ Iehovà manao ty hoe;
2 “Ọmọ ènìyàn sọtẹ́lẹ̀ lòdì sí àwọn wòlíì Israẹli tó ń sọtẹ́lẹ̀, kí o sì sọ fún àwọn tí ń sọtẹ́lẹ̀ láti inú èrò ọkàn wọn, ‘Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa!
O ana’ ondatio, Mitokia amo mpitoki’ Israele mitokio, le ano ty hoe o mitoky boak’ an-tro’e ao avaoo, Mijanjiña ty tsara’ Iehovà;
3 Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Ègbé ni fún àwọn aṣiwèrè wòlíì tó ń tẹ̀lé ẹ̀mí ara wọn tí wọn kò sì rí nǹkan kan!
Hoe t’Iehovà Talè, Feh’ohatse amo mpitoky dereñe mañorike ty tro’e avao ie tsy mahatrea raha!
4 Israẹli àwọn wòlíì rẹ dàbí kọ̀lọ̀kọ̀lọ̀ nínú pápá.
Ry Israele, Hoe fanalok’ an-tanan-taolo eo o mpitoki’ areoo.
5 Ẹ̀yin kò gòkè láti mọ odi tí ó ya ní ilé Israẹli kí wọ́n ba lè dúró gbọin ní ojú ogun ní ọjọ́ Olúwa.
Tsy niañambone mb’amo heba’e ao nahareo; tsy nandranjia’ areo ty fahetse hahafitroara’ i anjomba’ Israeley an-kotakotake amy andro’ Iehovày.
6 Ìran àti àfọ̀ṣẹ wọn jẹ́ èké. Wọ́n wí pé, “Olúwa wí,” nígbà tí Olúwa kò rán wọn, síbẹ̀ wọ́n fẹ́ kí Olúwa mú ọ̀rọ̀ wọn ṣẹ.
Raha tsy vente’e naho fisikiliañe vìlañe ty niisa’ iereo, ie manao ty hoe: Hoe t’Iehovà; ie tsy nirahe’ Iehovà, fe liñisa’ iareo ho venteñe i entañey.
7 Ẹ̀yin kò ha ti rí ìran asán, ẹ̀yin kò ha ti fọ àfọ̀ṣẹ èké, nígbà tí ẹ̀yin sọ pé, “Olúwa wí,” bẹ́ẹ̀ sì ni Èmi kò sọ̀rọ̀?
Tsy aroñarom-bìlañe hao ty niisa’ areo, tsy fisikilian-dremborake hao ty nijoroa’ areo? ie manao ty hoe, Hoe t’Iehovà.—Izaho tsy nivolañe.
8 “‘Nítorí náà, báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, Nítorí ọ̀rọ̀ asán àti ìran èké yín, mo lòdì sí yín: ni Olúwa Olódùmarè wí.
Aa le hoe ty nafè’ Iehovà Talè; Kanao nisaontsy hakoahañe nahareo naho nahaisake vande; le atreatreko hoe t’Iehovà Talè.
9 Ọwọ́ mi yóò sì wà lórí àwọn wòlíì tó ń ríran asán, tó sì ń sọ àfọ̀ṣẹ èké. Wọn kò ní sí nínú ìjọ àwọn ènìyàn mi, a ó sì yọ orúkọ wọn kúrò nínú àkọsílẹ̀ ilé Israẹli, bẹ́ẹ̀ ni wọn kò sì ní wọ ilẹ̀ Israẹli mọ́. Nígbà náà ni ẹ̀yin yóò sì mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa Olódùmarè.
Le hatreatre’ ty tañako o mpitoky mpandrendre-draha kafoake naho misi­kily vandeo, tsy ho mpiamo fivori’ ondatikoo, mbore tsy ho sokirañe amy fanokira’ i anjomba’ Israeley naho tsy himoaha’ iareo ka ty an-tane’ Israele, hahafohina’ areo te Izaho Iehovà Talè.
10 “‘Wọ́n ti mú àwọn ènìyàn mi ṣìnà, wọ́n ní, “Àlàáfíà,” nígbà tí kò sí àlàáfíà, nítorí pé bí àwọn ènìyàn bá mọ odi fẹ́lẹ́fẹ́lẹ́, wọn a fi amọ̀ àìpò rẹ́ ẹ, wọn ó sì fi ẹfun kùn ún,
Amy te sinigì’ iareo ondatikoo ami’ty hoe: Fanintsiñañe; ie tsy eo ty fanintsiñañe; eo ty mandrafitse rindriñe naho ipakora’e sokay.
11 nítorí náà, sọ fún àwọn tí ń fi amọ̀ àìpò rẹ́ ẹ àti àwọn tó fi ẹfun kùn ún pé, odi náà yóò wó, ìkún omi òjò yóò dé, Èmi yóò sì rán òkúta yìnyín sọ̀kalẹ̀, ìjì líle yóò ya á lulẹ̀.
Ano ty hoe amo mampipakotse aze antsokaio te hihotrake izay; ho avy ty orañe handopatse, naho ihe ry havandra ro hagnitrike ami’ty hagadaboñe, hampihotrak’ aze vaho tio-baratse ty handriatse aze.
12 Nígbà tí odi náà bá sì wó, ǹjẹ́ àwọn ènìyàn wọn kò níbi yín pé, “Rírẹ́ tí ẹ rẹ́ ẹ dà, ibo sì ni ẹfun tí ẹ fi kùn ún wà?”
Aa ie mideboñe i rindriñey tsy hañontaneañe ty hoe hao, Aia i fotake napako’ areo ama’ey?
13 “‘Nítorí náà, báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, Nínú ìbínú gbígbóná mi, èmi yóò tu afẹ́fẹ́ líle lé e lórí nínú ìrunú mi, àti nínú ìbínú mi, òjò yóò sì rọ̀ púpọ̀ nínú ìbínú mi, àti yìnyín ńlá nínú ìrunú mi láti pa wọ́n run.
Aa le hoe ty nafè’ Iehovà Talè, Toe hampandriateko tio-bey am-pifomboko naho an-kabosehako, añ’oram-pandopatse vaho havandra gadaboñe, hamotsek’ aze ampiforoforoako.
14 Èmi yóò wó ògiri tí ẹ fi amọ̀ àìpò rẹ́, èyí tí ẹ fi ẹfun kùn lulẹ̀ dé bi pé ìpìlẹ̀ rẹ yóò hàn jáde. Nígbà ti odi náà wó palẹ̀, a ó sì run yín sínú rẹ̀, ẹ̀yin yóò sì mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.
Aa le haro­tsako i kijoly nipakore’ areo an-tsokaiy vaho hadeboko an-tane eo, naho songa hiboake o faha’eo naho hidoiñe; ho mongoreñe añivo’e ao nahareo vaho ho fohi’ areo te Izaho Iehovà.
15 Báyìí ni Èmi yóò ṣe lo ìbínú mi lórí odi yìí àti àwọn to fi amọ̀ àìpò rẹ́ ẹ, tí wọ́n sì fi ẹfun kùn ún. Èmi yóò sì sọ fún yín pé, “Kò sí odi mọ́, bẹ́ẹ̀ ni àwọn tó rẹ́ ẹ náà kò sí mọ́.
Toe izay ty hañenefako ty habosehako amy kijoliy, naho amo nampipakotse sokay ama’eo, vaho hanoako ty hoe: Tsy eo ka i kijoliy rekets’ o nampipakotse azeo,
16 Àwọn wòlíì Israẹli tí ń sọtẹ́lẹ̀ sí Jerusalẹmu, tí wọn ríran àlàáfíà sí i nígbà ti kò sì àlàáfíà, báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí.”’
naho o mpitoki’ Israele mitoky am’ Ierosalaimeo, ie manao te mahaoniñe fanintsiñañe ho aze, ie po-panintsiñañe, hoe t’Iehovà Talè.
17 “Nísinsin yìí, ọmọ ènìyàn, dojúkọ àwọn ọmọbìnrin ènìyàn rẹ tí wọ́n ń sọtẹ́lẹ̀ láti inú èrò ọkàn wọn, sọtẹ́lẹ̀ sí wọn
Ihe ka, ana’ ondatio, ampiatrefo mb’ amo anak’ ampela’ondati’oo ty lahara’o, mb’amo mitoky ty an-tro’e ao avaoo; itokio fatse,
18 wí pé, ‘Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí. Ègbé ni fún ẹ̀yin obìnrin tí ẹ ń rán ìfúnpá òògùn sí ìgbọ̀nwọ́ àwọn ènìyàn, tí ẹ ń ṣe ìbòjú oríṣìíríṣìí fún orí oníkálùkù ènìyàn láti ṣọdẹ ọkàn wọn. Ẹ̀yin yóò wa dẹkùn fún ọkàn àwọn ènìyàn mi bí? Ẹ̀yin yóò sì gba ọkàn ti ó tọ̀ yín wá là bí?
ami’ty hoe, Hoe ty nafè’ Iehovà Talè; Hankàñe amo mitrebek’ ankalan-kihoke naho fikolopofan-doha ho ami’ty bey naho ty kede iabio hañoroña’ iareo fiaiñe! Ho horoñe’ areo ka hao ty arofo’ondatikoo hañarova’ areo ty tro’ areo?
19 Nítorí ẹ̀kúnwọ́ ọkà barle àti òkèlè oúnjẹ. Ẹ ti pa àwọn tí kò yẹ kí ẹ pa, ẹ sì fi àwọn tí kò yẹ kó wà láààyè sílẹ̀ nípa irọ́ tí ẹ ń pa fún àwọn ènìyàn mi, èyí tí àwọn náà ń fetí sí.
Fa tineratera’ areo am’ondatikoo iraho hahazoa’o vare maha­atsam-pitàñe tsy ampeampe naho tsila-mofo, hanja­mana’o ty havelo’ ondaty tsy ho vinonoo, vaho hamahanam-piay tsy ho vinelo, ami’ty fandañira’ areo am’ondatiko mitsanom-bandeo.
20 “‘Nítorí náà, báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí. Mo lòdì sí ìfúnpá òògùn tí ẹ fi ń ṣọdẹ ọkàn ènìyàn káàkiri bí ẹyẹ, Èmi yóò ya á kúrò lápá yín, Èmi yóò sì dá ọkàn àwọn ènìyàn tí ẹ ń ṣọdẹ sílẹ̀.
Aa le hoe ty nafè’ Iehovà Talè, Inao! hejeko o bandem-pitañe fi­tsatsa’areo ondaty veloñe hoe t’ie voroñe; ho riateko am-pità’ areo iereo vaho havotsoko o veloñeo, Eka! o haveloñe horoñe’ areo hoe voroñeo.
21 Èmi yóò ya àwọn ìbòjú yín, láti gba àwọn ènìyàn mi lọ́wọ́ yín, wọn kò sì ní jẹ́ ìjẹ fún yín mọ́. Nígbà náà ni ẹ̀yin yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.
Ho riateko ka o masoara’ areoo naho ho hahako am-pità’ areo ondatikoo, le tsy ho am-pità’ areo horoñeñe ka, vaho ho fohi’ areo te Izaho Iehovà.
22 Nítorí pé ẹ̀yin ti ba ọkàn àwọn olódodo jẹ́ pẹ̀lú irọ́ yín, nígbà tí Èmi kò mú ìbànújẹ́ bá wọn, àti nítorí ẹ̀yin ti mú ọkàn àwọn ènìyàn búburú le, kí wọ́n má ba à kúrò nínú ọ̀nà ibi wọn dé bi tí wọn yóò fi gba ẹ̀mí wọn là,
Aa kanao aman-dañitse ty nahalonjera’ areo ty arofo’ o vantañeo, o tsy nampanaheloekoo; naho nihafatrare’ areo ty fità’ o lo-tserekeo tsy hiviha’e amo sata’e ratio, hiveloma’e;
23 nítorí èyí, ẹ̀yin kò ní í ríran èké, ẹ̀yin kò sì ní fọ àfọ̀ṣẹ mọ́. Èmi yóò gba àwọn ènìyàn mi lọ́wọ́ yín. Ẹ̀yin yóò sì mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.’”
le tsy ho oni’ areo ka o aroñarom-bandeo, ndra ty fisikiliañe; fa havo­tsoko am-pità’ areo ondatikoo vaho ho fohi’ areo te Izaho Iehovà.

< Ezekiel 13 >