< Ezekiel 13 >

1 Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé:
És lett hozzám az Örökkévaló igéje, mondván:
2 “Ọmọ ènìyàn sọtẹ́lẹ̀ lòdì sí àwọn wòlíì Israẹli tó ń sọtẹ́lẹ̀, kí o sì sọ fún àwọn tí ń sọtẹ́lẹ̀ láti inú èrò ọkàn wọn, ‘Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa!
Ember fia, prófétálj Izrael prófétáiról, akik prófétálnak és mondd a saját szívükből való prófétáknak: halljátok az Örökkévaló igéjét.
3 Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Ègbé ni fún àwọn aṣiwèrè wòlíì tó ń tẹ̀lé ẹ̀mí ara wọn tí wọn kò sì rí nǹkan kan!
Így szól az Úr, az Örökkévaló: jaj az aljas próféták fölött, akik saját szellemük után járnak és aszerint, amit nem láttak.
4 Israẹli àwọn wòlíì rẹ dàbí kọ̀lọ̀kọ̀lọ̀ nínú pápá.
Mint rókák a romokban, olyanok a te prófétáid, Izrael.
5 Ẹ̀yin kò gòkè láti mọ odi tí ó ya ní ilé Israẹli kí wọ́n ba lè dúró gbọin ní ojú ogun ní ọjọ́ Olúwa.
Nem hágtatok a résekbe, hogy falat vontatok volna Izrael háza körül, megállva a harcban, az Örökkévaló napján.
6 Ìran àti àfọ̀ṣẹ wọn jẹ́ èké. Wọ́n wí pé, “Olúwa wí,” nígbà tí Olúwa kò rán wọn, síbẹ̀ wọ́n fẹ́ kí Olúwa mú ọ̀rọ̀ wọn ṣẹ.
Hamisságot láttak és hazug jóslatot, akik azt mondták: Úgymond az Örökkévaló, holott az Örökkévaló nem küldte őket, és biztatnak az ige teljesedésével.
7 Ẹ̀yin kò ha ti rí ìran asán, ẹ̀yin kò ha ti fọ àfọ̀ṣẹ èké, nígbà tí ẹ̀yin sọ pé, “Olúwa wí,” bẹ́ẹ̀ sì ni Èmi kò sọ̀rọ̀?
Nemde, hamis látomást láttatok és hazug jóslatot mondtatok, midőn mondtátok: Úgymond az Örökkévaló, holott én nem szóltam.
8 “‘Nítorí náà, báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, Nítorí ọ̀rọ̀ asán àti ìran èké yín, mo lòdì sí yín: ni Olúwa Olódùmarè wí.
Azért így szól az Úr, az Örökkévaló: Mivelhogy hamisságot beszéltetek és hazugságot láttatok, azért íme én ellenetek fordulok, úgymond az Úr, az Örökkévaló.
9 Ọwọ́ mi yóò sì wà lórí àwọn wòlíì tó ń ríran asán, tó sì ń sọ àfọ̀ṣẹ èké. Wọn kò ní sí nínú ìjọ àwọn ènìyàn mi, a ó sì yọ orúkọ wọn kúrò nínú àkọsílẹ̀ ilé Israẹli, bẹ́ẹ̀ ni wọn kò sì ní wọ ilẹ̀ Israẹli mọ́. Nígbà náà ni ẹ̀yin yóò sì mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa Olódùmarè.
És kezem lesz azon próféták ellen, akik hamisságot látnak és hazugságot jósolnak: népem tanácsában nem lesznek és Izrael házának jegyzékébe nem jegyeztetnek és Izrael földjére nem jutnak be; hogy megtudjátok, hogy én vagyok az Úr, az Örökkévaló.
10 “‘Wọ́n ti mú àwọn ènìyàn mi ṣìnà, wọ́n ní, “Àlàáfíà,” nígbà tí kò sí àlàáfíà, nítorí pé bí àwọn ènìyàn bá mọ odi fẹ́lẹ́fẹ́lẹ́, wọn a fi amọ̀ àìpò rẹ́ ẹ, wọn ó sì fi ẹfun kùn ún,
Csakis mivelhogy megtévesztették népemet, mondván: béke! és nincsen béke; ő rekeszfalat épít és ők azt bevakolják mázzal.
11 nítorí náà, sọ fún àwọn tí ń fi amọ̀ àìpò rẹ́ ẹ àti àwọn tó fi ẹfun kùn ún pé, odi náà yóò wó, ìkún omi òjò yóò dé, Èmi yóò sì rán òkúta yìnyín sọ̀kalẹ̀, ìjì líle yóò ya á lulẹ̀.
Szólj a mázzal vakolókhoz, hogy le fog dőlni; lesz áradó eső és ti, jégkövek, hullani fogtok és viharuk szele ki fog törni?
12 Nígbà tí odi náà bá sì wó, ǹjẹ́ àwọn ènìyàn wọn kò níbi yín pé, “Rírẹ́ tí ẹ rẹ́ ẹ dà, ibo sì ni ẹfun tí ẹ fi kùn ún wà?”
És íme bedől a fal; nemde azt mondják nektek: hol a vakolás, amit vakoltatok?
13 “‘Nítorí náà, báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, Nínú ìbínú gbígbóná mi, èmi yóò tu afẹ́fẹ́ líle lé e lórí nínú ìrunú mi, àti nínú ìbínú mi, òjò yóò sì rọ̀ púpọ̀ nínú ìbínú mi, àti yìnyín ńlá nínú ìrunú mi láti pa wọ́n run.
Azért így szól az Úr, az Örökkévaló: Kitöretem viharok szelét hevemben és áradó eső lesz haragomban és jégkövek hévvel végpusztításra.
14 Èmi yóò wó ògiri tí ẹ fi amọ̀ àìpò rẹ́, èyí tí ẹ fi ẹfun kùn lulẹ̀ dé bi pé ìpìlẹ̀ rẹ yóò hàn jáde. Nígbà ti odi náà wó palẹ̀, a ó sì run yín sínú rẹ̀, ẹ̀yin yóò sì mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.
És lerombolom a falat, melyet mázzal vakoltatok be es a földhöz éretem, hogy föltáruljon alapja; le fog dőlni és ti elpusztultok benne, hogy megtudjátok, hogy én vagyok az Örökkévaló.
15 Báyìí ni Èmi yóò ṣe lo ìbínú mi lórí odi yìí àti àwọn to fi amọ̀ àìpò rẹ́ ẹ, tí wọ́n sì fi ẹfun kùn ún. Èmi yóò sì sọ fún yín pé, “Kò sí odi mọ́, bẹ́ẹ̀ ni àwọn tó rẹ́ ẹ náà kò sí mọ́.
És elvégzem haragomat a falon és azokon, kik mázzal bevakolták; és azt mondom nektek: nincs a fal és nincsenek akik bevakolták.
16 Àwọn wòlíì Israẹli tí ń sọtẹ́lẹ̀ sí Jerusalẹmu, tí wọn ríran àlàáfíà sí i nígbà ti kò sì àlàáfíà, báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí.”’
Izrael prófétái, akik Jeruzsálemről prófétáltak és láttak neki béke-látomást, holott nincs béke, úgymond az Úr, az Örökkévaló.
17 “Nísinsin yìí, ọmọ ènìyàn, dojúkọ àwọn ọmọbìnrin ènìyàn rẹ tí wọ́n ń sọtẹ́lẹ̀ láti inú èrò ọkàn wọn, sọtẹ́lẹ̀ sí wọn
Te pedig, ember fia, fordítsd arcodat néped leányaihoz, akik saját szívükből prófétálkodnak és prófétálj róluk.
18 wí pé, ‘Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí. Ègbé ni fún ẹ̀yin obìnrin tí ẹ ń rán ìfúnpá òògùn sí ìgbọ̀nwọ́ àwọn ènìyàn, tí ẹ ń ṣe ìbòjú oríṣìíríṣìí fún orí oníkálùkù ènìyàn láti ṣọdẹ ọkàn wọn. Ẹ̀yin yóò wa dẹkùn fún ọkàn àwọn ènìyàn mi bí? Ẹ̀yin yóò sì gba ọkàn ti ó tọ̀ yín wá là bí?
És szólj: Így szól az Úr, az Örökkévaló: jaj azoknak, akik párnákat varrogatnak minden kézcsuklóra és kendőket készítnek minden termet fejére, hogy lelkeket vadásszanak. Vajon népem lelkeit vadásszátok-e és magatoknak a lelkeit életben tartjátok-e?
19 Nítorí ẹ̀kúnwọ́ ọkà barle àti òkèlè oúnjẹ. Ẹ ti pa àwọn tí kò yẹ kí ẹ pa, ẹ sì fi àwọn tí kò yẹ kó wà láààyè sílẹ̀ nípa irọ́ tí ẹ ń pa fún àwọn ènìyàn mi, èyí tí àwọn náà ń fetí sí.
Megszentségtelenítettetek engem népemnél néhány marok árpáért, néhány darab kenyérért, hogy lelkeket öljetek, amelyeknek nem kellene meghalniuk és hogy életben tartsatok lelkeket, melyeknek nem kellene élniük, amidőn hazudoztatok a hazugságra hallgató népemnek.
20 “‘Nítorí náà, báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí. Mo lòdì sí ìfúnpá òògùn tí ẹ fi ń ṣọdẹ ọkàn ènìyàn káàkiri bí ẹyẹ, Èmi yóò ya á kúrò lápá yín, Èmi yóò sì dá ọkàn àwọn ènìyàn tí ẹ ń ṣọdẹ sílẹ̀.
Azért így szól az Úr, az Örökkévaló: Íme én fordulok párnáitok ellen, amelyekkel a lelkeket, mint szárnyasokat vadásszátok, és leszaggatom azokat karjaitokról; és elbocsátom a lelkeket, amely lelkeket ti vadásztok, mint szárnyasokat.
21 Èmi yóò ya àwọn ìbòjú yín, láti gba àwọn ènìyàn mi lọ́wọ́ yín, wọn kò sì ní jẹ́ ìjẹ fún yín mọ́. Nígbà náà ni ẹ̀yin yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.
És leszaggatom kendőiteket és megmentem népemet kezetekből, és nem lesznek többé kezetekben vadászatra; és megtudjátok, hogy én vagyok az Örökkévaló.
22 Nítorí pé ẹ̀yin ti ba ọkàn àwọn olódodo jẹ́ pẹ̀lú irọ́ yín, nígbà tí Èmi kò mú ìbànújẹ́ bá wọn, àti nítorí ẹ̀yin ti mú ọkàn àwọn ènìyàn búburú le, kí wọ́n má ba à kúrò nínú ọ̀nà ibi wọn dé bi tí wọn yóò fi gba ẹ̀mí wọn là,
Mivelhogy hazugul bántalmaztátok az igaznak szívét, holott én nem búsítottam meg, és megerősítettétek a gonosznak kezeit, hogy ne térjen meg gonosz útjáról, úgy hogy életben maradna.
23 nítorí èyí, ẹ̀yin kò ní í ríran èké, ẹ̀yin kò sì ní fọ àfọ̀ṣẹ mọ́. Èmi yóò gba àwọn ènìyàn mi lọ́wọ́ yín. Ẹ̀yin yóò sì mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.’”
Azért hamisságot nem fogtok látni és jóslatot nem fogtok jósolni többé; és megmentem népemet kezetekből, hogy megtudjátok, hogy én vagyok az Örökkévaló.

< Ezekiel 13 >