< Ezekiel 13 >

1 Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé:
La parole de Yahweh me fut adressée en ces termes:
2 “Ọmọ ènìyàn sọtẹ́lẹ̀ lòdì sí àwọn wòlíì Israẹli tó ń sọtẹ́lẹ̀, kí o sì sọ fún àwọn tí ń sọtẹ́lẹ̀ láti inú èrò ọkàn wọn, ‘Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa!
" Fils de l'homme, prophétise contre les prophètes d'Israël, qui prophétisent, et dis à ceux qui prophétisent de leur chef: Ecoutez la parole de Yahweh:
3 Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Ègbé ni fún àwọn aṣiwèrè wòlíì tó ń tẹ̀lé ẹ̀mí ara wọn tí wọn kò sì rí nǹkan kan!
Ainsi parle le Seigneur Yahweh: Malheur aux prophètes insensés, qui suivent leur propre esprit, sans rien voir!
4 Israẹli àwọn wòlíì rẹ dàbí kọ̀lọ̀kọ̀lọ̀ nínú pápá.
Comme des renards dans des ruines, tels sont tes prophètes, ô Israël.
5 Ẹ̀yin kò gòkè láti mọ odi tí ó ya ní ilé Israẹli kí wọ́n ba lè dúró gbọin ní ojú ogun ní ọjọ́ Olúwa.
Vous n'êtes pas montés aux brèches, et vous n'avez pas élevé de muraille autour de la maison d'Israël, pour tenir ferme dans la bataille, au jour de Yahweh.
6 Ìran àti àfọ̀ṣẹ wọn jẹ́ èké. Wọ́n wí pé, “Olúwa wí,” nígbà tí Olúwa kò rán wọn, síbẹ̀ wọ́n fẹ́ kí Olúwa mú ọ̀rọ̀ wọn ṣẹ.
Ils ont des visions vaines, et des divinations de mensonge, ceux qui disent: Oracle de Yahweh, sans que Yahweh les ait envoyés, et qu'ils puissent espérer l'accomplissement de leur parole.
7 Ẹ̀yin kò ha ti rí ìran asán, ẹ̀yin kò ha ti fọ àfọ̀ṣẹ èké, nígbà tí ẹ̀yin sọ pé, “Olúwa wí,” bẹ́ẹ̀ sì ni Èmi kò sọ̀rọ̀?
N'est-ce pas des visions vaines que vous voyez, des divinations mensongères que vous prononcez, quand vous dites: Oracle de Yahweh! et moi, je n'ai point parlé?
8 “‘Nítorí náà, báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, Nítorí ọ̀rọ̀ asán àti ìran èké yín, mo lòdì sí yín: ni Olúwa Olódùmarè wí.
C'est pourquoi ainsi parle le Seigneur Yahweh: Parce que vous proférez la vanité, et que vous avez des visions de mensonge, voici que je viens à vous, — oracle du Seigneur Yahweh.
9 Ọwọ́ mi yóò sì wà lórí àwọn wòlíì tó ń ríran asán, tó sì ń sọ àfọ̀ṣẹ èké. Wọn kò ní sí nínú ìjọ àwọn ènìyàn mi, a ó sì yọ orúkọ wọn kúrò nínú àkọsílẹ̀ ilé Israẹli, bẹ́ẹ̀ ni wọn kò sì ní wọ ilẹ̀ Israẹli mọ́. Nígbà náà ni ẹ̀yin yóò sì mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa Olódùmarè.
Ma main sera sur les prophètes qui ont des visions vaines et des divinations de mensonge: ils ne seront pas dans le conseil de mon peuple; ils ne seront pas inscrits dans le livre de la maison d'Israël, et ils n'entreront pas dans la terre d'Israël, — et vous saurez que je suis le Seigneur Yahweh, —
10 “‘Wọ́n ti mú àwọn ènìyàn mi ṣìnà, wọ́n ní, “Àlàáfíà,” nígbà tí kò sí àlàáfíà, nítorí pé bí àwọn ènìyàn bá mọ odi fẹ́lẹ́fẹ́lẹ́, wọn a fi amọ̀ àìpò rẹ́ ẹ, wọn ó sì fi ẹfun kùn ún,
attendu qu'ils ont égaré mon peuple en disant: Paix! quand il n'y avait pas de paix. Mon peuple construit un mur et voici qu'ils le couvrent de plâtre!
11 nítorí náà, sọ fún àwọn tí ń fi amọ̀ àìpò rẹ́ ẹ àti àwọn tó fi ẹfun kùn ún pé, odi náà yóò wó, ìkún omi òjò yóò dé, Èmi yóò sì rán òkúta yìnyín sọ̀kalẹ̀, ìjì líle yóò ya á lulẹ̀.
Dis à ceux qui enduisent de plâtre, que le mur tombera. Viendra une pluie violente: Tombez, pierres de grêle! Vent des tempêtes, éclate!
12 Nígbà tí odi náà bá sì wó, ǹjẹ́ àwọn ènìyàn wọn kò níbi yín pé, “Rírẹ́ tí ẹ rẹ́ ẹ dà, ibo sì ni ẹfun tí ẹ fi kùn ún wà?”
Voici que le mur est tombé! Ne vous dira-t-on pas: Où est le plâtre dont vous l'aviez couvert?
13 “‘Nítorí náà, báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, Nínú ìbínú gbígbóná mi, èmi yóò tu afẹ́fẹ́ líle lé e lórí nínú ìrunú mi, àti nínú ìbínú mi, òjò yóò sì rọ̀ púpọ̀ nínú ìbínú mi, àti yìnyín ńlá nínú ìrunú mi láti pa wọ́n run.
C'est pourquoi ainsi parle le Seigneur Yahweh: Dans mon courroux, je déchaînerai un vent de tempêtes; dans ma colère, je ferai venir une pluie violente, et, dans mon courroux, des pierres de grêle pour exterminer.
14 Èmi yóò wó ògiri tí ẹ fi amọ̀ àìpò rẹ́, èyí tí ẹ fi ẹfun kùn lulẹ̀ dé bi pé ìpìlẹ̀ rẹ yóò hàn jáde. Nígbà ti odi náà wó palẹ̀, a ó sì run yín sínú rẹ̀, ẹ̀yin yóò sì mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.
J'abattrai le mur que vous avez couvert de plâtre, je le renverserai par terre, et le fondement en sera mis à nu; il tombera, et vous périrez au milieu de ses décombres, et vous saurez que je suis Yahweh.
15 Báyìí ni Èmi yóò ṣe lo ìbínú mi lórí odi yìí àti àwọn to fi amọ̀ àìpò rẹ́ ẹ, tí wọ́n sì fi ẹfun kùn ún. Èmi yóò sì sọ fún yín pé, “Kò sí odi mọ́, bẹ́ẹ̀ ni àwọn tó rẹ́ ẹ náà kò sí mọ́.
J'assouvirai ma colère contre le mur, et contre ceux qui l'ont couvert de plâtre, et je vous dirai: Plus de mur! Plus de ces gens qui le replâtraient,
16 Àwọn wòlíì Israẹli tí ń sọtẹ́lẹ̀ sí Jerusalẹmu, tí wọn ríran àlàáfíà sí i nígbà ti kò sì àlàáfíà, báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí.”’
de ces prophètes d'Israël qui prophétisaient sur Jérusalem et qui voyaient pour elle des visions de paix, quand il n'y avait point de paix, — oracle du Seigneur Yahweh! "
17 “Nísinsin yìí, ọmọ ènìyàn, dojúkọ àwọn ọmọbìnrin ènìyàn rẹ tí wọ́n ń sọtẹ́lẹ̀ láti inú èrò ọkàn wọn, sọtẹ́lẹ̀ sí wọn
" Et toi, fils de l'homme, tourne ta face contre les filles de ton peuple qui prophétisent de leur propre chef, et prophétise contre elles,
18 wí pé, ‘Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí. Ègbé ni fún ẹ̀yin obìnrin tí ẹ ń rán ìfúnpá òògùn sí ìgbọ̀nwọ́ àwọn ènìyàn, tí ẹ ń ṣe ìbòjú oríṣìíríṣìí fún orí oníkálùkù ènìyàn láti ṣọdẹ ọkàn wọn. Ẹ̀yin yóò wa dẹkùn fún ọkàn àwọn ènìyàn mi bí? Ẹ̀yin yóò sì gba ọkàn ti ó tọ̀ yín wá là bí?
et dis: Ainsi parle le Seigneur Yahweh: Malheur à celles qui cousent des coussins pour toutes les jointures des mains, et qui font des oreillers pour toutes les têtes de toute taille, pour prendre les âmes au piège. Vous prendriez au piège les âmes de mon peuple, et vos âmes, à vous, vivraient!
19 Nítorí ẹ̀kúnwọ́ ọkà barle àti òkèlè oúnjẹ. Ẹ ti pa àwọn tí kò yẹ kí ẹ pa, ẹ sì fi àwọn tí kò yẹ kó wà láààyè sílẹ̀ nípa irọ́ tí ẹ ń pa fún àwọn ènìyàn mi, èyí tí àwọn náà ń fetí sí.
Vous m'avez déshonoré auprès de mon peuple, pour une poignée d'orge et pour un morceau de pain, faisant mourir des âmes qui ne doivent point mourir, et faisant vivre des âmes qui ne doivent point vivre, trompant ainsi mon peuple qui écoute le mensonge.
20 “‘Nítorí náà, báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí. Mo lòdì sí ìfúnpá òògùn tí ẹ fi ń ṣọdẹ ọkàn ènìyàn káàkiri bí ẹyẹ, Èmi yóò ya á kúrò lápá yín, Èmi yóò sì dá ọkàn àwọn ènìyàn tí ẹ ń ṣọdẹ sílẹ̀.
C'est pourquoi ainsi parle le Seigneur Yahweh: Voici que j'en veux à vos coussins, par lesquels vous prenez les âmes au piège, et je les ferai s'envoler; ces coussins, je les déchirerai de dessus vos bras, et je délivrerai les âmes que vous prenez au piège, afin qu'elles s'envolent.
21 Èmi yóò ya àwọn ìbòjú yín, láti gba àwọn ènìyàn mi lọ́wọ́ yín, wọn kò sì ní jẹ́ ìjẹ fún yín mọ́. Nígbà náà ni ẹ̀yin yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.
Je déchirerai vos oreillers, et j'arracherai mon peuple de vos mains, et ils ne seront plus une proie dans vos mains, et vous saurez que je suis Yahweh.
22 Nítorí pé ẹ̀yin ti ba ọkàn àwọn olódodo jẹ́ pẹ̀lú irọ́ yín, nígbà tí Èmi kò mú ìbànújẹ́ bá wọn, àti nítorí ẹ̀yin ti mú ọkàn àwọn ènìyàn búburú le, kí wọ́n má ba à kúrò nínú ọ̀nà ibi wọn dé bi tí wọn yóò fi gba ẹ̀mí wọn là,
Parce que vous affligez le cœur du juste par des mensonges, quand moi-même je ne l'ai pas affligé, et que vous affermissez les mains du méchant, en sorte qu'il ne revienne pas de sa voie mauvaise, pour vivre,
23 nítorí èyí, ẹ̀yin kò ní í ríran èké, ẹ̀yin kò sì ní fọ àfọ̀ṣẹ mọ́. Èmi yóò gba àwọn ènìyàn mi lọ́wọ́ yín. Ẹ̀yin yóò sì mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.’”
à cause de cela, vous n'aurez plus de visions vaines, et vous n'aurez plus de divinations; j'arracherai mon peuple de vos mains, et vous saurez que je suis Yahweh. "

< Ezekiel 13 >