< Ezekiel 13 >

1 Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé:
И Господното слово дойде към мене и рече:
2 “Ọmọ ènìyàn sọtẹ́lẹ̀ lòdì sí àwọn wòlíì Israẹli tó ń sọtẹ́lẹ̀, kí o sì sọ fún àwọn tí ń sọtẹ́lẹ̀ láti inú èrò ọkàn wọn, ‘Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa!
Сине човешки, пророкувай против Израилевите пророци, които пророкуват, и кажи на ония, които пророкуват от своето си сърце: Слушайте словото Господно.
3 Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Ègbé ni fún àwọn aṣiwèrè wòlíì tó ń tẹ̀lé ẹ̀mí ara wọn tí wọn kò sì rí nǹkan kan!
Така казва Господ Иеова: Горко на глупавите пророци, Които се водят по своя си дух, Без да са видели някое видение!
4 Israẹli àwọn wòlíì rẹ dàbí kọ̀lọ̀kọ̀lọ̀ nínú pápá.
Израилю, твоите пророци са Като лисици в развалините.
5 Ẹ̀yin kò gòkè láti mọ odi tí ó ya ní ilé Israẹli kí wọ́n ba lè dúró gbọin ní ojú ogun ní ọjọ́ Olúwa.
Вие не се изкачихте в проломите, Нито издигнахте ограда за Израилевия дом, За да устои в боя в деня Господен.
6 Ìran àti àfọ̀ṣẹ wọn jẹ́ èké. Wọ́n wí pé, “Olúwa wí,” nígbà tí Olúwa kò rán wọn, síbẹ̀ wọ́n fẹ́ kí Olúwa mú ọ̀rọ̀ wọn ṣẹ.
Ония видяха суети и лъжливи предсказания, Които казват: Господ говори, Когато Господ не ги е пратил, И които направиха човеците да се надяват, Че думата им щяла да се изпълни.
7 Ẹ̀yin kò ha ti rí ìran asán, ẹ̀yin kò ha ti fọ àfọ̀ṣẹ èké, nígbà tí ẹ̀yin sọ pé, “Olúwa wí,” bẹ́ẹ̀ sì ni Èmi kò sọ̀rọ̀?
Не видяхте ли суетни видения, И не говорихте ли лъжливи предсказания, Когато казвате: Господ рече, При все че не съм говорил?
8 “‘Nítorí náà, báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, Nítorí ọ̀rọ̀ asán àti ìran èké yín, mo lòdì sí yín: ni Olúwa Olódùmarè wí.
Затова, така казва Господ Иеова; Понеже говорихте суети и видяхте лъжи, Затова, ето, Аз съм против вас, Казва Господ Иеова.
9 Ọwọ́ mi yóò sì wà lórí àwọn wòlíì tó ń ríran asán, tó sì ń sọ àfọ̀ṣẹ èké. Wọn kò ní sí nínú ìjọ àwọn ènìyàn mi, a ó sì yọ orúkọ wọn kúrò nínú àkọsílẹ̀ ilé Israẹli, bẹ́ẹ̀ ni wọn kò sì ní wọ ilẹ̀ Israẹli mọ́. Nígbà náà ni ẹ̀yin yóò sì mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa Olódùmarè.
И ръката Ми ще бъде против пророците, Които гледат суети и предсказват лъжи; Те не ще бъдат в съвета на людете Ми, Нито ще бъдат записани в списъка на Израилевия дом, Нито ще влязат в Израилевата земя; И ще познаете, че Аз съм Господ Иеова.
10 “‘Wọ́n ti mú àwọn ènìyàn mi ṣìnà, wọ́n ní, “Àlàáfíà,” nígbà tí kò sí àlàáfíà, nítorí pé bí àwọn ènìyàn bá mọ odi fẹ́lẹ́fẹ́lẹ́, wọn a fi amọ̀ àìpò rẹ́ ẹ, wọn ó sì fi ẹfun kùn ún,
Понеже, да! понеже измамиха людете Ми Като казваха: Мир! а пък няма мир; И когато някои градяха една слабичка стена, Ето, те я мажеха с кал,
11 nítorí náà, sọ fún àwọn tí ń fi amọ̀ àìpò rẹ́ ẹ àti àwọn tó fi ẹfun kùn ún pé, odi náà yóò wó, ìkún omi òjò yóò dé, Èmi yóò sì rán òkúta yìnyín sọ̀kalẹ̀, ìjì líle yóò ya á lulẹ̀.
Кажи на ония, които я мажат с кал, че ще падне, Понеже ще вали пороен дъжд, И ти, голяма, каменна градушка, ще паднеш върху нея, И бурен вятър ще я съсипе.
12 Nígbà tí odi náà bá sì wó, ǹjẹ́ àwọn ènìyàn wọn kò níbi yín pé, “Rírẹ́ tí ẹ rẹ́ ẹ dà, ibo sì ni ẹfun tí ẹ fi kùn ún wà?”
Ето, когато падне стената, няма ли да ви рекат: Где е калта, с която я мазахте?
13 “‘Nítorí náà, báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, Nínú ìbínú gbígbóná mi, èmi yóò tu afẹ́fẹ́ líle lé e lórí nínú ìrunú mi, àti nínú ìbínú mi, òjò yóò sì rọ̀ púpọ̀ nínú ìbínú mi, àti yìnyín ńlá nínú ìrunú mi láti pa wọ́n run.
Затова, така казва Господ Иеова: Непременно ще я съсипя в яростта Си с бурен вятър, В гнева Ми ще вали пороен дъжд, И в яростта Ми ще падне голяма градушка от камъни, за да я разруша.
14 Èmi yóò wó ògiri tí ẹ fi amọ̀ àìpò rẹ́, èyí tí ẹ fi ẹfun kùn lulẹ̀ dé bi pé ìpìlẹ̀ rẹ yóò hàn jáde. Nígbà ti odi náà wó palẹ̀, a ó sì run yín sínú rẹ̀, ẹ̀yin yóò sì mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.
Така ще съборя стената, Която измазахте с кал, И така ще я съсипя на земята, Щото ще се открият основите й; Тя ще падне, и вие ще загинете всред нея; И ще познаете, че Аз съм Господ.
15 Báyìí ni Èmi yóò ṣe lo ìbínú mi lórí odi yìí àti àwọn to fi amọ̀ àìpò rẹ́ ẹ, tí wọ́n sì fi ẹfun kùn ún. Èmi yóò sì sọ fún yín pé, “Kò sí odi mọ́, bẹ́ẹ̀ ni àwọn tó rẹ́ ẹ náà kò sí mọ́.
Така ще изчерпя яростта Си върху стената И върху ония, които са я измазали с кал, И ще ви река: Няма стената, Нито ония, които я измазаха, именно,
16 Àwọn wòlíì Israẹli tí ń sọtẹ́lẹ̀ sí Jerusalẹmu, tí wọn ríran àlàáfíà sí i nígbà ti kò sì àlàáfíà, báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí.”’
Израилевите пророци, които пророкуват за Ерусалим, И които виждат видения на мир за него, Когато няма мир, казва Господ Иеова.
17 “Nísinsin yìí, ọmọ ènìyàn, dojúkọ àwọn ọmọbìnrin ènìyàn rẹ tí wọ́n ń sọtẹ́lẹ̀ láti inú èrò ọkàn wọn, sọtẹ́lẹ̀ sí wọn
И ти, сине човешки, Насочи лицето си и против дъщерите на людете си, Които пророкуват от своето си сърце; И пророкувай против тях, като речеш:
18 wí pé, ‘Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí. Ègbé ni fún ẹ̀yin obìnrin tí ẹ ń rán ìfúnpá òògùn sí ìgbọ̀nwọ́ àwọn ènìyàn, tí ẹ ń ṣe ìbòjú oríṣìíríṣìí fún orí oníkálùkù ènìyàn láti ṣọdẹ ọkàn wọn. Ẹ̀yin yóò wa dẹkùn fún ọkàn àwọn ènìyàn mi bí? Ẹ̀yin yóò sì gba ọkàn ti ó tọ̀ yín wá là bí?
Така казва Господ Иеова: Горко на жените, които пришиват възглавнички на всеки лакът, И правят покривала за главите на лица от всякакъв ръст, за да ловят души! Ще ловите ли душите на людете Ми, И ще пазите ли души живи за себе си?
19 Nítorí ẹ̀kúnwọ́ ọkà barle àti òkèlè oúnjẹ. Ẹ ti pa àwọn tí kò yẹ kí ẹ pa, ẹ sì fi àwọn tí kò yẹ kó wà láààyè sílẹ̀ nípa irọ́ tí ẹ ń pa fún àwọn ènìyàn mi, èyí tí àwọn náà ń fetí sí.
Като лъжете людете Ми, които слушат лъжи, Ще Ме оскверните ли между людете Ми За шепи ечемик и късчета хляб, Та да убивате души, които не трябваше да умрат, И да опазите живи души, които не трябваше да живеят?
20 “‘Nítorí náà, báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí. Mo lòdì sí ìfúnpá òògùn tí ẹ fi ń ṣọdẹ ọkàn ènìyàn káàkiri bí ẹyẹ, Èmi yóò ya á kúrò lápá yín, Èmi yóò sì dá ọkàn àwọn ènìyàn tí ẹ ń ṣọdẹ sílẹ̀.
Затова, така казва Господ Иеова: Ето, Аз съм против възглавничките ви, С които ловите души като птици; Ще ги отдера от мишниците ви, И ще оставя да избягат душите, Душите, които вие ловите като птици.
21 Èmi yóò ya àwọn ìbòjú yín, láti gba àwọn ènìyàn mi lọ́wọ́ yín, wọn kò sì ní jẹ́ ìjẹ fún yín mọ́. Nígbà náà ni ẹ̀yin yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.
Ще раздера и покривалата ви, И ще избавя людете Си от ръката ви, Та няма вече да бъдат в ръката ви за лов; И ще познаете, че Аз съм Господ.
22 Nítorí pé ẹ̀yin ti ba ọkàn àwọn olódodo jẹ́ pẹ̀lú irọ́ yín, nígbà tí Èmi kò mú ìbànújẹ́ bá wọn, àti nítorí ẹ̀yin ti mú ọkàn àwọn ènìyàn búburú le, kí wọ́n má ba à kúrò nínú ọ̀nà ibi wọn dé bi tí wọn yóò fi gba ẹ̀mí wọn là,
Защото с лъжите оскърбихте сърцето на праведния, Когото Аз не оскърбих; И укрепихте ръцете на злодееца За да се не върне от нечестивия си път, Та да се спаси живота му.
23 nítorí èyí, ẹ̀yin kò ní í ríran èké, ẹ̀yin kò sì ní fọ àfọ̀ṣẹ mọ́. Èmi yóò gba àwọn ènìyàn mi lọ́wọ́ yín. Ẹ̀yin yóò sì mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.’”
Затова, няма вече да виждате суети, Нито ще предсказвате вече предсказания; И ще избавя людете Си от ръката ви! И ще познаете, че Аз съм Господ.

< Ezekiel 13 >