< Ezekiel 12 >

1 Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé:
Och Herrans ord skedde till mig, och sade:
2 “Ọmọ ènìyàn, ìwọ ń gbé ní àárín ọlọ̀tẹ̀ ènìyàn. Wọ́n lójú láti fi ríran, ṣùgbọ́n wọn kò ríran, bẹ́ẹ̀ ni wọ́n létí láti fi gbọ́rọ̀ ṣùgbọ́n wọn kò gbọ́rọ̀, torí pé ọlọ̀tẹ̀ ènìyàn ni wọ́n.
Du menniskobarn, du bor ibland ett ohörsamt folk, hvilke väl ögon hafva, att de se måtte, och vilja dock intet se; öron, att de höra måtte, och vilja dock intet höra; utan äro ett ohörsamt folk.
3 “Nítorí náà, ọmọ ènìyàn, palẹ̀ ẹrù rẹ mọ́ láti lọ sí ìgbèkùn, ní ọ̀sán gangan ní ojú wọn, kúrò láti ibi tí ìwọ wà lọ sí ibòmíràn. Bóyá bí wọ́n bá rí ọ, wọn yóò sì ronú bó tilẹ̀ jẹ́ pé ọlọ̀tẹ̀ ilé ni wọ́n.
Derföre, du menniskobarn, skicka dig som du ville färdas, och drag din väg om ljusa dagen för deras ögon; du skall bortfara ifrå ditt rum till ett annat rum för deras ögon; om de tilläfventyrs märka vilja, att de ett ohörsamt folk äro.
4 Di ẹrù ìgbèkùn rẹ lójú wọn ní ọ̀sán án gangan, nígbà tí ó bá sì di alẹ́, ní ojú wọn, máa lọ sí ìgbèkùn gẹ́gẹ́ bí àwọn tí ó lọ ìgbèkùn ṣe máa ń ṣe.
Och du skall hafva din tyg framme, lika som du färdas ville om ljusa dagen för deras ögon; och du skall draga din väg om aftonen för deras ögon, lika som man bortfar, då man vandra vill.
5 Dá ògiri lu ní ojú wọn, kí ìwọ sì gba ibẹ̀ kó ẹrù rẹ jáde.
Och du skall bryta dig genom väggena för deras ögon, och gack der ut igenom.
6 Gbé ẹrù rẹ lé èjìká ní ojú wọn, bo ojú rẹ, kí ìwọ má ba à rí ilẹ̀, sì ru ẹrù rẹ lọ ní alẹ́ nítorí pé mo fi ọ́ ṣe àmì fún ilé Israẹli.”
Och du skall tagat uppå dina skuldror, för deras ögon, och när mörkt ordet är, din väg draga; du skall binda om ditt ansigte, att du icke skall se landet; ty jag hafver satt dig Israels hus till ett vidunder.
7 Mo ṣe gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún mi. Mo kó ẹrù mi jáde ní ọ̀sán án láti lọ fun ìgbèkùn. Nígbà tó di ìrọ̀lẹ́, mo dá ògiri lu pẹ̀lú ọwọ́ mi. Mo sì gbe ẹrù mi lé èjìká nínú òkùnkùn ní ojú wọn.
Och jag gjorde såsom mig befaldt var, och bar min tyg fram, lika som jag färdas skulle om ljusan dag, och om aftonen bröt jag genom väggena med handene; och som det var mörkt vordet, tog jag det på skuldrorna, och bar det ut för deras ögon.
8 Ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé:
Och om morgonen bittida skedde Herrans ord till mig, och sade:
9 “Ọmọ ènìyàn, ǹjẹ́ ọlọ̀tẹ̀ ilé Israẹli tilẹ̀ bi ọ́ pé, ‘Kí ni ohun tí o ń ṣe túmọ̀ sí?’
Du menniskobarn, hafver Israels hus, det ohörsamma folket, icke sagt till dig: Hvad gör du?
10 “Sọ fún wọn pé, ‘Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, ọ̀rọ̀-ìjìnlẹ̀ yìí kan àwọn ọmọ-aládé Jerusalẹmu àti gbogbo ilé Israẹli tí ó wà ní àárín rẹ.
Så säg till dem: Detta säger Herren Herren: Denne tungen gäller Förstan uppå i Jerusalem, och hela Israels hus, som der är.
11 Sọ fún wọn pé, Èmi jẹ́ àmì fún yín’. “Gẹ́gẹ́ bí mo ti ṣe, bẹ́ẹ̀ ni a ó ṣe sí wọn. Wọn ó kó lọ sí ìgbèkùn. Gẹ́gẹ́ bí ẹni ti a dè ní ìgbèkùn.
Säg: Jag är edart vidunder; lika som jag gjort hafver, alltså skall eder ske, att I måsten färdas och fångne förde varda.
12 “Ọmọ-aládé tí ó wà ní àárín wọn yóò di ẹrù rẹ̀ lé èjìká ní alẹ́ yóò sì jáde lọ, òun náà yóò da ògiri lu kí ó le gba ibẹ̀ jáde. Yóò sì bo ojú rẹ̀ kí ó má ba à rí ilẹ̀.
Deras Förste skall bortförd varda på skuldrom i mörkrena, och måste gå ut igenom väggena, den de bryta skola, att de skola draga derigenom; hans ansigte skall förskylas, att han icke med något öga ser landet.
13 Èmi yóò ta àwọ̀n mi lé e lórí, yóò sì kó sínú okùn, Èmi yóò sì mú lọ sí Babeli, ní ilẹ̀ Kaldea, ṣùgbọ́n kò ní fojúrí ilẹ̀ náà ibẹ̀ ni yóò kú sí.
Jag skall ock kasta mitt nät öfver honom, att han i mine jagt fången varda skall; och jag vill låta honom komma till Babel uti de Chaldeers land, det han dock intet se skall och der måste han dö.
14 Gbogbo àwọn tó yí i ká láti ràn án lọ́wọ́ ọ̀pá ìtẹ̀lẹ̀ àti àwọn ọmọ-ogun rẹ̀ ni Èmi yóò túká sí afẹ́fẹ́, èmi yóò sì tún fi idà lé wọn kiri.
Och alle de som omkring honom äro, hans hjelpare och hans anhang, skall jag förströ i all väder, och draga ut svärdet efter dem.
15 “Wọn yóò sì mọ̀ pé èmi ni Olúwa nígbà tí mo bá tú wọn ká ní àárín àwọn orílẹ̀-èdè, tí mo sì fọ́n wọn ká sí ilẹ̀ káàkiri.
Alltså skola de förnimma, att jag är Herren, när jag bortdrifver dem ibland Hedningarna, och förstör dem i landen.
16 Ṣùgbọ́n èmi yóò ṣẹ́ díẹ̀ kù lára wọn, ní ọwọ́ idà, ìyàn àti àjàkálẹ̀-ààrùn, kí wọn le jẹ́wọ́ gbogbo ìṣe ìríra wọn ní àárín àwọn orílẹ̀-èdè yìí. Nígbà náà ni wọn yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.”
Men jag skall låta några få af dem igenblifva för svärdena, hungern och pestilentien, att de skola förtälja deras styggelse, ibland Hedningarna, dit de kommande varda, och skola förnimma, att jag är Herren.
17 Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé:
Och Herrans ord skedde till mig, och sade:
18 “Ọmọ ènìyàn, jẹ oúnjẹ rẹ pẹ̀lú ìwárìrì, sì mu omi rẹ pẹ̀lú ìwárìrì àti àìbalẹ̀ àyà.
Du menniskobarn, du skall äta ditt bröd med bäfvande, och dricka ditt vatten med darrande och sorg.
19 Sọ fún àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà pé, ‘Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí fún àwọn olùgbé Jerusalẹmu àti ilẹ̀ Israẹli pé, pẹ̀lú àìbalẹ̀ àyà ni wọn yóò máa jẹun wọn, wọn yóò sì mu omi pẹ̀lú àìnírètí, kí ilẹ̀ wọn lè di ahoro torí ìwà ipá àwọn tó ń gbé ibẹ̀.
Och säg till folket i landena: Detta säger Herren om inbyggarena i Jerusalem i Israels land: De skola äta sitt bröd i sorg, och dricka sitt vatten i elände: ty landet skall öde varda ifrån allt det deruti är, för alla inbyggarenas ondskas skull.
20 Ìlú tó jẹ́ ibùgbé ènìyàn tẹ́lẹ̀ yóò di òfo, ilẹ̀ náà yóò sì di ahoro. Ẹ̀yin yóò sì mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.’”
Och de städer, som väl besatte äro, skola tomme, och landet öde varda. Alltså skolen I förnimma, att jag är Herren.
21 Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá pé:
Och Herrans ord skedde till mig, och sade:
22 “Ọmọ ènìyàn, irú òwe wo ni ẹ pa nílẹ̀ Israẹli pé: ‘A fa ọjọ́ gùn, gbogbo ìran di asán’?
Du menniskobarn hvad hafven I för ett ordspråk uti Israels land, och sägen: Efter det dröjes så länge, så blifver nu intet mer af edra Prophetier?
23 Nítorí náà wí fún wọn pé, ‘Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, Èmi yóò fi òpin sí òwe yìí, wọn kò ní ipa mọ́ ní Israẹli.’ Sọ fún wọn, ‘Ọjọ́ náà súnmọ́ tòsí nígbà tí gbogbo ìran àti ìsọtẹ́lẹ̀ yóò sì wá sí ìmúṣẹ.
Derföre säg till dem: Detta säger Herren Herren: Jag skall lägga det ordspråket neder, att man det intet mer bruka skall i Israel; och säg till dem: Tiden är hardt när, och allt det som propheteradt är.
24 Nítorí kò ní sí ìran asán tàbí àfọ̀ṣẹ tí ó ń pọ́n ni mọ́ ní àárín ilé Israẹli.
Ty I skolen nu härefter förnimma, att ingen syn fela skall, eller någon Prophetie ljuga emot Israels hus.
25 Ṣùgbọ́n, Èmi Olúwa yóò sọ̀rọ̀, ọ̀rọ̀ tí mo sọ yóò sì ṣẹ láì falẹ̀. Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, ní àsìkò yín, ẹ̀yin ọlọ̀tẹ̀ ilé ni Èmi yóò mú ọ̀rọ̀ yówù tí mo bá sọ ṣẹ.’”
Ty Jag är Herren; hvad jag talar, det skall ske, och intet länger fördröjdt varda; utan i edor tid, I ohörsamma folk, skall jag göra det jag talar, säger Herren Herren.
26 Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá pé:
Och Herrans ord skedde till mig, och sade:
27 “Ọmọ ènìyàn, ilé Israẹli ń wí pé, ‘Ìran ọjọ́ pípẹ́ ni ìwọ rí, ìwọ sì sọtẹ́lẹ̀ nípa àsìkò tó jìnnà réré.’
Du menniskobarn, si, Israels hus säger: Den synen, som denne ser, dit är ännu långt, och propheterar om den tid, som ännu långt borto är.
28 “Nítorí náà sọ fún wọn, ‘Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, kò sí ọ̀kan nínú ọ̀rọ̀ mi tí yóò sún síwájú mọ́; ṣùgbọ́n ọ̀rọ̀ tí mo bá sọ yóò ṣẹ.’”
Derföre säg till dem: Så säger Herren Herren: Det jag talar, det skall icke länger fördröjdt varda; utan skall ske, säger Herren Herren.

< Ezekiel 12 >