< Ezekiel 12 >

1 Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé:
و کلام خداوند بر من نازل شده، گفت:۱
2 “Ọmọ ènìyàn, ìwọ ń gbé ní àárín ọlọ̀tẹ̀ ènìyàn. Wọ́n lójú láti fi ríran, ṣùgbọ́n wọn kò ríran, bẹ́ẹ̀ ni wọ́n létí láti fi gbọ́rọ̀ ṣùgbọ́n wọn kò gbọ́rọ̀, torí pé ọlọ̀tẹ̀ ènìyàn ni wọ́n.
«ای پسر انسان تو در میان خاندان فتنه انگیز ساکن می‌باشی که ایشان را چشمها به جهت دیدن هست اما نمی بینند و ایشان را گوشهابه جهت شنیدن هست اما نمی شنوند، چونکه خاندان فتنه انگیز می‌باشند.۲
3 “Nítorí náà, ọmọ ènìyàn, palẹ̀ ẹrù rẹ mọ́ láti lọ sí ìgbèkùn, ní ọ̀sán gangan ní ojú wọn, kúrò láti ibi tí ìwọ wà lọ sí ibòmíràn. Bóyá bí wọ́n bá rí ọ, wọn yóò sì ronú bó tilẹ̀ jẹ́ pé ọlọ̀tẹ̀ ilé ni wọ́n.
اما تو‌ای پسر انسان اسباب جلای وطن را برای خود مهیا ساز. و درنظر ایشان در وقت روز کوچ کن و از مکان خود به مکان دیگر به حضور ایشان نقل کن، شایدبفهمند. اگرچه خاندان فتنه انگیز می‌باشند.۳
4 Di ẹrù ìgbèkùn rẹ lójú wọn ní ọ̀sán án gangan, nígbà tí ó bá sì di alẹ́, ní ojú wọn, máa lọ sí ìgbèkùn gẹ́gẹ́ bí àwọn tí ó lọ ìgbèkùn ṣe máa ń ṣe.
واسباب خود را مثل اسباب جلای وطن در وقت روز به نظر ایشان بیرون آور. و شامگاهان مثل کسانی که برای جلای وطن بیرون می‌روند بیرون شو.۴
5 Dá ògiri lu ní ojú wọn, kí ìwọ sì gba ibẹ̀ kó ẹrù rẹ jáde.
و شکافی برای خود در دیوار به حضورایشان کرده، از آن بیرون ببر.۵
6 Gbé ẹrù rẹ lé èjìká ní ojú wọn, bo ojú rẹ, kí ìwọ má ba à rí ilẹ̀, sì ru ẹrù rẹ lọ ní alẹ́ nítorí pé mo fi ọ́ ṣe àmì fún ilé Israẹli.”
و در حضور ایشان آن را بر دوش خود بگذار و در تاریکی بیرون ببر وروی خود را بپوشان تا زمین را نبینی. زیرا که تو راعلامتی برای خاندان اسرائیل قرار داده‌ام.»۶
7 Mo ṣe gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún mi. Mo kó ẹrù mi jáde ní ọ̀sán án láti lọ fun ìgbèkùn. Nígbà tó di ìrọ̀lẹ́, mo dá ògiri lu pẹ̀lú ọwọ́ mi. Mo sì gbe ẹrù mi lé èjìká nínú òkùnkùn ní ojú wọn.
پس به نهجی که مامور شدم، عمل نمودم واسباب خود را مثل اسباب جلای وطن در وقت روز بیرون آوردم. و شبانگاه شکافی برای خود به‌دست خویش در دیوار کردم و آن را در تاریکی بیرون برده، به حضور ایشان بر دوش برداشتم.۷
8 Ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé:
وبامدادان کلام خداوند بر من نازل شده، گفت:۸
9 “Ọmọ ènìyàn, ǹjẹ́ ọlọ̀tẹ̀ ilé Israẹli tilẹ̀ bi ọ́ pé, ‘Kí ni ohun tí o ń ṣe túmọ̀ sí?’
«ای پسر انسان، آیا خاندان اسرائیل یعنی‌این خاندان فتنه انگیز به تو نگفتند: این چه‌کار است که می‌کنی؟۹
10 “Sọ fún wọn pé, ‘Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, ọ̀rọ̀-ìjìnlẹ̀ yìí kan àwọn ọmọ-aládé Jerusalẹmu àti gbogbo ilé Israẹli tí ó wà ní àárín rẹ.
پس به ایشان بگو خداوند یهوه چنین می‌گوید: این وحی اشاره به رئیسی است که دراورشلیم می‌باشد و به تمامی خاندان اسرائیل که ایشان در میان آنها می‌باشند۱۰
11 Sọ fún wọn pé, Èmi jẹ́ àmì fún yín’. “Gẹ́gẹ́ bí mo ti ṣe, bẹ́ẹ̀ ni a ó ṣe sí wọn. Wọn ó kó lọ sí ìgbèkùn. Gẹ́gẹ́ bí ẹni ti a dè ní ìgbèkùn.
بگو: من علامت برای شما هستم. به نهجی که من عمل نمودم، همچنان به ایشان کرده خواهد شد و جلای وطن شده، به اسیری خواهند رفت.۱۱
12 “Ọmọ-aládé tí ó wà ní àárín wọn yóò di ẹrù rẹ̀ lé èjìká ní alẹ́ yóò sì jáde lọ, òun náà yóò da ògiri lu kí ó le gba ibẹ̀ jáde. Yóò sì bo ojú rẹ̀ kí ó má ba à rí ilẹ̀.
و رئیسی که درمیان ایشان است (اسباب خود را) در تاریکی بردوش نهاده، بیرون خواهد رفت. و شکافی دردیوار خواهند کرد تا از آن بیرون ببرند. و او روی خود را خواهد پوشانید تا زمین را به چشمان خودنبیند.۱۲
13 Èmi yóò ta àwọ̀n mi lé e lórí, yóò sì kó sínú okùn, Èmi yóò sì mú lọ sí Babeli, ní ilẹ̀ Kaldea, ṣùgbọ́n kò ní fojúrí ilẹ̀ náà ibẹ̀ ni yóò kú sí.
و من دام خود را بر او خواهم گسترانید ودر کمند من گرفتار خواهد شد. و او را به بابل به زمین کلدانیان خواهم برد و اگرچه در آنجاخواهد مرد، ولی آن را نخواهد دید.۱۳
14 Gbogbo àwọn tó yí i ká láti ràn án lọ́wọ́ ọ̀pá ìtẹ̀lẹ̀ àti àwọn ọmọ-ogun rẹ̀ ni Èmi yóò túká sí afẹ́fẹ́, èmi yóò sì tún fi idà lé wọn kiri.
و جمیع مجاوران و معاونانش و تمامی لشکر او را بسوی هر باد پراکنده ساخته، شمشیری در عقب ایشان برهنه خواهم ساخت.۱۴
15 “Wọn yóò sì mọ̀ pé èmi ni Olúwa nígbà tí mo bá tú wọn ká ní àárín àwọn orílẹ̀-èdè, tí mo sì fọ́n wọn ká sí ilẹ̀ káàkiri.
و چون ایشان را در میان امت‌ها پراکنده ساخته و ایشان را در میان کشورهامتفرق نموده باشم، آنگاه خواهند دانست که من یهوه هستم.۱۵
16 Ṣùgbọ́n èmi yóò ṣẹ́ díẹ̀ kù lára wọn, ní ọwọ́ idà, ìyàn àti àjàkálẹ̀-ààrùn, kí wọn le jẹ́wọ́ gbogbo ìṣe ìríra wọn ní àárín àwọn orílẹ̀-èdè yìí. Nígbà náà ni wọn yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.”
لیکن عدد قلیلی از میان ایشان ازشمشیر و قحط و وبا باقی خواهم گذاشت تا همه رجاسات خود را در میان امت هایی که به آنهامی روند، بیان نمایند. پس خواهند دانست که من یهوه هستم.»۱۶
17 Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé:
و کلام خداوند بر من نازل شده، گفت:۱۷
18 “Ọmọ ènìyàn, jẹ oúnjẹ rẹ pẹ̀lú ìwárìrì, sì mu omi rẹ pẹ̀lú ìwárìrì àti àìbalẹ̀ àyà.
«ای پسر انسان! نان خود را با ارتعاش بخور وآب خویش را با لرزه و اضطراب بنوش.۱۸
19 Sọ fún àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà pé, ‘Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí fún àwọn olùgbé Jerusalẹmu àti ilẹ̀ Israẹli pé, pẹ̀lú àìbalẹ̀ àyà ni wọn yóò máa jẹun wọn, wọn yóò sì mu omi pẹ̀lú àìnírètí, kí ilẹ̀ wọn lè di ahoro torí ìwà ipá àwọn tó ń gbé ibẹ̀.
و به اهل زمین بگو خداوند یهوه درباره سکنه اورشلیم و اهل زمین اسرائیل چنین می‌فرماید: که نان خودرا با اضطراب خواهند خورد و آب خود را باحیرت خواهند نوشید. زیرا که زمین آنها به‌سبب ظلم جمیع ساکنانش از هر‌چه در آن است تهی خواهد شد.۱۹
20 Ìlú tó jẹ́ ibùgbé ènìyàn tẹ́lẹ̀ yóò di òfo, ilẹ̀ náà yóò sì di ahoro. Ẹ̀yin yóò sì mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.’”
و شهرهای مسکون ایشان خراب شده، زمین ویران خواهد شد. پس خواهیددانست که من یهوه هستم.»۲۰
21 Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá pé:
و کلام خداوند بر من نازل شده، گفت:۲۱
22 “Ọmọ ènìyàn, irú òwe wo ni ẹ pa nílẹ̀ Israẹli pé: ‘A fa ọjọ́ gùn, gbogbo ìran di asán’?
«ای پسر انسان این مثل شما چیست که درزمین اسرائیل می‌زنید و می‌گویید: ایام طویل می‌شود و هر رویا باطل می‌گردد.۲۲
23 Nítorí náà wí fún wọn pé, ‘Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, Èmi yóò fi òpin sí òwe yìí, wọn kò ní ipa mọ́ ní Israẹli.’ Sọ fún wọn, ‘Ọjọ́ náà súnmọ́ tòsí nígbà tí gbogbo ìran àti ìsọtẹ́lẹ̀ yóò sì wá sí ìmúṣẹ.
لهذا به ایشان بگو، خداوند یهوه چنین می‌گوید: این مثل را باطل خواهم ساخت و آن را بار دیگر دراسرائیل نخواهند‌آورد. بلکه به ایشان بگو: ایام، نزدیک است و انجام هر رویا، قریب.۲۳
24 Nítorí kò ní sí ìran asán tàbí àfọ̀ṣẹ tí ó ń pọ́n ni mọ́ ní àárín ilé Israẹli.
زیرا که هیچ‌رویای باطل و غیب گویی تملق‌آمیز در میان خاندان اسرائیل بار دیگر نخواهد بود.۲۴
25 Ṣùgbọ́n, Èmi Olúwa yóò sọ̀rọ̀, ọ̀rọ̀ tí mo sọ yóò sì ṣẹ láì falẹ̀. Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, ní àsìkò yín, ẹ̀yin ọlọ̀tẹ̀ ilé ni Èmi yóò mú ọ̀rọ̀ yówù tí mo bá sọ ṣẹ.’”
زیرا من که یهوه هستم سخن خواهم گفت و سخنی که من می‌گویم، واقع خواهد شد و بار دیگر تاخیرنخواهد افتاد. زیرا خداوند یهوه می‌گوید: ای خاندان فتنه انگیز در ایام شما سخنی خواهم گفت و آن را به انجام خواهم رسانید.»۲۵
26 Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá pé:
و کلام خداوند بر من نازل شده، گفت:۲۶
27 “Ọmọ ènìyàn, ilé Israẹli ń wí pé, ‘Ìran ọjọ́ pípẹ́ ni ìwọ rí, ìwọ sì sọtẹ́lẹ̀ nípa àsìkò tó jìnnà réré.’
«ای پسر انسان! هان خاندان اسرائیل می‌گویندرویایی که او می‌بیند، به جهت ایام طویل است واو برای زمانهای بعیده نبوت می‌نماید.۲۷
28 “Nítorí náà sọ fún wọn, ‘Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, kò sí ọ̀kan nínú ọ̀rọ̀ mi tí yóò sún síwájú mọ́; ṣùgbọ́n ọ̀rọ̀ tí mo bá sọ yóò ṣẹ.’”
بنابراین به ایشان بگو: خداوند یهوه چنین می‌فرماید که هیچ کلام من بعد از این تاخیرنخواهد افتاد. و خداوند یهوه می‌فرماید: کلامی که من می‌گویم واقع خواهد شد.»۲۸

< Ezekiel 12 >