< Ezekiel 12 >

1 Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé:
Then came the word of Yahweh unto me saying:
2 “Ọmọ ènìyàn, ìwọ ń gbé ní àárín ọlọ̀tẹ̀ ènìyàn. Wọ́n lójú láti fi ríran, ṣùgbọ́n wọn kò ríran, bẹ́ẹ̀ ni wọ́n létí láti fi gbọ́rọ̀ ṣùgbọ́n wọn kò gbọ́rọ̀, torí pé ọlọ̀tẹ̀ ènìyàn ni wọ́n.
Son of man. In the midst of a perverse house, dost thou dwell, — Who have eyes to see—and have not seen. Ears have they to hear—and have no heard, For a perverse house, they are.
3 “Nítorí náà, ọmọ ènìyàn, palẹ̀ ẹrù rẹ mọ́ láti lọ sí ìgbèkùn, ní ọ̀sán gangan ní ojú wọn, kúrò láti ibi tí ìwọ wà lọ sí ibòmíràn. Bóyá bí wọ́n bá rí ọ, wọn yóò sì ronú bó tilẹ̀ jẹ́ pé ọlọ̀tẹ̀ ilé ni wọ́n.
Thou, therefore Son of man, Prepare thee baggage for exile, and exile thyself, by day, before their eyes, —so shalt thou exile thyself out of thy place unto another place before their eyes, peradventure they will consider— though a perverse house, they are.
4 Di ẹrù ìgbèkùn rẹ lójú wọn ní ọ̀sán án gangan, nígbà tí ó bá sì di alẹ́, ní ojú wọn, máa lọ sí ìgbèkùn gẹ́gẹ́ bí àwọn tí ó lọ ìgbèkùn ṣe máa ń ṣe.
Therefore shalt thou take forth thy baggage as baggage for exile, by day before their eyes, —and thou thyself, shalt go forth in the evening, before their eyes, like them who go forth to exile.
5 Dá ògiri lu ní ojú wọn, kí ìwọ sì gba ibẹ̀ kó ẹrù rẹ jáde.
Before their eyes, break thou forth by thyself through the wall, —and carry forth through it.
6 Gbé ẹrù rẹ lé èjìká ní ojú wọn, bo ojú rẹ, kí ìwọ má ba à rí ilẹ̀, sì ru ẹrù rẹ lọ ní alẹ́ nítorí pé mo fi ọ́ ṣe àmì fún ilé Israẹli.”
Before their eyes, Upon the shoulder, shalt thou lift it. In thick darkness, take it forth, Thy face, shalt thou cover so that thou see not the land; For a sign, have I appointed thee to the house of Israel.
7 Mo ṣe gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún mi. Mo kó ẹrù mi jáde ní ọ̀sán án láti lọ fun ìgbèkùn. Nígbà tó di ìrọ̀lẹ́, mo dá ògiri lu pẹ̀lú ọwọ́ mi. Mo sì gbe ẹrù mi lé èjìká nínú òkùnkùn ní ojú wọn.
And I did so, just as I was commanded, My baggage, took I forth as baggage for exile by day, and in the evening, I brake forth by myself through the wall, by force: in the twilight, I took it forth—on to my shoulder, I lifted it, before their eyes.
8 Ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé:
Then came the word of Yahweh unto me in the morning, saying:
9 “Ọmọ ènìyàn, ǹjẹ́ ọlọ̀tẹ̀ ilé Israẹli tilẹ̀ bi ọ́ pé, ‘Kí ni ohun tí o ń ṣe túmọ̀ sí?’
Son of man, Have not the house of Israel the perverse house, said unto thee, — What art thou doing?
10 “Sọ fún wọn pé, ‘Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, ọ̀rọ̀-ìjìnlẹ̀ yìí kan àwọn ọmọ-aládé Jerusalẹmu àti gbogbo ilé Israẹli tí ó wà ní àárín rẹ.
Say unto them, Thus, saith My Lord, Yahweh, — [For] the Bearer, is this burden, in Jerusalem, and [for] all the house of Israel such as are in their midst.
11 Sọ fún wọn pé, Èmi jẹ́ àmì fún yín’. “Gẹ́gẹ́ bí mo ti ṣe, bẹ́ẹ̀ ni a ó ṣe sí wọn. Wọn ó kó lọ sí ìgbèkùn. Gẹ́gẹ́ bí ẹni ti a dè ní ìgbèkùn.
Say, I, am your sign: As I have done, so. shall it be done to them, Into exile—into captivity, shall they go.
12 “Ọmọ-aládé tí ó wà ní àárín wọn yóò di ẹrù rẹ̀ lé èjìká ní alẹ́ yóò sì jáde lọ, òun náà yóò da ògiri lu kí ó le gba ibẹ̀ jáde. Yóò sì bo ojú rẹ̀ kí ó má ba à rí ilẹ̀.
Yea, the Bearer who is in their midst, Upon his shoulder, shall lift it. In thick darkness, shall he go forth, Through the wall, shall they break to bear forth through it, — His face, shall he cover, to the end that, his own eye, may not see the land.
13 Èmi yóò ta àwọ̀n mi lé e lórí, yóò sì kó sínú okùn, Èmi yóò sì mú lọ sí Babeli, ní ilẹ̀ Kaldea, ṣùgbọ́n kò ní fojúrí ilẹ̀ náà ibẹ̀ ni yóò kú sí.
Then will I spread my net over him, and he shall be taken in my snare; And I will take him to Babylon. in the land of the Chaldeans, The which, indeed, he shall not see. And yet there, shall he die!
14 Gbogbo àwọn tó yí i ká láti ràn án lọ́wọ́ ọ̀pá ìtẹ̀lẹ̀ àti àwọn ọmọ-ogun rẹ̀ ni Èmi yóò túká sí afẹ́fẹ́, èmi yóò sì tún fi idà lé wọn kiri.
And all who are round about him to help him and all his troops, will I scatter to every wind, —and, a sword, will I make bare after them.
15 “Wọn yóò sì mọ̀ pé èmi ni Olúwa nígbà tí mo bá tú wọn ká ní àárín àwọn orílẹ̀-èdè, tí mo sì fọ́n wọn ká sí ilẹ̀ káàkiri.
So shall they know that, I, am Yahweh, — By my dispersing them among the nations, And scattering them throughout the lands.
16 Ṣùgbọ́n èmi yóò ṣẹ́ díẹ̀ kù lára wọn, ní ọwọ́ idà, ìyàn àti àjàkálẹ̀-ààrùn, kí wọn le jẹ́wọ́ gbogbo ìṣe ìríra wọn ní àárín àwọn orílẹ̀-èdè yìí. Nígbà náà ni wọn yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.”
Yet will I leave remaining of them men easily counted, from the sword from the famine and from the pestilence, —that they may recount all their abominations among the nations whither they have come, So shall they know that, I, am Yahweh.
17 Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé:
Then came the word of Yahweh unto me, saying:
18 “Ọmọ ènìyàn, jẹ oúnjẹ rẹ pẹ̀lú ìwárìrì, sì mu omi rẹ pẹ̀lú ìwárìrì àti àìbalẹ̀ àyà.
Son of man, Thy bread with trembling, shalt thou eat, — And, thy water in agitation and in fear, shalt thou drink.
19 Sọ fún àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà pé, ‘Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí fún àwọn olùgbé Jerusalẹmu àti ilẹ̀ Israẹli pé, pẹ̀lú àìbalẹ̀ àyà ni wọn yóò máa jẹun wọn, wọn yóò sì mu omi pẹ̀lú àìnírètí, kí ilẹ̀ wọn lè di ahoro torí ìwà ipá àwọn tó ń gbé ibẹ̀.
Then shalt thou say unto the people of the land, Thus saith My Lord Yahweh concerning the inhabitants of Jerusalem upon the soil of Israel, Their bread with anxious care, shall they eat, And, their water in astonishment, shall they drink, — That her land, may be deserted, of her fulness, because of the violence of all them who dwell therein:
20 Ìlú tó jẹ́ ibùgbé ènìyàn tẹ́lẹ̀ yóò di òfo, ilẹ̀ náà yóò sì di ahoro. Ẹ̀yin yóò sì mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.’”
Yea, the cities that are inhabited, shall be laid waste, And, the land, shall become, an astonishment, — So shall ye know that, I, am Yahweh.
21 Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá pé:
And the word of Yahweh came unto me saying:
22 “Ọmọ ènìyàn, irú òwe wo ni ẹ pa nílẹ̀ Israẹli pé: ‘A fa ọjọ́ gùn, gbogbo ìran di asán’?
Son of man What is this proverb ye have, concerning the soil of Israel, saying, — The days, are prolonged, Therefore shall every vision come to nought?
23 Nítorí náà wí fún wọn pé, ‘Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, Èmi yóò fi òpin sí òwe yìí, wọn kò ní ipa mọ́ ní Israẹli.’ Sọ fún wọn, ‘Ọjọ́ náà súnmọ́ tòsí nígbà tí gbogbo ìran àti ìsọtẹ́lẹ̀ yóò sì wá sí ìmúṣẹ.
Therefore say unto them, Thus, saith My Lord Yahweh, I will cause this proverb to cease, And they shall use it as a proverb no more in Israel, — But speak unto them, The days, are drawn near, And the substance of every vision.
24 Nítorí kò ní sí ìran asán tàbí àfọ̀ṣẹ tí ó ń pọ́n ni mọ́ ní àárín ilé Israẹli.
For there shall no more be— Any vision of falsehood Or divination of deceit, In the midst of the house of Israel.
25 Ṣùgbọ́n, Èmi Olúwa yóò sọ̀rọ̀, ọ̀rọ̀ tí mo sọ yóò sì ṣẹ láì falẹ̀. Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, ní àsìkò yín, ẹ̀yin ọlọ̀tẹ̀ ilé ni Èmi yóò mú ọ̀rọ̀ yówù tí mo bá sọ ṣẹ.’”
For, I, Yahweh will speak whatsoever word I please to speak, And it shall be done, It shall not be delayed any more, — For in your own days, O perverse house, will I speak a word and perform it, Declareth My Lord. Yahweh.
26 Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá pé:
And the word of Yahweh came unto me, saying:
27 “Ọmọ ènìyàn, ilé Israẹli ń wí pé, ‘Ìran ọjọ́ pípẹ́ ni ìwọ rí, ìwọ sì sọtẹ́lẹ̀ nípa àsìkò tó jìnnà réré.’
Son of man. Lo! the house of Israel are saying, the vision which he seeth is for many days, Yea for times far away, hath he prophesied.
28 “Nítorí náà sọ fún wọn, ‘Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, kò sí ọ̀kan nínú ọ̀rọ̀ mi tí yóò sún síwájú mọ́; ṣùgbọ́n ọ̀rọ̀ tí mo bá sọ yóò ṣẹ.’”
Therefore say unto them. Thus saith My Lord Yahweh, None of my words shall be delayed any more, — Whatsoever word I speak, then shall it be performed, Declareth My Lord Yahweh.

< Ezekiel 12 >