< Ezekiel 11 >

1 Ẹ̀mí sì gbé mi sókè, ó mú mi lọ sí ẹnu-ọ̀nà ilé Olúwa èyí tó dojúkọ ìlà-oòrùn. Ní àbáwọlé ẹnu-ọ̀nà yìí ni àwọn ọkùnrin mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n wá, mo rí Jaaṣaniah ọmọ Assuri àti Pelatiah ọmọ Benaiah, tí wọ́n jẹ́ ìjòyè àwọn ènìyàn.
و روح مرا برداشته، به دروازه شرقی خانه خداوند که بسوی مشرق متوجه است آورد. و اینک نزد دهنه دروازه بیست و پنج مرد بودند و در میان ایشان یازنیا ابن عزور و فلطیاابن بنایا روسای قوم را دیدم.۱
2 Olúwa sì sọ fún mi pé, “Ọmọ ènìyàn, àwọn ọkùnrin yìí ló ń pète ibi, wọ́n sì ń gbé ìmọ̀ràn búburú kalẹ̀ nínú ìlú.
و او مرا گفت: «ای پسر انسان اینها آن کسانی می‌باشند که تدابیرفاسد می‌کنند و در این شهر مشورتهای قبیح می‌دهند.۲
3 Wọ́n ní, ‘Kò ha tí ì tó àsìkò láti kọ́lé? Ìlú yìí ni ìkòkò ìdáná, àwa sì ni ẹran’.
و می‌گویند وقت نزدیک نیست که خانه‌ها را بنا نماییم، بلکه این شهر دیگ است و ما گوشت می‌باشیم.۳
4 Nítorí náà sọtẹ́lẹ̀ nípa wọn; ọmọ ènìyàn, sọtẹ́lẹ̀.”
بنابراین برای ایشان نبوت کن. ای پسر انسان نبوت کن.»۴
5 Ẹ̀mí Olúwa sì bà lé mi, ó sì wí pé, “Sọ̀rọ̀!” Báyìí ni Olúwa wí, ohun tí ẹ ń sọ nìyìí, ilé Israẹli, mo mọ ohun tó wà lọ́kàn yín.
آنگاه روح خداوند بر من نازل شده، مرافرمود: «بگو که خداوند چنین می‌فرماید: ای خاندان اسرائیل شما به اینطور سخن می‌گویید واما من خیالات دل شما را می‌دانم.۵
6 Ẹ̀yin ti sọ òkú yín di púpọ̀ nínú ìlú yìí, òkú sì ti kún gbogbo ìgboro rẹ̀.
بسیاری را دراین شهر کشته‌اید و کوچه هایش را از کشتگان پرکرده‌اید.۶
7 “Torí náà, báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, àwọn òkú tí ẹ fọn sílẹ̀ sí àárín yín ni ẹran, ìlú yìí sì ni ìkòkò ìdáná ṣùgbọ́n èmi yóò le yín jáde níbẹ̀.
لهذا خداوند یهوه چنین می‌گوید: کشتگان شما که در میانش گذاشته‌اید، گوشت می‌باشند و شهر دیگ است. لیکن شما را ازمیانش بیرون خواهم برد.۷
8 Ẹ bẹ̀rù idà, èmi yóò sì mú idà wá sórí yín, bẹ́ẹ̀ ni Olúwa Olódùmarè wí.
شما از شمشیرمی ترسید، اما خداوند یهوه می‌گوید شمشیر را برشما خواهم آورد.۸
9 Èmi yóò lé yín jáde kúrò ní ìlú yìí, èmi yóò sì fà yín lé àjèjì lọ́wọ́, èmi yóò sì mú ìdájọ́ ṣẹ lé yín lórí.
و شما را از میان شهر بیرون برده، شما را به‌دست غریبان تسلیم خواهم نمودو بر شما داوری خواهم کرد.۹
10 Nípa idà ni ẹ̀yin yóò ṣubú, èmi yóò sì ṣe ìdájọ́ yín ní àwọn ààlà ìlú Israẹli. Nígbà náà ni ẹ̀yin yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.
به شمشیرخواهید افتاد و در حدود اسرائیل بر شما داوری خواهم نمود و خواهید دانست که من یهوه هستم.۱۰
11 Ìlú yìí kò ní i jẹ́ ìkòkò ìdáná, bẹ́ẹ̀ ni ẹ̀yin náà kò sì ní jẹ́ ẹran nínú rẹ̀, Èmi yóò ṣe ìdájọ́ yín ní àwọn ààlà ìlú Israẹli.
این شهر برای شما دیگ نخواهد بود و شما درآن گوشت نخواهید بود، بلکه در حدود اسرائیل بر شما داوری خواهم نمود.۱۱
12 Ẹ̀yin yóò sì mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa, nítorí pé ẹ̀yin kò tẹ̀lé àṣẹ mi ẹ̀yin kò sì pa òfin mi mọ́, ṣùgbọ́n ẹ̀yin ti hùwà gẹ́gẹ́ bí àwọn aláìgbàgbọ́ orílẹ̀-èdè tó yí yín ká.”
و خواهید دانست که من آن یهوه هستم که در فرایض من سلوک ننمودید و احکام مرا بجا نیاوردید، بلکه برحسب احکام امت هایی که به اطراف شمامی باشند عمل نمودید.»۱۲
13 Bí mo ṣe ń sọtẹ́lẹ̀ lọ́wọ́, Pelatiah ọmọ Benaiah kú. Mo sì dojúbolẹ̀, mo sì kígbe sókè pé, “Háà! Olúwa Olódùmarè! Ṣé ìwọ yóò ha pa ìyókù Israẹli run pátápátá ni?”
و واقع شد که چون نبوت کردم، فلطیا ابن بنایا مرد. پس به روی خوددر‌افتاده، به آواز بلند فریاد نمودم و گفتم: «آه‌ای خداوند یهوه آیا تو بقیه اسرائیل را تمام هلاک خواهی ساخت؟»۱۳
14 Ọ̀rọ̀ Olúwa tún tọ̀ mí wá wí pé,
و کلام خداوند بر من نازل شده، گفت:۱۴
15 “Ọmọ ènìyàn, àwọn arákùnrin rẹ, àní àwọn ará rẹ, àwọn ọkùnrin nínú ìbátan rẹ, àti gbogbo ilé Israẹli pátápátá, ni àwọn ará Jerusalẹmu ti wí fún pé, ‘Ẹ jìnnà sí Olúwa, àwa ni a fi ilẹ̀ yìí fún yín ní ìní.’
«ای پسر انسان برادران تو یعنی برادرانت که از اهل خاندان تو می‌باشند و تمامی خاندان اسرائیل جمیع کسانی می‌باشند که سکنه اورشلیم به ایشان می‌گویند: شما از خداوند دورشوید و این زمین به ما به ملکیت داده شده است.۱۵
16 “Nítorí náà, sọ fún àwọn tó wà ní ìgbèkùn pé, ‘Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, bó tilẹ̀ jẹ́ pé mo ti fọ́n wọn káàkiri orílẹ̀-èdè, síbẹ̀ fún ìgbà díẹ̀, èmi yóò jẹ́ ibi mímọ́ fún wọn níbi tí wọ́n lọ.’
بنابراین بگو: خداوند یهوه چنین می‌گوید: اگرچه ایشان را در میان امت‌ها دور کنم و ایشان را درمیان کشورها پراکنده سازم، اما من برای ایشان درآن کشورهایی که به آنها رفته باشند اندک زمانی مقدس خواهم بود.۱۶
17 “Nítorí náà, wí pé, ‘Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, Èmi yóò kó wọn jọ kúrò láàrín àwọn orílẹ̀-èdè tí mo fọ́n wọn ká sí, Èmi yóò sì fún wọn ní ilẹ̀ Israẹli padà.’
پس بگو خداوند یهوه چنین می‌فرماید: شما را از میان امت‌ها جمع خواهم کرد و شما را از کشورهایی که در آنهاپراکنده شده‌اید فراهم خواهم آورد و زمین اسرائیل را به شما خواهم داد.۱۷
18 “Wọn yóò padà síbẹ̀, wọn yóò sì mú gbogbo àwòrán ìríra rẹ̀ àti ìbọ̀rìṣà rẹ̀ kúrò.
و به آنجا داخل شده، تمامی مکروهات و جمیع رجاسات آن رااز میانش دور خواهند کرد.۱۸
19 Èmi yóò fún wọn ní ọ̀kankan; èmi yóò sì fi ẹ̀mí tuntun sínú wọn, Èmi yóò mú ọkàn òkúta kúrò lára wọn, èmi yóò sì fún wọn ní ọkàn tó rọ̀ bí ara ẹran.
و ایشان را یکدل خواهم داد و در اندرون ایشان روح تازه خواهم نهاد و دل سنگی را از جسد ایشان دور کرده، دل گوشتی به ایشان خواهم بخشید.۱۹
20 Kí wọn le tẹ̀lé àṣẹ mi, kí wọn sì le pa òfin mi mọ́. Wọ́n yóò jẹ́ ènìyàn mi, Èmi náà yóò sì jẹ́ Ọlọ́run wọn.
تا در فرایض من سلوک نمایند و احکام مرا نگاه داشته، آنها رابجا آورند. و ایشان قوم من خواهند بود و من خدای ایشان خواهم بود.۲۰
21 Ṣùgbọ́n fún àwọn tí wọ́n ń fi gbogbo ọkàn wọn sin àwọn àwòrán ìríra àti àwọn òrìṣà, Èmi yóò mú ẹ̀san ohun tí wọ́n ṣe wá sí orí wọn bẹ́ẹ̀ ni Olúwa Olódùmarè wí.”
اما آنانی که دل ایشان از عقب مکروهات و رجاسات ایشان می‌رود، پس خداوند یهوه می‌گوید: من رفتارایشان را بر سر ایشان وارد خواهم آورد.»۲۱
22 Àwọn kérúbù sì gbé ìyẹ́ wọn sókè pẹ̀lú kẹ̀kẹ́ lẹ́gbẹ̀ẹ́ wọn, ògo Ọlọ́run Israẹli sì wà lókè orí wọn.
آنگاه کروبیان بالهای خود را برافراشتند وچرخها به پهلوی ایشان بود و جلال خدای اسرائیل از طرف بالا بر ایشان قرار گرفت.۲۲
23 Ògo Olúwa sì gòkè lọ kúrò láàrín ìlú, ó sì dúró lórí òkè tó wà ní ìlà-oòrùn ìlú náà.
وجلال خداوند از بالای میان شهر صعود نموده، برکوهی که بطرف شرقی شهر است قرار گرفت.۲۳
24 Lẹ́yìn náà, Ẹ̀mí gbé mi sókè, ó sì mú mi wá sí Kaldea lójú ìran, nípa ti Ẹ̀mí Ọlọ́run sí ọ̀dọ̀ àwọn ti ìgbèkùn. Bẹ́ẹ̀ ni ìran tí mo rí lọ kúrò ní ọ̀dọ̀ mi,
و روح مرا برداشت و در عالم رویا مرا به روح خدا به زمین کلدانیان نزد اسیران برد و آن رویایی که دیده بودم از نظر من مرتفع شد.۲۴
25 mo sì sọ gbogbo ohun tí Olúwa fihàn mí fún àwọn tó wà ní ìgbèkùn.
و تمامی کلام خداوند را که به من نشان داده بود، برای اسیران بیان کردم.۲۵

< Ezekiel 11 >