< Ezekiel 11 >

1 Ẹ̀mí sì gbé mi sókè, ó mú mi lọ sí ẹnu-ọ̀nà ilé Olúwa èyí tó dojúkọ ìlà-oòrùn. Ní àbáwọlé ẹnu-ọ̀nà yìí ni àwọn ọkùnrin mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n wá, mo rí Jaaṣaniah ọmọ Assuri àti Pelatiah ọmọ Benaiah, tí wọ́n jẹ́ ìjòyè àwọn ènìyàn.
I hapainga ake ano ahau e te wairua, a kawea ana e ia ki te keti ki te rawhiti o te whare o Ihowa, ki tera e anga ra ki te rawhiti. Na i te kuwaha o te keti e rua tekau ma rima nga tangata; a i kite ahau i roto i a ratou i a Iaatania tama a Aturu raua ko Peratia tama a Penaia, he rangatira no te iwi.
2 Olúwa sì sọ fún mi pé, “Ọmọ ènìyàn, àwọn ọkùnrin yìí ló ń pète ibi, wọ́n sì ń gbé ìmọ̀ràn búburú kalẹ̀ nínú ìlú.
Na ka mea ia ki ahau, E te tama a te tangata, ko nga tangata enei e whakaaro ana i te kino, e whakatakoto ana i te tikanga he i roto i tenei pa:
3 Wọ́n ní, ‘Kò ha tí ì tó àsìkò láti kọ́lé? Ìlú yìí ni ìkòkò ìdáná, àwa sì ni ẹran’.
E ki ana, kahore ano i tata te wa e hanga whare ai: ko tenei pa te kohua, ko tatou te kikokiko.
4 Nítorí náà sọtẹ́lẹ̀ nípa wọn; ọmọ ènìyàn, sọtẹ́lẹ̀.”
Mo reira poropititia te he mo ratou; poropititia, e te tama a te tangata.
5 Ẹ̀mí Olúwa sì bà lé mi, ó sì wí pé, “Sọ̀rọ̀!” Báyìí ni Olúwa wí, ohun tí ẹ ń sọ nìyìí, ilé Israẹli, mo mọ ohun tó wà lọ́kàn yín.
Na ka tau te wairua o Ihowa ki ahau, a ka mea ki ahau, Ki atu, Ko te kupu tenei a Ihowa, Ko ta koutou korero tenei, e te whare o Iharaira: na, ko na mea e puta ake ana i o koutou wairua, mohio tonu ahau.
6 Ẹ̀yin ti sọ òkú yín di púpọ̀ nínú ìlú yìí, òkú sì ti kún gbogbo ìgboro rẹ̀.
Kua whakatokomahatia e koutou a koutou tupapaku ki tenei pa, kua whakakiia ano e koutou ona huarahi ki te tupapaku.
7 “Torí náà, báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, àwọn òkú tí ẹ fọn sílẹ̀ sí àárín yín ni ẹran, ìlú yìí sì ni ìkòkò ìdáná ṣùgbọ́n èmi yóò le yín jáde níbẹ̀.
Mo reira ko te kupu tenei a te Ariki, a Ihowa, Ko a koutou tupapaku kua hinga nei i a koutou ki waenganui o tenei pa, ko ratou te kikokiko, ko tenei pa te kohua: ko koutou ia ka whakaputaina atu i waenganui o konei.
8 Ẹ bẹ̀rù idà, èmi yóò sì mú idà wá sórí yín, bẹ́ẹ̀ ni Olúwa Olódùmarè wí.
I wehi koutou i te hoari; ka kawea mai ano e ahau te hoari ki a koutou, e ai ta te Ariki, ta Ihowa.
9 Èmi yóò lé yín jáde kúrò ní ìlú yìí, èmi yóò sì fà yín lé àjèjì lọ́wọ́, èmi yóò sì mú ìdájọ́ ṣẹ lé yín lórí.
Ka whakaputaina atu ano koutou e ahau i waenganui o konei, ka hoatu ki te ringa o te tangata ke, ka mahia ano e ahau he whakawa i waenganui i a koutou.
10 Nípa idà ni ẹ̀yin yóò ṣubú, èmi yóò sì ṣe ìdájọ́ yín ní àwọn ààlà ìlú Israẹli. Nígbà náà ni ẹ̀yin yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.
Ka hinga koutou i te hoari; ka whakawakia koutou e ahau ki te rohe o Iharaira, a ka mohio koutou ko Ihowa, ahau.
11 Ìlú yìí kò ní i jẹ́ ìkòkò ìdáná, bẹ́ẹ̀ ni ẹ̀yin náà kò sì ní jẹ́ ẹran nínú rẹ̀, Èmi yóò ṣe ìdájọ́ yín ní àwọn ààlà ìlú Israẹli.
E kore tenei pa e waiho hei kohua mo koutou, e kore ano hoki koutou e waiho hei kikokiko mo roto; ka whakawakia koutou e ahau ki te rohe o Iharaira;
12 Ẹ̀yin yóò sì mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa, nítorí pé ẹ̀yin kò tẹ̀lé àṣẹ mi ẹ̀yin kò sì pa òfin mi mọ́, ṣùgbọ́n ẹ̀yin ti hùwà gẹ́gẹ́ bí àwọn aláìgbàgbọ́ orílẹ̀-èdè tó yí yín ká.”
A ka mohio koutou ko Ihowa ahau; kihai hoki koutou i haere i runga i aku tikanga, a kihai i mahia e koutou aku whakaritenga, engari i rite tonu a koutou mahi ki nga ritenga a nga iwi i tetahi taha, i tetahi taha o koutou.
13 Bí mo ṣe ń sọtẹ́lẹ̀ lọ́wọ́, Pelatiah ọmọ Benaiah kú. Mo sì dojúbolẹ̀, mo sì kígbe sókè pé, “Háà! Olúwa Olódùmarè! Ṣé ìwọ yóò ha pa ìyókù Israẹli run pátápátá ni?”
Na i ahau e poropiti ana, ka mate a Peratia tama a Penaia. Katahi ahau ka tapapa ki raro, he nui toku reo ki te karanga, i mea ahau, Aue, e te Ariki, e Ihowa! ka poto rawa ranei i a koe nga morehu o Iharaira?
14 Ọ̀rọ̀ Olúwa tún tọ̀ mí wá wí pé,
I puta mai ano te kupu a Ihowa ki ahau, i mea ia,
15 “Ọmọ ènìyàn, àwọn arákùnrin rẹ, àní àwọn ará rẹ, àwọn ọkùnrin nínú ìbátan rẹ, àti gbogbo ilé Israẹli pátápátá, ni àwọn ará Jerusalẹmu ti wí fún pé, ‘Ẹ jìnnà sí Olúwa, àwa ni a fi ilẹ̀ yìí fún yín ní ìní.’
E te tama a te tangata, ko ou tuakana, ko ou teina, ko ou whanaunga, ko te whare katoa ano o Iharaira, rupeke, rupeke, ko ratou enei, kua ki mai nei nga tangata o Hiruharama ki a ratou, kia matara atu i a Ihowa; kua homai tenei whenua ki a matou hei kainga tupu:
16 “Nítorí náà, sọ fún àwọn tó wà ní ìgbèkùn pé, ‘Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, bó tilẹ̀ jẹ́ pé mo ti fọ́n wọn káàkiri orílẹ̀-èdè, síbẹ̀ fún ìgbà díẹ̀, èmi yóò jẹ́ ibi mímọ́ fún wọn níbi tí wọ́n lọ.’
Mo reira me ki atu, Ko te kupu tenei a te Ariki, a Ihowa, Ahakoa i maka atu ratou e ahau ki tawhiti, ki roto ki nga iwi, ahakoa i whakamararatia ratou e ahau ki nga whenua, ka ai ano ia ahau hei wahi tapu mo ratou i nga whenua e tae ai ratou mo te wa nohinohi nei.
17 “Nítorí náà, wí pé, ‘Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, Èmi yóò kó wọn jọ kúrò láàrín àwọn orílẹ̀-èdè tí mo fọ́n wọn ká sí, Èmi yóò sì fún wọn ní ilẹ̀ Israẹli padà.’
Mo reira me ki atu, Ko te kupu tenei a te Ariki, a Ihowa, Ka kohikohia koutou e ahau i roto i nga iwi, ka huihuia ano i nga whenua i whakamararatia ai koutou, ka hoatu ano e ahau te oneone o Iharaira ki a koutou.
18 “Wọn yóò padà síbẹ̀, wọn yóò sì mú gbogbo àwòrán ìríra rẹ̀ àti ìbọ̀rìṣà rẹ̀ kúrò.
Ka tae ano ratou ki reira, ka whakakahoretia ano e ratou nga mea whakarihariha katoa o reira, me nga mea anuanu o reira.
19 Èmi yóò fún wọn ní ọ̀kankan; èmi yóò sì fi ẹ̀mí tuntun sínú wọn, Èmi yóò mú ọkàn òkúta kúrò lára wọn, èmi yóò sì fún wọn ní ọkàn tó rọ̀ bí ara ẹran.
Ka hoatu ano e ahau he ngakau kotahi ki a ratou, ka hoatu ano he wairua hou ki a koutou; ka tangohia ano e ahau te ngakau kohatu i o ratou kikokiko, a ka hoatu he ngakau kikokiko ki a ratou:
20 Kí wọn le tẹ̀lé àṣẹ mi, kí wọn sì le pa òfin mi mọ́. Wọ́n yóò jẹ́ ènìyàn mi, Èmi náà yóò sì jẹ́ Ọlọ́run wọn.
Kia haere ai ratou i runga i aku tikanga, kia puritia ai aku whakaritenga, mahia iho: a waiho tonu iho ratou hei iwi maku, ko ahau ano hei Atua mo ratou.
21 Ṣùgbọ́n fún àwọn tí wọ́n ń fi gbogbo ọkàn wọn sin àwọn àwòrán ìríra àti àwọn òrìṣà, Èmi yóò mú ẹ̀san ohun tí wọ́n ṣe wá sí orí wọn bẹ́ẹ̀ ni Olúwa Olódùmarè wí.”
Ko te hunga ia kei te whai nei o ratou ngakau i te ngakau o a ratou mea whakarihariha, o a ratou mea anuanu, ka utua e ahau o ratou ara ki runga ki o ratou mahunga, e ai ta te Ariki, ta Ihowa.
22 Àwọn kérúbù sì gbé ìyẹ́ wọn sókè pẹ̀lú kẹ̀kẹ́ lẹ́gbẹ̀ẹ́ wọn, ògo Ọlọ́run Israẹli sì wà lókè orí wọn.
Katahi ka ara nga parirau o nga kerupima, a ko nga wira i to ratou taha; i runga ano hoki te kororia o te Atua o Iharaira i a ratou, i te taha ki runga.
23 Ògo Olúwa sì gòkè lọ kúrò láàrín ìlú, ó sì dúró lórí òkè tó wà ní ìlà-oòrùn ìlú náà.
Na ka kake te kororia o Ihowa i roto i te pa, tu rawa ki runga ki te maunga ki te taha ki te rawhiti o te pa.
24 Lẹ́yìn náà, Ẹ̀mí gbé mi sókè, ó sì mú mi wá sí Kaldea lójú ìran, nípa ti Ẹ̀mí Ọlọ́run sí ọ̀dọ̀ àwọn ti ìgbèkùn. Bẹ́ẹ̀ ni ìran tí mo rí lọ kúrò ní ọ̀dọ̀ mi,
Muri iho ka hapainga ahau e te wairua, he mea i roto i te whakakitenga, na te wairua o te Atua, ki Karari, ki nga whakarau. Heoi ka kake atu i ahau te kitenga i kitea e ahau.
25 mo sì sọ gbogbo ohun tí Olúwa fihàn mí fún àwọn tó wà ní ìgbèkùn.
Na korerotia ana e ahau ki nga whakarau nga mea katoa i whakakitea ki ahau e Ihowa.

< Ezekiel 11 >