< Ezekiel 11 >

1 Ẹ̀mí sì gbé mi sókè, ó mú mi lọ sí ẹnu-ọ̀nà ilé Olúwa èyí tó dojúkọ ìlà-oòrùn. Ní àbáwọlé ẹnu-ọ̀nà yìí ni àwọn ọkùnrin mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n wá, mo rí Jaaṣaniah ọmọ Assuri àti Pelatiah ọmọ Benaiah, tí wọ́n jẹ́ ìjòyè àwọn ènìyàn.
A KAIKAI iho la ka uhane ia'u, a lawe ia'u i ka pukapa hikina o ko Iehova hale e nana ana ma ka hikina; aia hoi, ma ke pani o ka pukapa he iwakaluakumamalima kanaka, a iwaena o lakou ike aku la au ia Iaazania ke keiki a Azura, a me Pelatia ke keiki a Benaia, na'lii o na kanaka.
2 Olúwa sì sọ fún mi pé, “Ọmọ ènìyàn, àwọn ọkùnrin yìí ló ń pète ibi, wọ́n sì ń gbé ìmọ̀ràn búburú kalẹ̀ nínú ìlú.
Alaila olelo mai la oia ia'u, E ke keiki a ke kanaka, eia na kanaka i kukakuka i ka mea ino, a haawi hoi i ka oleloao hewa iloko o keia kulanakauhale:
3 Wọ́n ní, ‘Kò ha tí ì tó àsìkò láti kọ́lé? Ìlú yìí ni ìkòkò ìdáná, àwa sì ni ẹran’.
Na mea olelo, Aole kokoke mai, e kukulu kakou i na hale: eia ka ipuhao nui, a o kakou ka io.
4 Nítorí náà sọtẹ́lẹ̀ nípa wọn; ọmọ ènìyàn, sọtẹ́lẹ̀.”
Nolaila o wanana ku e ia lakou, e wanana, e ke keiki a ke kanaka.
5 Ẹ̀mí Olúwa sì bà lé mi, ó sì wí pé, “Sọ̀rọ̀!” Báyìí ni Olúwa wí, ohun tí ẹ ń sọ nìyìí, ilé Israẹli, mo mọ ohun tó wà lọ́kàn yín.
A haule mai la ka Uhane o Iehova, a olelo mai la ia'u, E olelo oe, Ke i mai nei o Iehova penei; Ua olelo oukou pela, e ka ohana a Iseraela: no ka mea, ua ike au i na mea a pau i komo iloko o ko oukou naau.
6 Ẹ̀yin ti sọ òkú yín di púpọ̀ nínú ìlú yìí, òkú sì ti kún gbogbo ìgboro rẹ̀.
Ua hoonui oukou i ko oukou poe i hoomakeia iloko o keia kulanakauhale, a ua hoopiha oukou i kona mau alanui me na mea i make i ka pepohiia.
7 “Torí náà, báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, àwọn òkú tí ẹ fọn sílẹ̀ sí àárín yín ni ẹran, ìlú yìí sì ni ìkòkò ìdáná ṣùgbọ́n èmi yóò le yín jáde níbẹ̀.
Nolaila ke i mai nei o Iehova ka Haku, O ko oukou poe i make i ka pepehiia a oukou i hoomoe iho ai iwaenakonu ona, o lakou ka io, a o keia ka ipuhao nui; aka, e lawe ae au ia oukou iwaho, mai waenakonu ae ona.
8 Ẹ bẹ̀rù idà, èmi yóò sì mú idà wá sórí yín, bẹ́ẹ̀ ni Olúwa Olódùmarè wí.
O ka pahikaua ka oukou i makau ai; a o ka pahikaua ka'u e hooili ai maluna o oukou, wahi a Iehova ka Haku.
9 Èmi yóò lé yín jáde kúrò ní ìlú yìí, èmi yóò sì fà yín lé àjèjì lọ́wọ́, èmi yóò sì mú ìdájọ́ ṣẹ lé yín lórí.
A e lawe ae au ia oukou mai waenakonu ae ona, a e haawi ia oukou i na lima o na malihini, a e hana au ma ka hoopai ana iwaena o oukou.
10 Nípa idà ni ẹ̀yin yóò ṣubú, èmi yóò sì ṣe ìdájọ́ yín ní àwọn ààlà ìlú Israẹli. Nígbà náà ni ẹ̀yin yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.
A e haulo oukou i ka pahikaua; e hoopai au ia oukou ma ka palena o ka Iseraela; a e ike no oukou owau no Iehova.
11 Ìlú yìí kò ní i jẹ́ ìkòkò ìdáná, bẹ́ẹ̀ ni ẹ̀yin náà kò sì ní jẹ́ ẹran nínú rẹ̀, Èmi yóò ṣe ìdájọ́ yín ní àwọn ààlà ìlú Israẹli.
Aole e lilo keia i ipuhao nui no oukou, aole hoi oukou ka io iwaenakonu ona; aka, ma ka palena o ka Iseraela e hoopai aku ai au ia oukou.
12 Ẹ̀yin yóò sì mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa, nítorí pé ẹ̀yin kò tẹ̀lé àṣẹ mi ẹ̀yin kò sì pa òfin mi mọ́, ṣùgbọ́n ẹ̀yin ti hùwà gẹ́gẹ́ bí àwọn aláìgbàgbọ́ orílẹ̀-èdè tó yí yín ká.”
A e ike oukou owau no Iehova; e ka poe hele ole ma ko'u mau kanawai, aole hana i ka'u mau oihana, aka, ua hana oukou mamuli o na oihana a na lahuikanaka e hoopuni ana ia oukou.
13 Bí mo ṣe ń sọtẹ́lẹ̀ lọ́wọ́, Pelatiah ọmọ Benaiah kú. Mo sì dojúbolẹ̀, mo sì kígbe sókè pé, “Háà! Olúwa Olódùmarè! Ṣé ìwọ yóò ha pa ìyókù Israẹli run pátápátá ni?”
Eia kekahi, i kuu wanana ana, make iho la o Pelatia ke keiki a Benaia. Alaila moe iho au ilalo ke alo, a kahea aku la me ka leo nui, i aku la, Auwe, e Iehova ka Haku e! e hoopau io anei oe i ke koena o ka Iseraela?
14 Ọ̀rọ̀ Olúwa tún tọ̀ mí wá wí pé,
Hiki hou mai la ka olelo a Iehova ia'u, i mai la,
15 “Ọmọ ènìyàn, àwọn arákùnrin rẹ, àní àwọn ará rẹ, àwọn ọkùnrin nínú ìbátan rẹ, àti gbogbo ilé Israẹli pátápátá, ni àwọn ará Jerusalẹmu ti wí fún pé, ‘Ẹ jìnnà sí Olúwa, àwa ni a fi ilẹ̀ yìí fún yín ní ìní.’
E ke keiki a ke kanaka, o kou poe hoahanau, o kou poe hoahanau, o na kanaka hanauna on, a me ka ohana okoa o ka Iseraela, o lakou ka poe a ko Ierusalema i kauoha aku ai, E hoomamao loa aku oukou ia Iehova; no ka mea, ua haawiia mai keia aina no makou i waiwai ili.
16 “Nítorí náà, sọ fún àwọn tó wà ní ìgbèkùn pé, ‘Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, bó tilẹ̀ jẹ́ pé mo ti fọ́n wọn káàkiri orílẹ̀-èdè, síbẹ̀ fún ìgbà díẹ̀, èmi yóò jẹ́ ibi mímọ́ fún wọn níbi tí wọ́n lọ.’
Nolaila e olelo oe, Ke i mai nei Iehova ka Haku penei; I kipaku hoi au ia lakou i kahi loihi aku mawaena o na lahuikanaka, a i hoopuehu hoi au ia lakou iwaena o na aina, e lilo no nae au i wahi keenakapu iki no lakou, i na aina e hiki ai lakou.
17 “Nítorí náà, wí pé, ‘Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, Èmi yóò kó wọn jọ kúrò láàrín àwọn orílẹ̀-èdè tí mo fọ́n wọn ká sí, Èmi yóò sì fún wọn ní ilẹ̀ Israẹli padà.’
Nolaila e olelo aku oe, Ke i mai nei o Iehova ka Haku, E houluulu au ia oukou mai waena mai o na kanaka, a e hoakoakoa ia oukou mai loko mai o na aina i puehuia'i oukou, a e haawi aku au i ka aina o ka Iseraela ia oukou.
18 “Wọn yóò padà síbẹ̀, wọn yóò sì mú gbogbo àwòrán ìríra rẹ̀ àti ìbọ̀rìṣà rẹ̀ kúrò.
A e hele mai no lakou ilaila, a e lawe aku lakou i na mea i hoowahawahaia a pau ona, a me na mea i inainaia a pau ona mai laila aku.
19 Èmi yóò fún wọn ní ọ̀kankan; èmi yóò sì fi ẹ̀mí tuntun sínú wọn, Èmi yóò mú ọkàn òkúta kúrò lára wọn, èmi yóò sì fún wọn ní ọkàn tó rọ̀ bí ara ẹran.
A e haawi aku au ia lakou i ka naau hookahi, e haawi hoi au i uhane hou iloko o oukou, a e lawe aku au i ka naau pohaku mailoko aku o ka lakou io, a e haawi aku au i ka naau io ia lakou;
20 Kí wọn le tẹ̀lé àṣẹ mi, kí wọn sì le pa òfin mi mọ́. Wọ́n yóò jẹ́ ènìyàn mi, Èmi náà yóò sì jẹ́ Ọlọ́run wọn.
I hele lakou ma ko'u mau kanawai, a e malama hoi i ka'u mau oihana, a e hana hoi ia mau mea; a e lilo lakou i kanaka no'u, a owau hoi i Akua no lakou.
21 Ṣùgbọ́n fún àwọn tí wọ́n ń fi gbogbo ọkàn wọn sin àwọn àwòrán ìríra àti àwọn òrìṣà, Èmi yóò mú ẹ̀san ohun tí wọ́n ṣe wá sí orí wọn bẹ́ẹ̀ ni Olúwa Olódùmarè wí.”
Aka, o ka poe i hele ko lakou naau mamuli o ka naau o ko lakou mau mea i hoowahawahaia, a me ko lakou mau mea inainaia, e uku aku au i ko lakou aoao maluna o ko lakou poo iho, wahi a Iehova ka Haku.
22 Àwọn kérúbù sì gbé ìyẹ́ wọn sókè pẹ̀lú kẹ̀kẹ́ lẹ́gbẹ̀ẹ́ wọn, ògo Ọlọ́run Israẹli sì wà lókè orí wọn.
Alaila hapai ae la na keruba i ko lakou mau eheu, a me na huila ma ko lakou mau aoao; aia maluna o lakou ka nani o ke Akua o ka Iseraela.
23 Ògo Olúwa sì gòkè lọ kúrò láàrín ìlú, ó sì dúró lórí òkè tó wà ní ìlà-oòrùn ìlú náà.
A pii ae la ka nani o Iehova mai waenakonu aku o ke kulanakauhale, a kau ma ka mauna ma ka aoao hikina o ke kulanakauhale.
24 Lẹ́yìn náà, Ẹ̀mí gbé mi sókè, ó sì mú mi wá sí Kaldea lójú ìran, nípa ti Ẹ̀mí Ọlọ́run sí ọ̀dọ̀ àwọn ti ìgbèkùn. Bẹ́ẹ̀ ni ìran tí mo rí lọ kúrò ní ọ̀dọ̀ mi,
A mahope iho kaikai ae la ka uhane, a lawe ia'u iloko o ka hihio ma ka Uhane o ke Akua i Kaledea i ka poe pio. A pii ae la ka hihio a'u i ike aku ai mai o'u aku la.
25 mo sì sọ gbogbo ohun tí Olúwa fihàn mí fún àwọn tó wà ní ìgbèkùn.
Alaila olelo aku au i ka poe pio i na mea a pau a Iehova i hoike mai ai ia'u.

< Ezekiel 11 >