< Ezekiel 11 >

1 Ẹ̀mí sì gbé mi sókè, ó mú mi lọ sí ẹnu-ọ̀nà ilé Olúwa èyí tó dojúkọ ìlà-oòrùn. Ní àbáwọlé ẹnu-ọ̀nà yìí ni àwọn ọkùnrin mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n wá, mo rí Jaaṣaniah ọmọ Assuri àti Pelatiah ọmọ Benaiah, tí wọ́n jẹ́ ìjòyè àwọn ènìyàn.
L’Esprit m’enleva et m’amena à la porte orientale de la maison de Yahweh, celle qui regarde l’orient. Et voici qu’à l’entrée de la porte, il y avait vingt-cinq hommes, et je vis au milieu d’eux Jézonias, fils d’Azzur, et Pheltias, fils de Banaïas, chefs du peuple.
2 Olúwa sì sọ fún mi pé, “Ọmọ ènìyàn, àwọn ọkùnrin yìí ló ń pète ibi, wọ́n sì ń gbé ìmọ̀ràn búburú kalẹ̀ nínú ìlú.
Et Yahweh me dit: « Fils de l’homme, ce sont là les hommes qui méditent l’iniquité, et qui donnent de mauvais conseils dans cette ville;
3 Wọ́n ní, ‘Kò ha tí ì tó àsìkò láti kọ́lé? Ìlú yìí ni ìkòkò ìdáná, àwa sì ni ẹran’.
qui disent: Le malheur n’est pas si proche! Bâtissons des maisons! Cette ville est la chaudière, et nous sommes la viande.
4 Nítorí náà sọtẹ́lẹ̀ nípa wọn; ọmọ ènìyàn, sọtẹ́lẹ̀.”
C’est pourquoi prophétise contre eux, prophétise, fils de l’homme. »
5 Ẹ̀mí Olúwa sì bà lé mi, ó sì wí pé, “Sọ̀rọ̀!” Báyìí ni Olúwa wí, ohun tí ẹ ń sọ nìyìí, ilé Israẹli, mo mọ ohun tó wà lọ́kàn yín.
Et l’Esprit de Yahweh tomba sur moi, et il me dit: « Dis: Ainsi parle Yahweh: C’est ainsi que vous parlez, maison d’Israël! Ce qui monte à votre esprit, moi je le connais.
6 Ẹ̀yin ti sọ òkú yín di púpọ̀ nínú ìlú yìí, òkú sì ti kún gbogbo ìgboro rẹ̀.
Vous avez multiplié vos meurtres dans cette ville et rempli ses rues de cadavres.
7 “Torí náà, báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, àwọn òkú tí ẹ fọn sílẹ̀ sí àárín yín ni ẹran, ìlú yìí sì ni ìkòkò ìdáná ṣùgbọ́n èmi yóò le yín jáde níbẹ̀.
C’est pourquoi ainsi parle le Seigneur Yahweh: Vos morts, que vous avez étendus au milieu de la ville, c’est la chair, et la ville est la chaudière; mais on vous fera sortir du milieu d’elle.
8 Ẹ bẹ̀rù idà, èmi yóò sì mú idà wá sórí yín, bẹ́ẹ̀ ni Olúwa Olódùmarè wí.
Vous craignez l’épée, et je ferai venir sur vous l’épée, — oracle du Seigneur Yahweh.
9 Èmi yóò lé yín jáde kúrò ní ìlú yìí, èmi yóò sì fà yín lé àjèjì lọ́wọ́, èmi yóò sì mú ìdájọ́ ṣẹ lé yín lórí.
Je vous ferai sortir du milieu de la ville, je vous livrerai à la main des étrangers et j’exercerai sur vous mes jugements.
10 Nípa idà ni ẹ̀yin yóò ṣubú, èmi yóò sì ṣe ìdájọ́ yín ní àwọn ààlà ìlú Israẹli. Nígbà náà ni ẹ̀yin yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.
Vous tomberez par l’épée; je vous jugerai à la frontière d’Israël, et vous saurez que je suis Yahweh.
11 Ìlú yìí kò ní i jẹ́ ìkòkò ìdáná, bẹ́ẹ̀ ni ẹ̀yin náà kò sì ní jẹ́ ẹran nínú rẹ̀, Èmi yóò ṣe ìdájọ́ yín ní àwọn ààlà ìlú Israẹli.
Cette ville ne sera pas pour vous la chaudière, et vous ne serez pas la viande au milieu d’elle; c’est à la frontière d’Israël que je vous jugerai.
12 Ẹ̀yin yóò sì mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa, nítorí pé ẹ̀yin kò tẹ̀lé àṣẹ mi ẹ̀yin kò sì pa òfin mi mọ́, ṣùgbọ́n ẹ̀yin ti hùwà gẹ́gẹ́ bí àwọn aláìgbàgbọ́ orílẹ̀-èdè tó yí yín ká.”
Et vous saurez que je suis Yahweh dont vous n’avez pas suivi les ordonnances, ni pratiqué les lois; mais vous avez agi selon les lois des nations qui vous entourent. »
13 Bí mo ṣe ń sọtẹ́lẹ̀ lọ́wọ́, Pelatiah ọmọ Benaiah kú. Mo sì dojúbolẹ̀, mo sì kígbe sókè pé, “Háà! Olúwa Olódùmarè! Ṣé ìwọ yóò ha pa ìyókù Israẹli run pátápátá ni?”
Comme je prophétisais, Pheltias, fils de Banaïas, mourut; et je tombai sur ma face, et je criai à haute voix, et je dis: « Ah! Seigneur, Yahweh, vas-tu anéantir ce qui reste d’Israël? »
14 Ọ̀rọ̀ Olúwa tún tọ̀ mí wá wí pé,
Et la parole de Yahweh me fut adressée en ces termes:
15 “Ọmọ ènìyàn, àwọn arákùnrin rẹ, àní àwọn ará rẹ, àwọn ọkùnrin nínú ìbátan rẹ, àti gbogbo ilé Israẹli pátápátá, ni àwọn ará Jerusalẹmu ti wí fún pé, ‘Ẹ jìnnà sí Olúwa, àwa ni a fi ilẹ̀ yìí fún yín ní ìní.’
« Fils de l’homme, tes frères, tes frères, hommes de ta parenté, et toute la maison d’Israël, ce sont tous ceux à qui les habitants de Jérusalem disent: Restez loin de Yahweh, c’est à nous que le pays a été donné en possession.
16 “Nítorí náà, sọ fún àwọn tó wà ní ìgbèkùn pé, ‘Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, bó tilẹ̀ jẹ́ pé mo ti fọ́n wọn káàkiri orílẹ̀-èdè, síbẹ̀ fún ìgbà díẹ̀, èmi yóò jẹ́ ibi mímọ́ fún wọn níbi tí wọ́n lọ.’
C’est pourquoi dis-leur: Ainsi parle le Seigneur Yahweh: Oui, je les ai éloignés parmi les nations, je les ai dispersés dans les pays; mais je serai pour eux un sanctuaire pendant un peu de temps, dans les pays où ils sont allés.
17 “Nítorí náà, wí pé, ‘Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, Èmi yóò kó wọn jọ kúrò láàrín àwọn orílẹ̀-èdè tí mo fọ́n wọn ká sí, Èmi yóò sì fún wọn ní ilẹ̀ Israẹli padà.’
C’est pourquoi dis-leur: Ainsi parle le Seigneur Yahweh: je vous rassemblerai du milieu des peuples, je vous recueillerai des pays où vous avez été dispersés, et je vous donnerai la terre d’Israël.
18 “Wọn yóò padà síbẹ̀, wọn yóò sì mú gbogbo àwòrán ìríra rẹ̀ àti ìbọ̀rìṣà rẹ̀ kúrò.
Ils y entreront et en ôteront toutes ses infamies et toutes ses abominations.
19 Èmi yóò fún wọn ní ọ̀kankan; èmi yóò sì fi ẹ̀mí tuntun sínú wọn, Èmi yóò mú ọkàn òkúta kúrò lára wọn, èmi yóò sì fún wọn ní ọkàn tó rọ̀ bí ara ẹran.
Et je leur donnerai un seul cœur; je mettrai au-dedans d’eux un esprit nouveau; et j’ôterai de leur chair le cœur de pierre, et je leur donnerai un cœur de chair,
20 Kí wọn le tẹ̀lé àṣẹ mi, kí wọn sì le pa òfin mi mọ́. Wọ́n yóò jẹ́ ènìyàn mi, Èmi náà yóò sì jẹ́ Ọlọ́run wọn.
afin qu’ils suivent mes ordonnances, et qu’ils gardent mes lois et les pratiquent; et ils seront mon peuple, et moi je serai leur Dieu.
21 Ṣùgbọ́n fún àwọn tí wọ́n ń fi gbogbo ọkàn wọn sin àwọn àwòrán ìríra àti àwọn òrìṣà, Èmi yóò mú ẹ̀san ohun tí wọ́n ṣe wá sí orí wọn bẹ́ẹ̀ ni Olúwa Olódùmarè wí.”
Quant à ceux dont le cœur suit le cœur de leurs idoles abominables, je ferai retomber leurs œuvres sur leurs têtes, — oracle du Seigneur Yahweh.
22 Àwọn kérúbù sì gbé ìyẹ́ wọn sókè pẹ̀lú kẹ̀kẹ́ lẹ́gbẹ̀ẹ́ wọn, ògo Ọlọ́run Israẹli sì wà lókè orí wọn.
Alors les Chérubins dressèrent leurs ailes, et les roues se mirent en mouvement avec eux, et la gloire du Dieu d’Israël reposait au-dessus d’eux.
23 Ògo Olúwa sì gòkè lọ kúrò láàrín ìlú, ó sì dúró lórí òkè tó wà ní ìlà-oòrùn ìlú náà.
Et la gloire de Yahweh, s’élevant de dessus le milieu de la ville, s’arrêta sur la montagne qui est à l’orient de la ville.
24 Lẹ́yìn náà, Ẹ̀mí gbé mi sókè, ó sì mú mi wá sí Kaldea lójú ìran, nípa ti Ẹ̀mí Ọlọ́run sí ọ̀dọ̀ àwọn ti ìgbèkùn. Bẹ́ẹ̀ ni ìran tí mo rí lọ kúrò ní ọ̀dọ̀ mi,
Et l’Esprit m’enleva et m’emmena en Chaldée auprès des captifs, en vision, dans l’esprit de Dieu; et la vision que j’avais eue disparut de devant moi.
25 mo sì sọ gbogbo ohun tí Olúwa fihàn mí fún àwọn tó wà ní ìgbèkùn.
Et je racontai aux captifs toutes les choses que Yahweh m’avait fait voir.

< Ezekiel 11 >