< Ezekiel 11 >
1 Ẹ̀mí sì gbé mi sókè, ó mú mi lọ sí ẹnu-ọ̀nà ilé Olúwa èyí tó dojúkọ ìlà-oòrùn. Ní àbáwọlé ẹnu-ọ̀nà yìí ni àwọn ọkùnrin mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n wá, mo rí Jaaṣaniah ọmọ Assuri àti Pelatiah ọmọ Benaiah, tí wọ́n jẹ́ ìjòyè àwọn ènìyàn.
Moreover, the Spirite lift me vp, and brought me vnto the East gate of the Lordes house, which lyeth Eastwarde, and beholde, at the entrie of the gate were fiue and twentie men: among whome I sawe Iaazaniah the sonne of Azur, and Pelatiah the sonne of Benaiah, the princes of the people.
2 Olúwa sì sọ fún mi pé, “Ọmọ ènìyàn, àwọn ọkùnrin yìí ló ń pète ibi, wọ́n sì ń gbé ìmọ̀ràn búburú kalẹ̀ nínú ìlú.
Then said he vnto me, Sonne of man, these are the men that imagine mischiefe, and deuise wicked counsell in this citie.
3 Wọ́n ní, ‘Kò ha tí ì tó àsìkò láti kọ́lé? Ìlú yìí ni ìkòkò ìdáná, àwa sì ni ẹran’.
For they say, It is not neere, let vs builde houses: this citie is the caldron, and wee be the flesh.
4 Nítorí náà sọtẹ́lẹ̀ nípa wọn; ọmọ ènìyàn, sọtẹ́lẹ̀.”
Therefore prophesie against them, sonne of man, prophesie.
5 Ẹ̀mí Olúwa sì bà lé mi, ó sì wí pé, “Sọ̀rọ̀!” Báyìí ni Olúwa wí, ohun tí ẹ ń sọ nìyìí, ilé Israẹli, mo mọ ohun tó wà lọ́kàn yín.
And the Spirite of the Lord fell vpon me, and said vnto me, Speake, Thus saith the Lord, O ye house of Israel, this haue ye said, and I know that which riseth vp of your mindes.
6 Ẹ̀yin ti sọ òkú yín di púpọ̀ nínú ìlú yìí, òkú sì ti kún gbogbo ìgboro rẹ̀.
Many haue ye murthered in this citie, and ye haue filled the streets thereof with the slaine.
7 “Torí náà, báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, àwọn òkú tí ẹ fọn sílẹ̀ sí àárín yín ni ẹran, ìlú yìí sì ni ìkòkò ìdáná ṣùgbọ́n èmi yóò le yín jáde níbẹ̀.
Therefore thus saith the Lord God, They that ye haue slaine, and haue layed in the middes of it, they are the flesh, and this citie is the caldron, but I wil bring you foorth of the mids of it.
8 Ẹ bẹ̀rù idà, èmi yóò sì mú idà wá sórí yín, bẹ́ẹ̀ ni Olúwa Olódùmarè wí.
Ye haue feared the sworde, and I wil bring a sworde vpon you, saith the Lord God.
9 Èmi yóò lé yín jáde kúrò ní ìlú yìí, èmi yóò sì fà yín lé àjèjì lọ́wọ́, èmi yóò sì mú ìdájọ́ ṣẹ lé yín lórí.
And I will bring you out of the middes thereof, and deliuer you into the hands of strangers, and will execute iudgements among you.
10 Nípa idà ni ẹ̀yin yóò ṣubú, èmi yóò sì ṣe ìdájọ́ yín ní àwọn ààlà ìlú Israẹli. Nígbà náà ni ẹ̀yin yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.
Ye shall fall by the sworde, and I wil iudge you in the border of Israel, and ye shall knowe that I am the Lord.
11 Ìlú yìí kò ní i jẹ́ ìkòkò ìdáná, bẹ́ẹ̀ ni ẹ̀yin náà kò sì ní jẹ́ ẹran nínú rẹ̀, Èmi yóò ṣe ìdájọ́ yín ní àwọn ààlà ìlú Israẹli.
This citie shall not be your caldron, neyther shall ye be the flesh in the middes thereof, but I will iudge you in the border of Israel.
12 Ẹ̀yin yóò sì mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa, nítorí pé ẹ̀yin kò tẹ̀lé àṣẹ mi ẹ̀yin kò sì pa òfin mi mọ́, ṣùgbọ́n ẹ̀yin ti hùwà gẹ́gẹ́ bí àwọn aláìgbàgbọ́ orílẹ̀-èdè tó yí yín ká.”
And ye shall knowe that I am the Lord: for ye haue not walked in my statutes, neither executed my iudgements, but haue done after the maners of the heathen, that are round about you.
13 Bí mo ṣe ń sọtẹ́lẹ̀ lọ́wọ́, Pelatiah ọmọ Benaiah kú. Mo sì dojúbolẹ̀, mo sì kígbe sókè pé, “Háà! Olúwa Olódùmarè! Ṣé ìwọ yóò ha pa ìyókù Israẹli run pátápátá ni?”
And when I prophesied, Pelatiah the sonne of Benaiah dyed: then fell I downe vpon my face, and cryed with a loude voyce, and saide, Ah Lord God, wilt thou then vtterly destroy all the remnant of Israel?
14 Ọ̀rọ̀ Olúwa tún tọ̀ mí wá wí pé,
Againe the worde of the Lord came vnto me, saying,
15 “Ọmọ ènìyàn, àwọn arákùnrin rẹ, àní àwọn ará rẹ, àwọn ọkùnrin nínú ìbátan rẹ, àti gbogbo ilé Israẹli pátápátá, ni àwọn ará Jerusalẹmu ti wí fún pé, ‘Ẹ jìnnà sí Olúwa, àwa ni a fi ilẹ̀ yìí fún yín ní ìní.’
Sonne of man, thy brethren, euen thy brethren, the men of thy kindred, and all the house of Israel, wholy are they vnto whome the inhabitants of Ierusalem haue said, Depart ye farre from the Lord: for the lande is giuen vs in possession.
16 “Nítorí náà, sọ fún àwọn tó wà ní ìgbèkùn pé, ‘Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, bó tilẹ̀ jẹ́ pé mo ti fọ́n wọn káàkiri orílẹ̀-èdè, síbẹ̀ fún ìgbà díẹ̀, èmi yóò jẹ́ ibi mímọ́ fún wọn níbi tí wọ́n lọ.’
Therefore say, Thus saith the Lord God, Although I haue cast them farre off among the heathen, and although I haue scattered them among the countreis, yet wil I be to them as a litle Sanctuarie in ye countreis where they shall come.
17 “Nítorí náà, wí pé, ‘Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, Èmi yóò kó wọn jọ kúrò láàrín àwọn orílẹ̀-èdè tí mo fọ́n wọn ká sí, Èmi yóò sì fún wọn ní ilẹ̀ Israẹli padà.’
Therefore say, Thus saith the Lord God, I will gather you againe from the people, and assemble you out of the countreis where ye haue bene scattered, and I will giue you ye land of Israel.
18 “Wọn yóò padà síbẹ̀, wọn yóò sì mú gbogbo àwòrán ìríra rẹ̀ àti ìbọ̀rìṣà rẹ̀ kúrò.
And they shall come thither, and they shall take away all the idoles thereof, and all the abominations thereof from thence.
19 Èmi yóò fún wọn ní ọ̀kankan; èmi yóò sì fi ẹ̀mí tuntun sínú wọn, Èmi yóò mú ọkàn òkúta kúrò lára wọn, èmi yóò sì fún wọn ní ọkàn tó rọ̀ bí ara ẹran.
And I will giue them one heart, and I will put a newe spirit within their bowels: and I will take the stonie heart out of their bodies, and will giue them an heart of flesh,
20 Kí wọn le tẹ̀lé àṣẹ mi, kí wọn sì le pa òfin mi mọ́. Wọ́n yóò jẹ́ ènìyàn mi, Èmi náà yóò sì jẹ́ Ọlọ́run wọn.
That they may walke in my statutes, and keepe my iudgements, and execute them: and they shall be my people, and I will be their God.
21 Ṣùgbọ́n fún àwọn tí wọ́n ń fi gbogbo ọkàn wọn sin àwọn àwòrán ìríra àti àwọn òrìṣà, Èmi yóò mú ẹ̀san ohun tí wọ́n ṣe wá sí orí wọn bẹ́ẹ̀ ni Olúwa Olódùmarè wí.”
But vpon them, whose heart is towarde their idoles, and whose affection goeth after their abominations, I will lay their way vpon their owne heades, saith the Lord God.
22 Àwọn kérúbù sì gbé ìyẹ́ wọn sókè pẹ̀lú kẹ̀kẹ́ lẹ́gbẹ̀ẹ́ wọn, ògo Ọlọ́run Israẹli sì wà lókè orí wọn.
Then did the Cherubims lift vp their wings, and the wheeles besides them, and the glorie of the God of Israel was vpon them on hie.
23 Ògo Olúwa sì gòkè lọ kúrò láàrín ìlú, ó sì dúró lórí òkè tó wà ní ìlà-oòrùn ìlú náà.
And the glorie of the Lord went vp from the middes of the citie, and stoode vpon the moutaine which is towarde the East side of the citie.
24 Lẹ́yìn náà, Ẹ̀mí gbé mi sókè, ó sì mú mi wá sí Kaldea lójú ìran, nípa ti Ẹ̀mí Ọlọ́run sí ọ̀dọ̀ àwọn ti ìgbèkùn. Bẹ́ẹ̀ ni ìran tí mo rí lọ kúrò ní ọ̀dọ̀ mi,
Afterwarde the Spirite tooke me vp, and brought me in a vision by the Spirit of God into Caldea to them that were led away captiues: so the vision that I had seene, went vp from me.
25 mo sì sọ gbogbo ohun tí Olúwa fihàn mí fún àwọn tó wà ní ìgbèkùn.
Then I declared vnto them that were led away captiues, all the things that the Lord had shewed me.