< Ezekiel 11 >
1 Ẹ̀mí sì gbé mi sókè, ó mú mi lọ sí ẹnu-ọ̀nà ilé Olúwa èyí tó dojúkọ ìlà-oòrùn. Ní àbáwọlé ẹnu-ọ̀nà yìí ni àwọn ọkùnrin mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n wá, mo rí Jaaṣaniah ọmọ Assuri àti Pelatiah ọmọ Benaiah, tí wọ́n jẹ́ ìjòyè àwọn ènìyàn.
Og Aanden opløftede mig og førte mig til den østre Port paa Herrens Hus, den, som er vendt imod Østen, og se, ved Indgangen til Porten var der fem og tyve Mænd; og jeg saa Jaasanja, Assurs Søn, midt iblandt dem, og Pelatja, Benajas Søn, Folkets Fyrster.
2 Olúwa sì sọ fún mi pé, “Ọmọ ènìyàn, àwọn ọkùnrin yìí ló ń pète ibi, wọ́n sì ń gbé ìmọ̀ràn búburú kalẹ̀ nínú ìlú.
Og han sagde til mig: Du Menneskesøn! det er de Mænd, som udtænke Uret, og som give onde Raad i denne Stad;
3 Wọ́n ní, ‘Kò ha tí ì tó àsìkò láti kọ́lé? Ìlú yìí ni ìkòkò ìdáná, àwa sì ni ẹran’.
og som sige: Det er ikke saa nær, at vi skulle bygge Huse; denne er Gryden, og vi ere Kødet.
4 Nítorí náà sọtẹ́lẹ̀ nípa wọn; ọmọ ènìyàn, sọtẹ́lẹ̀.”
Derfor spaa imod dem, spaa, du Menneskesøn!
5 Ẹ̀mí Olúwa sì bà lé mi, ó sì wí pé, “Sọ̀rọ̀!” Báyìí ni Olúwa wí, ohun tí ẹ ń sọ nìyìí, ilé Israẹli, mo mọ ohun tó wà lọ́kàn yín.
Og Herrens Aand faldt paa mig, og han sagde til mig: Sig, saa siger Herren: Saaledes sige I af Israels Hus, men de Tanker, som opstige i eders Aand, kender jeg.
6 Ẹ̀yin ti sọ òkú yín di púpọ̀ nínú ìlú yìí, òkú sì ti kún gbogbo ìgboro rẹ̀.
I have gjort dem af eder ihjelslagne mange i denne Stad og fyldt dens Gader med ihjelslagne.
7 “Torí náà, báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, àwọn òkú tí ẹ fọn sílẹ̀ sí àárín yín ni ẹran, ìlú yìí sì ni ìkòkò ìdáná ṣùgbọ́n èmi yóò le yín jáde níbẹ̀.
Derfor, saa siger den Herre, Herre: Eders ihjelslagne, som I have lagt midt i den, de ere Kødet, og den selv er Gryden; men eder skal man udføre midt af den.
8 Ẹ bẹ̀rù idà, èmi yóò sì mú idà wá sórí yín, bẹ́ẹ̀ ni Olúwa Olódùmarè wí.
For Sværdet frygte I, og Sværdet vil jeg lade komme over eder, siger den Herre, Herre.
9 Èmi yóò lé yín jáde kúrò ní ìlú yìí, èmi yóò sì fà yín lé àjèjì lọ́wọ́, èmi yóò sì mú ìdájọ́ ṣẹ lé yín lórí.
Og jeg vil udføre eder midt af den og give eder i fremmedes Haand og holde Dom over eder.
10 Nípa idà ni ẹ̀yin yóò ṣubú, èmi yóò sì ṣe ìdájọ́ yín ní àwọn ààlà ìlú Israẹli. Nígbà náà ni ẹ̀yin yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.
For Sværdet skulle I falde, paa Israels Grænse vil jeg dømme eder; og I skulle fornemme, at jeg er Herren.
11 Ìlú yìí kò ní i jẹ́ ìkòkò ìdáná, bẹ́ẹ̀ ni ẹ̀yin náà kò sì ní jẹ́ ẹran nínú rẹ̀, Èmi yóò ṣe ìdájọ́ yín ní àwọn ààlà ìlú Israẹli.
Den, den skal ikke blive eder Gryden, saa at I blive Kødet derudi; ved Israels Grænse vil jeg dømme eder.
12 Ẹ̀yin yóò sì mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa, nítorí pé ẹ̀yin kò tẹ̀lé àṣẹ mi ẹ̀yin kò sì pa òfin mi mọ́, ṣùgbọ́n ẹ̀yin ti hùwà gẹ́gẹ́ bí àwọn aláìgbàgbọ́ orílẹ̀-èdè tó yí yín ká.”
Og I skulle fornemme, at jeg er Herren, fordi I ikke have vandret efter mine Skikke og ikke holdt mine Bud, men gjort efter Hedningernes Vis, som ere trindt omkring eder.
13 Bí mo ṣe ń sọtẹ́lẹ̀ lọ́wọ́, Pelatiah ọmọ Benaiah kú. Mo sì dojúbolẹ̀, mo sì kígbe sókè pé, “Háà! Olúwa Olódùmarè! Ṣé ìwọ yóò ha pa ìyókù Israẹli run pátápátá ni?”
Og det skete, der jeg spaaede, da døde Pelatja, Benajas Søn; og jeg faldt ned paa mit Ansigt og raabte med høj Røst og sagde: Ak, Herre, Herre! du gør det jo aldeles af med det overblevne af Israel!
14 Ọ̀rọ̀ Olúwa tún tọ̀ mí wá wí pé,
Da kom Herrens Ord til mig, og han sagde:
15 “Ọmọ ènìyàn, àwọn arákùnrin rẹ, àní àwọn ará rẹ, àwọn ọkùnrin nínú ìbátan rẹ, àti gbogbo ilé Israẹli pátápátá, ni àwọn ará Jerusalẹmu ti wí fún pé, ‘Ẹ jìnnà sí Olúwa, àwa ni a fi ilẹ̀ yìí fún yín ní ìní.’
Du Menneskesøn! dine Brødre, dine Brødre ere dine næste Slægtninge og hele Israels Hus, alle de, til hvilke de, som bo i Jerusalem, sige: Gaar bort langt fra Herren, os er dette Land givet til Ejendom.
16 “Nítorí náà, sọ fún àwọn tó wà ní ìgbèkùn pé, ‘Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, bó tilẹ̀ jẹ́ pé mo ti fọ́n wọn káàkiri orílẹ̀-èdè, síbẹ̀ fún ìgbà díẹ̀, èmi yóò jẹ́ ibi mímọ́ fún wọn níbi tí wọ́n lọ.’
Derfor sig: Saa siger den Herre, Herre: Jeg har ladet dem fare langt bort iblandt Hedningerne, og jeg har adspredt dem i Landene, men jeg er dog bleven dem til en Helligdom for en kort Tid i Landene, hvorhen de ere komne.
17 “Nítorí náà, wí pé, ‘Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, Èmi yóò kó wọn jọ kúrò láàrín àwọn orílẹ̀-èdè tí mo fọ́n wọn ká sí, Èmi yóò sì fún wọn ní ilẹ̀ Israẹli padà.’
Derfor sig: Saa siger den Herre, Herre: Jeg vil samle eder fra Folkene og sanke eder fra Landene, i hvilke I ere adspredte, og jeg vil give eder Israels Land.
18 “Wọn yóò padà síbẹ̀, wọn yóò sì mú gbogbo àwòrán ìríra rẹ̀ àti ìbọ̀rìṣà rẹ̀ kúrò.
Og derhen skulle de komme, og de skulle fjerne alle dets Afskyeligheder og alle dets Vederstyggeligheder fra det.
19 Èmi yóò fún wọn ní ọ̀kankan; èmi yóò sì fi ẹ̀mí tuntun sínú wọn, Èmi yóò mú ọkàn òkúta kúrò lára wọn, èmi yóò sì fún wọn ní ọkàn tó rọ̀ bí ara ẹran.
Og jeg vil give dem eet Hjerte og give en ny Aand i deres Indre „og borttage Stenhjertet af deres Kød og give dem et Kødhjerte,
20 Kí wọn le tẹ̀lé àṣẹ mi, kí wọn sì le pa òfin mi mọ́. Wọ́n yóò jẹ́ ènìyàn mi, Èmi náà yóò sì jẹ́ Ọlọ́run wọn.
paa det de skulle vandre i mine Skikke og holde mine Bud og gøre efter dem; og de skulle være mit Folk, og jeg skal være deres Gud.
21 Ṣùgbọ́n fún àwọn tí wọ́n ń fi gbogbo ọkàn wọn sin àwọn àwòrán ìríra àti àwọn òrìṣà, Èmi yóò mú ẹ̀san ohun tí wọ́n ṣe wá sí orí wọn bẹ́ẹ̀ ni Olúwa Olódùmarè wí.”
Men de, hvis Hjerte vandrer efter deres Afskyeligheders og deres Vederstyggeligheders Hjerte, deres Vej vil jeg lade falde til— bage paa deres Hoved, siger den Herre, Herre.
22 Àwọn kérúbù sì gbé ìyẹ́ wọn sókè pẹ̀lú kẹ̀kẹ́ lẹ́gbẹ̀ẹ́ wọn, ògo Ọlọ́run Israẹli sì wà lókè orí wọn.
Da opløftede Keruberne deres Vinger og Hjulene ved Siden af dem, og Israels Guds Herlighed var oven over dem.
23 Ògo Olúwa sì gòkè lọ kúrò láàrín ìlú, ó sì dúró lórí òkè tó wà ní ìlà-oòrùn ìlú náà.
Og Herrens Herlighed steg op fra Stadens Midte og blev staaende paa Bjerget, som er Østen for Staden.
24 Lẹ́yìn náà, Ẹ̀mí gbé mi sókè, ó sì mú mi wá sí Kaldea lójú ìran, nípa ti Ẹ̀mí Ọlọ́run sí ọ̀dọ̀ àwọn ti ìgbèkùn. Bẹ́ẹ̀ ni ìran tí mo rí lọ kúrò ní ọ̀dọ̀ mi,
Og Aanden opløftede mig og førte mig i Synet, i Guds Aand, til Kaldæa til de bortførte; og det Fyn, som jeg havde set, forsvandt for mig i det høje.
25 mo sì sọ gbogbo ohun tí Olúwa fihàn mí fún àwọn tó wà ní ìgbèkùn.
Og jeg talte til de bortførte alle Herrens Ord, som han havde ladet mig se.