< Ezekiel 11 >

1 Ẹ̀mí sì gbé mi sókè, ó mú mi lọ sí ẹnu-ọ̀nà ilé Olúwa èyí tó dojúkọ ìlà-oòrùn. Ní àbáwọlé ẹnu-ọ̀nà yìí ni àwọn ọkùnrin mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n wá, mo rí Jaaṣaniah ọmọ Assuri àti Pelatiah ọmọ Benaiah, tí wọ́n jẹ́ ìjòyè àwọn ènìyàn.
I vznesl mne Duch, a přivedl mne k bráně východní domu Hospodinova, kteráž patří na východ, a aj, ve vratech brány té pětmecítma mužů, mezi kterýmiž jsem viděl Jazaniáše syna Azurova, a Pelatiáše syna Banaiášova, knížata lidu.
2 Olúwa sì sọ fún mi pé, “Ọmọ ènìyàn, àwọn ọkùnrin yìí ló ń pète ibi, wọ́n sì ń gbé ìmọ̀ràn búburú kalẹ̀ nínú ìlú.
Tedy řekl mi: Synu člověčí, to jsou ti muži, kteříž smýšlejí nepravost, a skládají radu zlou v městě tomto,
3 Wọ́n ní, ‘Kò ha tí ì tó àsìkò láti kọ́lé? Ìlú yìí ni ìkòkò ìdáná, àwa sì ni ẹran’.
Říkajíce: Nestavějme domů blízko, sic město bude hrnec a my maso.
4 Nítorí náà sọtẹ́lẹ̀ nípa wọn; ọmọ ènìyàn, sọtẹ́lẹ̀.”
Protož prorokuj proti nim, prorokuj, synu člověčí.
5 Ẹ̀mí Olúwa sì bà lé mi, ó sì wí pé, “Sọ̀rọ̀!” Báyìí ni Olúwa wí, ohun tí ẹ ń sọ nìyìí, ilé Israẹli, mo mọ ohun tó wà lọ́kàn yín.
I sstoupil na mne Duch Hospodinův, a řekl mi: Rci: Takto dí Hospodin: Tak říkáte, dome Izraelský. Nebo což vám koli vstupuje na mysl, o tom já vím.
6 Ẹ̀yin ti sọ òkú yín di púpọ̀ nínú ìlú yìí, òkú sì ti kún gbogbo ìgboro rẹ̀.
Veliké množství zmordovali jste v městě tomto, a naplnili jste ulice jeho zbitými.
7 “Torí náà, báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, àwọn òkú tí ẹ fọn sílẹ̀ sí àárín yín ni ẹran, ìlú yìí sì ni ìkòkò ìdáná ṣùgbọ́n èmi yóò le yín jáde níbẹ̀.
Protož takto praví Panovník Hospodin: Ti, kteříž jsou zbiti od vás, kteréž jste skladli u prostřed něho, oniť jsou maso, město pak hrnec, ale vás vyvedu z prostředku jeho.
8 Ẹ bẹ̀rù idà, èmi yóò sì mú idà wá sórí yín, bẹ́ẹ̀ ni Olúwa Olódùmarè wí.
Báli jste se meče, ale meč uvedu na vás, praví Panovník Hospodin.
9 Èmi yóò lé yín jáde kúrò ní ìlú yìí, èmi yóò sì fà yín lé àjèjì lọ́wọ́, èmi yóò sì mú ìdájọ́ ṣẹ lé yín lórí.
A vyvedu vás z prostředku jeho, a dám vás v ruku cizích, a vykonám nad vámi soudy.
10 Nípa idà ni ẹ̀yin yóò ṣubú, èmi yóò sì ṣe ìdájọ́ yín ní àwọn ààlà ìlú Israẹli. Nígbà náà ni ẹ̀yin yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.
Mečem padnete, na pomezí Izraelském souditi vás budu, a zvíte, že já jsem Hospodin.
11 Ìlú yìí kò ní i jẹ́ ìkòkò ìdáná, bẹ́ẹ̀ ni ẹ̀yin náà kò sì ní jẹ́ ẹran nínú rẹ̀, Èmi yóò ṣe ìdájọ́ yín ní àwọn ààlà ìlú Israẹli.
Město nebude vám hrnec, aniž vy budete u prostřed něho maso, na pomezí Izraelském souditi vás budu.
12 Ẹ̀yin yóò sì mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa, nítorí pé ẹ̀yin kò tẹ̀lé àṣẹ mi ẹ̀yin kò sì pa òfin mi mọ́, ṣùgbọ́n ẹ̀yin ti hùwà gẹ́gẹ́ bí àwọn aláìgbàgbọ́ orílẹ̀-èdè tó yí yín ká.”
I zvíte, že já jsem Hospodin, poněvadž jste v ustanoveních mých nechodili, a soudů mých nečinili, a podlé soudů těch národů, kteříž jsou vůkol vás, činili jste.
13 Bí mo ṣe ń sọtẹ́lẹ̀ lọ́wọ́, Pelatiah ọmọ Benaiah kú. Mo sì dojúbolẹ̀, mo sì kígbe sókè pé, “Háà! Olúwa Olódùmarè! Ṣé ìwọ yóò ha pa ìyókù Israẹli run pátápátá ni?”
Stalo se pak, když jsem prorokoval, že Pelatiáš syn Banaiášův umřel. Pročež padl jsem na tvář svou, a zvolal jsem hlasem velikým, řka: Ach, Panovníče Hospodine, skonání, činíš ostatkům Izraelským.
14 Ọ̀rọ̀ Olúwa tún tọ̀ mí wá wí pé,
Tedy stalo se slovo Hospodinovo ke mně, řkoucí:
15 “Ọmọ ènìyàn, àwọn arákùnrin rẹ, àní àwọn ará rẹ, àwọn ọkùnrin nínú ìbátan rẹ, àti gbogbo ilé Israẹli pátápátá, ni àwọn ará Jerusalẹmu ti wí fún pé, ‘Ẹ jìnnà sí Olúwa, àwa ni a fi ilẹ̀ yìí fún yín ní ìní.’
Synu člověčí, bratří tvoji, bratří tvoji, příbuzní tvoji, a všecken dům Izraelský, všecken dům, kterýmž říkali obyvatelé Jeruzalémští: Daleko zajděte od Hospodina, nám jest dána země tato v dědictví.
16 “Nítorí náà, sọ fún àwọn tó wà ní ìgbèkùn pé, ‘Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, bó tilẹ̀ jẹ́ pé mo ti fọ́n wọn káàkiri orílẹ̀-èdè, síbẹ̀ fún ìgbà díẹ̀, èmi yóò jẹ́ ibi mímọ́ fún wọn níbi tí wọ́n lọ.’
Protož rci: Takto praví Panovník Hospodin: Ačkoli daleko zahnal jsem je mezi národy, a ačkoli rozptýlil jsem je do zemí, však budu jim svatyní i za ten malý čas v zemích těch, do kterýchž přijdou.
17 “Nítorí náà, wí pé, ‘Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, Èmi yóò kó wọn jọ kúrò láàrín àwọn orílẹ̀-èdè tí mo fọ́n wọn ká sí, Èmi yóò sì fún wọn ní ilẹ̀ Israẹli padà.’
Protož rci: Takto praví Panovník Hospodin: Shromáždím vás z národů a zberu vás z zemí, do kterýchž rozptýleni jste, a dám vám zemi Izraelskou.
18 “Wọn yóò padà síbẹ̀, wọn yóò sì mú gbogbo àwòrán ìríra rẹ̀ àti ìbọ̀rìṣà rẹ̀ kúrò.
I vejdou tam, a vyvrhou všecky mrzkosti její, i všecky ohavnosti její z ní.
19 Èmi yóò fún wọn ní ọ̀kankan; èmi yóò sì fi ẹ̀mí tuntun sínú wọn, Èmi yóò mú ọkàn òkúta kúrò lára wọn, èmi yóò sì fún wọn ní ọkàn tó rọ̀ bí ara ẹran.
Nebo dám jim srdce jedno, a Ducha nového dám do vnitřností vašich, a odejmu srdce kamenné z těla jejich, a dám jim srdce masité,
20 Kí wọn le tẹ̀lé àṣẹ mi, kí wọn sì le pa òfin mi mọ́. Wọ́n yóò jẹ́ ènìyàn mi, Èmi náà yóò sì jẹ́ Ọlọ́run wọn.
Aby v ustanoveních mých chodili, a soudů mých ostříhali, a činili je. I budou lidem mým, a já budu jejich Bohem.
21 Ṣùgbọ́n fún àwọn tí wọ́n ń fi gbogbo ọkàn wọn sin àwọn àwòrán ìríra àti àwọn òrìṣà, Èmi yóò mú ẹ̀san ohun tí wọ́n ṣe wá sí orí wọn bẹ́ẹ̀ ni Olúwa Olódùmarè wí.”
Kterýchž pak srdce chodilo by po žádostech mrzkostí svých a ohavností svých, těch cestu na hlavu jejich obrátím, praví Panovník Hospodin.
22 Àwọn kérúbù sì gbé ìyẹ́ wọn sókè pẹ̀lú kẹ̀kẹ́ lẹ́gbẹ̀ẹ́ wọn, ògo Ọlọ́run Israẹli sì wà lókè orí wọn.
Tedy vznesli cherubínové křídla svá i kola s nimi, sláva pak Boha Izraelského nad nimi svrchu.
23 Ògo Olúwa sì gòkè lọ kúrò láàrín ìlú, ó sì dúró lórí òkè tó wà ní ìlà-oòrùn ìlú náà.
I odešla sláva Hospodinova z prostředku města, a stála na hoře, kteráž jest na východ městu.
24 Lẹ́yìn náà, Ẹ̀mí gbé mi sókè, ó sì mú mi wá sí Kaldea lójú ìran, nípa ti Ẹ̀mí Ọlọ́run sí ọ̀dọ̀ àwọn ti ìgbèkùn. Bẹ́ẹ̀ ni ìran tí mo rí lọ kúrò ní ọ̀dọ̀ mi,
Duch pak vznesl mne, a zase mne přivedl do země Kaldejské k zajatým, u vidění skrze Ducha Božího. I odešlo ode mne vidění, kteréž jsem viděl.
25 mo sì sọ gbogbo ohun tí Olúwa fihàn mí fún àwọn tó wà ní ìgbèkùn.
A mluvil jsem k zajatým všecky ty věci Hospodinovy, kteréž mi ukázal.

< Ezekiel 11 >