< Ezekiel 10 >

1 Mo sì wò ó, mo rí ohun kan tó dàbí òkúta safire nínú òfúrufú tó wà lókè orí kérúbù, ìrísí ohun yìí sì dàbí ìtẹ́.
Et je regardai, et voilà que sur le firmament, qui était au-dessus de la tête des chérubins, il y avait comme un saphir, image d'un trône au-dessus d'eux.
2 Olúwa sì sọ fún ọkùnrin tó wọ aṣọ funfun pé, “Lọ sí àárín àwọn kẹ̀kẹ́ tó wà lábẹ́ kérúbù. Bu ẹyin iná tó kúnwọ́ rẹ láàrín kérúbù, kí o sì fọ́n sórí ìlú náà.” Ó sì lọ lójú mi.
Et le Seigneur dit à l'homme revêtu d'une longue robe: Entre au milieu des roues sous les chérubins, et prends à pleines mains des charbons au foyer qui est entre les chérubins, et disperse-les sur la ville. Et il y entra devant moi.
3 Àwọn kérúbù dúró sí apá gúúsù tẹmpili nígbà tí ọkùnrin náà wọlé, ìkùùkuu sì bo inú àgbàlá.
Et quand l'homme y entra, les chérubins étaient à droite dans le temple, et une nuée remplit le parvis intérieur.
4 Ògo Olúwa sì kúrò lórí àwọn kérúbù, ó bọ́ sí ibi ìloro tẹmpili. Ìkùùkuu sì bo inú tẹmpili, àgbàlá sì kún fún ìmọ́lẹ̀ àti ògo Olúwa.
Alors la gloire du Seigneur s'éleva, et des chérubins passa au portique du temple, et la nuée remplit le temple; et le parvis était rempli des rayons de la gloire du Seigneur.
5 A sì gbọ́ ariwo ìyẹ́ àwọn kérúbù yìí títí dé àgbàlá tó wà ní ìta gẹ́gẹ́ bí ìgbà tí Ọlọ́run Olódùmarè bá ń sọ̀rọ̀.
Et le bruit des ailes des chérubins s'entendit jusqu'au parvis extérieur, semblable à la voix du Dieu tout-puissant quand il parle.
6 Nígbà tí Olúwa pàṣẹ fún ọkùnrin aláṣọ funfun yìí pé, “Mú iná láàrín àwọn kẹ̀kẹ́, láàrín àwọn kérúbù,” ó sì lọ dúró ṣẹ́gbẹ̀ẹ́ àwọn kẹ̀kẹ́ náà.
Et ceci advint: pendant que le Seigneur donnait ses ordres à l'homme revêtu de la robe sainte, disant: Prends du feu au milieu des roues, parmi les chérubins; l'homme entra et s'arrêta près des roues.
7 Ọ̀kan nínú àwọn kérúbù sì nawọ́ sí ibi iná tó wà láàrín kérúbù yòókù. Ó mú lára rẹ, ó fi sínú ọwọ́ ọkùnrin aláṣọ funfun, òun náà gbà á, ó sì jáde lọ.
Et le Seigneur étendit la main sur le feu qui était parmi les chérubins, et il en prit, et il en remplit les mains de l'homme qui était revêtu de la robe sainte; et celui-ci le prit, et il sortit.
8 (Ohun tó dàbí ọwọ́ ènìyàn wà lábẹ́ ìyẹ́ àwọn kérúbù yìí.)
Et je vis les chérubins ayant l'image d'une main d'homme sur leurs ailes.
9 Nígbà tí mo sì wò, kíyèsí i, àwọn kẹ̀kẹ́ mẹ́rin wà lẹ́gbẹ̀ẹ́ àwọn kérúbù yìí, kẹ̀kẹ́ kọ̀ọ̀kan wà lẹ́gbẹ̀ẹ́ kérúbù kọ̀ọ̀kan; ìrí àwọn kẹ̀kẹ́ yìí ń tàn yanran bí àwọ̀ òkúta berili.
Et je vis, et voilà que les quatre roues étaient arrêtées près des chérubins; chaque roue touchait un chérubin, et l'aspect des roues était comme l'aspect d'une escarboucle.
10 Ní ti ìrísí wọn, gbogbo wọn jọra wọn; ọ̀kọ̀ọ̀kan rí bí ìgbà tí kẹ̀kẹ́ kan wà nínú kẹ̀kẹ́ mìíràn.
Et, quant à leur aspect; elles avaient toutes les quatre le même aspect, c'était comme si une roue était au milieu d'une roue.
11 Nígbà tí wọ́n ń lọ, wọ́n tẹ̀lé ọ̀kan nínú ọ̀nà mẹ́rin tí àwọn kérúbù dojúkọ; àwọn kẹ̀kẹ́ náà kò yípadà bí àwọn kérúbù ti ń lọ. Àwọn kérúbù ń lọ sí ibi tí orí dojúkọ láì yà.
Lorsqu'elles allaient, elles allaient de leurs quatre parties, et en allant elles ne se retournaient pas; quel que fut le lieu qu'avait regardé la première tète, elles y allaient, et, en allant, elles ne se retournaient pas.
12 Gbogbo ara wọn àti ẹ̀yìn, ọwọ́ wọn àti ìyẹ́ wọn, àti àwọn kẹ̀kẹ́ kún fún ojú yíkákiri kẹ̀kẹ́, tí àwọn mẹ́rẹ̀ẹ̀rin ní.
Et leurs moyeux, leurs mains, leurs ailes et leurs bandes étaient pleins d'yeux, tout alentour aux quatre roues.
13 Mo gbọ́ tí wọ́n pe àwọn kẹ̀kẹ́ yìí ni “kẹ̀kẹ́ àjà.”
Et tandis que j'écoutais, le nom de Gelgel fut donné aux quatre roues.
14 Ọ̀kọ̀ọ̀kan àwọn kérúbù yìí ni ojú mẹ́rin: ojú èkínní jẹ́ ojú kérúbù, ojú kejì jẹ́ ti ènìyàn, ojú kẹta jẹ́ ti kìnnìún nígbà tí ojú kẹrin jẹ́ ti ẹyẹ idì.
15 A gbé àwọn kérúbù sókè. Èyí ni àwọn ẹ̀dá alààyè tí mo rí létí odò Kebari.
Et les chérubins étaient ces mêmes créatures vivantes que j'avais vues sur le fleuve Chobar.
16 Bí àwọn kérúbù yìí bá ń lọ àwọn kẹ̀kẹ́ ẹgbẹ́ wọn náà yóò lọ; bẹ́ẹ̀ ni bí àwọn kérúbù bá tú ìyẹ́ wọn ká láti dìde nílẹ̀, àwọn kẹ̀kẹ́ yìí kò ní kúrò lẹ́gbẹ̀ẹ́ wọn.
Et quand les chérubins allaient, les roues allaient, et elles étaient tout près d'eux; et quand les chérubins étendaient les ailes pour s'élever au- dessus de terre, les roues ne se détournaient point d'eux.
17 Bí àwọn kérúbù bá dúró díẹ̀ àwọn kẹ̀kẹ́ náà yóò dúró jẹ́ẹ́; bí àwọn kérúbù bá dìde àwọn kẹ̀kẹ́ náà yóò dìde, nítorí pé ẹ̀mí àwọn ẹ̀dá alààyè yìí wà nínú wọn.
Et quand ils s'arrêtaient, elles s'arrêtaient; et quand ils s'élevaient, elles s'élevaient avec eux, parce qu'il y avait en elles un esprit de vie.
18 Ògo Olúwa kúrò níbi ìloro tẹmpili, ó sì dúró sórí àwọn kérúbù.
Et la gloire du Seigneur sortit du temple, et alla sur les chérubins.
19 Àwọn kérúbù gbé ìyẹ́ wọn sókè, wọ́n sì fò kúrò nílẹ̀ lójú mi, wọ́n sì lọ pẹ̀lú kẹ̀kẹ́ wọn lẹ́ẹ̀kan náà. Wọ́n dúró níbi ìlẹ̀kùn ẹnu-ọ̀nà ìlà-oòrùn ilé Olúwa, ògo Ọlọ́run Israẹli sì wà lórí wọn.
Et les chérubins déployèrent leurs ailes, et ils planèrent au-dessus de terre devant moi; lorsqu'ils partirent, les roues étaient toujours auprès d'eux, et ils s'arrêtèrent sur le vestibule de la façade du temple du Seigneur; et la gloire du Dieu d'Israël était sur eux.
20 Àwọn wọ̀nyí ni ẹ̀dá alààyè tí mo rí lábẹ́ Ọlọ́run Israẹli létí odò Kebari, mo sì mọ̀ pé kérúbù ni wọ́n.
Et c'étaient les créatures vivantes que j'avais vues au-dessous du Dieu d'Israël, vers le fleuve de Chobar, et je reconnus que c'étaient des chérubins.
21 Ọ̀kọ̀ọ̀kan wọn ní ojú mẹ́rin àti ìyẹ́ mẹ́rin, lábẹ́ ìyẹ́ wọn ni ohun tó jọ ọwọ́ ènìyàn wà.
Chacun avait quatre faces et huit ailes, et sous les ailes l'image d'une main d'homme.
22 Àfiwé ojú àti ìrísí wọn rí bákan náà pẹ̀lú àwọn tí mo rí létí odò Kebari. Olúkúlùkù wọn sì ń lọ sí ọ̀kánkán tààrà.
Et leurs visages se ressemblaient, et c'étaient les visages que j'avais vus sous la gloire du Dieu d'Israël, vers le fleuve Chobar, et chacun marchait droit devant lui.

< Ezekiel 10 >