< Exodus 1 >

1 Ìwọ̀nyí ni àwọn orúkọ ọmọ Israẹli tí wọ́n bá Jakọbu lọ sí Ejibiti, ẹnìkọ̀ọ̀kan pẹ̀lú ìdílé rẹ̀:
We töwendikiler Israil [bilen bille] Misirgha barghan oghullirining isimliri (ular herqaysisi öz bala-chaqilirini élip, Yaqup bilen bille Misirgha barghanidi): —
2 Reubeni, Simeoni, Lefi àti Juda;
Ruben, Shiméon, Lawiy, Yehuda,
3 Isakari, Sebuluni àti Benjamini;
Issakar, Zebulun, Binyamin,
4 Dani àti Naftali; Gadi àti Aṣeri.
Dan, Naftali, Gad we Ashir.
5 Àwọn ìran Jakọbu sì jẹ́ àádọ́rin ní àpapọ̀; Josẹfu sì ti wà ní Ejibiti.
Emdi Yaqupning pushtidin bolghanlar jemiy bolup yetmish adem idi. Bu waqitta Yüsüp Misirda idi.
6 Wàyí o, Josẹfu àti gbogbo àwọn arákùnrin rẹ̀ àti gbogbo ìran náà kú,
Kéyin Yüsüp, uning barliq qérindashliri hemde barliq zamandashliri ölüp tügidi.
7 ṣùgbọ́n àwọn ará Israẹli ń bí sí i, wọ́n ń pọ̀ sí i gidigidi, wọ́n kò sì ní òǹkà tí ó fi jẹ́ pé wọ́n kún ilẹ̀ náà.
Shundaqtimu, Israillar köp tughulup, téz awup, intayin kücheydi; ular zémin’gha bir keldi.
8 Nígbà náà ni ọba tuntun mìíràn tí kò mọ Josẹfu jẹ ní ilẹ̀ Ejibiti.
U waqitlarda Yüsüpni bilmeydighan yéngi bir padishah Misirda textke chiqti.
9 Ó sọ fún àwọn ènìyàn rẹ̀, “Ẹ wò ó, àwọn ará Israẹli ti pọ̀ ní iye àti agbára jù fún wa.
U xelqige: Mana, Israillarning xelqi bizdin ziyade awup hemde bizdinmu küchlinip ketti.
10 Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a lo ọgbọ́n àlùmọ̀kọ́rọ́yí láti dá wọn lẹ́kun, bí kò ṣe bẹ́ẹ̀ wọn yóò túbọ̀ máa pọ̀ sí i. Bí ogun bá sì bẹ́ sílẹ̀, wọn yóò darapọ̀ mọ́ àwọn ọ̀tá wa, wọn yóò sì da ojú ìjà kọ wá, wọn yóò sì sá àsálà kúrò ní ilẹ̀ yìí.”
Emdi biz ulargha nisbeten aqilane ish tutayli; bolmisa, ular téximu awup kétidu, mubada urush partlap qalsa, shundaq boliduki, ular düshmenlirimiz terepke ötüp, bizge hujum qilip, yurttin chiqip kétishi mumkin, — dédi.
11 Nítorí náà, wọ́n yan àwọn ọ̀gá akóniṣiṣẹ́ lé wọn lórí láti máa ni wọ́n lára pẹ̀lú iṣẹ́ àṣekára. Wọ́n sì kọ́ Pitomi àti Ramesesi gẹ́gẹ́ bí ìlú ìṣúra pamọ́ sí fún Farao.
Shuning bilen ular ularni qattiq emgekler bilen xarlash üchün ish bashlirini teyinlep nazaretchilikke qoydi. Shuning bilen Israillar Pirewn üchün Pitom bilen Raamses dégen maddiy eshya saqlaydighan sheherlerni yasap berdi.
12 Ṣùgbọ́n bí a ti ń ni wọ́n lára tó, bẹ́ẹ̀ ni wọ́n ń pọ̀ sí i, tí wọ́n sì ń tànkálẹ̀. Nítorí náà, àwọn ará Ejibiti bẹ̀rù nítorí àwọn ará Israẹli.
Lékin ularni [qanche] ezgenséri, bular shunche köpiyip hemme yerni qaplidi; buning bilen misirliqlar Israillargha öch bolup ketti.
13 Àwọn ará Ejibiti sì mú àwọn ọmọ Israẹli sìn ní àsìnpa.
Shuning bilen misirliqlar Israillargha zulum qilip, ularni téximu qattiq ishlitip éghir ishlargha saldi.
14 Wọ́n mú wọn gbé ìgbé ayé kíkorò nípa iṣẹ́ bíríkì àti àwọn onírúurú iṣẹ́ oko; àwọn ará Ejibiti ń lò wọ́n ní ìlòkulò.
Misirliqlar ularni laychiliq, xish-kések quyush we étizlarning herxil emgeklirige sélip, ishning qattiqliqi bilen ularning turmushigha qattiq éghirchiliq saldi; ularni néme emgekke salmisun, intayin japaliq idi.
15 Ọba Ejibiti sọ fún àwọn agbẹ̀bí Heberu ti orúkọ wọn ń jẹ́ Ṣifura àti Pua pé,
Misir padishahi ikki ibraniy tughut anisigha söz qilip (ularning birining ismi Shifrah, yene birining ismi Puah idi):
16 “Nígbà ti ẹ̀yin bá ń gbẹ̀bí àwọn obìnrin Heberu, tí ẹ sì kíyèsi wọn lórí ìkúnlẹ̀ ìrọbí wọn, bí ó bá jẹ́ ọkùnrin ni ọmọ náà, ẹ pa á; ṣùgbọ́n bí ó bá jẹ́ obìnrin, ẹ jẹ́ kí ó wà láààyè.”
— siler qachanliki ibraniy xotunlarni tughdursanglar, tughqanda obdan qaranglar; bowaq oghul bolsa, öltürüwétinglar; qiz bolsa, tirik qoyunglar, — dédi.
17 Ṣùgbọ́n àwọn agbẹ̀bí bẹ̀rù Ọlọ́run, wọn kò sì ṣe gẹ́gẹ́ bí ọba Ejibiti ti wí fún wọn; wọ́n jẹ́ kí àwọn ọmọkùnrin wà láààyè.
Lékin tughut aniliri Xudadin qorqup, Misirning padishahi ulargha éytqandek qilmay, belki oghul bowaqlarni tirik qoydi.
18 Ọba Ejibiti pe àwọn agbẹ̀bí ó sì béèrè lọ́wọ́ wọn pé, “Èéṣe tí ẹ̀yin fi ṣe èyí? Èéṣe tí ẹ̀yin fi dá àwọn ọmọkùnrin si?”
Shunga Misirning padishahi tughut anilirini chaqirtip ulardin: — Bu néme qilghininglar?! Oghul balilarni némishqa tirik qoydunglar? — dep soridi.
19 Àwọn agbẹ̀bí náà sì dá Farao lóhùn pé, “Àwọn obìnrin Heberu kò rí bí àwọn obìnrin Ejibiti, wọ́n ní agbára, wọ́n sì ti máa ń bí ọmọ kí àwọn agbẹ̀bí tó dé ọ̀dọ̀ wọn.”
Tughut aniliri Pirewn’ge jawab bérip: — Ibraniy ayallar misirliq ayallargha oxshimaydu. Ular küchlük, saghlam-timen bolghini üchün tughut aniliri ularning qéshigha yétip barghuche, özliri tughup bolidu, — dédi.
20 Nítorí náà Ọlọ́run ṣàánú fún àwọn agbẹ̀bí náà, àwọn ọmọ Israẹli sì ń le sí i, wọ́n sì ń pọ̀ sí i jọjọ.
Netijide, Xuda tughut anilirigha iltipat körsetti; Israil xelqi dawamliq köpiyip, téximu kücheydi.
21 Nítorí pé àwọn agbẹ̀bí bẹ̀rù Ọlọ́run, Ọlọ́run sì fún wọn ni ìdílé tiwọn.
Shundaq boldiki, tughut aniliri Xudadin qorqidighan ixlasmen bolghanliqi üchün Xuda ularni aililik bolushqa muyesser qildi.
22 Nígbà náà ni Farao pàṣẹ yìí fún gbogbo àwọn ènìyàn rẹ̀ pé, “Gbogbo ọmọkùnrin tí a bí ni kí ẹ gbé jù sínú odò Naili, ṣùgbọ́n gbogbo àwọn ọmọbìnrin ni kí ẹ jẹ́ kí wọn ó wà láààyè.”
Buning bilen Pirewn barliq puxralirigha: — Israillardin yéngi tughulghan oghul balilarning hemmisini deryagha tashlanglar, lékin qiz balilarning hemmisini tirik qaldurunglar, dep emr qildi.

< Exodus 1 >