< Exodus 1 >
1 Ìwọ̀nyí ni àwọn orúkọ ọmọ Israẹli tí wọ́n bá Jakọbu lọ sí Ejibiti, ẹnìkọ̀ọ̀kan pẹ̀lú ìdílé rẹ̀:
Ezek pedig az Izráel fiainak nevei, a kik Jákóbbal Égyiptomba menének; kiki az ő házanépével méne:
2 Reubeni, Simeoni, Lefi àti Juda;
Rúben, Simeon, Lévi és Júda;
3 Isakari, Sebuluni àti Benjamini;
Izsakhár, Zebulon és Benjámin;
4 Dani àti Naftali; Gadi àti Aṣeri.
Dán és Nafthali, Gád és Áser.
5 Àwọn ìran Jakọbu sì jẹ́ àádọ́rin ní àpapọ̀; Josẹfu sì ti wà ní Ejibiti.
Mindazok a lelkek pedig, a kik Jákób ágyékából származtak vala, hetvenen valának. József pedig Égyiptomban vala.
6 Wàyí o, Josẹfu àti gbogbo àwọn arákùnrin rẹ̀ àti gbogbo ìran náà kú,
És meghala József és minden ő atyjafia és az az egész nemzedék.
7 ṣùgbọ́n àwọn ará Israẹli ń bí sí i, wọ́n ń pọ̀ sí i gidigidi, wọ́n kò sì ní òǹkà tí ó fi jẹ́ pé wọ́n kún ilẹ̀ náà.
Izráel fiai pedig szaporák valának, szaporodának és sokasodának és igen-igen elhatalmazának, úgy hogy megtelék velök az ország.
8 Nígbà náà ni ọba tuntun mìíràn tí kò mọ Josẹfu jẹ ní ilẹ̀ Ejibiti.
Azonközben új király támada Égyiptomban, a ki Józsefet nem ismerte vala.
9 Ó sọ fún àwọn ènìyàn rẹ̀, “Ẹ wò ó, àwọn ará Israẹli ti pọ̀ ní iye àti agbára jù fún wa.
És monda az ő népének: Ímé az Izráel fiainak népe több, és hatalmasabb nálunknál.
10 Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a lo ọgbọ́n àlùmọ̀kọ́rọ́yí láti dá wọn lẹ́kun, bí kò ṣe bẹ́ẹ̀ wọn yóò túbọ̀ máa pọ̀ sí i. Bí ogun bá sì bẹ́ sílẹ̀, wọn yóò darapọ̀ mọ́ àwọn ọ̀tá wa, wọn yóò sì da ojú ìjà kọ wá, wọn yóò sì sá àsálà kúrò ní ilẹ̀ yìí.”
Nosza bánjunk okosan vele, hogy el ne sokasodjék és az ne legyen, hogy ha háború támad, ő is ellenségünkhöz adja magát és ellenünk harczoljon és az országból kimenjen.
11 Nítorí náà, wọ́n yan àwọn ọ̀gá akóniṣiṣẹ́ lé wọn lórí láti máa ni wọ́n lára pẹ̀lú iṣẹ́ àṣekára. Wọ́n sì kọ́ Pitomi àti Ramesesi gẹ́gẹ́ bí ìlú ìṣúra pamọ́ sí fún Farao.
Rendelének azért föléjök robotmestereket, hogy nehéz munkákkal sanyargassák őket. És építe a Faraónak gabonatartó városokat, Pithomot és Ramszeszt.
12 Ṣùgbọ́n bí a ti ń ni wọ́n lára tó, bẹ́ẹ̀ ni wọ́n ń pọ̀ sí i, tí wọ́n sì ń tànkálẹ̀. Nítorí náà, àwọn ará Ejibiti bẹ̀rù nítorí àwọn ará Israẹli.
De minél inkább sanyargatják vala őt, annál inkább sokasodik és annál inkább terjeszkedik vala, s félnek vala az Izráel fiaitól.
13 Àwọn ará Ejibiti sì mú àwọn ọmọ Israẹli sìn ní àsìnpa.
Pedig kegyetlenűl dolgoztaták az égyiptomiak az Izráel fiait.
14 Wọ́n mú wọn gbé ìgbé ayé kíkorò nípa iṣẹ́ bíríkì àti àwọn onírúurú iṣẹ́ oko; àwọn ará Ejibiti ń lò wọ́n ní ìlòkulò.
És kemény munkával keseríték életöket, sárcsinálással, téglavetéssel és mindenféle mezei munkával, minden munkájokkal, melyeket kegyetlenűl dolgoztatnak vala velök.
15 Ọba Ejibiti sọ fún àwọn agbẹ̀bí Heberu ti orúkọ wọn ń jẹ́ Ṣifura àti Pua pé,
És szóla Égyiptom királya a héber bábáknak, a kik közűl egyiknek Sifra, a másiknak Puá vala neve.
16 “Nígbà ti ẹ̀yin bá ń gbẹ̀bí àwọn obìnrin Heberu, tí ẹ sì kíyèsi wọn lórí ìkúnlẹ̀ ìrọbí wọn, bí ó bá jẹ́ ọkùnrin ni ọmọ náà, ẹ pa á; ṣùgbọ́n bí ó bá jẹ́ obìnrin, ẹ jẹ́ kí ó wà láààyè.”
És monda: Mikoron héber asszonyok körűl bábálkodtok, nézzetek a szűlőszékre: ha fiú az, azt öljétek meg, ha pedig leány az, hadd éljen.
17 Ṣùgbọ́n àwọn agbẹ̀bí bẹ̀rù Ọlọ́run, wọn kò sì ṣe gẹ́gẹ́ bí ọba Ejibiti ti wí fún wọn; wọ́n jẹ́ kí àwọn ọmọkùnrin wà láààyè.
De a bábák félék az Istent és nem cselekedének úgy a mint Égyiptom királya parancsolta vala nékik, hanem életben hagyják vala a gyermekeket.
18 Ọba Ejibiti pe àwọn agbẹ̀bí ó sì béèrè lọ́wọ́ wọn pé, “Èéṣe tí ẹ̀yin fi ṣe èyí? Èéṣe tí ẹ̀yin fi dá àwọn ọmọkùnrin si?”
Hívatá annakokáért Égyiptom királya a bábákat és monda nékik: Miért míveltétek azt, hogy életben hagytátok a gyermekeket?
19 Àwọn agbẹ̀bí náà sì dá Farao lóhùn pé, “Àwọn obìnrin Heberu kò rí bí àwọn obìnrin Ejibiti, wọ́n ní agbára, wọ́n sì ti máa ń bí ọmọ kí àwọn agbẹ̀bí tó dé ọ̀dọ̀ wọn.”
A bábák pedig mondának a Faraónak: Mert a héber asszonyok nem olyanok, mint az Égyiptombeliek: mert azok élet-erősek; minekelőtte a bába hozzájok eljutna, már szűlnek.
20 Nítorí náà Ọlọ́run ṣàánú fún àwọn agbẹ̀bí náà, àwọn ọmọ Israẹli sì ń le sí i, wọ́n sì ń pọ̀ sí i jọjọ.
Annakokáért jól tőn Isten a bábákkal, a nép pedig sokasodék és igen elhatalmazék.
21 Nítorí pé àwọn agbẹ̀bí bẹ̀rù Ọlọ́run, Ọlọ́run sì fún wọn ni ìdílé tiwọn.
És lőn, hogy mivel a bábák félék az Istent: megépíté az ő házukat.
22 Nígbà náà ni Farao pàṣẹ yìí fún gbogbo àwọn ènìyàn rẹ̀ pé, “Gbogbo ọmọkùnrin tí a bí ni kí ẹ gbé jù sínú odò Naili, ṣùgbọ́n gbogbo àwọn ọmọbìnrin ni kí ẹ jẹ́ kí wọn ó wà láààyè.”
Parancsola azért a Faraó minden ő népének, mondván: Minden fiút, a ki születik, vessetek a folyóvízbe, a leányt pedig hagyjátok mind életben.