< Exodus 1 >

1 Ìwọ̀nyí ni àwọn orúkọ ọmọ Israẹli tí wọ́n bá Jakọbu lọ sí Ejibiti, ẹnìkọ̀ọ̀kan pẹ̀lú ìdílé rẹ̀:
Voici les noms des fils d'Israël qui vinrent en Égypte (chaque homme et sa famille vinrent avec Jacob):
2 Reubeni, Simeoni, Lefi àti Juda;
Ruben, Siméon, Lévi et Juda,
3 Isakari, Sebuluni àti Benjamini;
Issacar, Zabulon et Benjamin,
4 Dani àti Naftali; Gadi àti Aṣeri.
Dan et Nephtali, Gad et Asher.
5 Àwọn ìran Jakọbu sì jẹ́ àádọ́rin ní àpapọ̀; Josẹfu sì ti wà ní Ejibiti.
Toutes les âmes qui sortirent du corps de Jacob étaient au nombre de soixante-dix, et Joseph était déjà en Égypte.
6 Wàyí o, Josẹfu àti gbogbo àwọn arákùnrin rẹ̀ àti gbogbo ìran náà kú,
Joseph mourut, ainsi que tous ses frères et toute cette génération.
7 ṣùgbọ́n àwọn ará Israẹli ń bí sí i, wọ́n ń pọ̀ sí i gidigidi, wọ́n kò sì ní òǹkà tí ó fi jẹ́ pé wọ́n kún ilẹ̀ náà.
Les enfants d'Israël furent féconds, ils augmentèrent en abondance, ils se multiplièrent, ils devinrent extrêmement puissants, et le pays fut rempli d'eux.
8 Nígbà náà ni ọba tuntun mìíràn tí kò mọ Josẹfu jẹ ní ilẹ̀ Ejibiti.
Or, il se leva un nouveau roi sur l'Égypte, qui ne connaissait pas Joseph.
9 Ó sọ fún àwọn ènìyàn rẹ̀, “Ẹ wò ó, àwọn ará Israẹli ti pọ̀ ní iye àti agbára jù fún wa.
Il dit à son peuple: « Voici que le peuple des enfants d'Israël est plus nombreux et plus puissant que nous.
10 Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a lo ọgbọ́n àlùmọ̀kọ́rọ́yí láti dá wọn lẹ́kun, bí kò ṣe bẹ́ẹ̀ wọn yóò túbọ̀ máa pọ̀ sí i. Bí ogun bá sì bẹ́ sílẹ̀, wọn yóò darapọ̀ mọ́ àwọn ọ̀tá wa, wọn yóò sì da ojú ìjà kọ wá, wọn yóò sì sá àsálà kúrò ní ilẹ̀ yìí.”
Venez, traitons-les avec sagesse, de peur qu'ils ne se multiplient et que, lorsqu'une guerre éclatera, ils ne se joignent à nos ennemis, ne nous combattent et ne s'échappent du pays. »
11 Nítorí náà, wọ́n yan àwọn ọ̀gá akóniṣiṣẹ́ lé wọn lórí láti máa ni wọ́n lára pẹ̀lú iṣẹ́ àṣekára. Wọ́n sì kọ́ Pitomi àti Ramesesi gẹ́gẹ́ bí ìlú ìṣúra pamọ́ sí fún Farao.
Ils établirent donc sur eux des maîtres de corvées pour les accabler de leurs fardeaux. Ils construisirent des villes de stockage pour Pharaon: Pithom et Raamsès.
12 Ṣùgbọ́n bí a ti ń ni wọ́n lára tó, bẹ́ẹ̀ ni wọ́n ń pọ̀ sí i, tí wọ́n sì ń tànkálẹ̀. Nítorí náà, àwọn ará Ejibiti bẹ̀rù nítorí àwọn ará Israẹli.
Mais plus ils les accablaient, plus ils se multipliaient et plus ils s'étendaient. Ils se mirent à redouter les enfants d'Israël.
13 Àwọn ará Ejibiti sì mú àwọn ọmọ Israẹli sìn ní àsìnpa.
Les Égyptiens firent servir les enfants d'Israël sans pitié,
14 Wọ́n mú wọn gbé ìgbé ayé kíkorò nípa iṣẹ́ bíríkì àti àwọn onírúurú iṣẹ́ oko; àwọn ará Ejibiti ń lò wọ́n ní ìlòkulò.
et ils leur rendirent la vie amère par un dur service dans le mortier et dans la brique, et par toutes sortes de services dans les champs, tous leurs services, dans lesquels ils les firent servir sans pitié.
15 Ọba Ejibiti sọ fún àwọn agbẹ̀bí Heberu ti orúkọ wọn ń jẹ́ Ṣifura àti Pua pé,
Le roi d'Égypte parla aux sages-femmes hébraïques, dont l'une s'appelait Shiphrah et l'autre Puah,
16 “Nígbà ti ẹ̀yin bá ń gbẹ̀bí àwọn obìnrin Heberu, tí ẹ sì kíyèsi wọn lórí ìkúnlẹ̀ ìrọbí wọn, bí ó bá jẹ́ ọkùnrin ni ọmọ náà, ẹ pa á; ṣùgbọ́n bí ó bá jẹ́ obìnrin, ẹ jẹ́ kí ó wà láààyè.”
et il dit: « Lorsque vous exercerez la fonction de sage-femme auprès des femmes hébraïques et que vous les verrez sur l'escabeau, si c'est un fils, vous le tuerez; mais si c'est une fille, elle vivra. »
17 Ṣùgbọ́n àwọn agbẹ̀bí bẹ̀rù Ọlọ́run, wọn kò sì ṣe gẹ́gẹ́ bí ọba Ejibiti ti wí fún wọn; wọ́n jẹ́ kí àwọn ọmọkùnrin wà láààyè.
Mais les sages-femmes craignirent Dieu et ne firent pas ce que le roi d'Égypte leur avait ordonné, mais elles sauvèrent les petits garçons vivants.
18 Ọba Ejibiti pe àwọn agbẹ̀bí ó sì béèrè lọ́wọ́ wọn pé, “Èéṣe tí ẹ̀yin fi ṣe èyí? Èéṣe tí ẹ̀yin fi dá àwọn ọmọkùnrin si?”
Le roi d'Égypte fit venir les sages-femmes et leur dit: « Pourquoi avez-vous fait cela et sauvé les garçons en vie? ».
19 Àwọn agbẹ̀bí náà sì dá Farao lóhùn pé, “Àwọn obìnrin Heberu kò rí bí àwọn obìnrin Ejibiti, wọ́n ní agbára, wọ́n sì ti máa ń bí ọmọ kí àwọn agbẹ̀bí tó dé ọ̀dọ̀ wọn.”
Les sages-femmes dirent à Pharaon: « Parce que les femmes hébreues ne sont pas comme les Egyptiennes, car elles sont vigoureuses et accouchent avant que la sage-femme ne vienne les voir. »
20 Nítorí náà Ọlọ́run ṣàánú fún àwọn agbẹ̀bí náà, àwọn ọmọ Israẹli sì ń le sí i, wọ́n sì ń pọ̀ sí i jọjọ.
Dieu traita bien les sages-femmes, et le peuple se multiplia et devint très puissant.
21 Nítorí pé àwọn agbẹ̀bí bẹ̀rù Ọlọ́run, Ọlọ́run sì fún wọn ni ìdílé tiwọn.
Comme les sages-femmes craignaient Dieu, il leur donna des familles.
22 Nígbà náà ni Farao pàṣẹ yìí fún gbogbo àwọn ènìyàn rẹ̀ pé, “Gbogbo ọmọkùnrin tí a bí ni kí ẹ gbé jù sínú odò Naili, ṣùgbọ́n gbogbo àwọn ọmọbìnrin ni kí ẹ jẹ́ kí wọn ó wà láààyè.”
Pharaon donna cet ordre à tout son peuple: « Vous jetterez dans le fleuve tout fils qui naîtra, et vous sauverez vivante toute fille. »

< Exodus 1 >