< Exodus 1 >
1 Ìwọ̀nyí ni àwọn orúkọ ọmọ Israẹli tí wọ́n bá Jakọbu lọ sí Ejibiti, ẹnìkọ̀ọ̀kan pẹ̀lú ìdílé rẹ̀:
The sons of Jacob who went to Egypt with him along with their families were
2 Reubeni, Simeoni, Lefi àti Juda;
Reuben, Simeon, Levi, Judah,
3 Isakari, Sebuluni àti Benjamini;
Issachar, Zebulun, Benjamin,
4 Dani àti Naftali; Gadi àti Aṣeri.
Dan, Naphtali, Gad, and Asher.
5 Àwọn ìran Jakọbu sì jẹ́ àádọ́rin ní àpapọ̀; Josẹfu sì ti wà ní Ejibiti.
Altogether there were 70 people [who went with] Jacob. That included his [sons, his grandsons, and two great-grandsons]. [His son] Joseph was already in Egypt.
6 Wàyí o, Josẹfu àti gbogbo àwọn arákùnrin rẹ̀ àti gbogbo ìran náà kú,
[Eventually] Joseph and his [older and younger] brothers and everyone [else in their family who lived] (in that generation/at that time) died.
7 ṣùgbọ́n àwọn ará Israẹli ń bí sí i, wọ́n ń pọ̀ sí i gidigidi, wọ́n kò sì ní òǹkà tí ó fi jẹ́ pé wọ́n kún ilẹ̀ náà.
But Jacob’s descendants kept giving birth to many children [IDM]. The number [of his descendants] kept becoming larger and larger. As a result, there were so many of them that they were everywhere in Egypt (OR, that they [became a threat] to the Egyptians).
8 Nígbà náà ni ọba tuntun mìíràn tí kò mọ Josẹfu jẹ ní ilẹ̀ Ejibiti.
Then [several hundred years later], a new king began to rule [MTY] in Egypt. He did not know [what] Joseph [had done for the people of Egypt long ago].
9 Ó sọ fún àwọn ènìyàn rẹ̀, “Ẹ wò ó, àwọn ará Israẹli ti pọ̀ ní iye àti agbára jù fún wa.
He said to his people, “Look [at what has happened]! The Israeli people have become so numerous and so powerful that they [now might conquer] us!
10 Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a lo ọgbọ́n àlùmọ̀kọ́rọ́yí láti dá wọn lẹ́kun, bí kò ṣe bẹ́ẹ̀ wọn yóò túbọ̀ máa pọ̀ sí i. Bí ogun bá sì bẹ́ sílẹ̀, wọn yóò darapọ̀ mọ́ àwọn ọ̀tá wa, wọn yóò sì da ojú ìjà kọ wá, wọn yóò sì sá àsálà kúrò ní ilẹ̀ yìí.”
We must find a way to control them! If we do not do that, their population will continue to grow. Then, if enemies [PRS] attack us, they will join with our enemies and fight against us, and they will escape from [our] land.”
11 Nítorí náà, wọ́n yan àwọn ọ̀gá akóniṣiṣẹ́ lé wọn lórí láti máa ni wọ́n lára pẹ̀lú iṣẹ́ àṣekára. Wọ́n sì kọ́ Pitomi àti Ramesesi gẹ́gẹ́ bí ìlú ìṣúra pamọ́ sí fún Farao.
So [the king and his officials] put supervisors over the Israeli people to cause them to suffer very much by [forcing them] to work very hard. They forced [the Israeli people to] build [two] cities, Pithom and Ramses, in which to store [supplies for the king/government].
12 Ṣùgbọ́n bí a ti ń ni wọ́n lára tó, bẹ́ẹ̀ ni wọ́n ń pọ̀ sí i, tí wọ́n sì ń tànkálẹ̀. Nítorí náà, àwọn ará Ejibiti bẹ̀rù nítorí àwọn ará Israẹli.
But the more cruelly they treated the [Israeli people], the bigger the Israeli [population] grew, and they became more numerous all over [the land]. So the Egyptian people began to be afraid of the Israeli people.
13 Àwọn ará Ejibiti sì mú àwọn ọmọ Israẹli sìn ní àsìnpa.
They forced the Israeli people to work very hard,
14 Wọ́n mú wọn gbé ìgbé ayé kíkorò nípa iṣẹ́ bíríkì àti àwọn onírúurú iṣẹ́ oko; àwọn ará Ejibiti ń lò wọ́n ní ìlòkulò.
and by making them slaves, they made their lives miserable. They [forced them] to [build many buildings with] mortar and bricks. [They also forced them to do] other work in the fields. [In making them do all this work, the Egyptian officials treated them] ruthlessly/cruelly.
15 Ọba Ejibiti sọ fún àwọn agbẹ̀bí Heberu ti orúkọ wọn ń jẹ́ Ṣifura àti Pua pé,
There were two Hebrew (midwives/women who helped the women when they were giving birth). [Hebrew means the same as Israeli.] The names of the women were Shiphrah and Puah. The king of Egypt said to [those two women],
16 “Nígbà ti ẹ̀yin bá ń gbẹ̀bí àwọn obìnrin Heberu, tí ẹ sì kíyèsi wọn lórí ìkúnlẹ̀ ìrọbí wọn, bí ó bá jẹ́ ọkùnrin ni ọmọ náà, ẹ pa á; ṣùgbọ́n bí ó bá jẹ́ obìnrin, ẹ jẹ́ kí ó wà láààyè.”
“When you help the Hebrew women when they are giving birth [MTY], if [the baby that is born] is a boy, you must kill it. If [the baby] is a girl, you (may let it live/do not have to kill them).”
17 Ṣùgbọ́n àwọn agbẹ̀bí bẹ̀rù Ọlọ́run, wọn kò sì ṣe gẹ́gẹ́ bí ọba Ejibiti ti wí fún wọn; wọ́n jẹ́ kí àwọn ọmọkùnrin wà láààyè.
But the midwives feared/revered God. So they did not do what the king told them to do. They allowed the baby boys to live.
18 Ọba Ejibiti pe àwọn agbẹ̀bí ó sì béèrè lọ́wọ́ wọn pé, “Èéṣe tí ẹ̀yin fi ṣe èyí? Èéṣe tí ẹ̀yin fi dá àwọn ọmọkùnrin si?”
So the king summoned the [two] midwives and said to them, “Why are you doing this? Why are you letting the baby boys live?”
19 Àwọn agbẹ̀bí náà sì dá Farao lóhùn pé, “Àwọn obìnrin Heberu kò rí bí àwọn obìnrin Ejibiti, wọ́n ní agbára, wọ́n sì ti máa ń bí ọmọ kí àwọn agbẹ̀bí tó dé ọ̀dọ̀ wọn.”
[One of] the midwives replied to the king, “[You need to realize that] the Hebrew women are not like the Egyptian women. The Hebrew women are very strong/healthy. They give birth [to their babies] before we can get to them [to help them].”
20 Nítorí náà Ọlọ́run ṣàánú fún àwọn agbẹ̀bí náà, àwọn ọmọ Israẹli sì ń le sí i, wọ́n sì ń pọ̀ sí i jọjọ.
So God acted kindly toward the midwives, and the [Hebrew] people became even more numerous and strong.
21 Nítorí pé àwọn agbẹ̀bí bẹ̀rù Ọlọ́run, Ọlọ́run sì fún wọn ni ìdílé tiwọn.
Furthermore, because the midwives feared/revered God, he enabled them also to give birth to children.
22 Nígbà náà ni Farao pàṣẹ yìí fún gbogbo àwọn ènìyàn rẹ̀ pé, “Gbogbo ọmọkùnrin tí a bí ni kí ẹ gbé jù sínú odò Naili, ṣùgbọ́n gbogbo àwọn ọmọbìnrin ni kí ẹ jẹ́ kí wọn ó wà láààyè.”
Then the king commanded all (the [Egyptian] people/his [advisors]): “You must throw into the Nile [River] every baby boy born that the [Hebrew women] give birth to! But you can allow the baby girls to live.”