< Exodus 9 >

1 Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Mose pé, “Lọ sọ fún Farao, ‘Èyí ni Olúwa Ọlọ́run àwọn Heberu sọ, “Jẹ́ kí àwọn ènìyàn Mi kí ó lọ, kí wọn bá à lè sìn Mí.”
Atunci DOMNUL i-a spus lui Moise: Intră la Faraon și spune-i: Astfel vorbește DOMNUL Dumnezeul evreilor: Lasă poporul meu să plece ca să îmi servească.
2 Bí ìwọ bá kọ̀ láti jẹ́ kí wọn ó lọ, tí ó sì dá wọn dúró.
Căci dacă refuzi să îi lași să plece și îi vei ține pe loc,
3 Ọwọ́ Olúwa yóò mú ààrùn búburú wá sí ara ẹran ọ̀sìn nínú oko, sí ara ẹṣin, kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, ìbákasẹ, màlúù, àgùntàn àti ewúrẹ́ yín.
Iată, mâna DOMNULUI este asupra vitelor tale din câmp, asupra cailor, asupra măgarilor, asupra cămilelor, asupra boilor și asupra oilor tale: va fi o ciumă foarte apăsătoare.
4 Ṣùgbọ́n Olúwa yóò pààlà sí àárín ẹran ọ̀sìn tí ó jẹ́ ti Israẹli àti ti àwọn ara Ejibiti tí yóò fi jẹ́ pé kò sí ẹran ọ̀sìn ti ó jẹ́ ti ará Israẹli tí yóò kùú.’”
Și DOMNUL va face deosebire între vitele lui Israel și vitele Egiptului, și nu va muri nimic din tot ce este al copiilor lui Israel.
5 Olúwa sì dá àkókò kan wí pé, “Ní ọ̀la ni Olúwa yóò ṣe èyí ni ilẹ̀ yìí.”
Și DOMNUL a rânduit un timp cuvenit, spunând: Mâine DOMNUL va face acest lucru în țară.
6 Olúwa sí ṣe é ni ọjọ́ kejì. Gbogbo ẹran ọ̀sìn ará Ejibiti kú, ṣùgbọ́n ẹyọ kan kò kú lára ẹran ọ̀sìn àwọn Israẹli.
Și DOMNUL a făcut acel lucru a doua zi și toate vitele Egiptului au murit, dar din vitele copiilor lui Israel nu a murit niciuna.
7 Farao rán àwọn ènìyàn rẹ̀ láti lọ ṣe ìwádìí, wọ́n sì rí pé ẹyọ kan kò kú lára àwọn ẹran ọ̀sìn ará Israẹli. Síbẹ̀ náà, Farao kò yí ọkàn rẹ̀ padà àti pé kò jẹ́ kí àwọn ènìyàn ó lọ.
Și Faraon a trimis și, iată, nu a murit niciuna dintre vitele israeliților. Și inima lui Faraon s-a împietrit și nu a lăsat poporul să plece.
8 Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Mose àti Aaroni, “Ẹ bu ẹ̀kúnwọ́ eérú gbígbóná láti inú ààrò, kí Mose kù ú sí inú afẹ́fẹ́ ni iwájú Farao.
Și DOMNUL le-a spus lui Moise și lui Aaron: Luați-vă mâinile pline cu cenușă din cuptor și Moise să o arunce spre cer înaintea ochilor lui Faraon.
9 Yóò sì di eruku lẹ́búlẹ́bú ni gbogbo ilẹ̀ Ejibiti, yóò sì di oówo ti ń tú pẹ̀lú ìléròrò sí ara àwọn ènìyàn àti ẹran jákèjádò gbogbo ilẹ̀ Ejibiti.”
Și va deveni țărână în toată țara Egiptului și va fi ulcer, răspândindu-se cu bășici pe om și pe vită, prin toată țara Egiptului.
10 Nígbà náà ni wọ́n bú eérú gbígbóná láti inú ààrò, wọ́n dúró ní iwájú Farao. Mose sì ku eérú náà sínú afẹ́fẹ́, ó sì di oówo tí ń tú pẹ̀lú ìléròrò ni ara àwọn ènìyàn àti lára ẹran.
Și au luat cenușă din cuptor și au stat în picioare înaintea lui Faraon; și Moise a aruncat cenușa în sus spre cer; și aceasta a devenit un ulcer, răspândindu-se cu bășici pe om și pe vită.
11 Àwọn onídán kò le è dúró níwájú Mose nítorí oówo ti ó wà lára wọn àti ni ara gbogbo àwọn ara Ejibiti.
Și magicienii nu au putut sta în picioare înaintea lui Moise din cauza ulcerelor, pentru că ulcerul era peste magicieni și peste toți egiptenii.
12 Ṣùgbọ́n Ọlọ́run sé ọkàn Farao le, kò sì gbọ́ ti Mose àti Aaroni, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti sọ fún Mose.
Și DOMNUL a împietrit inima lui Faraon și nu le-a dat ascultare; precum DOMNUL spusese lui Moise.
13 Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Mose pé, “Dìde ni òwúrọ̀ kùtùkùtù, kí o sì tọ Farao lọ, kí o sì wí fún un pé, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run àwọn Heberu wí, Jẹ́ kí àwọn ènìyàn mi kí ó lọ, kí wọn bá à lè sìn mí,
Și DOMNUL i-a spus lui Moise: Scoală-te devreme dimineața și stai în picioare înaintea lui Faraon și spune-i: Astfel vorbește DOMNUL Dumnezeul evreilor: Lasă poporul meu să plece, ca să îmi servească.
14 nítorí nígbà yìí ni èmi yóò rán àjàkálẹ̀-ààrùn ti ó ní agbára gidigidi sí ọ, sí àwọn ìjòyè rẹ àti sí àwọn ènìyàn rẹ, kí ìwọ kí ó lè mọ̀ pé, kò sí ẹni bí èmi ni gbogbo ayé.
Căci de această dată voi trimite toate plăgile mele asupra inimii tale și asupra servitorilor tăi și asupra poporului tău, ca să cunoști că nu este nimeni asemenea mie pe tot pământul.
15 Ó ti yẹ kí n ti na ọwọ́ mi jáde láti kọlù ọ́ àti àwọn ènìyàn rẹ pẹ̀lú ààrùn búburú ti kò bá ti run yín kúrò ni orí ilẹ̀.
Căci acum îmi voi întinde mâna, ca să te lovesc pe tine și poporul tău cu ciumă; și vei fi stârpit de pe pământ.
16 Ṣùgbọ́n nítorí èyí ni èmi ṣe mú ọ dúró, kí èmi kí ó le fi agbára mi hàn lára rẹ, àti kí a bá à le máa ròyìn orúkọ mi ká gbogbo ayé.
Și tocmai pentru această cauză te-am ridicat, ca să îmi arăt în tine puterea, și ca numele meu să fie vestit peste tot pământul.
17 Síbẹ̀ ìwọ tún gbógun ti àwọn ènìyàn mi, ìwọ kò sì jẹ́ kí wọn lọ.
Te mai înalți tu însuți împotriva poporului meu, ca să refuzi să îi lași să plece?
18 Nítorí náà, ni ìwòyí ọ̀la, Èmi yóò rán òjò o yìnyín tí irú rẹ̀ kò tí i rọ̀ rí ni Ejibiti láti ìpilẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ títí di àkókò yìí.
Iată, mâine, pe timpul acesta, voi face să plouă o grindină foarte apăsătoare, așa cum nu a fost în Egipt de la întemeierea lui chiar până acum.
19 Pàṣẹ nísinsin yìí láti kó ẹran ọ̀sìn yín àti ohun gbogbo ti ẹ ni ní pápá wá sí abẹ́ ààbò, nítorí òjò yìnyín yóò rọ̀ sí orí àwọn ènìyàn àti ẹran ti a kò kó wá sí abẹ́ ààbò tí wọ́n sì wà ni orí pápá, wọn yóò sì kú.’”
De aceea trimite acum și adună vitele tale și tot ceea ce ai în câmp; căci fiecare om și animal care va fi găsit în câmp și nu va fi adus acasă, grindina va cădea peste ei și vor muri.
20 Àwọn ti ó bẹ̀rù ọ̀rọ̀ Olúwa lára àwọn ìjòyè Farao yára lọ láti kó àwọn ẹrú àti àwọn ẹran ọ̀sìn wọn wá sí abẹ́ ààbò.
Cel ce s-a temut de cuvântul DOMNULUI printre servitorii lui Faraon a pus pe servitorii săi și vitele sale să fugă în case;
21 Ṣùgbọ́n àwọn ti kò kà ọ̀rọ̀ Olúwa sí fi àwọn ẹrú wọn àti àwọn ẹran ọ̀sìn wọn sílẹ̀ ni pápá.
Și cel ce nu a luat în considerare cuvântul DOMNULUI a lăsat pe servitorii săi și vitele sale în câmp.
22 Olúwa sọ fún Mose pé, “Gbé ọwọ́ rẹ sókè sí ọ̀run kí yìnyín bá à lè rọ̀ sí orí gbogbo ilẹ̀ Ejibiti, sí orí ènìyàn àti ẹranko, àti sí orí gbogbo ohun ọ̀gbìn tí ó wà ni inú oko.”
Și DOMNUL i-a spus lui Moise: Întinde-ți mâna spre cer, ca să fie grindină în toată țara Egiptului, peste om și peste animal și peste fiecare iarbă din câmp, prin toată țara Egiptului.
23 Nígbà tí Mose gbé ọ̀pá rẹ̀ sókè sí ojú ọ̀run, Olúwa rán àrá àti yìnyín, mọ̀nàmọ́ná sì bùsi orí ilẹ̀. Olúwa rọ òjò yìnyín sí orí ilẹ̀ Ejibiti.
Și Moise și-a întins toiagul spre cer și DOMNUL a trimis tunet și grindină și focul a alergat de-a lungul pământului; și DOMNUL a plouat grindină peste țara Egiptului.
24 Yìnyín rọ̀, mọ̀nàmọ́ná sì bẹ̀rẹ̀ sí bùsi orí ilẹ̀ èyí ni ó tí ì burú jù ti ó ṣẹlẹ̀ láti ìgbà ti Ejibiti ti di orílẹ̀-èdè.
Astfel a fost grindină și foc amestecat cu grindină, foarte apăsătoare, cum nu a mai fost asemenea în toată țara Egiptului de când a devenit o națiune.
25 Jákèjádò gbogbo ilẹ̀ Ejibiti ni yìnyín ti pa gbogbo ohun tí ó wà ni orí pápá; ènìyàn àti ẹranko, ó wò gbogbo ohun ọ̀gbìn lulẹ̀ ó sì fa gbogbo igi ya pẹ̀lú.
Și grindina a lovit în toată țara Egiptului tot ce era în câmp, deopotrivă om și animal; și grindina a lovit fiecare iarbă din câmp și a frânt fiecare copac din câmp.
26 Ilẹ̀ Goṣeni ni ibi ti àwọn Israẹli wà nìkan ni òjò yìnyín náà kò rọ̀ dé.
Numai în ținutul Gosen, unde erau copiii lui Israel, nu a fost grindină.
27 Nígbà náà ni Farao pe Mose àti Aaroni sì ọ̀dọ́ rẹ̀, ó sì wí fún wọn pé, “Èmi ti ṣẹ̀ ní àkókò yìí; Olúwa jẹ́ olódodo ṣùgbọ́n èmi àti àwọn ènìyàn mi ni aláìṣòdodo.
Și Faraon a trimis și a chemat pe Moise și Aaron și le-a spus: Eu am păcătuit de această dată; DOMNUL este drept și eu și poporul meu suntem stricați.
28 Èyí ti òjò yìnyín àti àrá rọ̀ yìí tó gẹ́ẹ́, gbàdúrà sí Olúwa kí ó dáwọ́ rẹ̀ dúró. Èmi yóò jẹ́ kí ẹ lọ, n kò tún ni dá a yín dúró mọ́.”
Rugați pe DOMNUL (pentru că este destul) ca să nu mai fie tunete puternice și grindină; și vă voi lăsa să plecați și nu veți mai sta.
29 Mose dá a lóhùn pé, “Bí mo bá ti jáde kúrò ní àárín ìlú, èmi yóò gbé ọwọ́ mi sókè sí Olúwa, sísán àrá yóò dáwọ́ dúró, yìnyín kò sì ni rọ̀ mọ́, kí ìwọ kí ó lè mọ̀ pé Olúwa ni ó ni ilẹ̀.
Și Moise i-a spus: Imediat ce voi fi ieșit din cetate, îmi voi întinde mâinile spre DOMNUL; și tunetul va înceta, nici nu va mai fi grindină; ca să știi că pământul este al DOMNULUI.
30 Ṣùgbọ́n èmi mọ̀ pé síbẹ̀síbẹ̀ ìwọ àti àwọn ìjòyè rẹ kò bẹ̀rù Olúwa Ọlọ́run.”
Dar cât despre tine și servitorii tăi, știu că nu vă veți teme de DOMNUL Dumnezeu.
31 (A sì lu ọ̀gbọ̀ àti ọkà barle bolẹ̀; nítorí barle wà ní ìpẹ́, ọ̀gbọ̀ sì rudi.
Și inul și orzul au fost lovite, pentru că orzul era în spic și inul era înflorit.
32 Alikama àti ọkà ni a kò lù bolẹ̀, nítorí tí wọ́n kò tí ì dàgbà.)
Dar grâul și alacul nu s-au stricat, fiindcă nu erau coapte.
33 Nígbà náà ni Mose jáde kúrò ni iwájú Farao, ó kúrò ni àárín ìgboro kọjá lọ sí ẹ̀yìn odi ìlú, ó sì gbé ọwọ́ rẹ̀ sókè sí Olúwa, sísán àrá àti òjò yìnyín ti ń rọ̀ sì dáwọ́ dúró, òjò kò sì rọ̀ sí orí ilẹ̀ mọ́.
Și Moise a ieșit din cetate de la Faraon și și-a întins mâinile spre DOMNUL; și tunetele și grindina au încetat și ploaia nu a mai fost turnată pe pământ.
34 Nígbà tí Farao rí i pé òjò àti yìnyín àti àrá ti ń sán ti dáwọ́ dúró, ó tún ṣẹ̀ ní ẹ̀ẹ̀kan sí i. Òun àti àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ ṣì sé àyà wọn le.
Și când Faraon a văzut că ploaia și grindina și tunetele au încetat, a păcătuit și mai mult și și-a împietrit inima, el și servitorii săi.
35 Àyà Farao sì le, bẹ́ẹ̀ ni kò sì jẹ́ kí àwọn ọmọ Israẹli kí ó lọ, bí Olúwa ti sọ láti ẹnu Mose.
Și inima lui Faraon s-a împietrit și nu a lăsat pe copiii lui Israel să plece; precum DOMNUL vorbise prin Moise.

< Exodus 9 >