< Exodus 9 >

1 Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Mose pé, “Lọ sọ fún Farao, ‘Èyí ni Olúwa Ọlọ́run àwọn Heberu sọ, “Jẹ́ kí àwọn ènìyàn Mi kí ó lọ, kí wọn bá à lè sìn Mí.”
És monda az Úr Mózesnek: Menj a Faraóhoz és beszélj vele: Ezt mondja az Úr, a héberek Istene: Bocsásd el az én népemet, hogy szolgáljanak nékem:
2 Bí ìwọ bá kọ̀ láti jẹ́ kí wọn ó lọ, tí ó sì dá wọn dúró.
Mert ha nem akarod elbocsátani és tovább is tartóztatod őket:
3 Ọwọ́ Olúwa yóò mú ààrùn búburú wá sí ara ẹran ọ̀sìn nínú oko, sí ara ẹṣin, kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, ìbákasẹ, màlúù, àgùntàn àti ewúrẹ́ yín.
Ímé az Úr keze lészen a te mezei barmaidon, lovakon, szamarakon, tevéken, ökrökön és juhokon; igen nagy döghalál.
4 Ṣùgbọ́n Olúwa yóò pààlà sí àárín ẹran ọ̀sìn tí ó jẹ́ ti Israẹli àti ti àwọn ara Ejibiti tí yóò fi jẹ́ pé kò sí ẹran ọ̀sìn ti ó jẹ́ ti ará Israẹli tí yóò kùú.’”
De különbséget tesz az Úr az Izráel barmai között és Égyiptom barmai között, és mindabból, a mi Izráel fiaié, egy sem vész el.
5 Olúwa sì dá àkókò kan wí pé, “Ní ọ̀la ni Olúwa yóò ṣe èyí ni ilẹ̀ yìí.”
Időt is hagya az Úr, mondván: Holnap cselekszi az Úr ezt a dolgot a földön.
6 Olúwa sí ṣe é ni ọjọ́ kejì. Gbogbo ẹran ọ̀sìn ará Ejibiti kú, ṣùgbọ́n ẹyọ kan kò kú lára ẹran ọ̀sìn àwọn Israẹli.
Meg is cselekedé az Úr ezt a dolgot másodnapon, és elhulla Égyiptomnak minden barma, de az Izráel fiainak barma közül egy sem hullott el.
7 Farao rán àwọn ènìyàn rẹ̀ láti lọ ṣe ìwádìí, wọ́n sì rí pé ẹyọ kan kò kú lára àwọn ẹran ọ̀sìn ará Israẹli. Síbẹ̀ náà, Farao kò yí ọkàn rẹ̀ padà àti pé kò jẹ́ kí àwọn ènìyàn ó lọ.
El is külde a Faraó, és ímé egy sem hullt vala el az Izráeliták barma közül: de a Faraó szíve kemény maradt, és nem bocsátá el a népet.
8 Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Mose àti Aaroni, “Ẹ bu ẹ̀kúnwọ́ eérú gbígbóná láti inú ààrò, kí Mose kù ú sí inú afẹ́fẹ́ ni iwájú Farao.
Az Úr pedig monda Mózesnek és Áronnak: Vegyétek tele markaitokat kemenczehamuval, és szórja azt Mózes az ég felé a Faraó szeme láttára.
9 Yóò sì di eruku lẹ́búlẹ́bú ni gbogbo ilẹ̀ Ejibiti, yóò sì di oówo ti ń tú pẹ̀lú ìléròrò sí ara àwọn ènìyàn àti ẹran jákèjádò gbogbo ilẹ̀ Ejibiti.”
Hogy porrá legyen Égyiptomnak egész földén, s emberen és barmon hólyagosan fakadó fekéllyé legyen Égyiptomnak egész földén.
10 Nígbà náà ni wọ́n bú eérú gbígbóná láti inú ààrò, wọ́n dúró ní iwájú Farao. Mose sì ku eérú náà sínú afẹ́fẹ́, ó sì di oówo tí ń tú pẹ̀lú ìléròrò ni ara àwọn ènìyàn àti lára ẹran.
Vevének azért kemenczehamut és a Faraó elé állának, és Mózes az ég felé szórá azt; és lőn az emberen és barmon hólyagosan fakadó fekély.
11 Àwọn onídán kò le è dúró níwájú Mose nítorí oówo ti ó wà lára wọn àti ni ara gbogbo àwọn ara Ejibiti.
És az írástudók nem állhatnak vala Mózes előtt a fekély miatt; mert fekély vala az írástudókon s mind az Égyiptombelieken.
12 Ṣùgbọ́n Ọlọ́run sé ọkàn Farao le, kò sì gbọ́ ti Mose àti Aaroni, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti sọ fún Mose.
De az Úr megkeményíté a Faraó szívét, és nem hallgata reájok, a mint megmondotta vala az Úr Mózesnek.
13 Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Mose pé, “Dìde ni òwúrọ̀ kùtùkùtù, kí o sì tọ Farao lọ, kí o sì wí fún un pé, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run àwọn Heberu wí, Jẹ́ kí àwọn ènìyàn mi kí ó lọ, kí wọn bá à lè sìn mí,
És monda az Úr Mózesnek: Kelj fel reggel és állj a Faraó eleibe és mondd néki: Ezt mondja az Úr, a héberek Istene: Bocsásd el az én népemet, hogy szolgáljanak nékem.
14 nítorí nígbà yìí ni èmi yóò rán àjàkálẹ̀-ààrùn ti ó ní agbára gidigidi sí ọ, sí àwọn ìjòyè rẹ àti sí àwọn ènìyàn rẹ, kí ìwọ kí ó lè mọ̀ pé, kò sí ẹni bí èmi ni gbogbo ayé.
Mert ezúttal minden csapásomat reá bocsátom a te szívedre, a te szolgáidra és a te népedre azért, hogy megtudd, hogy nincs én hozzám hasonló az egész földön.
15 Ó ti yẹ kí n ti na ọwọ́ mi jáde láti kọlù ọ́ àti àwọn ènìyàn rẹ pẹ̀lú ààrùn búburú ti kò bá ti run yín kúrò ni orí ilẹ̀.
Mert ha most kinyujtanám kezemet és megvernélek téged és a te népedet döghalállal, akkor kivágattatnál a földről.
16 Ṣùgbọ́n nítorí èyí ni èmi ṣe mú ọ dúró, kí èmi kí ó le fi agbára mi hàn lára rẹ, àti kí a bá à le máa ròyìn orúkọ mi ká gbogbo ayé.
Ámde azért tartottalak fenn tégedet, hogy megmutassam néked az én hatalmamat, és hogy hirdessék az én nevemet az egész földön.
17 Síbẹ̀ ìwọ tún gbógun ti àwọn ènìyàn mi, ìwọ kò sì jẹ́ kí wọn lọ.
Ha tovább is feltartóztatod az én népemet és nem bocsátod el őket:
18 Nítorí náà, ni ìwòyí ọ̀la, Èmi yóò rán òjò o yìnyín tí irú rẹ̀ kò tí i rọ̀ rí ni Ejibiti láti ìpilẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ títí di àkókò yìí.
Ímé holnap ilyenkor igen nagy jégesőt bocsátok, a melyhez hasonló nem volt Égyiptomban az napságtól fogva hogy fundáltatott, mind ez ideig.
19 Pàṣẹ nísinsin yìí láti kó ẹran ọ̀sìn yín àti ohun gbogbo ti ẹ ni ní pápá wá sí abẹ́ ààbò, nítorí òjò yìnyín yóò rọ̀ sí orí àwọn ènìyàn àti ẹran ti a kò kó wá sí abẹ́ ààbò tí wọ́n sì wà ni orí pápá, wọn yóò sì kú.’”
Most annakokáért küldj el, hajtasd be barmaidat és mindenedet, valamid a mezőn van; minden ember és barom, a mely a mezőn találtatik és házba nem hajtatik, – jégeső szakad arra, és meghal.
20 Àwọn ti ó bẹ̀rù ọ̀rọ̀ Olúwa lára àwọn ìjòyè Farao yára lọ láti kó àwọn ẹrú àti àwọn ẹran ọ̀sìn wọn wá sí abẹ́ ààbò.
A ki a Faraó szolgái közűl az Úr beszédétől megfélemedék, szolgáit és barmait házakba futtatá.
21 Ṣùgbọ́n àwọn ti kò kà ọ̀rọ̀ Olúwa sí fi àwọn ẹrú wọn àti àwọn ẹran ọ̀sìn wọn sílẹ̀ ni pápá.
A ki pedig nem törődék az Úr beszédével, szolgáit és barmát a mezőn hagyá.
22 Olúwa sọ fún Mose pé, “Gbé ọwọ́ rẹ sókè sí ọ̀run kí yìnyín bá à lè rọ̀ sí orí gbogbo ilẹ̀ Ejibiti, sí orí ènìyàn àti ẹranko, àti sí orí gbogbo ohun ọ̀gbìn tí ó wà ni inú oko.”
Az Úr pedig monda Mózesnek: Nyújtsd ki kezedet az égre, hogy legyen jégeső Égyiptom egész földén az emberre, baromra és a mező minden fűvére, Égyiptom földén.
23 Nígbà tí Mose gbé ọ̀pá rẹ̀ sókè sí ojú ọ̀run, Olúwa rán àrá àti yìnyín, mọ̀nàmọ́ná sì bùsi orí ilẹ̀. Olúwa rọ òjò yìnyín sí orí ilẹ̀ Ejibiti.
Kinyujtá azért Mózes az ő vesszejét az égre, az Úr pedig mennydörgést támaszta és jégesőt, és tűz szálla le a földre, és jégesőt bocsáta az Úr Égyiptom földére.
24 Yìnyín rọ̀, mọ̀nàmọ́ná sì bẹ̀rẹ̀ sí bùsi orí ilẹ̀ èyí ni ó tí ì burú jù ti ó ṣẹlẹ̀ láti ìgbà ti Ejibiti ti di orílẹ̀-èdè.
És lőn jégeső, és a tűz egymást éré az igen nagy jégeső közt, a melyhez hasonló nem volt az egész Égyiptom földén, mióta nép lakja.
25 Jákèjádò gbogbo ilẹ̀ Ejibiti ni yìnyín ti pa gbogbo ohun tí ó wà ni orí pápá; ènìyàn àti ẹranko, ó wò gbogbo ohun ọ̀gbìn lulẹ̀ ó sì fa gbogbo igi ya pẹ̀lú.
És elveré a jégeső egész Égyiptom földén mindazt, a mi a mezőn vala, embertől baromig; a mező minden fűvét is elveré a jégeső és a mező minden fáját is egybe rontá.
26 Ilẹ̀ Goṣeni ni ibi ti àwọn Israẹli wà nìkan ni òjò yìnyín náà kò rọ̀ dé.
Csak a Gósen földén, hol Izráel fiai valának, nem volt jégeső.
27 Nígbà náà ni Farao pe Mose àti Aaroni sì ọ̀dọ́ rẹ̀, ó sì wí fún wọn pé, “Èmi ti ṣẹ̀ ní àkókò yìí; Olúwa jẹ́ olódodo ṣùgbọ́n èmi àti àwọn ènìyàn mi ni aláìṣòdodo.
A Faraó pedig elkülde és hívatá Mózest és Áront, és monda nékik: Vétkeztem ezúttal; az Úr az igaz; én pedig és az én népem gonoszok vagyunk.
28 Èyí ti òjò yìnyín àti àrá rọ̀ yìí tó gẹ́ẹ́, gbàdúrà sí Olúwa kí ó dáwọ́ rẹ̀ dúró. Èmi yóò jẹ́ kí ẹ lọ, n kò tún ni dá a yín dúró mọ́.”
Imádkozzatok az Úrhoz, hogy legyen elég a mennydörgés és jégeső, és akkor elbocsátlak titeket és nem maradtok tovább.
29 Mose dá a lóhùn pé, “Bí mo bá ti jáde kúrò ní àárín ìlú, èmi yóò gbé ọwọ́ mi sókè sí Olúwa, sísán àrá yóò dáwọ́ dúró, yìnyín kò sì ni rọ̀ mọ́, kí ìwọ kí ó lè mọ̀ pé Olúwa ni ó ni ilẹ̀.
Mózes pedig monda néki: Mihelyt kimegyek a városból, felemelem kezeimet az Úrhoz; megszűnnek a mennydörgések és nem lesz többé jégeső, hogy megtudd, hogy az Úré a föld.
30 Ṣùgbọ́n èmi mọ̀ pé síbẹ̀síbẹ̀ ìwọ àti àwọn ìjòyè rẹ kò bẹ̀rù Olúwa Ọlọ́run.”
De tudom, hogy te és a te szolgáid még nem féltek az Úr Istentől.
31 (A sì lu ọ̀gbọ̀ àti ọkà barle bolẹ̀; nítorí barle wà ní ìpẹ́, ọ̀gbọ̀ sì rudi.
A len pedig és az árpa elvereték, mert az árpa kalászos, a len pedig bimbós vala.
32 Alikama àti ọkà ni a kò lù bolẹ̀, nítorí tí wọ́n kò tí ì dàgbà.)
De a búza és a tönköly nem vereték el, mert azok késeiek.
33 Nígbà náà ni Mose jáde kúrò ni iwájú Farao, ó kúrò ni àárín ìgboro kọjá lọ sí ẹ̀yìn odi ìlú, ó sì gbé ọwọ́ rẹ̀ sókè sí Olúwa, sísán àrá àti òjò yìnyín ti ń rọ̀ sì dáwọ́ dúró, òjò kò sì rọ̀ sí orí ilẹ̀ mọ́.
És kiméne Mózes a Faraótól a városból és felemelé kezeit az Úrhoz, és megszűnének a mennydörgések s a jégeső és eső sem ömlik vala a földre.
34 Nígbà tí Farao rí i pé òjò àti yìnyín àti àrá ti ń sán ti dáwọ́ dúró, ó tún ṣẹ̀ ní ẹ̀ẹ̀kan sí i. Òun àti àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ ṣì sé àyà wọn le.
Amint látá a Faraó, hogy megszűnék az eső, meg a jégeső és a mennydörgés, ismét vétkezék és megkeményíté szívét ő és az ő szolgái.
35 Àyà Farao sì le, bẹ́ẹ̀ ni kò sì jẹ́ kí àwọn ọmọ Israẹli kí ó lọ, bí Olúwa ti sọ láti ẹnu Mose.
És kemény maradt a Faraó szíve, és nem bocsátá el az Izráel fiait, a mint megmondotta vala az Úr Mózes által.

< Exodus 9 >