< Exodus 9 >

1 Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Mose pé, “Lọ sọ fún Farao, ‘Èyí ni Olúwa Ọlọ́run àwọn Heberu sọ, “Jẹ́ kí àwọn ènìyàn Mi kí ó lọ, kí wọn bá à lè sìn Mí.”
Yahvé dit à Moïse: « Va trouver Pharaon et dis-lui: « Voici ce que dit Yahvé, le Dieu des Hébreux: « Laisse aller mon peuple, afin qu'il me serve.
2 Bí ìwọ bá kọ̀ láti jẹ́ kí wọn ó lọ, tí ó sì dá wọn dúró.
Car si tu refuses de les laisser aller et si tu les retiens,
3 Ọwọ́ Olúwa yóò mú ààrùn búburú wá sí ara ẹran ọ̀sìn nínú oko, sí ara ẹṣin, kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, ìbákasẹ, màlúù, àgùntàn àti ewúrẹ́ yín.
voici que la main de l'Éternel se porte sur ton bétail qui est dans les champs, sur les chevaux, sur les ânes, sur les chameaux, sur les troupeaux et sur les brebis, par une peste très redoutable.
4 Ṣùgbọ́n Olúwa yóò pààlà sí àárín ẹran ọ̀sìn tí ó jẹ́ ti Israẹli àti ti àwọn ara Ejibiti tí yóò fi jẹ́ pé kò sí ẹran ọ̀sìn ti ó jẹ́ ti ará Israẹli tí yóò kùú.’”
Yahvé fera la distinction entre le bétail d'Israël et le bétail d'Égypte, et rien ne mourra de tout ce qui appartient aux enfants d'Israël. »'"
5 Olúwa sì dá àkókò kan wí pé, “Ní ọ̀la ni Olúwa yóò ṣe èyí ni ilẹ̀ yìí.”
Yahvé fixa un temps déterminé, en disant: « Demain, Yahvé fera cette chose dans le pays. »
6 Olúwa sí ṣe é ni ọjọ́ kejì. Gbogbo ẹran ọ̀sìn ará Ejibiti kú, ṣùgbọ́n ẹyọ kan kò kú lára ẹran ọ̀sìn àwọn Israẹli.
Yahvé fit cette chose le lendemain; et tout le bétail de l'Égypte mourut, mais du bétail des enfants d'Israël, pas un seul ne mourut.
7 Farao rán àwọn ènìyàn rẹ̀ láti lọ ṣe ìwádìí, wọ́n sì rí pé ẹyọ kan kò kú lára àwọn ẹran ọ̀sìn ará Israẹli. Síbẹ̀ náà, Farao kò yí ọkàn rẹ̀ padà àti pé kò jẹ́ kí àwọn ènìyàn ó lọ.
Pharaon envoya chercher, et voici, il n'y avait pas un seul animal mort parmi les troupeaux des Israélites. Mais le cœur de Pharaon était obstiné, et il ne laissa pas partir le peuple.
8 Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Mose àti Aaroni, “Ẹ bu ẹ̀kúnwọ́ eérú gbígbóná láti inú ààrò, kí Mose kù ú sí inú afẹ́fẹ́ ni iwájú Farao.
Yahvé dit à Moïse et à Aaron: « Prenez des poignées de cendres de la fournaise, et que Moïse en fasse l'aspersion vers le ciel, sous les yeux de Pharaon.
9 Yóò sì di eruku lẹ́búlẹ́bú ni gbogbo ilẹ̀ Ejibiti, yóò sì di oówo ti ń tú pẹ̀lú ìléròrò sí ara àwọn ènìyàn àti ẹran jákèjádò gbogbo ilẹ̀ Ejibiti.”
Elle deviendra une petite poussière sur tout le pays d'Égypte, et il y aura des furoncles et des ampoules qui éclateront sur les hommes et sur les animaux, dans tout le pays d'Égypte. »
10 Nígbà náà ni wọ́n bú eérú gbígbóná láti inú ààrò, wọ́n dúró ní iwájú Farao. Mose sì ku eérú náà sínú afẹ́fẹ́, ó sì di oówo tí ń tú pẹ̀lú ìléròrò ni ara àwọn ènìyàn àti lára ẹran.
Ils prirent de la cendre de la fournaise et se tinrent devant Pharaon; Moïse la répandit vers le ciel, et elle devint des furoncles et des ampoules qui se déclarèrent sur les hommes et sur les animaux.
11 Àwọn onídán kò le è dúró níwájú Mose nítorí oówo ti ó wà lára wọn àti ni ara gbogbo àwọn ara Ejibiti.
Les magiciens ne purent se tenir devant Moïse à cause des furoncles, car les furoncles étaient sur les magiciens et sur tous les Égyptiens.
12 Ṣùgbọ́n Ọlọ́run sé ọkàn Farao le, kò sì gbọ́ ti Mose àti Aaroni, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti sọ fún Mose.
Yahvé endurcit le cœur de Pharaon, et il ne les écouta pas, comme Yahvé l'avait dit à Moïse.
13 Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Mose pé, “Dìde ni òwúrọ̀ kùtùkùtù, kí o sì tọ Farao lọ, kí o sì wí fún un pé, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run àwọn Heberu wí, Jẹ́ kí àwọn ènìyàn mi kí ó lọ, kí wọn bá à lè sìn mí,
Yahvé dit à Moïse: « Lève-toi de bon matin, présente-toi devant Pharaon et dis-lui: « Voici ce que dit Yahvé, le Dieu des Hébreux: « Laisse aller mon peuple, afin qu'il me serve.
14 nítorí nígbà yìí ni èmi yóò rán àjàkálẹ̀-ààrùn ti ó ní agbára gidigidi sí ọ, sí àwọn ìjòyè rẹ àti sí àwọn ènìyàn rẹ, kí ìwọ kí ó lè mọ̀ pé, kò sí ẹni bí èmi ni gbogbo ayé.
Car cette fois, je vais envoyer toutes mes plaies contre ton cœur, contre tes fonctionnaires et contre ton peuple, afin que tu saches qu'il n'y a personne comme moi sur toute la terre.
15 Ó ti yẹ kí n ti na ọwọ́ mi jáde láti kọlù ọ́ àti àwọn ènìyàn rẹ pẹ̀lú ààrùn búburú ti kò bá ti run yín kúrò ni orí ilẹ̀.
Car maintenant, j'aurais étendu ma main, je vous aurais frappés de peste, toi et ton peuple, et vous auriez été exterminés de la terre;
16 Ṣùgbọ́n nítorí èyí ni èmi ṣe mú ọ dúró, kí èmi kí ó le fi agbára mi hàn lára rẹ, àti kí a bá à le máa ròyìn orúkọ mi ká gbogbo ayé.
mais c'est pour cela que je t'ai fait subsister: pour te montrer ma puissance, et pour que mon nom soit proclamé par toute la terre,
17 Síbẹ̀ ìwọ tún gbógun ti àwọn ènìyàn mi, ìwọ kò sì jẹ́ kí wọn lọ.
parce que tu t'exaltes encore contre mon peuple, que tu ne veux pas le laisser aller.
18 Nítorí náà, ni ìwòyí ọ̀la, Èmi yóò rán òjò o yìnyín tí irú rẹ̀ kò tí i rọ̀ rí ni Ejibiti láti ìpilẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ títí di àkókò yìí.
Voici, demain, à cette heure-ci, je ferai pleuvoir une grêle très violente, telle qu'il n'y en a pas eu en Égypte depuis le jour de sa fondation jusqu'à présent.
19 Pàṣẹ nísinsin yìí láti kó ẹran ọ̀sìn yín àti ohun gbogbo ti ẹ ni ní pápá wá sí abẹ́ ààbò, nítorí òjò yìnyín yóò rọ̀ sí orí àwọn ènìyàn àti ẹran ti a kò kó wá sí abẹ́ ààbò tí wọ́n sì wà ni orí pápá, wọn yóò sì kú.’”
Ordonnez maintenant que tout votre bétail et tout ce que vous avez dans les champs soient mis à l'abri. La grêle tombera sur tous les hommes et sur tous les animaux qui se trouveront dans les champs et qui ne seront pas ramenés à l'abri, et ils mourront. »'"
20 Àwọn ti ó bẹ̀rù ọ̀rọ̀ Olúwa lára àwọn ìjòyè Farao yára lọ láti kó àwọn ẹrú àti àwọn ẹran ọ̀sìn wọn wá sí abẹ́ ààbò.
Ceux qui respectaient la parole de Yahvé parmi les serviteurs de Pharaon faisaient fuir leurs serviteurs et leurs bêtes dans les maisons.
21 Ṣùgbọ́n àwọn ti kò kà ọ̀rọ̀ Olúwa sí fi àwọn ẹrú wọn àti àwọn ẹran ọ̀sìn wọn sílẹ̀ ni pápá.
Ceux qui ne respectaient pas la parole de Yahvé laissaient leurs serviteurs et leurs bêtes dans les champs.
22 Olúwa sọ fún Mose pé, “Gbé ọwọ́ rẹ sókè sí ọ̀run kí yìnyín bá à lè rọ̀ sí orí gbogbo ilẹ̀ Ejibiti, sí orí ènìyàn àti ẹranko, àti sí orí gbogbo ohun ọ̀gbìn tí ó wà ni inú oko.”
Yahvé dit à Moïse: « Étends ta main vers le ciel, afin qu'il y ait de la grêle dans tout le pays d'Égypte, sur les hommes, sur les animaux et sur toutes les herbes des champs, dans tout le pays d'Égypte. »
23 Nígbà tí Mose gbé ọ̀pá rẹ̀ sókè sí ojú ọ̀run, Olúwa rán àrá àti yìnyín, mọ̀nàmọ́ná sì bùsi orí ilẹ̀. Olúwa rọ òjò yìnyín sí orí ilẹ̀ Ejibiti.
Moïse étendit sa verge vers les cieux, et Yahvé envoya le tonnerre et la grêle; les éclairs tombèrent sur la terre. Yahvé fit pleuvoir de la grêle sur le pays d'Égypte.
24 Yìnyín rọ̀, mọ̀nàmọ́ná sì bẹ̀rẹ̀ sí bùsi orí ilẹ̀ èyí ni ó tí ì burú jù ti ó ṣẹlẹ̀ láti ìgbà ti Ejibiti ti di orílẹ̀-èdè.
Il y eut une grêle très forte, et les éclairs se mêlèrent à la grêle, comme il n'y en avait pas eu dans tout le pays d'Égypte depuis qu'il était devenu une nation.
25 Jákèjádò gbogbo ilẹ̀ Ejibiti ni yìnyín ti pa gbogbo ohun tí ó wà ni orí pápá; ènìyàn àti ẹranko, ó wò gbogbo ohun ọ̀gbìn lulẹ̀ ó sì fa gbogbo igi ya pẹ̀lú.
La grêle frappa dans tout le pays d'Égypte tout ce qui se trouvait dans les champs, tant les hommes que les animaux; la grêle frappa toutes les herbes des champs et brisa tous les arbres des champs.
26 Ilẹ̀ Goṣeni ni ibi ti àwọn Israẹli wà nìkan ni òjò yìnyín náà kò rọ̀ dé.
Il n'y eut de grêle que dans le pays de Gosen, où se trouvaient les enfants d'Israël.
27 Nígbà náà ni Farao pe Mose àti Aaroni sì ọ̀dọ́ rẹ̀, ó sì wí fún wọn pé, “Èmi ti ṣẹ̀ ní àkókò yìí; Olúwa jẹ́ olódodo ṣùgbọ́n èmi àti àwọn ènìyàn mi ni aláìṣòdodo.
Pharaon fit appeler Moïse et Aaron, et leur dit: « Cette fois, j'ai péché. Yahvé est juste, et moi et mon peuple sommes méchants.
28 Èyí ti òjò yìnyín àti àrá rọ̀ yìí tó gẹ́ẹ́, gbàdúrà sí Olúwa kí ó dáwọ́ rẹ̀ dúró. Èmi yóò jẹ́ kí ẹ lọ, n kò tún ni dá a yín dúró mọ́.”
Priez Yahvé, car il y a eu assez de tonnerres et de grêle. Je vais vous laisser partir, et vous ne resterez pas plus longtemps. »
29 Mose dá a lóhùn pé, “Bí mo bá ti jáde kúrò ní àárín ìlú, èmi yóò gbé ọwọ́ mi sókè sí Olúwa, sísán àrá yóò dáwọ́ dúró, yìnyín kò sì ni rọ̀ mọ́, kí ìwọ kí ó lè mọ̀ pé Olúwa ni ó ni ilẹ̀.
Moïse lui dit: « Dès que je serai sorti de la ville, j'étendrai mes mains vers Yahvé. Les tonnerres cesseront, et il n'y aura plus de grêle, afin que tu saches que la terre appartient à Yahvé.
30 Ṣùgbọ́n èmi mọ̀ pé síbẹ̀síbẹ̀ ìwọ àti àwọn ìjòyè rẹ kò bẹ̀rù Olúwa Ọlọ́run.”
Mais quant à toi et à tes serviteurs, je sais que vous ne craignez pas encore Yahvé Dieu. »
31 (A sì lu ọ̀gbọ̀ àti ọkà barle bolẹ̀; nítorí barle wà ní ìpẹ́, ọ̀gbọ̀ sì rudi.
Le lin et l'orge furent frappés, car l'orge avait mûri et le lin était en fleur.
32 Alikama àti ọkà ni a kò lù bolẹ̀, nítorí tí wọ́n kò tí ì dàgbà.)
Mais le blé et l'épeautre ne furent pas frappés, car ils n'avaient pas encore poussé.
33 Nígbà náà ni Mose jáde kúrò ni iwájú Farao, ó kúrò ni àárín ìgboro kọjá lọ sí ẹ̀yìn odi ìlú, ó sì gbé ọwọ́ rẹ̀ sókè sí Olúwa, sísán àrá àti òjò yìnyín ti ń rọ̀ sì dáwọ́ dúró, òjò kò sì rọ̀ sí orí ilẹ̀ mọ́.
Moïse sortit de la ville, loin de Pharaon, et étendit ses mains vers Yahvé; les tonnerres et la grêle cessèrent, et la pluie ne fut pas versée sur la terre.
34 Nígbà tí Farao rí i pé òjò àti yìnyín àti àrá ti ń sán ti dáwọ́ dúró, ó tún ṣẹ̀ ní ẹ̀ẹ̀kan sí i. Òun àti àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ ṣì sé àyà wọn le.
Lorsque Pharaon vit que la pluie, la grêle et les tonnerres avaient cessé, il pécha encore plus et endurcit son cœur, lui et ses serviteurs.
35 Àyà Farao sì le, bẹ́ẹ̀ ni kò sì jẹ́ kí àwọn ọmọ Israẹli kí ó lọ, bí Olúwa ti sọ láti ẹnu Mose.
Le cœur de Pharaon s'endurcit et il ne laissa pas aller les enfants d'Israël, comme Yahvé l'avait dit par Moïse.

< Exodus 9 >