< Exodus 9 >
1 Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Mose pé, “Lọ sọ fún Farao, ‘Èyí ni Olúwa Ọlọ́run àwọn Heberu sọ, “Jẹ́ kí àwọn ènìyàn Mi kí ó lọ, kí wọn bá à lè sìn Mí.”
Og Herren sagde til Mose: Gak til Farao, og du skal sige til ham: Saa siger Herren, Hebræernes Gud: Lad mit Folk fare, at de kunne tjene mig.
2 Bí ìwọ bá kọ̀ láti jẹ́ kí wọn ó lọ, tí ó sì dá wọn dúró.
Thi dersom du vægrer dig ved at lade dem fare, og du fremdeles holder paa dem,
3 Ọwọ́ Olúwa yóò mú ààrùn búburú wá sí ara ẹran ọ̀sìn nínú oko, sí ara ẹṣin, kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, ìbákasẹ, màlúù, àgùntàn àti ewúrẹ́ yín.
se, da skal Herrens Haand komme over dit Kvæg, som er paa Marken, over Heste, over Asener, over Kameler, over Øksne og over smaat Kvæg, en saare svar Pest.
4 Ṣùgbọ́n Olúwa yóò pààlà sí àárín ẹran ọ̀sìn tí ó jẹ́ ti Israẹli àti ti àwọn ara Ejibiti tí yóò fi jẹ́ pé kò sí ẹran ọ̀sìn ti ó jẹ́ ti ará Israẹli tí yóò kùú.’”
Og Herren skal gøre Skilsmisse imellem Israels Kvæg og imellem Ægypternes Kvæg, og der skal intet dø af alt det, Israels Børn have.
5 Olúwa sì dá àkókò kan wí pé, “Ní ọ̀la ni Olúwa yóò ṣe èyí ni ilẹ̀ yìí.”
Og Herren satte en bestemt Tid og sagde: I Morgen skal Herren gøre denne Gerning i Landet.
6 Olúwa sí ṣe é ni ọjọ́ kejì. Gbogbo ẹran ọ̀sìn ará Ejibiti kú, ṣùgbọ́n ẹyọ kan kò kú lára ẹran ọ̀sìn àwọn Israẹli.
Og Herren gjorde denne Gerning den næste Dag, og alt Ægypternes Kvæg døde; men der døde ikke eet Stykke af Israels Børns Kvæg.
7 Farao rán àwọn ènìyàn rẹ̀ láti lọ ṣe ìwádìí, wọ́n sì rí pé ẹyọ kan kò kú lára àwọn ẹran ọ̀sìn ará Israẹli. Síbẹ̀ náà, Farao kò yí ọkàn rẹ̀ padà àti pé kò jẹ́ kí àwọn ènìyàn ó lọ.
Og Farao sendte Bud, og se, end ikke eet Stykke var død af Israels Kvæg; men Faraos Hjerte forhærdedes, og han lod ikke Folket fare.
8 Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Mose àti Aaroni, “Ẹ bu ẹ̀kúnwọ́ eérú gbígbóná láti inú ààrò, kí Mose kù ú sí inú afẹ́fẹ́ ni iwájú Farao.
Da sagde Herren til Mose og til Aron: Tager eders Næver fulde af Aske fra Ovnen, og Mose skal slaa den ud mod Himmelen for Faraos Øjne.
9 Yóò sì di eruku lẹ́búlẹ́bú ni gbogbo ilẹ̀ Ejibiti, yóò sì di oówo ti ń tú pẹ̀lú ìléròrò sí ara àwọn ènìyàn àti ẹran jákèjádò gbogbo ilẹ̀ Ejibiti.”
Og den skal vorde til Støv over alt Ægyptens Land, og det skal vorde til Bylder, som skal bryde ud med Blegner, paa Folket og paa Kvæget i alt Ægyptens Land.
10 Nígbà náà ni wọ́n bú eérú gbígbóná láti inú ààrò, wọ́n dúró ní iwájú Farao. Mose sì ku eérú náà sínú afẹ́fẹ́, ó sì di oówo tí ń tú pẹ̀lú ìléròrò ni ara àwọn ènìyàn àti lára ẹran.
Saa toge de Aske fra Ovnen og stode for Farao, og Mose slog den ud mod Himmelen; og der blev Bylder, som brød ud med Blegner, paa Folket og paa Kvæget.
11 Àwọn onídán kò le è dúró níwájú Mose nítorí oówo ti ó wà lára wọn àti ni ara gbogbo àwọn ara Ejibiti.
Og Koglerne kunde ikke bestaa for Mose, formedelst Bylderne; thi der var Bylder paa Koglerne og paa alle Ægyptere.
12 Ṣùgbọ́n Ọlọ́run sé ọkàn Farao le, kò sì gbọ́ ti Mose àti Aaroni, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti sọ fún Mose.
Men Herren forhærdede Faraos Hjerte, saa at han ikke hørte dem, som Herren havde sagt til Mose.
13 Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Mose pé, “Dìde ni òwúrọ̀ kùtùkùtù, kí o sì tọ Farao lọ, kí o sì wí fún un pé, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run àwọn Heberu wí, Jẹ́ kí àwọn ènìyàn mi kí ó lọ, kí wọn bá à lè sìn mí,
Da sagde Herren til Mose: Staa aarle op om Morgenen og stil dig for Farao og sig til ham: Saa siger Herren, Hebræernes Gud: Lad mit Folk fare, at de kunne tjene mig.
14 nítorí nígbà yìí ni èmi yóò rán àjàkálẹ̀-ààrùn ti ó ní agbára gidigidi sí ọ, sí àwọn ìjòyè rẹ àti sí àwọn ènìyàn rẹ, kí ìwọ kí ó lè mọ̀ pé, kò sí ẹni bí èmi ni gbogbo ayé.
Thi denne Gang vil jeg sende alle mine Plager, saa det gaar dig til Hjerte, baade paa dine Tjenere og paa dit Folk, at du skal fornemme, at der er ingen som jeg paa al Jorden.
15 Ó ti yẹ kí n ti na ọwọ́ mi jáde láti kọlù ọ́ àti àwọn ènìyàn rẹ pẹ̀lú ààrùn búburú ti kò bá ti run yín kúrò ni orí ilẹ̀.
Thi havde jeg allerede udrakt min Haand og slaget dig og dit Folk med Pest, da havde du været udslettet af Jorden;
16 Ṣùgbọ́n nítorí èyí ni èmi ṣe mú ọ dúró, kí èmi kí ó le fi agbára mi hàn lára rẹ, àti kí a bá à le máa ròyìn orúkọ mi ká gbogbo ayé.
men sandelig derfor har jeg ladet dig blive staaende, for at lade dig se min Magt, og for at mit Navn skal kundgøres i alle Lande.
17 Síbẹ̀ ìwọ tún gbógun ti àwọn ènìyàn mi, ìwọ kò sì jẹ́ kí wọn lọ.
Ophøjer du dig endnu over mit Folk, saa at du ikke vil lade dem fare?
18 Nítorí náà, ni ìwòyí ọ̀la, Èmi yóò rán òjò o yìnyín tí irú rẹ̀ kò tí i rọ̀ rí ni Ejibiti láti ìpilẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ títí di àkókò yìí.
Se, jeg vil i Morgen paa denne Tid lade regne en saare svar Hagel, hvis Lige var aldrig før i Ægypten fra den Dag, det blev grundfæstet og hidindtil.
19 Pàṣẹ nísinsin yìí láti kó ẹran ọ̀sìn yín àti ohun gbogbo ti ẹ ni ní pápá wá sí abẹ́ ààbò, nítorí òjò yìnyín yóò rọ̀ sí orí àwọn ènìyàn àti ẹran ti a kò kó wá sí abẹ́ ààbò tí wọ́n sì wà ni orí pápá, wọn yóò sì kú.’”
Saa send nu hen, saml dit Kvæg og alt det, du har paa Marken; thi alle Mennesker og alt Kvæg, som findes paa Marken og ikke ere samlede i Hus, og som Hagelen slaar ned paa, skulle dø.
20 Àwọn ti ó bẹ̀rù ọ̀rọ̀ Olúwa lára àwọn ìjòyè Farao yára lọ láti kó àwọn ẹrú àti àwọn ẹran ọ̀sìn wọn wá sí abẹ́ ààbò.
Hvo som da frygtede Herrens Ord blandt Faraos Tjenere, han lod sine Tjenere og sit Kvæg fly til Husene;
21 Ṣùgbọ́n àwọn ti kò kà ọ̀rọ̀ Olúwa sí fi àwọn ẹrú wọn àti àwọn ẹran ọ̀sìn wọn sílẹ̀ ni pápá.
men hvo som ikke lagde Herrens Ord paa sit Hjerte, lod sine Tjenere og sit Kvæg blive paa Marken.
22 Olúwa sọ fún Mose pé, “Gbé ọwọ́ rẹ sókè sí ọ̀run kí yìnyín bá à lè rọ̀ sí orí gbogbo ilẹ̀ Ejibiti, sí orí ènìyàn àti ẹranko, àti sí orí gbogbo ohun ọ̀gbìn tí ó wà ni inú oko.”
Da sagde Herren til Mose: Ræk din Haand op mod Himmelen, og der skal vorde Hagel over hele Ægyptens Land, over Mennesker og over Kvæg og over alle Urter paa Marken i Ægyptens Land.
23 Nígbà tí Mose gbé ọ̀pá rẹ̀ sókè sí ojú ọ̀run, Olúwa rán àrá àti yìnyín, mọ̀nàmọ́ná sì bùsi orí ilẹ̀. Olúwa rọ òjò yìnyín sí orí ilẹ̀ Ejibiti.
Og Mose rakte sin Stav op mod Himmelen, og Herren lod tordne og hagle, og der for Ild ned paa Jorden; og Herren lod regne Hagel over Ægyptens Land.
24 Yìnyín rọ̀, mọ̀nàmọ́ná sì bẹ̀rẹ̀ sí bùsi orí ilẹ̀ èyí ni ó tí ì burú jù ti ó ṣẹlẹ̀ láti ìgbà ti Ejibiti ti di orílẹ̀-èdè.
Og der blev Hagel og Ild, som slyngede sig midt i Hagelen, saare svar, saadan som ikke havde været i hele Ægyptens Land, fra den Tid det havde været et Folks Land.
25 Jákèjádò gbogbo ilẹ̀ Ejibiti ni yìnyín ti pa gbogbo ohun tí ó wà ni orí pápá; ènìyàn àti ẹranko, ó wò gbogbo ohun ọ̀gbìn lulẹ̀ ó sì fa gbogbo igi ya pẹ̀lú.
Og Hagelen nedslog i hele Ægyptens Land det, som var paa Marken, baade Mennesker og Kvæg; og alle Urter paa Marken slog Hagelen og knækkede alle Træer paa Marken.
26 Ilẹ̀ Goṣeni ni ibi ti àwọn Israẹli wà nìkan ni òjò yìnyín náà kò rọ̀ dé.
Alene i Gosen Land, hvor Israels Børn vare, faldt der ikke Hagel.
27 Nígbà náà ni Farao pe Mose àti Aaroni sì ọ̀dọ́ rẹ̀, ó sì wí fún wọn pé, “Èmi ti ṣẹ̀ ní àkókò yìí; Olúwa jẹ́ olódodo ṣùgbọ́n èmi àti àwọn ènìyàn mi ni aláìṣòdodo.
Da sendte Farao hen og lod kalde ad Mose og Aron og sagde til dem: Jeg har syndet denne Gang; Herren er den retfærdige, men jeg og mit Folk ere de ugudelige.
28 Èyí ti òjò yìnyín àti àrá rọ̀ yìí tó gẹ́ẹ́, gbàdúrà sí Olúwa kí ó dáwọ́ rẹ̀ dúró. Èmi yóò jẹ́ kí ẹ lọ, n kò tún ni dá a yín dúró mọ́.”
Beder til Herren, at det maa være nok med den Guds Torden og Hagel, saa vil jeg lade eder fare, at I ikke skulle bie længere.
29 Mose dá a lóhùn pé, “Bí mo bá ti jáde kúrò ní àárín ìlú, èmi yóò gbé ọwọ́ mi sókè sí Olúwa, sísán àrá yóò dáwọ́ dúró, yìnyín kò sì ni rọ̀ mọ́, kí ìwọ kí ó lè mọ̀ pé Olúwa ni ó ni ilẹ̀.
Og Mose sagde til ham: Naar jeg kommer ud af Staden, da vil jeg udbrede mine Hænder til Herren, saa skal Tordenen høre op, og Hagelen skal ikke falde mere, at du skal fornemme, at Jorden hører Herren til.
30 Ṣùgbọ́n èmi mọ̀ pé síbẹ̀síbẹ̀ ìwọ àti àwọn ìjòyè rẹ kò bẹ̀rù Olúwa Ọlọ́run.”
Dog om dig og dine Tjenere ved jeg, at I endnu ikke frygte for den Herre Guds Ansigt.
31 (A sì lu ọ̀gbọ̀ àti ọkà barle bolẹ̀; nítorí barle wà ní ìpẹ́, ọ̀gbọ̀ sì rudi.
Da blev baade Hør og Byg nedslaget; thi Bygget var skudt i Aks og Hørren i Knevler.
32 Alikama àti ọkà ni a kò lù bolẹ̀, nítorí tí wọ́n kò tí ì dàgbà.)
Men Hveden og Spelten bleve ikke nedslagne; thi de vare endnu ikke skredne.
33 Nígbà náà ni Mose jáde kúrò ni iwájú Farao, ó kúrò ni àárín ìgboro kọjá lọ sí ẹ̀yìn odi ìlú, ó sì gbé ọwọ́ rẹ̀ sókè sí Olúwa, sísán àrá àti òjò yìnyín ti ń rọ̀ sì dáwọ́ dúró, òjò kò sì rọ̀ sí orí ilẹ̀ mọ́.
Og Mose gik fra Farao ud af Staden og udbredte sine Hænder til Herren; saa lod det af at tordne og hagle, og Regnen blev ikke mere udøst paa Jorden.
34 Nígbà tí Farao rí i pé òjò àti yìnyín àti àrá ti ń sán ti dáwọ́ dúró, ó tún ṣẹ̀ ní ẹ̀ẹ̀kan sí i. Òun àti àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ ṣì sé àyà wọn le.
Der Farao saa, at det holdt op at regne og hagle og tordne, da syndede han endda; og han forhærdede sit Hjerte, han og hans Tjenere.
35 Àyà Farao sì le, bẹ́ẹ̀ ni kò sì jẹ́ kí àwọn ọmọ Israẹli kí ó lọ, bí Olúwa ti sọ láti ẹnu Mose.
Saa blev Faraos Hjerte forhærdet, og han lod ikke Israels Børn fare, som Herren havde sagt ved Mose.