< Exodus 9 >

1 Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Mose pé, “Lọ sọ fún Farao, ‘Èyí ni Olúwa Ọlọ́run àwọn Heberu sọ, “Jẹ́ kí àwọn ènìyàn Mi kí ó lọ, kí wọn bá à lè sìn Mí.”
BOEIPA loh Moses te, “Pharaoh taengah cet lamtah anih te thui pah. Hebrew kah Pathen Yahweh loh he ni a thui. Ka pilnam te hlah lamtah kai ham thothueng uh saeh.
2 Bí ìwọ bá kọ̀ láti jẹ́ kí wọn ó lọ, tí ó sì dá wọn dúró.
Tedae hlah ham na aal tih amih te na yuengyet pueng atah,
3 Ọwọ́ Olúwa yóò mú ààrùn búburú wá sí ara ẹran ọ̀sìn nínú oko, sí ara ẹṣin, kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, ìbákasẹ, màlúù, àgùntàn àti ewúrẹ́ yín.
BOEIPA kut te lohma kah na boiva soah, marhang soah, laak soah, kalauk soah, saelhung soah tla vetih boiva dongah duektahaw la muep tlung ne.
4 Ṣùgbọ́n Olúwa yóò pààlà sí àárín ẹran ọ̀sìn tí ó jẹ́ ti Israẹli àti ti àwọn ara Ejibiti tí yóò fi jẹ́ pé kò sí ẹran ọ̀sìn ti ó jẹ́ ti ará Israẹli tí yóò kùú.’”
Tedae BOEIPA loh Israel kah boiva laklo neh Egypt kah boiva laklo ah a hoep vetih Israel ca rhoek kah boeih tah ol nen pataeng duek pah mahpawh.
5 Olúwa sì dá àkókò kan wí pé, “Ní ọ̀la ni Olúwa yóò ṣe èyí ni ilẹ̀ yìí.”
BOEIPA loh thangvuen ah thui hamla khoning a khueh coeng. He kah hno he BOEIPA loh khohmuen ah a saii ni,” a ti nah.
6 Olúwa sí ṣe é ni ọjọ́ kejì. Gbogbo ẹran ọ̀sìn ará Ejibiti kú, ṣùgbọ́n ẹyọ kan kò kú lára ẹran ọ̀sìn àwọn Israẹli.
Tekah BOEIPA loh ol te a vuen ah a thoeng sak. Te dongah Egypt kah boiva tah boeih duek. Tedae Israel ca rhoek kah boiva tah pakhat khaw duek pawh.
7 Farao rán àwọn ènìyàn rẹ̀ láti lọ ṣe ìwádìí, wọ́n sì rí pé ẹyọ kan kò kú lára àwọn ẹran ọ̀sìn ará Israẹli. Síbẹ̀ náà, Farao kò yí ọkàn rẹ̀ padà àti pé kò jẹ́ kí àwọn ènìyàn ó lọ.
Te vaengah Pharaoh loh hlang a tueih akhaw Israel kah boiva tah pakhat pataeng a duek moenih ne. Tedae Pharaoh lungbuei te a thangpom pueng tih pilnam te hlah pawh.
8 Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Mose àti Aaroni, “Ẹ bu ẹ̀kúnwọ́ eérú gbígbóná láti inú ààrò, kí Mose kù ú sí inú afẹ́fẹ́ ni iwájú Farao.
Te phoeiah BOEIPA loh Moses neh Aaron te, “Hmailing khangvai te namamih rhoi ham na kutnarhum a bae lo rhoi lamtah Moses loh Pharaoh mikhmuh ah vaan la haeh saeh.
9 Yóò sì di eruku lẹ́búlẹ́bú ni gbogbo ilẹ̀ Ejibiti, yóò sì di oówo ti ń tú pẹ̀lú ìléròrò sí ara àwọn ènìyàn àti ẹran jákèjádò gbogbo ilẹ̀ Ejibiti.”
Te vaengah Egypt kho tom ah laipi la poeh vetih, Egypt khohmuen boeih kah hlang so neh rhamsa dongah buhlut la om a hnai neh phuem ni,” a ti nah.
10 Nígbà náà ni wọ́n bú eérú gbígbóná láti inú ààrò, wọ́n dúró ní iwájú Farao. Mose sì ku eérú náà sínú afẹ́fẹ́, ó sì di oówo tí ń tú pẹ̀lú ìléròrò ni ara àwọn ènìyàn àti lára ẹran.
Te dongah hmailing khangvai te a loh rhoi tih Pharaoh mikhmuh ah pai rhoi. Te te Moses loh vaan la a haeh tih buhlut la poeh tih hlang pum dong neh rhamsa dongah a hnai a coe pah.
11 Àwọn onídán kò le è dúró níwájú Mose nítorí oówo ti ó wà lára wọn àti ni ara gbogbo àwọn ara Ejibiti.
Te vaengah hmayuep rhoek tah buhlut dongah Moses mikhmuh la pai ham noeng uh pawh. Buhlut te hmayuep rhoek so neh Egypt pum soah a om pah.
12 Ṣùgbọ́n Ọlọ́run sé ọkàn Farao le, kò sì gbọ́ ti Mose àti Aaroni, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti sọ fún Mose.
Tedae BOEIPA loh Pharaoh kah lungbuei te a moem pah dongah BOEIPA loh Moses taengah a thui bangla amih rhoi ol te hnatun pawh.
13 Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Mose pé, “Dìde ni òwúrọ̀ kùtùkùtù, kí o sì tọ Farao lọ, kí o sì wí fún un pé, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run àwọn Heberu wí, Jẹ́ kí àwọn ènìyàn mi kí ó lọ, kí wọn bá à lè sìn mí,
Te phoeiah BOEIPA loh Moses taengah, “Mincang ah thoo lamtah Pharaoh mikhmuh ah pai pah. Te vaengah anih te thui pah. Hebrew kah Pathen Yahweh loh he ni a thui. Ka pilnam he hlah lamtah kai ham thothueng saeh.
14 nítorí nígbà yìí ni èmi yóò rán àjàkálẹ̀-ààrùn ti ó ní agbára gidigidi sí ọ, sí àwọn ìjòyè rẹ àti sí àwọn ènìyàn rẹ, kí ìwọ kí ó lè mọ̀ pé, kò sí ẹni bí èmi ni gbogbo ayé.
Tahae voei khat la kai kah lucik cungkuem te na lungbuei neh na sal rhoek taengah, na pilnam taengah kan tueih. Te nen ni diklai pum ah kamah bang a om pawt te na ming eh.
15 Ó ti yẹ kí n ti na ọwọ́ mi jáde láti kọlù ọ́ àti àwọn ènìyàn rẹ pẹ̀lú ààrùn búburú ti kò bá ti run yín kúrò ni orí ilẹ̀.
Ka kut he ka hlah tih namah neh na pilnam te duektahaw neh kang ngawn coeng dongah diklai lamloh na pat pawn ni.
16 Ṣùgbọ́n nítorí èyí ni èmi ṣe mú ọ dúró, kí èmi kí ó le fi agbára mi hàn lára rẹ, àti kí a bá à le máa ròyìn orúkọ mi ká gbogbo ayé.
He kong dongah ka thadueng na phoe ham ni nang kam pai sak. Te dongah ka ming he diklai pum ah thui ham om.
17 Síbẹ̀ ìwọ tún gbógun ti àwọn ènìyàn mi, ìwọ kò sì jẹ́ kí wọn lọ.
Amih hlah pawt ham te ka pilnam taengah na picai uh pueng.
18 Nítorí náà, ni ìwòyí ọ̀la, Èmi yóò rán òjò o yìnyín tí irú rẹ̀ kò tí i rọ̀ rí ni Ejibiti láti ìpilẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ títí di àkókò yìí.
Thangvuen a tue vai khat tah rhael muep kan tlan sak khungdaeng pueng ni he. Te bang te a suen khohnin lamloh tahae hil khaw Egypt ah a om moenih.
19 Pàṣẹ nísinsin yìí láti kó ẹran ọ̀sìn yín àti ohun gbogbo ti ẹ ni ní pápá wá sí abẹ́ ààbò, nítorí òjò yìnyín yóò rọ̀ sí orí àwọn ènìyàn àti ẹran ti a kò kó wá sí abẹ́ ààbò tí wọ́n sì wà ni orí pápá, wọn yóò sì kú.’”
Te dongah tueih lamtah na boiva neh na taengkah boeih te khaw, khohmuen kah hlang boeih neh lohma kah a hmuh rhamsa khaw bakuep sak laeh. Im la a coi pawt te rhael loh a tlak thil vetih duek ni,” a ti nah.
20 Àwọn ti ó bẹ̀rù ọ̀rọ̀ Olúwa lára àwọn ìjòyè Farao yára lọ láti kó àwọn ẹrú àti àwọn ẹran ọ̀sìn wọn wá sí abẹ́ ààbò.
Pharaoh sal rhoek khuikah BOEIPA ol aka rhih long tah a sal rhoek neh a boiva khaw im la a rhaelrham puei.
21 Ṣùgbọ́n àwọn ti kò kà ọ̀rọ̀ Olúwa sí fi àwọn ẹrú wọn àti àwọn ẹran ọ̀sìn wọn sílẹ̀ ni pápá.
Tedae BOEIPA ol te a lungbuei ah aka khueh pawt long tah a sal neh a boiva te lohma ah a hnoo.
22 Olúwa sọ fún Mose pé, “Gbé ọwọ́ rẹ sókè sí ọ̀run kí yìnyín bá à lè rọ̀ sí orí gbogbo ilẹ̀ Ejibiti, sí orí ènìyàn àti ẹranko, àti sí orí gbogbo ohun ọ̀gbìn tí ó wà ni inú oko.”
BOEIPA loh Moses taengah, “Na kut te vaan la thueng lamtah Egypt khohmuen boeih ah hlang so neh rhamsa soah khaw, Egypt diklai kah khohmuen baelhing boeih soah rhael tla bitni,” a ti nah.
23 Nígbà tí Mose gbé ọ̀pá rẹ̀ sókè sí ojú ọ̀run, Olúwa rán àrá àti yìnyín, mọ̀nàmọ́ná sì bùsi orí ilẹ̀. Olúwa rọ òjò yìnyín sí orí ilẹ̀ Ejibiti.
Moses loh a conghol te vaan la a thueng tangloeng vaengah BOEIPA loh a ol neh rhael neh a tueih tih hmai khaw diklai la cet. Te vaengah BOEIPA loh Egypt khohmuen ah rhael a tlan sak.
24 Yìnyín rọ̀, mọ̀nàmọ́ná sì bẹ̀rẹ̀ sí bùsi orí ilẹ̀ èyí ni ó tí ì burú jù ti ó ṣẹlẹ̀ láti ìgbà ti Ejibiti ti di orílẹ̀-èdè.
Rhael a tlak vaengah rhael lakli ah hmai khaw muep hli khungdaeng. Namtom taengah aka om parhi te Egypt khohmuen tom ah te bang a om noek moenih.
25 Jákèjádò gbogbo ilẹ̀ Ejibiti ni yìnyín ti pa gbogbo ohun tí ó wà ni orí pápá; ènìyàn àti ẹranko, ó wò gbogbo ohun ọ̀gbìn lulẹ̀ ó sì fa gbogbo igi ya pẹ̀lú.
Egypt kho tom ah rhael loh lohma kah boeih, hlang lamloh rhamsa hil khaw a ngawn. Khohmuen baelhing boeih te rhael loh a ngawn tih khohmuen thingkung boeih a khong.
26 Ilẹ̀ Goṣeni ni ibi ti àwọn Israẹli wà nìkan ni òjò yìnyín náà kò rọ̀ dé.
Israel ca rhoek kah Goshen khohmuen bueng ah ni rhael a tlak pawh.
27 Nígbà náà ni Farao pe Mose àti Aaroni sì ọ̀dọ́ rẹ̀, ó sì wí fún wọn pé, “Èmi ti ṣẹ̀ ní àkókò yìí; Olúwa jẹ́ olódodo ṣùgbọ́n èmi àti àwọn ènìyàn mi ni aláìṣòdodo.
Te vaengah Pharaoh loh ol a tah tih Moses neh Aaron te a khue. Te phoeiah amih rhoi te, “Ka tholh bal coeng, BOEIPA he dueng ngawn dae kamah neh ka pilnam ni aka halang coeng.
28 Èyí ti òjò yìnyín àti àrá rọ̀ yìí tó gẹ́ẹ́, gbàdúrà sí Olúwa kí ó dáwọ́ rẹ̀ dúró. Èmi yóò jẹ́ kí ẹ lọ, n kò tún ni dá a yín dúró mọ́.”
BOEIPA taengah thangthui rhoi laeh. Pathen kah ol neh rhael a tlak khaw yet coeng. Nangmih te kan tueih daengah nan pai thil ham te na khoep pawt eh?,” a ti nah.
29 Mose dá a lóhùn pé, “Bí mo bá ti jáde kúrò ní àárín ìlú, èmi yóò gbé ọwọ́ mi sókè sí Olúwa, sísán àrá yóò dáwọ́ dúró, yìnyín kò sì ni rọ̀ mọ́, kí ìwọ kí ó lè mọ̀ pé Olúwa ni ó ni ilẹ̀.
Te vaengah Moses loh anih te, “Khopuei he ka nong tak tih BOEIPA taengah ka kut ka phuel ni. Ol khaw paa tih rhael koep a bo pawt daengah ni diklai he BOEIPA ham ni tila na ming eh.
30 Ṣùgbọ́n èmi mọ̀ pé síbẹ̀síbẹ̀ ìwọ àti àwọn ìjòyè rẹ kò bẹ̀rù Olúwa Ọlọ́run.”
Tedae namah neh na sal rhoek loh BOEIPA Pathen mikhmuh ah na rhih uh hlan tila ka ming.
31 (A sì lu ọ̀gbọ̀ àti ọkà barle bolẹ̀; nítorí barle wà ní ìpẹ́, ọ̀gbọ̀ sì rudi.
Thut neh cangtun neh khaw cangtun vueilue neh thut muem khaw a ngawn coeng.
32 Alikama àti ọkà ni a kò lù bolẹ̀, nítorí tí wọ́n kò tí ì dàgbà.)
Tedae cang neh cangkuem tah a hnong pueng dongah ngawn pawh.
33 Nígbà náà ni Mose jáde kúrò ni iwájú Farao, ó kúrò ni àárín ìgboro kọjá lọ sí ẹ̀yìn odi ìlú, ó sì gbé ọwọ́ rẹ̀ sókè sí Olúwa, sísán àrá àti òjò yìnyín ti ń rọ̀ sì dáwọ́ dúró, òjò kò sì rọ̀ sí orí ilẹ̀ mọ́.
Moses loh Pharaoh taeng lamkah khopuei a nong tak tih BOEIPA taengah a kut a phuel. Te daengah rhaek ol neh rhael khaw paa tih khotlan loh khohmuen ah bo pawh.
34 Nígbà tí Farao rí i pé òjò àti yìnyín àti àrá ti ń sán ti dáwọ́ dúró, ó tún ṣẹ̀ ní ẹ̀ẹ̀kan sí i. Òun àti àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ ṣì sé àyà wọn le.
Khotlan neh rhael neh ol paa coeng tila Pharaoh loh a hmuh van neh tholh te a khoep tih amah neh a sal rhoek loh a lungbuei a thangpom.
35 Àyà Farao sì le, bẹ́ẹ̀ ni kò sì jẹ́ kí àwọn ọmọ Israẹli kí ó lọ, bí Olúwa ti sọ láti ẹnu Mose.
Te dongah Pharaoh lungbuei tah ning tih BOEIPA loh Moses kut ah a uen bangla Israel ca hlah pawh.

< Exodus 9 >