< Exodus 7 >
1 Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Mose pé, “Wò ó, Èmi ti ṣe ọ bí Ọlọ́run fún Farao, Aaroni arákùnrin rẹ ni yóò jẹ́ agbẹnusọ rẹ.
A ka mea a Ihowa ki a Mohi, Na, kua oti koe te mea e ahau hei atua ki a Parao; ko Arona hoki, ko tou tuakana, hei poropiti mau.
2 Ìwọ yóò sì sọ ohun gbogbo tí Èmi ti pàṣẹ fún ọ, Aaroni arákùnrin rẹ yóò sísọ fún Farao kí ó jẹ́ kí àwọn ọmọ Israẹli jáde kúrò ni ilẹ̀ rẹ̀.
Korerotia nga mea katoa e ki ai ahau ki a koe; a ma Arona, ma tou tuakana, e korero ki a Parao, kia tukua e ia nga tama a Iharaira i tona whenua.
3 Ṣùgbọ́n èmi yóò sé Farao lọ́kàn le. Bí Mo tilẹ̀ ṣe ọ̀pọ̀lọpọ̀ iṣẹ́ àmì àti ìyanu ni Ejibiti,
A maku e whakapakeke te ngakau o Parao, e whakamaha hoki aku tohu me aku merekara ki te whenua o Ihipa.
4 síbẹ̀ òun kì yóò fi etí sí ọ. Nígbà náà ni Èmi yóò gbé ọwọ́ mi lé Ejibiti, pẹ̀lú agbára ìdájọ́ ńlá mi ni èmi yóò mú àwọn ènìyàn mi Israẹli jáde ní ọ̀wọ̀ọ̀wọ́.
Otiia e kore a Parao e rongo ki a korua, a ka pa toku ringa ki Ihipa, he nui ano hoki nga whakawa e whakaputaina ai e ahau aku mano tini, taku iwi, nga tama a Iharaira, i te whenua o Ihipa.
5 Àwọn ará Ejibiti yóò sì mọ̀ pé Èmi ni Olúwa ní ìgbà tí mo bá na ọwọ́ mi jáde lé Ejibiti, tí mo sì mú àwọn ọmọ Israẹli jáde kúrò níbẹ̀.”
A e mohio nga Ihipiana ko Ihowa ahau, ina totoro toku ringa ki Ihipa, a ka whakaputaina mai e ahau nga tama a Iharaira i roto i a ratou.
6 Mose àti Aaroni sì ṣe gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún wọn.
I mea ano a Mohi raua ko Arona i ta Ihowa i whakahau ai ki a raua, pera ana raua.
7 Mose jẹ́ ọmọ ọgọ́rin ọdún Aaroni sì jẹ́ ọmọ ọdún mẹ́tàlélọ́gọ́rin ni ìgbà tí wọ́n bá Farao sọ̀rọ̀.
A e waru tekau nga tau o Mohi, e waru tekau ma toru nga tau o Arona, i ta raua korerotanga ki a Parao.
8 Olúwa sọ fún Mose àti Aaroni,
A i korero a Ihowa ki a Mohi raua ko Arona, i mea,
9 “Ní ìgbà tí Farao bá sọ fún un yín pé, ‘Ẹ ṣe iṣẹ́ ìyanu kan,’ sọ fún Aaroni ní ìgbà náà pé, ‘Mú ọ̀pá rẹ kí ó sì sọ ọ́ sílẹ̀ níwájú Farao,’ yóò sì di ejò.”
Ki te puta ki a korua ta Parao kupu, Tena koa, tetahi merekara i a korua; ko reira koe mea ai ki a Arona, E mau ki tau tokotoko, maka iho ki te aroaro o Parao, a ka nakahi.
10 Nígbà náà ni Mose àti Aaroni tọ Farao lọ, wọ́n sì ṣe bí Olúwa ti pàṣẹ fún wọn, Aaroni ju ọ̀pá rẹ̀ sílẹ̀ ní iwájú Farao àti àwọn ìjòyè rẹ̀, ọ̀pá náà sì di ejò.
Na ka haere a Mohi raua ko Arona ki a Parao, a peratia ana e raua me ta Ihowa i mea ai: maka iho ana e Arona tona tokotoko ki te aroaro o Parao, ki te aroaro hoki o ana tangata, na, kua nakahi.
11 Farao sì pe àwọn amòye, àwọn oṣó àti àwọn onídán ilẹ̀ Ejibiti jọ, wọ́n sì fi idán wọn ṣe ohun tí Mose àti Aaroni ṣe.
Na ka karanga hoki a Parao i nga tangata mohio, i nga tohunga maori: na, ko ratou, ko nga tohunga o Ihipa, i pera ano ratou ki a ratou nei karakia maori.
12 Ẹnìkọ̀ọ̀kan wọn sọ ọ̀pá rẹ̀ sílẹ̀, ọ̀pá náà sì di ejò. Ṣùgbọ́n ọ̀pá Aaroni gbé ọ̀pá tiwọn mì.
Maka iho ana hoki e tenei, e tenei, a ratou tokotoko, a nakahi ana: otiia i horomia a ratou tokotoko e te tokotoko a Arona.
13 Síbẹ̀ ọkàn Farao sì yigbì, kò si fetí sí wọn gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti sọ.
Na ka whakapakeketia e ia te ngakau o Parao, a kihai ia i rongo ki a raua, ko ta Ihowa hoki i ki ai.
14 Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Mose pé, “Ọkàn Farao ti di líle, ó kọ̀ láti jẹ́ kí àwọn ènìyàn náà ó lọ.
I mea ano a Ihowa ki a Mohi, E pakeke ana te ngakau o Parao, kahore ia e whakaae ana ki te tuku i te iwi.
15 Tọ Farao lọ ni òwúrọ̀ kùtùkùtù bí ó ti ń lọ sí etí odò, dúró ni etí bèbè odò Naili láti pàdé rẹ, mú ọ̀pá rẹ tí ó di ejò ni ọwọ́ rẹ.
Haere ki a Parao i te ata, na, e haere ana ia ki te wai; a hei te pareparenga o te awa tu atu ai koe ki a ia; ko te tokotoko hoki i nakahi ra, maua i tou ringa.
16 Sọ fún un pé, ‘Olúwa Ọlọ́run àwọn Heberu rán mi sí ọ láti sọ fún ọ pé, Jẹ́ kí àwọn ènìyàn mi kí ó lọ, kí wọn kí ó lè sìn mi ni aginjù. Ṣùgbọ́n títí di àkókò yìí, ìwọ kò gba.
A ka mea koe ki a ia, Na Ihowa, na te Atua o nga Hiperu ahau i unga mai ki a koe; e mea ana ia, Tukua taku iwi kia mahi ki ahau i te koraha: titiro, kahore koe kia rongo a mohoa noa nei.
17 Èyí ni Olúwa wí, nípa èyí ni ìwọ yóò mọ̀ pé Èmi ni Olúwa. Wò ó, èmi yóò fi ọ̀pá ti ó wà ní ọwọ́ mi, èmi yóò ná omi tí ó wà nínú odò Naili yóò sì di ẹ̀jẹ̀.
Ko te kupu tenei a Ihowa, ma konei e mohio ai koe ko Ihowa ahau: nana, maku e patu nga wai i te awa ki te tokotoko i toku ringa, a ka riro ke hei toto.
18 Àwọn ẹja tí ó wà nínú odò Naili yóò kú, odò náà yóò sì máa rùn, àwọn ará Ejibiti kò sì ni lè mu omi rẹ̀.’”
E mate hoki nga ika i roto i te awa, a e piro te awa; a e anuanu nga Ihipiana ki te inu i te wai o te awa.
19 Olúwa sọ fún Mose, “Sọ fún Aaroni, ‘Mú ọ̀pá rẹ kí ó sì na ọwọ́ rẹ jáde lórí àwọn omi Ejibiti. Lórí àwọn odò kéékèèké àti odò ńlá, lórí àbàtà àti adágún omi, wọn yóò sì di ẹ̀jẹ̀.’ Ẹ̀jẹ̀ yóò wà ni ibi gbogbo ni Ejibiti, àní nínú ọpọ́n àti nínú kete omi àti nínú ìkòkò tí a pọn omi sí nínú ilé.”
A i korero a Ihowa ki a Mohi, Mea atu ki a Arona, E mau ki tau tokotoko, totoro hoki tou ringa ki nga wai o Ihipa, ki o ratou wai e rere ana, ki o ratou awa, ki o ratou roto, ki o ratou huihuinga wai katoa, kia meinga ai hei toto; a ka whai toto nga oko rakau, kohatu hoki, i te whenua katoa o Ihipa.
20 Mose àti Aaroni sí ṣe gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún wọn. Ó gbé ọ̀pá rẹ̀ sókè ni iwájú Farao àti àwọn ìjòyè rẹ̀, ó sì lu omi odò Naili, omi odò náà sì yípadà sí ẹ̀jẹ̀.
A peratia ana e Mohi raua ko Arona me ta Ihowa i ako ai; hapainga ana e ia te tokotoko, patua ana ki nga wai o te awa, i te tirohanga a Parao, i te tirohanga ano hoki a ana tangata; a riro ke ana hei toto nga wai katoa o te awa.
21 Ẹja inú odò Naili sì kú, odò náà ń rùn gidigidi tí ó fi jẹ́ pé àwọn ará Ejibiti kò le è mu omi inú rẹ̀. Ẹ̀jẹ̀ sì wà ni ibi gbogbo ni ilẹ̀ Ejibiti.
A mate ana nga ika i te awa; a piro ana te awa, kihai hoki i ahei i nga Ihipiana te inu i te wai o te awa: na he toto tera i te whenua katoa o Ihipa.
22 Ṣùgbọ́n àwọn apidán ilẹ̀ Ejibiti sì ṣe bákan náà pẹ̀lú agbára òkùnkùn wọn, ọkàn Farao sì yigbì síbẹ̀ kò sì fetí sí wọn gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti sọ.
A, peratia ana e nga tohunga o Ihipa ki a ratou na mahi maori: a ka whakapakeketia te ngakau o Parao, kahore hoki ia i whakarongo ki a raua; i rite tonu ki ta Ihowa i korero ai.
23 Dípò bẹ́ẹ̀, ó yíjú padà, ó sì lọ sí ààfin rẹ̀, kò sì jẹ́ kí àwọn nǹkan wọ̀nyí wà ni oókan àyà rẹ̀.
Na tahuri ana a Parao, haere ana ki roto ki tona whare, kihai ano hoki i whakaanga i tona ngakau ki tenei.
24 Nígbà náà ni gbogbo àwọn ará Ejibiti bẹ̀rẹ̀ sí í gbẹ́ etí odò Naili láti wá omi tí wọn yóò mu, nítorí wọn kò le è mu omi tí ó wà nínú odò náà.
Na ka keri nga Ihipiana katoa ki nga taha o te awa i te wai hei inu; kihai hoki i ahei te inu i te wai o te awa.
25 Ọjọ́ méje sì kọjá ti Olúwa ti lu odò Naili.
Na kua rite nga ra e whitu i muri i ta Ihowa patunga i te awa.