< Exodus 7 >

1 Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Mose pé, “Wò ó, Èmi ti ṣe ọ bí Ọlọ́run fún Farao, Aaroni arákùnrin rẹ ni yóò jẹ́ agbẹnusọ rẹ.
BAWIPA ni Mosi koe, nang teh faro siangpahrang e cathut lah na o sak. Na hmau Aron teh na profet lah ao han.
2 Ìwọ yóò sì sọ ohun gbogbo tí Èmi ti pàṣẹ fún ọ, Aaroni arákùnrin rẹ yóò sísọ fún Farao kí ó jẹ́ kí àwọn ọmọ Israẹli jáde kúrò ni ilẹ̀ rẹ̀.
Kâ na poe e naw pueng hah nang ni bout na dei han. Faro siangpahrang ni Isarelnaw hah a ram dawk hoi a tâco sak nahanlah na hmau Aron ni ahni koe a dei pouh han.
3 Ṣùgbọ́n èmi yóò sé Farao lọ́kàn le. Bí Mo tilẹ̀ ṣe ọ̀pọ̀lọpọ̀ iṣẹ́ àmì àti ìyanu ni Ejibiti,
Kai ni hai Faro e lung ka pata sak vaiteh, Izip ram dawk kaie kângairu mitnoutnaw hah ka pung sak han.
4 síbẹ̀ òun kì yóò fi etí sí ọ. Nígbà náà ni Èmi yóò gbé ọwọ́ mi lé Ejibiti, pẹ̀lú agbára ìdájọ́ ńlá mi ni èmi yóò mú àwọn ènìyàn mi Israẹli jáde ní ọ̀wọ̀ọ̀wọ́.
Hateiteh, Faro siangpahrang ni nangmae lawk hah ngâi laipalah ao han. Kai ni hai Izip ram lathueng ka kut ka dâw vaiteh, kalenpounge lacik hoi ka ransahu, ka tami Isarelnaw hah Izip ram hoi ka tâcokhai han.
5 Àwọn ará Ejibiti yóò sì mọ̀ pé Èmi ni Olúwa ní ìgbà tí mo bá na ọwọ́ mi jáde lé Ejibiti, tí mo sì mú àwọn ọmọ Israẹli jáde kúrò níbẹ̀.”
Hottelah, Izip ram lathueng ka kut ka dâw vaiteh, Isarelnaw ahnimouh koehoi ka tâcokhai toteh, Kai teh BAWIPA doeh tie Izipnaw ni a panue awh han telah Mosi koe atipouh.
6 Mose àti Aaroni sì ṣe gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún wọn.
Mosi hoi Aron ni BAWIPA e kâpoelawk patetlah a sak roi.
7 Mose jẹ́ ọmọ ọgọ́rin ọdún Aaroni sì jẹ́ ọmọ ọdún mẹ́tàlélọ́gọ́rin ni ìgbà tí wọ́n bá Farao sọ̀rọ̀.
Faro koe a dei pouh roi navah, Mosi teh a kum 80, Aron teh a kum 83 touh a pha roi.
8 Olúwa sọ fún Mose àti Aaroni,
BAWIPA ni Mosi hoi Aron koe bout a dei pouh e teh,
9 “Ní ìgbà tí Farao bá sọ fún un yín pé, ‘Ẹ ṣe iṣẹ́ ìyanu kan,’ sọ fún Aaroni ní ìgbà náà pé, ‘Mú ọ̀pá rẹ kí ó sì sọ ọ́ sílẹ̀ níwájú Farao,’ yóò sì di ejò.”
Faro siangpahrang ni nangmouh koe kângairuhno na patue haw tetpawiteh, na sonron hah lat nateh a hmalah tâkhawng pouh telah Aron koe a dei pouh. Sonron haiyah tahrun lah a kangcoung han telah atipouh.
10 Nígbà náà ni Mose àti Aaroni tọ Farao lọ, wọ́n sì ṣe bí Olúwa ti pàṣẹ fún wọn, Aaroni ju ọ̀pá rẹ̀ sílẹ̀ ní iwájú Farao àti àwọn ìjòyè rẹ̀, ọ̀pá náà sì di ejò.
Mosi hoi Aron ni Faro siangpahrang koe a kâen roi teh BAWIPA ni a dei e patetlah a sak pouh roi. Aron ni Faro siangpahrang hoi a sannaw e hmalah sonron a tâkhawng teh tahrun lah a kangcoung.
11 Farao sì pe àwọn amòye, àwọn oṣó àti àwọn onídán ilẹ̀ Ejibiti jọ, wọ́n sì fi idán wọn ṣe ohun tí Mose àti Aaroni ṣe.
Hat navah, Faro siangpahrang ni lungkaangnaw camkathoumnaw hah a kaw teh Izip ram e mitpaleikathoumnaw nihai, hot patetlah a sak awh.
12 Ẹnìkọ̀ọ̀kan wọn sọ ọ̀pá rẹ̀ sílẹ̀, ọ̀pá náà sì di ejò. Ṣùgbọ́n ọ̀pá Aaroni gbé ọ̀pá tiwọn mì.
A sin awh e sonronnaw hah a tâkhawng awh teh tahrun lah a kangcoung awh. Hateiteh, Aron e sonron ni ahnimae sonronnaw hah koung a payawp.
13 Síbẹ̀ ọkàn Farao sì yigbì, kò si fetí sí wọn gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti sọ.
BAWIPA ni a dei e patetlah Faro siangpahrang teh a lungpata sak teh, ahnimae lawk hah ngâi laipalah ao.
14 Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Mose pé, “Ọkàn Farao ti di líle, ó kọ̀ láti jẹ́ kí àwọn ènìyàn náà ó lọ.
BAWIPA nihai, Faro siangpahrang e lung a pata sak teh Isarelnaw hah tâcawt sak hoeh.
15 Tọ Farao lọ ni òwúrọ̀ kùtùkùtù bí ó ti ń lọ sí etí odò, dúró ni etí bèbè odò Naili láti pàdé rẹ, mú ọ̀pá rẹ tí ó di ejò ni ọwọ́ rẹ.
Amom vah, Faro siangpahrang koe cet haw. Ahni ni tui namran lah a cei han. Ahni a pha hoehnahlan tuipui namran lah kangdout haw. Tahrun lah kangcoung e sonron hah na kut dawk sin haw.
16 Sọ fún un pé, ‘Olúwa Ọlọ́run àwọn Heberu rán mi sí ọ láti sọ fún ọ pé, Jẹ́ kí àwọn ènìyàn mi kí ó lọ, kí wọn kí ó lè sìn mi ni aginjù. Ṣùgbọ́n títí di àkókò yìí, ìwọ kò gba.
Hebru miphunnaw e Cathut Jehovah ni kaie taminaw ni kahrawng vah Kai na bawk hanelah, ahnimouh hah tâcawt sak leih telah kai heh nang koe na patoun toe. Nang ni atu totouh ngâi laipalah na o awh rah.
17 Èyí ni Olúwa wí, nípa èyí ni ìwọ yóò mọ̀ pé Èmi ni Olúwa. Wò ó, èmi yóò fi ọ̀pá ti ó wà ní ọwọ́ mi, èmi yóò ná omi tí ó wà nínú odò Naili yóò sì di ẹ̀jẹ̀.
BAWIPA ni Kai teh BAWIPA doeh tie hah nang ni bangtelamaw na panue thai han tetpawiteh, ka sin e sonron hoi tuipui ka hem vaiteh hote tui teh thi lah a coung han.
18 Àwọn ẹja tí ó wà nínú odò Naili yóò kú, odò náà yóò sì máa rùn, àwọn ará Ejibiti kò sì ni lè mu omi rẹ̀.’”
Tuipui dawk kaawm e tanganaw a due awh han. Tuipui hai a hmui a tho han. Izipnaw ni tuipui tui a panuet awh han. Akong hah bout dei pouh telah Mosi koe atipouh.
19 Olúwa sọ fún Mose, “Sọ fún Aaroni, ‘Mú ọ̀pá rẹ kí ó sì na ọwọ́ rẹ jáde lórí àwọn omi Ejibiti. Lórí àwọn odò kéékèèké àti odò ńlá, lórí àbàtà àti adágún omi, wọn yóò sì di ẹ̀jẹ̀.’ Ẹ̀jẹ̀ yóò wà ni ibi gbogbo ni Ejibiti, àní nínú ọpọ́n àti nínú kete omi àti nínú ìkòkò tí a pọn omi sí nínú ilé.”
BAWIPA ni Mosi koe bout a dei pouh e teh, Aron koe, na sonron sin nateh Izip ram kaawm e palang, tuipui, tuikamuem tui, tuido hoi tuiphueknaw pueng e lathueng vah kut dâw haw. Izip ram pueng dawk thing manang, talung hlaamnaw pueng dawk thi ao hane kong hah dei pouh telah atipouh.
20 Mose àti Aaroni sí ṣe gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún wọn. Ó gbé ọ̀pá rẹ̀ sókè ni iwájú Farao àti àwọn ìjòyè rẹ̀, ó sì lu omi odò Naili, omi odò náà sì yípadà sí ẹ̀jẹ̀.
Mosi hoi Aron ni BAWIPA ni a dei e patetlah a sak roi teh, Aron ni Faro siangpahrang hoi a sannaw e hmalah sonron a pho teh tuipui a hem teh tui pueng teh thi lah a coung.
21 Ẹja inú odò Naili sì kú, odò náà ń rùn gidigidi tí ó fi jẹ́ pé àwọn ará Ejibiti kò le è mu omi inú rẹ̀. Ẹ̀jẹ̀ sì wà ni ibi gbogbo ni ilẹ̀ Ejibiti.
Tuipui dawk kaawm e tanganaw hai a due. Tuipui teh a hmui a tho dawkvah Izip taminaw ni tuipui hah net thai awh hoeh. Izip ram pueng dawk thi hah koung ao.
22 Ṣùgbọ́n àwọn apidán ilẹ̀ Ejibiti sì ṣe bákan náà pẹ̀lú agbára òkùnkùn wọn, ọkàn Farao sì yigbì síbẹ̀ kò sì fetí sí wọn gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti sọ.
Izip miphun camkathoumnaw ni hai camthoumnae lahoi hottelah a sak awh. BAWIPA ni a dei tangcoung patetlah Faro siangpahrang teh a lungpata teh ahnimae lawk ngâi laipalah ao.
23 Dípò bẹ́ẹ̀, ó yíjú padà, ó sì lọ sí ààfin rẹ̀, kò sì jẹ́ kí àwọn nǹkan wọ̀nyí wà ni oókan àyà rẹ̀.
Faro teh a im a ban teh hote hnonaw hah a lungthin dawk tat hoeh.
24 Nígbà náà ni gbogbo àwọn ará Ejibiti bẹ̀rẹ̀ sí í gbẹ́ etí odò Naili láti wá omi tí wọn yóò mu, nítorí wọn kò le è mu omi tí ó wà nínú odò náà.
Hat navah, Izipnaw ni tuipui tui hah a nei thai awh hoeh dawkvah tui nei hane a hmu thai a nahanlah tuipui rai lah tui a tai awh.
25 Ọjọ́ méje sì kọjá ti Olúwa ti lu odò Naili.
BAWIPA ni tuipui a hem hnukkhu hnin sari touh aloum sak.

< Exodus 7 >