< Exodus 7 >

1 Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Mose pé, “Wò ó, Èmi ti ṣe ọ bí Ọlọ́run fún Farao, Aaroni arákùnrin rẹ ni yóò jẹ́ agbẹnusọ rẹ.
BOEIPA loh Moses te, “So lah, nang te Pharaoh taengah Pathen la kang khueh tih na maya Aaron te nang kah tonghma la om coeng.
2 Ìwọ yóò sì sọ ohun gbogbo tí Èmi ti pàṣẹ fún ọ, Aaroni arákùnrin rẹ yóò sísọ fún Farao kí ó jẹ́ kí àwọn ọmọ Israẹli jáde kúrò ni ilẹ̀ rẹ̀.
Nang kang uen boeih te namah loh thui lamtah na maya Aaron loh Pharaoh taengah thui saeh. Te vaengah Israel ca rhoek te a khohmuen lamloh a hlah bitni.
3 Ṣùgbọ́n èmi yóò sé Farao lọ́kàn le. Bí Mo tilẹ̀ ṣe ọ̀pọ̀lọpọ̀ iṣẹ́ àmì àti ìyanu ni Ejibiti,
Tedae kai loh Pharaoh kah lungbuei te ka mangkhak sak vetih ka miknoek neh kai kah kopoekrhai he Egypt khohmuen ah ka ping sak ni.
4 síbẹ̀ òun kì yóò fi etí sí ọ. Nígbà náà ni Èmi yóò gbé ọwọ́ mi lé Ejibiti, pẹ̀lú agbára ìdájọ́ ńlá mi ni èmi yóò mú àwọn ènìyàn mi Israẹli jáde ní ọ̀wọ̀ọ̀wọ́.
Te lalah nang ol te Pharaoh loh hnatun pawt cakhaw ka kut he Egypt soah ka hlah ni. Te vaengah tholhphu tanglue a paek rhangneh ka pilnam Israel ca Egypt khohmuen lamloh ka caempuei la ka khuen ni.
5 Àwọn ará Ejibiti yóò sì mọ̀ pé Èmi ni Olúwa ní ìgbà tí mo bá na ọwọ́ mi jáde lé Ejibiti, tí mo sì mú àwọn ọmọ Israẹli jáde kúrò níbẹ̀.”
Egypt te ka kut ka hlah thil tih Israel ca te amih khui lamloh ka khuen vaengah Egypt loh kai he BOEIPA la a ming uh bitni,” a ti nah.
6 Mose àti Aaroni sì ṣe gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún wọn.
A saii vaengah khaw BOEIPA kah a uen banglam ni Moses neh Aaron loh amih taengah a saii rhoi.
7 Mose jẹ́ ọmọ ọgọ́rin ọdún Aaroni sì jẹ́ ọmọ ọdún mẹ́tàlélọ́gọ́rin ni ìgbà tí wọ́n bá Farao sọ̀rọ̀.
Pharaoh taengah a voek rhoi vaengah he Moses te kum sawmrhet lo ca tih Aaron te kum sawmrhet kum thum lo ca coeng.
8 Olúwa sọ fún Mose àti Aaroni,
BOEIPA loh Moses neh Aaron te a voek tih,
9 “Ní ìgbà tí Farao bá sọ fún un yín pé, ‘Ẹ ṣe iṣẹ́ ìyanu kan,’ sọ fún Aaroni ní ìgbà náà pé, ‘Mú ọ̀pá rẹ kí ó sì sọ ọ́ sílẹ̀ níwájú Farao,’ yóò sì di ejò.”
“Pharaoh loh nangmih te m'voek tih, 'Nangmih kah kopoekrhai tueng sak,’ a ti. Te vaengah Aaron te,’ Na conghol te khuen laeh. Te phoeiah Pharaoh mikhmuh ah tloeng lamtah tuihnam la poeh bitni,” a ti nah.
10 Nígbà náà ni Mose àti Aaroni tọ Farao lọ, wọ́n sì ṣe bí Olúwa ti pàṣẹ fún wọn, Aaroni ju ọ̀pá rẹ̀ sílẹ̀ ní iwájú Farao àti àwọn ìjòyè rẹ̀, ọ̀pá náà sì di ejò.
Te dongah Moses neh Aaron te Pharaoh taengah cet rhoi tih BOEIPA loh a uen vanbangla a saii rhoi. Te vaengah Aaron loh a conghol te Pharaoh mikhmuh neh a sal rhoek mikhmuh ah a voeih pah tih tuihnam la poeh.
11 Farao sì pe àwọn amòye, àwọn oṣó àti àwọn onídán ilẹ̀ Ejibiti jọ, wọ́n sì fi idán wọn ṣe ohun tí Mose àti Aaroni ṣe.
Pharaoh long khaw hlangcueih neh hlangbi rhoek te a khue. Amih Egypt hmayuep rhoek long khaw amamih kah hmaitak neh phek a saii uh.
12 Ẹnìkọ̀ọ̀kan wọn sọ ọ̀pá rẹ̀ sílẹ̀, ọ̀pá náà sì di ejò. Ṣùgbọ́n ọ̀pá Aaroni gbé ọ̀pá tiwọn mì.
Hlang loh a conghol tah a voeih uh tih tuihnam la poeh ngawn dae Aaron kah conghol loh amih kah conghol te a dolh pah.
13 Síbẹ̀ ọkàn Farao sì yigbì, kò si fetí sí wọn gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti sọ.
Te phoeiah Pharaoh kah lungbuei tah mangkhak pueng tih BOEIPA kah a thui bangla amih rhoi ol te hnatun pawh.
14 Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Mose pé, “Ọkàn Farao ti di líle, ó kọ̀ láti jẹ́ kí àwọn ènìyàn náà ó lọ.
Te phoeiah BOEIPA loh Moses te, “Pharaoh kah lungbuei tah thah tih pilnam te hlah ham a aal.
15 Tọ Farao lọ ni òwúrọ̀ kùtùkùtù bí ó ti ń lọ sí etí odò, dúró ni etí bèbè odò Naili láti pàdé rẹ, mú ọ̀pá rẹ tí ó di ejò ni ọwọ́ rẹ.
Pharaoh te mincang ah a paan rhoi. Tui taengla a pawk vaengah sokko soktaeng ah anih tong ham ana pai rhoi ne. Te vaengah rhul la aka poeh conghol te na kut dongah khuen rhoi.
16 Sọ fún un pé, ‘Olúwa Ọlọ́run àwọn Heberu rán mi sí ọ láti sọ fún ọ pé, Jẹ́ kí àwọn ènìyàn mi kí ó lọ, kí wọn kí ó lè sìn mi ni aginjù. Ṣùgbọ́n títí di àkókò yìí, ìwọ kò gba.
Te phoeiah anih te, 'Hebrew kah Pathen Yahweh loh nang taengah kai he n'tueih tih, 'Ka pilnam te tueih lamtah khosoek ah kai ham thothueng uh saeh,’ a ti. Tedae tahae duela na hnatun moenih ko he.
17 Èyí ni Olúwa wí, nípa èyí ni ìwọ yóò mọ̀ pé Èmi ni Olúwa. Wò ó, èmi yóò fi ọ̀pá ti ó wà ní ọwọ́ mi, èmi yóò ná omi tí ó wà nínú odò Naili yóò sì di ẹ̀jẹ̀.
BOEIPA loh he ni a thui. He nen ni kai he BOEIPA la na ming eh. Ka kut dongkah conghol neh sokko kah tui te ka boh vetih thii la poeh pawn ni he.
18 Àwọn ẹja tí ó wà nínú odò Naili yóò kú, odò náà yóò sì máa rùn, àwọn ará Ejibiti kò sì ni lè mu omi rẹ̀.’”
Sokko kah nga te duek vetih sokko te rhim ni. Sokko lamkah tui a ok ham vaengah Egypt rhoek te khobing uh ni,’ ti nah,” a ti nah.
19 Olúwa sọ fún Mose, “Sọ fún Aaroni, ‘Mú ọ̀pá rẹ kí ó sì na ọwọ́ rẹ jáde lórí àwọn omi Ejibiti. Lórí àwọn odò kéékèèké àti odò ńlá, lórí àbàtà àti adágún omi, wọn yóò sì di ẹ̀jẹ̀.’ Ẹ̀jẹ̀ yóò wà ni ibi gbogbo ni Ejibiti, àní nínú ọpọ́n àti nínú kete omi àti nínú ìkòkò tí a pọn omi sí nínú ilé.”
BOEIPA loh Moses taengah, “Aaron te, 'Na conghol khuen lamtah Egypt tui so neh a tuiva soah, a sokko so neh a tuibap ah, a tui tungnah boeih soah na kut thueng pah. Te vaengah thii la poeh vetih Egypt khohmuen tom ah thing khuikah neh lungto khuikah khaw thii la poeh ni, 'ti nah,” a ti nah.
20 Mose àti Aaroni sí ṣe gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún wọn. Ó gbé ọ̀pá rẹ̀ sókè ni iwájú Farao àti àwọn ìjòyè rẹ̀, ó sì lu omi odò Naili, omi odò náà sì yípadà sí ẹ̀jẹ̀.
Moses neh Aaron loh BOEIPA kah a uen bangla a saii rhoi. Conghol te a thueng tih Pharaoh mikhmuh neh a sal rhoek mikhmuh ah sokko kah tui te a boh. Te vaengah sokko kah tui boeih te thii la poeh.
21 Ẹja inú odò Naili sì kú, odò náà ń rùn gidigidi tí ó fi jẹ́ pé àwọn ará Ejibiti kò le è mu omi inú rẹ̀. Ẹ̀jẹ̀ sì wà ni ibi gbogbo ni ilẹ̀ Ejibiti.
Te vaengah sokko kah nga khaw duek tih sokko te rhim coeng. Te dongah Egypt rhoek loh sokko lamkah tui ok ham coeng voel pawh. Egypt khohmuen tom ah thii om.
22 Ṣùgbọ́n àwọn apidán ilẹ̀ Ejibiti sì ṣe bákan náà pẹ̀lú agbára òkùnkùn wọn, ọkàn Farao sì yigbì síbẹ̀ kò sì fetí sí wọn gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti sọ.
Tedae Egypt hmayuep rhoek long khaw a tuisiduei neh a saii uh van. Te dongah Pharaoh kah lungbuei mangkhak tih BOEIPA kah a thui bangla amih rhoi ol te hnatun pawh.
23 Dípò bẹ́ẹ̀, ó yíjú padà, ó sì lọ sí ààfin rẹ̀, kò sì jẹ́ kí àwọn nǹkan wọ̀nyí wà ni oókan àyà rẹ̀.
Pharaoh te mael tih amah im la a pawk phoeiah tah he he a lungbuei ah dueh pawh.
24 Nígbà náà ni gbogbo àwọn ará Ejibiti bẹ̀rẹ̀ sí í gbẹ́ etí odò Naili láti wá omi tí wọn yóò mu, nítorí wọn kò le è mu omi tí ó wà nínú odò náà.
Sokko tui te ok ham a coeng pawt dongah, ok ham tui te Egypt pum loh sokko kaepvai ah a too.
25 Ọjọ́ méje sì kọjá ti Olúwa ti lu odò Naili.
BOEIPA loh sokko a ngawn te ahnukah hnin rhih a cup sak.

< Exodus 7 >