< Exodus 6 >
1 Nígbà náà ní Olúwa sọ fún Mose pé, “Ní ìsin yìí, ìwọ yóò rí ohun tí èmi yóò ṣe sí Farao pẹ̀lú ọwọ́ agbára ńlá mi ni yóò fi jẹ́ kí wọn lọ; pẹ̀lú ọwọ́ agbára ńlá mi, òun yóò lé wọn jáde kúrò ní orílẹ̀-èdè rẹ̀.”
А Господ рече Мојсију: Сад ћеш видети шта ћу учинити Фараону; јер под руком крепком пустиће их, и истераће их из земље своје под руком крепком.
2 Ọlọ́run sì tún sọ fún Mose pé, “Èmi ni Olúwa.
Још говори Бог Мојсију и рече му: Ја сам Господ.
3 Mo fi ara hàn Abrahamu, Isaaki àti Jakọbu bí Ọlọ́run alágbára, ṣùgbọ́n nípa orúkọ mi Olúwa, Èmi kò fi ara mi hàn wọ́n.
И јавио сам се Авраму, Исаку и Јакову именом Бог Свемогући, а именом својим, Господ, не бих им познат.
4 Èmí sì tún fi ìdí májẹ̀mú mi múlẹ̀ pẹ̀lú wọn láti fún wọn ní ilẹ̀ Kenaani, ilẹ̀ tí wọn gbé gẹ́gẹ́ bí àjèjì.
И учиних завет свој с њима да ћу им дати земљу хананску, земљу у којој беху дошљаци, у којој живљаху као странци.
5 Èmi sì ti tún gbọ́ kíkùn àwọn ọmọ Israẹli àwọn tí àwọn ará Ejibiti mú gẹ́gẹ́ bí ẹrú, àti pé èmi sì ti rántí májẹ̀mú mi.
И чух уздисање синова Израиљевих, које Мисирци држе у ропству, и опоменух се завета свог.
6 “Sọ fún àwọn ará ilé Israẹli, ‘Èmi ni Olúwa, Èmi yóò sọ yín di òmìnira kúrò nínú àjàgà àwọn ará Ejibiti. Èmi yóò sì gbà yín sílẹ̀ kúrò ní oko ẹrú wọn. Èmi yóò dá a yín sílẹ̀ pẹ̀lú apá nínà (àwọn iṣẹ́ ìyanu) àti pẹ̀lú ìdájọ́ ńlá.
Зато кажи синовима Израиљевим: Ја сам Господ, и извешћу вас испод бремена мисирских, и опростићу вас ропства њиховог, и избавићу вас мишицом подигнутом и судовима великим.
7 Èmi yóò mú un yín bí ènìyàn mi, èmi yóò sì jẹ́ Ọlọ́run yín. Nígbà náà ni ẹ̀yin yóò mọ̀ pé, èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín, ẹni tí ó mú un yín jáde kúrò nínú àjàgà àwọn ará Ejibiti.
И узећу вас да ми будете народ, и ја ћу вам бити Бог, те ћете познати да сам ја Господ Бог ваш, који вас изводим испод бремена мисирских.
8 Èmi yóò mú un yín wá ilẹ̀ náà ti èmi ti búra pẹ̀lú ìgbọ́wọ́sókè láti fi fún Abrahamu. Isaaki àti Jakọbu. Èmi yóò fi fún un yín bí ohun ìní, Èmi ni Olúwa.’”
Пак ћу вас одвести у своју земљу, за коју подигох руку своју заклињући се да ћу је дати Авраму, Исаку и Јакову; и даћу вам је у наследство, ја Господ.
9 Mose sì sọ èyí fún àwọn ará Israẹli, ṣùgbọ́n wọn kò fi etí sílẹ̀ sí Mose nítorí ọkàn wọn tó rẹ̀wẹ̀sì àti nítorí ìgbèkùn búburú bí ohun tí ó ti kọ́ sọ kó wọn sí ní oko ẹrú wọn.
И Мојсије каза тако синовима Израиљевим; али не послушаше Мојсија од слабости духа свог и од љутог ропства.
10 Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Mose.
И Господ рече Мојсију говорећи:
11 “Lọ, sọ fún Farao ọba Ejibiti pé kí ó jẹ́ kí àwọn ará Israẹli lọ kúrò ní orílẹ̀-èdè rẹ̀.”
Иди, кажи Фараону, цару мисирском, нека пусти синове Израиљеве из земље своје.
12 Ṣùgbọ́n Mose sọ fún Olúwa pé, “Nígbà ti àwọn ará Israẹli tó jẹ́ ènìyàn mi kó fetí sí ọ̀rọ̀ mi, báwo ni Farao yóò ṣe fetí sí ọ̀rọ̀ mi, nígbà ti mo jẹ́ akólòlò?”
А Мојсије проговори пред Господом и рече: Ето, синови Израиљеви не послушаше ме, а како ће ме послушати Фараон, кад сам необрезаних усана?
13 Olúwa bá ìran Mose àti Aaroni sọ̀rọ̀ nípa àwọn ará Israẹli àti Farao ọba Ejibiti, ó pàṣẹ fún wọn pé kí wọn kó àwọn Israẹli jáde kúrò ni ilẹ̀ Ejibiti.
Али Господ говори Мојсију и Арону, и заповеди им да иду к синовима Израиљевим и к Фараону, да изведу синове Израиљеве из земље мисирске.
14 Wọ̀nyí ni olórí ìran wọn: àwọn ọmọ Reubeni àkọ́bí Israẹli ni: Hanoku, Pallu, Hesroni àti Karmi. Àwọn wọ̀nyí ni ìdílé Reubeni.
Ово су поглавице у домовима отаца својих: синови Рувима, првенца Израиљевог: Енох и Фалуј, Асрон и Хармија; то су породице Рувимове.
15 Àwọn ọmọ Simeoni ni: Jemueli, Jamini, Ohadi, Jakini, Sohari àti Saulu ọmọ obìnrin Kenaani. Àwọn wọ̀nyí ni ìran Simeoni.
А синови Симеунови: Јемуило и Јамин и Аод и Ахин и Сар и Саул, син неке Хананејке; то су породице Симеунове.
16 Ìwọ̀nyí ni orúkọ àwọn ọmọ Lefi gẹ́gẹ́ bí àkọsílẹ̀ wọn: Gerṣoni, Kohati àti Merari. Lefi lo ẹ̀tàdínlógóje ọdún láyé.
А ово су имена синова Левијевих по породицама њиховим: Гирсон и Кат и Мерарије; а Левије поживе сто и тридесет и седам година.
17 Àwọn ọmọ Gerṣoni ni ìran wọn ni: Libni àti Ṣimei.
А ово су синови Гирсонови: Ловеније и Семеј по породицама својим.
18 Àwọn ọmọ Kohati ni: Amramu, Isari, Hebroni àti Usieli. Kohati lo ẹ̀tàléláádóje ọdún láyé.
А синови Катови: Амрам и Исар и Хеврон и Озило; а Кат поживе сто и тридесет и три године.
19 Àwọn ọmọ Merari ni: Mahili àti Muṣi. Ìwọ̀nyí ni ìran Lefi gẹ́gẹ́ bí àkọsílẹ̀ wọn.
А синови Мераријеви: Молија и Мусија. То су породице Левијеве по лозама својим.
20 Amramu sì fẹ́ Jokebedi arábìnrin baba rẹ̀ ní ìyàwó. Jokebedi sì bí Aaroni àti Mose fún un. Amramu lo ẹ̀tàdínlógóje ọdún láyé.
А Амрам се ожени Јохаведом братучедом својом, и она му роди Арона и Мојсија. А поживе Амрам сто и тридесет и седам година.
21 Àwọn ọmọ Isari ni: Kora, Nefegi àti Sikri.
А синови Исарови беху: Кореј и Нафек и Зехрија.
22 Àwọn ọmọ Usieli ni: Miṣaeli, Elsafani àti Sitiri.
А синови Озилови: Мисаило и Елисафан и Сегрија.
23 Aaroni fẹ́ Eliṣeba ọmọbìnrin Amminadabu tí í ṣe arábìnrin Nahiṣoni, ó sì bí Nadabu, Abihu, Eleasari àti Itamari.
А Арон се ожени Јелисаветом кћерју Аминадавовом, сестром Насоновом; и она му роди Надава и Авијуда и Елеазара и Итамара.
24 Àwọn ọmọ Kora ni: Asiri, Elkana àti Abiasafu. Ìwọ̀nyí ni ìran Kora.
А синови Корејеви беху: Асир и Елкана и Авијасар. То су породице Корејеве.
25 Eleasari ọmọ Aaroni fẹ́ ọ̀kan lára àwọn ọmọbìnrin Putieli ní ìyàwó, ó sì bí Finehasi fún un. Ìwọ̀nyí ni olórí àwọn Lefi ni ìdílé ìdílé.
И Елеазар, син Аронов, ожени се једном од кћери Футилових, и она му роди Финеса. То су поглавице између отаца левитских по својим породицама.
26 Aaroni àti Mose yìí kan náà ni Olúwa sọ fún pé, “Ẹ kó àwọn ará Israẹli jáde kúrò ni ilẹ̀ Ejibiti ní ìsọ̀rí ìsọ̀rí.”
То је Арон и Мојсије, којима рече Господ: Изведите синове Израиљеве из земље мисирске у четама њиховим.
27 Àwọn ni ó bá Farao ọba Ejibiti sọ̀rọ̀ nípa kíkó àwọn ará Israẹli jáde kúrò ni Ejibiti, àní Mose àti Aaroni yìí kan náà ni.
То су који говорише Фараону, цару мисирском, да изведу синове Израиљеве из Мисира; то је Мојсије и то је Арон.
28 Nígbà tí Olúwa bá Mose sọ̀rọ̀ ni Ejibiti,
И кад Господ говораше Мојсију у земљи мисирској,
29 Olúwa sì sọ fún Mose pé, “Èmi ni Olúwa. Sọ ohun gbogbo ti mo ti sọ fún ọ fún Farao ọba Ejibiti.”
Рече Господ Мојсију говорећи: Ја сам Господ; кажи Фараону цару мисирском све што сам ти казао.
30 Ṣùgbọ́n Mose sì wí ní iwájú Olúwa pé, “Níwọ́n ìgbà ti mo jẹ́ akólòlò, ọ̀nà dà ti Farao yóò ṣe fi etí sí mi?”
И Мојсије рече пред Господом: Ево сам необрезаних усана, па како ће ме послушати Фараон?