< Exodus 6 >

1 Nígbà náà ní Olúwa sọ fún Mose pé, “Ní ìsin yìí, ìwọ yóò rí ohun tí èmi yóò ṣe sí Farao pẹ̀lú ọwọ́ agbára ńlá mi ni yóò fi jẹ́ kí wọn lọ; pẹ̀lú ọwọ́ agbára ńlá mi, òun yóò lé wọn jáde kúrò ní orílẹ̀-èdè rẹ̀.”
Az Úr pedig monda Mózesnek: Majd meglátod mit cselekszem a Faraóval; mert hatalmas kéz miatt kell őket elbocsátani és hatalmas kéz miatt űzi el őket az ő földéről.
2 Ọlọ́run sì tún sọ fún Mose pé, “Èmi ni Olúwa.
Az Isten pedig szóla Mózeshez és monda néki: Én vagyok az Úr.
3 Mo fi ara hàn Abrahamu, Isaaki àti Jakọbu bí Ọlọ́run alágbára, ṣùgbọ́n nípa orúkọ mi Olúwa, Èmi kò fi ara mi hàn wọ́n.
Ábrahámnak, Izsáknak és Jákóbnak úgy jelentem meg mint mindenható Isten, de az én Jehova nevemen nem voltam előttük ismeretes.
4 Èmí sì tún fi ìdí májẹ̀mú mi múlẹ̀ pẹ̀lú wọn láti fún wọn ní ilẹ̀ Kenaani, ilẹ̀ tí wọn gbé gẹ́gẹ́ bí àjèjì.
Szövetséget is kötöttem velek, hogy nékik adom a Kanaán földét, az ő tartózkodásuk földét, a melyen tartózkodjanak.
5 Èmi sì ti tún gbọ́ kíkùn àwọn ọmọ Israẹli àwọn tí àwọn ará Ejibiti mú gẹ́gẹ́ bí ẹrú, àti pé èmi sì ti rántí májẹ̀mú mi.
Fohászkodását is meghallottam az Izráel fiainak a miatt, hogy az Égyiptombeliek szolgálatra szorítják őket, megemlékeztem az én szövetségemről.
6 “Sọ fún àwọn ará ilé Israẹli, ‘Èmi ni Olúwa, Èmi yóò sọ yín di òmìnira kúrò nínú àjàgà àwọn ará Ejibiti. Èmi yóò sì gbà yín sílẹ̀ kúrò ní oko ẹrú wọn. Èmi yóò dá a yín sílẹ̀ pẹ̀lú apá nínà (àwọn iṣẹ́ ìyanu) àti pẹ̀lú ìdájọ́ ńlá.
Annakokáért mondd meg az Izráel fiainak: Én vagyok az Úr és kiviszlek titeket Égyiptom nehéz munkái alól és megszabadítlak titeket az ő szolgálatjoktól és megmentlek titeket kinyújtott karral és nagy büntető ítéletek által.
7 Èmi yóò mú un yín bí ènìyàn mi, èmi yóò sì jẹ́ Ọlọ́run yín. Nígbà náà ni ẹ̀yin yóò mọ̀ pé, èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín, ẹni tí ó mú un yín jáde kúrò nínú àjàgà àwọn ará Ejibiti.
És népemmé fogadlak titeket s Istentekké lészek néktek és megtudjátok, hogy én vagyok a ti Uratok Istentek, a ki kihoztalak titeket Égyiptom nehéz munkái alól.
8 Èmi yóò mú un yín wá ilẹ̀ náà ti èmi ti búra pẹ̀lú ìgbọ́wọ́sókè láti fi fún Abrahamu. Isaaki àti Jakọbu. Èmi yóò fi fún un yín bí ohun ìní, Èmi ni Olúwa.’”
És béviszlek titeket a földre, a mely felől esküre emeltem fel kezemet, hogy Ábrahámnak, Izsáknak és Jákóbnak adom azt, és néktek adom azt örökségül, én az Úr.
9 Mose sì sọ èyí fún àwọn ará Israẹli, ṣùgbọ́n wọn kò fi etí sílẹ̀ sí Mose nítorí ọkàn wọn tó rẹ̀wẹ̀sì àti nítorí ìgbèkùn búburú bí ohun tí ó ti kọ́ sọ kó wọn sí ní oko ẹrú wọn.
Eképen szóla Mózes az Izráel fiaihoz; de nem hallgatának Mózesre, a kislelkűség és a kemény szolgálat miatt.
10 Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Mose.
Az Úr pedig szóla Mózeshez mondván:
11 “Lọ, sọ fún Farao ọba Ejibiti pé kí ó jẹ́ kí àwọn ará Israẹli lọ kúrò ní orílẹ̀-èdè rẹ̀.”
Eredj be, szólj a Faraónak, Égyiptom királyának, hogy bocsássa el Izráel fiait az ő földéről.
12 Ṣùgbọ́n Mose sọ fún Olúwa pé, “Nígbà ti àwọn ará Israẹli tó jẹ́ ènìyàn mi kó fetí sí ọ̀rọ̀ mi, báwo ni Farao yóò ṣe fetí sí ọ̀rọ̀ mi, nígbà ti mo jẹ́ akólòlò?”
Mózes pedig szóla az Úr előtt, mondván: Ímé Izráel fiai nem hallgatnak reám, hogy hallgatna hát reám a Faraó, holott én nehéz ajkú vagyok?
13 Olúwa bá ìran Mose àti Aaroni sọ̀rọ̀ nípa àwọn ará Israẹli àti Farao ọba Ejibiti, ó pàṣẹ fún wọn pé kí wọn kó àwọn Israẹli jáde kúrò ni ilẹ̀ Ejibiti.
És szóla az Úr Mózeshez és Áronhoz és rendelé őket Izráel fiaihoz és a Faraóhoz, Égyiptom királyához, hogy hozzák ki az Izráel fiait Égyiptom földéről.
14 Wọ̀nyí ni olórí ìran wọn: àwọn ọmọ Reubeni àkọ́bí Israẹli ni: Hanoku, Pallu, Hesroni àti Karmi. Àwọn wọ̀nyí ni ìdílé Reubeni.
Ezek atyáik házanépének fejei: Rúbennek, Izráel elsőszülöttének fiai: Khanókh, Pallu, Kheczrón és Karmi. Ezek a Rúben nemzetségei.
15 Àwọn ọmọ Simeoni ni: Jemueli, Jamini, Ohadi, Jakini, Sohari àti Saulu ọmọ obìnrin Kenaani. Àwọn wọ̀nyí ni ìran Simeoni.
Simeon fiai pedig: Jemúél, Jámin, Óhad, Jákin, Czohar és Saul, a kanaánbeli asszony fiai. Ezek a Simeon nemzetségei.
16 Ìwọ̀nyí ni orúkọ àwọn ọmọ Lefi gẹ́gẹ́ bí àkọsílẹ̀ wọn: Gerṣoni, Kohati àti Merari. Lefi lo ẹ̀tàdínlógóje ọdún láyé.
Ezek pedig a Lévi fiainak nevei az ő születésök szerint: Gersón, Kehát és Merári. Lévi életének esztendei pedig: száz harminczhét esztendő.
17 Àwọn ọmọ Gerṣoni ni ìran wọn ni: Libni àti Ṣimei.
Gersón fiai: Libni, Simhi, az ő nemzetségeik szerint.
18 Àwọn ọmọ Kohati ni: Amramu, Isari, Hebroni àti Usieli. Kohati lo ẹ̀tàléláádóje ọdún láyé.
Kehát fiai pedig: Amrám, Jiczhár, Khebrón és Huzziél. Kehát életének esztendei pedig: száz harminczhárom esztendő.
19 Àwọn ọmọ Merari ni: Mahili àti Muṣi. Ìwọ̀nyí ni ìran Lefi gẹ́gẹ́ bí àkọsílẹ̀ wọn.
Merári fiai pedig: Makhli és Músi. Ezek a Lévi nemzetségei az ő születésök szerint.
20 Amramu sì fẹ́ Jokebedi arábìnrin baba rẹ̀ ní ìyàwó. Jokebedi sì bí Aaroni àti Mose fún un. Amramu lo ẹ̀tàdínlógóje ọdún láyé.
Amrám pedig feleségűl vevé magának Jókébedet, atyjának húgát s ez szűlé néki Áront és Mózest. Amrám életének esztendei pedig száz harminczhét esztendő.
21 Àwọn ọmọ Isari ni: Kora, Nefegi àti Sikri.
Jiczhár fiai pedig: Kórákh, Nefeg és Zikri.
22 Àwọn ọmọ Usieli ni: Miṣaeli, Elsafani àti Sitiri.
Huzziél fiai pedig: Misáél, Elczáfán és Szithri.
23 Aaroni fẹ́ Eliṣeba ọmọbìnrin Amminadabu tí í ṣe arábìnrin Nahiṣoni, ó sì bí Nadabu, Abihu, Eleasari àti Itamari.
Áron pedig feleségűl vevé magának Elisebát, Aminádáb leányát, Nakhsón húgát s ez szűlé néki Nádábot, Abíhut, Eleázárt és Ithámárt.
24 Àwọn ọmọ Kora ni: Asiri, Elkana àti Abiasafu. Ìwọ̀nyí ni ìran Kora.
Kórákh fiai pedig: Asszir, Elkánáh és Abiászáf. Ezek a Kórákh nemzetségei.
25 Eleasari ọmọ Aaroni fẹ́ ọ̀kan lára àwọn ọmọbìnrin Putieli ní ìyàwó, ó sì bí Finehasi fún un. Ìwọ̀nyí ni olórí àwọn Lefi ni ìdílé ìdílé.
Eleázár pedig az Áron fia, a Putiél leányai közűl vőn magának feleséget s ez szűlé néki Fineást. Ezek a Léviták atyáinak fejei az ő nemzetségeik szerint.
26 Aaroni àti Mose yìí kan náà ni Olúwa sọ fún pé, “Ẹ kó àwọn ará Israẹli jáde kúrò ni ilẹ̀ Ejibiti ní ìsọ̀rí ìsọ̀rí.”
Ez Áron és Mózes, a kiknek mondá az Úr: Hozzátok ki az Izráel fiait Égyiptom földéről, az ő seregeik szerint.
27 Àwọn ni ó bá Farao ọba Ejibiti sọ̀rọ̀ nípa kíkó àwọn ará Israẹli jáde kúrò ni Ejibiti, àní Mose àti Aaroni yìí kan náà ni.
Ők azok, a kik szóltak a Faraónak Égyiptom királyának, hogy kihozhassák az Izráel fiait Égyiptomból. Ez Mózes és Áron.
28 Nígbà tí Olúwa bá Mose sọ̀rọ̀ ni Ejibiti,
És lőn a mikor szóla az Úr Mózesnek Égyiptom földén.
29 Olúwa sì sọ fún Mose pé, “Èmi ni Olúwa. Sọ ohun gbogbo ti mo ti sọ fún ọ fún Farao ọba Ejibiti.”
Így szóla az Úr Mózesnek, mondván: Én vagyok az Úr: mondd el a Faraónak Égyiptom királyának mindazt, a mit én szólok néked.
30 Ṣùgbọ́n Mose sì wí ní iwájú Olúwa pé, “Níwọ́n ìgbà ti mo jẹ́ akólòlò, ọ̀nà dà ti Farao yóò ṣe fi etí sí mi?”
Mózes pedig monda az Úr előtt: Ímé én nehéz ajakú vagyok, hogy hallgatna reám a Faraó?

< Exodus 6 >