< Exodus 6 >

1 Nígbà náà ní Olúwa sọ fún Mose pé, “Ní ìsin yìí, ìwọ yóò rí ohun tí èmi yóò ṣe sí Farao pẹ̀lú ọwọ́ agbára ńlá mi ni yóò fi jẹ́ kí wọn lọ; pẹ̀lú ọwọ́ agbára ńlá mi, òun yóò lé wọn jáde kúrò ní orílẹ̀-èdè rẹ̀.”
És mondta az Örökkévaló Mózesnek: Most fogod meglátni, hogy mit teszek Fáraóval, mert erős kéz által fogja őket elbocsátani és erős kéz által fogja őket elűzni országából.
2 Ọlọ́run sì tún sọ fún Mose pé, “Èmi ni Olúwa.
Szólt Isten Mózeshez és mondta neki: Én vagyok az Örökkévaló!
3 Mo fi ara hàn Abrahamu, Isaaki àti Jakọbu bí Ọlọ́run alágbára, ṣùgbọ́n nípa orúkọ mi Olúwa, Èmi kò fi ara mi hàn wọ́n.
Megjelentem Ábrahámnak, Izsáknak és Jákobnak mint Isten, mindenható, de nevemet: Örökkévaló, nem ismertettem meg velük.
4 Èmí sì tún fi ìdí májẹ̀mú mi múlẹ̀ pẹ̀lú wọn láti fún wọn ní ilẹ̀ Kenaani, ilẹ̀ tí wọn gbé gẹ́gẹ́ bí àjèjì.
És meg is kötöttem szövetségemet velük, hogy nekik adom Kánaán országát, az ő tartózkodásuk országát, amelyben tartózkodtak.
5 Èmi sì ti tún gbọ́ kíkùn àwọn ọmọ Israẹli àwọn tí àwọn ará Ejibiti mú gẹ́gẹ́ bí ẹrú, àti pé èmi sì ti rántí májẹ̀mú mi.
És hallottam is Izrael fiai jajkiáltását, mivelhogy az egyiptomiak szolgálatra szorítják őket és megemlékeztem szövetségemről.
6 “Sọ fún àwọn ará ilé Israẹli, ‘Èmi ni Olúwa, Èmi yóò sọ yín di òmìnira kúrò nínú àjàgà àwọn ará Ejibiti. Èmi yóò sì gbà yín sílẹ̀ kúrò ní oko ẹrú wọn. Èmi yóò dá a yín sílẹ̀ pẹ̀lú apá nínà (àwọn iṣẹ́ ìyanu) àti pẹ̀lú ìdájọ́ ńlá.
Azért mondd Izrael fiainak: Én vagyok az Örökkévaló, kivezetlek benneteket Egyiptom rabmunkái alól, megmentelek benneteket az ő szolgálatukból, megváltalak benneteket kinyújtott karral és nagy ítéletekkel.
7 Èmi yóò mú un yín bí ènìyàn mi, èmi yóò sì jẹ́ Ọlọ́run yín. Nígbà náà ni ẹ̀yin yóò mọ̀ pé, èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín, ẹni tí ó mú un yín jáde kúrò nínú àjàgà àwọn ará Ejibiti.
És veszlek benneteket magamnak népemül, én pedig leszek nektek Istenetek, hogy megtudjátok, hogy én vagyok az Örökkévaló, a ti Istenetek, aki kivezet benneteket Egyiptom rabmunkái alól.
8 Èmi yóò mú un yín wá ilẹ̀ náà ti èmi ti búra pẹ̀lú ìgbọ́wọ́sókè láti fi fún Abrahamu. Isaaki àti Jakọbu. Èmi yóò fi fún un yín bí ohun ìní, Èmi ni Olúwa.’”
És elviszlek benneteket az országba, melyre nézve felemeltem kezemet, hogy adom azt Ábrahámnak, Izsáknak és Jákobnak, és nektek adom azt örökségül, én az Örökkévaló.
9 Mose sì sọ èyí fún àwọn ará Israẹli, ṣùgbọ́n wọn kò fi etí sílẹ̀ sí Mose nítorí ọkàn wọn tó rẹ̀wẹ̀sì àti nítorí ìgbèkùn búburú bí ohun tí ó ti kọ́ sọ kó wọn sí ní oko ẹrú wọn.
És szólt Mózes Izrael fiaihoz ekképpen, de ők nem hallgattak? Mózesre kislelkűség és a kemény munka miatt.
10 Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Mose.
És szólt az Örökkévaló Mózeshez, mondván:
11 “Lọ, sọ fún Farao ọba Ejibiti pé kí ó jẹ́ kí àwọn ará Israẹli lọ kúrò ní orílẹ̀-èdè rẹ̀.”
Menj be, szólj Fáraóhoz, Egyiptom királyához, hogy bocsássa el Izrael fiait az országából.
12 Ṣùgbọ́n Mose sọ fún Olúwa pé, “Nígbà ti àwọn ará Israẹli tó jẹ́ ènìyàn mi kó fetí sí ọ̀rọ̀ mi, báwo ni Farao yóò ṣe fetí sí ọ̀rọ̀ mi, nígbà ti mo jẹ́ akólòlò?”
De szólt Mózes az Örökkévaló színe előtt mondván: Íme, Izrael fiai nem hallgattak rám, hogyan hallgatna meg Fáraó, holott én metéletlen ajkú vagyok?
13 Olúwa bá ìran Mose àti Aaroni sọ̀rọ̀ nípa àwọn ará Israẹli àti Farao ọba Ejibiti, ó pàṣẹ fún wọn pé kí wọn kó àwọn Israẹli jáde kúrò ni ilẹ̀ Ejibiti.
De az Örökkévaló szólt Mózeshez meg Áronhoz és parancsot adott nekik Izrael fiaihoz és Fáraóhoz, Egyiptom királyához, hogy vezessék ki Izrael fiait Egyiptom országából.
14 Wọ̀nyí ni olórí ìran wọn: àwọn ọmọ Reubeni àkọ́bí Israẹli ni: Hanoku, Pallu, Hesroni àti Karmi. Àwọn wọ̀nyí ni ìdílé Reubeni.
Ezek atyai házuk fejei: Rúbén, Izrael elsőszülöttjének fiai: Chánóch és Fállú, Checrón és Chármi; ezek Rúbén családjai.
15 Àwọn ọmọ Simeoni ni: Jemueli, Jamini, Ohadi, Jakini, Sohari àti Saulu ọmọ obìnrin Kenaani. Àwọn wọ̀nyí ni ìran Simeoni.
Simon fiai pedig: Jemúél, Jómiu, Ohód, Jóchin, Cóchár és Sóul, a kánaánita nő fia; ezek Simon családjai.
16 Ìwọ̀nyí ni orúkọ àwọn ọmọ Lefi gẹ́gẹ́ bí àkọsílẹ̀ wọn: Gerṣoni, Kohati àti Merari. Lefi lo ẹ̀tàdínlógóje ọdún láyé.
Ezek pedig Lévi fiainak nevei, nemzetségeik szerint: Gérsón, Kehosz és Meróri. Lévi életének évei pedig százharminchét év.
17 Àwọn ọmọ Gerṣoni ni ìran wọn ni: Libni àti Ṣimei.
Gérsón fiai: Livni és Símei családjaik szerint.
18 Àwọn ọmọ Kohati ni: Amramu, Isari, Hebroni àti Usieli. Kohati lo ẹ̀tàléláádóje ọdún láyé.
Kehosz fiai pedig: Ámrom, Jichor, Chevrón és Uziél; Kehosz életének évei pedig: százharminchárom év.
19 Àwọn ọmọ Merari ni: Mahili àti Muṣi. Ìwọ̀nyí ni ìran Lefi gẹ́gẹ́ bí àkọsílẹ̀ wọn.
Merori fiai pedig: Máchli és Músi; ezek Lévi családjai nemzetségeik szerint.
20 Amramu sì fẹ́ Jokebedi arábìnrin baba rẹ̀ ní ìyàwó. Jokebedi sì bí Aaroni àti Mose fún un. Amramu lo ẹ̀tàdínlógóje ọdún láyé.
És elvette Ámrom Jóchevedet, nagynénjét, magának feleségül és ez szülte neki Áront és Mózest; Ámrom életének évei pedig százharminckét év.
21 Àwọn ọmọ Isari ni: Kora, Nefegi àti Sikri.
Jichor fiai: Kórách, Nefeg és Zichri.
22 Àwọn ọmọ Usieli ni: Miṣaeli, Elsafani àti Sitiri.
Uzziél fiai pedig: Misóél; Elccófon és Sziszri.
23 Aaroni fẹ́ Eliṣeba ọmọbìnrin Amminadabu tí í ṣe arábìnrin Nahiṣoni, ó sì bí Nadabu, Abihu, Eleasari àti Itamari.
És elvette Áron Elisevát, Ámminódov leányát, Náchsón nővérét magának feleségül és ez szülte neki Nádábot, Ábihút, Eleázárt és Itámárt.
24 Àwọn ọmọ Kora ni: Asiri, Elkana àti Abiasafu. Ìwọ̀nyí ni ìran Kora.
Kórách fiai pedig: Ásszir, Elkóno és Aviószof; ezek a Korchi családjai.
25 Eleasari ọmọ Aaroni fẹ́ ọ̀kan lára àwọn ọmọbìnrin Putieli ní ìyàwó, ó sì bí Finehasi fún un. Ìwọ̀nyí ni olórí àwọn Lefi ni ìdílé ìdílé.
Eleázár, Áron fia pedig vett magának Pútiél leányai közül feleséget és ez szülte neki Pinchoszt; ezek a leviták atyáinak fejei, családjaik szerint.
26 Aaroni àti Mose yìí kan náà ni Olúwa sọ fún pé, “Ẹ kó àwọn ará Israẹli jáde kúrò ni ilẹ̀ Ejibiti ní ìsọ̀rí ìsọ̀rí.”
Ez Áron és Mózes, akiknek az Örökkévaló mondta: Vezessétek ki Izrael fiait Egyiptom országából, seregeik szerint;
27 Àwọn ni ó bá Farao ọba Ejibiti sọ̀rọ̀ nípa kíkó àwọn ará Israẹli jáde kúrò ni Ejibiti, àní Mose àti Aaroni yìí kan náà ni.
ők azok, akik szóltak Fáraóhoz, Egyiptom királyához, hogy kivezessék Izrael fiait Egyiptomból. Ez Mózes és Áron.
28 Nígbà tí Olúwa bá Mose sọ̀rọ̀ ni Ejibiti,
És történt az nap, midőn szólt az Örökkévaló Mózeshez, Egyiptom országában,
29 Olúwa sì sọ fún Mose pé, “Èmi ni Olúwa. Sọ ohun gbogbo ti mo ti sọ fún ọ fún Farao ọba Ejibiti.”
és szólt az Örökkévaló Mózeshez, mondván: Én vagyok az Örökkévaló! Mondd el Fáraónak, Egyiptom királyának mindazt, amit én mondok neked.
30 Ṣùgbọ́n Mose sì wí ní iwájú Olúwa pé, “Níwọ́n ìgbà ti mo jẹ́ akólòlò, ọ̀nà dà ti Farao yóò ṣe fi etí sí mi?”
De Mózes mondta az Örökkévaló színe előtt: Íme, én metéletlen ajkú vagyok, hogy hallgatna rám Fáraó?

< Exodus 6 >