< Exodus 6 >

1 Nígbà náà ní Olúwa sọ fún Mose pé, “Ní ìsin yìí, ìwọ yóò rí ohun tí èmi yóò ṣe sí Farao pẹ̀lú ọwọ́ agbára ńlá mi ni yóò fi jẹ́ kí wọn lọ; pẹ̀lú ọwọ́ agbára ńlá mi, òun yóò lé wọn jáde kúrò ní orílẹ̀-èdè rẹ̀.”
Ningĩ Jehova akĩĩra Musa atĩrĩ, “Rĩu nĩũkuona ũrĩa ngwĩka Firaũni: Nĩ tondũ wa guoko gwakwa kũrĩ hinya-rĩ, nĩakamarekereria mathiĩ; na ningĩ nĩ tondũ wa guoko gwakwa kũrĩ hinya, nĩakamaingata moime bũrũri wake.”
2 Ọlọ́run sì tún sọ fún Mose pé, “Èmi ni Olúwa.
Ngai agĩcooka akĩĩra Musa atĩrĩ, “Nĩ niĩ Jehova.
3 Mo fi ara hàn Abrahamu, Isaaki àti Jakọbu bí Ọlọ́run alágbára, ṣùgbọ́n nípa orúkọ mi Olúwa, Èmi kò fi ara mi hàn wọ́n.
Nĩ niĩ ndoimĩrĩire Iburahĩmu, na Isaaka, o na Jakubu ndĩ Mũrungu Mwene-Hinya-Wothe, no matiamenyire na rĩĩtwa rĩu rĩakwa Jehova.
4 Èmí sì tún fi ìdí májẹ̀mú mi múlẹ̀ pẹ̀lú wọn láti fún wọn ní ilẹ̀ Kenaani, ilẹ̀ tí wọn gbé gẹ́gẹ́ bí àjèjì.
O na nĩndathondekire kĩrĩkanĩro gĩakwa nao atĩ nĩngamahe bũrũri wa Kaanani, kũrĩa maatũũraga marĩ ageni.
5 Èmi sì ti tún gbọ́ kíkùn àwọn ọmọ Israẹli àwọn tí àwọn ará Ejibiti mú gẹ́gẹ́ bí ẹrú, àti pé èmi sì ti rántí májẹ̀mú mi.
Na makĩria-rĩ, nĩnjiguĩte gũcaaya kwa andũ a Isiraeli, arĩa matuĩtwo ngombo nĩ andũ a Misiri, na nĩndirikanĩte kĩrĩkanĩro gĩakwa nao.
6 “Sọ fún àwọn ará ilé Israẹli, ‘Èmi ni Olúwa, Èmi yóò sọ yín di òmìnira kúrò nínú àjàgà àwọn ará Ejibiti. Èmi yóò sì gbà yín sílẹ̀ kúrò ní oko ẹrú wọn. Èmi yóò dá a yín sílẹ̀ pẹ̀lú apá nínà (àwọn iṣẹ́ ìyanu) àti pẹ̀lú ìdájọ́ ńlá.
“Nĩ ũndũ ũcio, ĩra andũ a Isiraeli atĩrĩ: ‘Niĩ nĩ niĩ Jehova, na nĩngamwaũra icooki rĩu mũigĩrĩirwo nĩ andũ a Misiri. Nĩngamuohora mũtige gũcooka gũtuĩka ngombo ciao, na nĩngamũkũũra ndambũrũkĩtie guoko na ciĩko nene cia ũtuanĩri ciira.
7 Èmi yóò mú un yín bí ènìyàn mi, èmi yóò sì jẹ́ Ọlọ́run yín. Nígbà náà ni ẹ̀yin yóò mọ̀ pé, èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín, ẹni tí ó mú un yín jáde kúrò nínú àjàgà àwọn ará Ejibiti.
Ngaamuoya ta andũ akwa kĩũmbe, na nduĩke Ngai wanyu. Hĩndĩ ĩyo nĩmũkamenya atĩ nĩ niĩ Jehova Ngai wanyu ũrĩa wamũrutire icooki-inĩ rĩa andũ a Misiri.
8 Èmi yóò mú un yín wá ilẹ̀ náà ti èmi ti búra pẹ̀lú ìgbọ́wọ́sókè láti fi fún Abrahamu. Isaaki àti Jakọbu. Èmi yóò fi fún un yín bí ohun ìní, Èmi ni Olúwa.’”
Na nĩngamũtwara bũrũri ũrĩa ndeeranĩire na mwĩhĩtwa nyambararĩtie guoko atĩ nĩngaahe Iburahĩmu, na Isaaka, o na Jakubu. Nĩguo ngũmũhe mũwĩgwatĩre ũtuĩke wanyu. Niĩ nĩ niĩ Jehova.’”
9 Mose sì sọ èyí fún àwọn ará Israẹli, ṣùgbọ́n wọn kò fi etí sílẹ̀ sí Mose nítorí ọkàn wọn tó rẹ̀wẹ̀sì àti nítorí ìgbèkùn búburú bí ohun tí ó ti kọ́ sọ kó wọn sí ní oko ẹrú wọn.
Musa agĩkĩheana ũhoro ũcio kũrĩ andũ a Isiraeli, no matiamũiguire nĩ ũrĩa maakuĩte ngoro nĩkũhinyĩrĩrio nĩ ũkombo.
10 Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Mose.
Ningĩ Jehova akĩĩra Musa atĩrĩ,
11 “Lọ, sọ fún Farao ọba Ejibiti pé kí ó jẹ́ kí àwọn ará Israẹli lọ kúrò ní orílẹ̀-èdè rẹ̀.”
“Thiĩ wĩre Firaũni, mũthamaki wa bũrũri wa Misiri arekererie andũ a Isiraeli moime bũrũri wake.”
12 Ṣùgbọ́n Mose sọ fún Olúwa pé, “Nígbà ti àwọn ará Israẹli tó jẹ́ ènìyàn mi kó fetí sí ọ̀rọ̀ mi, báwo ni Farao yóò ṣe fetí sí ọ̀rọ̀ mi, nígbà ti mo jẹ́ akólòlò?”
No Musa akĩĩra Jehova atĩrĩ, “Angĩkorwo andũ a Isiraeli matingĩnjigua-rĩ, nĩkĩ kĩngĩtũma Firaũni anjigue, kuona njaragia ngĩtondoiraga?”
13 Olúwa bá ìran Mose àti Aaroni sọ̀rọ̀ nípa àwọn ará Israẹli àti Farao ọba Ejibiti, ó pàṣẹ fún wọn pé kí wọn kó àwọn Israẹli jáde kúrò ni ilẹ̀ Ejibiti.
Ngai nĩacookire akĩaria na Musa na Harũni ũhoro wĩgiĩ andũ a Isiraeli na Firaũni mũthamaki wa bũrũri wa Misiri na akĩmaatha marute andũ a Isiraeli moime bũrũri wa Misiri.
14 Wọ̀nyí ni olórí ìran wọn: àwọn ọmọ Reubeni àkọ́bí Israẹli ni: Hanoku, Pallu, Hesroni àti Karmi. Àwọn wọ̀nyí ni ìdílé Reubeni.
Aya nĩo maarĩ atongoria a nyũmba ciao: Ariũ a Rubeni ũrĩa irigithathi rĩa Isiraeli maarĩ Hanoku na Palu, na Hezironi, na Karimi. Acio nĩo maarĩ mbarĩ cia Rubeni.
15 Àwọn ọmọ Simeoni ni: Jemueli, Jamini, Ohadi, Jakini, Sohari àti Saulu ọmọ obìnrin Kenaani. Àwọn wọ̀nyí ni ìran Simeoni.
Ariũ a Simeoni maarĩ Jemueli, na Jamini, na Ohadi, na Jakini, na Sohari, na Shauli ũrĩa warĩ mũriũ wa mũtumia Mũkaanani. Acio nĩo maarĩ mbarĩ cia Simeoni.
16 Ìwọ̀nyí ni orúkọ àwọn ọmọ Lefi gẹ́gẹ́ bí àkọsílẹ̀ wọn: Gerṣoni, Kohati àti Merari. Lefi lo ẹ̀tàdínlógóje ọdún láyé.
Maya nĩmo maarĩ marĩĩtwa ma ariũ a Lawi kũringana na maandĩko mao: Gerishoni, na Kohathu, na Merari. Lawi aatũũrire muoyo mĩaka 137.
17 Àwọn ọmọ Gerṣoni ni ìran wọn ni: Libni àti Ṣimei.
Ariũ a Gerishoni kũringana na mbarĩ ciao maarĩ Libini na Shimei.
18 Àwọn ọmọ Kohati ni: Amramu, Isari, Hebroni àti Usieli. Kohati lo ẹ̀tàléláádóje ọdún láyé.
Ariũ a Kohathu maarĩ Amuramu, na Iziharu, na Hebironi, na Uzieli. Kohathu aatũũrire muoyo mĩaka 133.
19 Àwọn ọmọ Merari ni: Mahili àti Muṣi. Ìwọ̀nyí ni ìran Lefi gẹ́gẹ́ bí àkọsílẹ̀ wọn.
Ariũ a Merari maarĩ Mahali na Mushi. Acio nĩo maarĩ mbarĩ cia Lawi kũringana na maandĩko mao.
20 Amramu sì fẹ́ Jokebedi arábìnrin baba rẹ̀ ní ìyàwó. Jokebedi sì bí Aaroni àti Mose fún un. Amramu lo ẹ̀tàdínlógóje ọdún láyé.
Amuramu nĩahikirie mwarĩ wa nyina na ithe wetagwo Jokebedi, ũrĩa wamũciarĩire Harũni na Musa. Amuramu aatũũrire muoyo mĩaka 137.
21 Àwọn ọmọ Isari ni: Kora, Nefegi àti Sikri.
Ariũ a Iziharu maarĩ Kora, na Nefegu, na Zikiri.
22 Àwọn ọmọ Usieli ni: Miṣaeli, Elsafani àti Sitiri.
Ariũ a Uzieli maarĩ Mishaeli, na Elizafani, na Sithiri.
23 Aaroni fẹ́ Eliṣeba ọmọbìnrin Amminadabu tí í ṣe arábìnrin Nahiṣoni, ó sì bí Nadabu, Abihu, Eleasari àti Itamari.
Harũni nĩahikirie Elisheba, mwarĩ wa Aminadabu, o ũrĩa warĩ mwarĩ wa nyina na Nahashoni, nake akĩmũciarĩra Nadabu na Abihu, na Eleazaru, na Ithamaru.
24 Àwọn ọmọ Kora ni: Asiri, Elkana àti Abiasafu. Ìwọ̀nyí ni ìran Kora.
Ariũ a Kora maarĩ Asiri, na Elikana, na Abiasafu. Acio nĩo mbarĩ cia Akora.
25 Eleasari ọmọ Aaroni fẹ́ ọ̀kan lára àwọn ọmọbìnrin Putieli ní ìyàwó, ó sì bí Finehasi fún un. Ìwọ̀nyí ni olórí àwọn Lefi ni ìdílé ìdílé.
Eleazaru mũrũ wa Harũni nĩahikirie mũirĩtu ũmwe wa Putieli, nake akĩmũciarĩra Finehasi. Acio nĩo maarĩ atongoria a nyũmba cia Alawii, o mbarĩ o mbarĩ.
26 Aaroni àti Mose yìí kan náà ni Olúwa sọ fún pé, “Ẹ kó àwọn ará Israẹli jáde kúrò ni ilẹ̀ Ejibiti ní ìsọ̀rí ìsọ̀rí.”
Harũni o ũcio, marĩ na Musa, nĩo meerirwo nĩ Jehova atĩrĩ, “Rutai andũ a Isiraeli kuuma bũrũri wa Misiri kũringana na ikundi ciao.”
27 Àwọn ni ó bá Farao ọba Ejibiti sọ̀rọ̀ nípa kíkó àwọn ará Israẹli jáde kúrò ni Ejibiti, àní Mose àti Aaroni yìí kan náà ni.
Nĩo maarĩirie Firaũni, mũthamaki wa bũrũri wa Misiri, ũhoro wa kũruta andũ a Isiraeli kuuma bũrũri wa Misiri. Maarĩ Musa o ũcio na Harũni.
28 Nígbà tí Olúwa bá Mose sọ̀rọ̀ ni Ejibiti,
Na rĩrĩ, hĩndĩ ĩrĩa Jehova aarĩirie Musa arĩ kũu bũrũri wa Misiri-rĩ,
29 Olúwa sì sọ fún Mose pé, “Èmi ni Olúwa. Sọ ohun gbogbo ti mo ti sọ fún ọ fún Farao ọba Ejibiti.”
aamwĩrire atĩrĩ, “Niĩ nĩ niĩ Jehova. Ĩra Firaũni mũthamaki wa bũrũri wa Misiri ũrĩa wothe ngũkwĩra.”
30 Ṣùgbọ́n Mose sì wí ní iwájú Olúwa pé, “Níwọ́n ìgbà ti mo jẹ́ akólòlò, ọ̀nà dà ti Farao yóò ṣe fi etí sí mi?”
No Musa akĩĩra Jehova atĩrĩ, “Kuona njaragia ngĩtondoiraga-rĩ, Firaũni angĩkĩnjigua nĩkĩ?”

< Exodus 6 >