< Exodus 6 >

1 Nígbà náà ní Olúwa sọ fún Mose pé, “Ní ìsin yìí, ìwọ yóò rí ohun tí èmi yóò ṣe sí Farao pẹ̀lú ọwọ́ agbára ńlá mi ni yóò fi jẹ́ kí wọn lọ; pẹ̀lú ọwọ́ agbára ńlá mi, òun yóò lé wọn jáde kúrò ní orílẹ̀-èdè rẹ̀.”
Yahvé dit à Moïse: « Tu verras maintenant ce que je ferai à Pharaon, car c'est à main forte qu'il les laissera aller, et c'est à main forte qu'il les chassera de son pays. »
2 Ọlọ́run sì tún sọ fún Mose pé, “Èmi ni Olúwa.
Dieu parla à Moïse, et lui dit: « Je suis Yahvé.
3 Mo fi ara hàn Abrahamu, Isaaki àti Jakọbu bí Ọlọ́run alágbára, ṣùgbọ́n nípa orúkọ mi Olúwa, Èmi kò fi ara mi hàn wọ́n.
J'ai apparu à Abraham, à Isaac et à Jacob, en tant que Dieu tout-puissant, mais je ne leur ai pas été connu sous mon nom de Yahvé.
4 Èmí sì tún fi ìdí májẹ̀mú mi múlẹ̀ pẹ̀lú wọn láti fún wọn ní ilẹ̀ Kenaani, ilẹ̀ tí wọn gbé gẹ́gẹ́ bí àjèjì.
J'ai aussi établi mon alliance avec eux, pour leur donner le pays de Canaan, le pays de leurs voyages, dans lequel ils vivaient comme des étrangers.
5 Èmi sì ti tún gbọ́ kíkùn àwọn ọmọ Israẹli àwọn tí àwọn ará Ejibiti mú gẹ́gẹ́ bí ẹrú, àti pé èmi sì ti rántí májẹ̀mú mi.
J'ai entendu les gémissements des enfants d'Israël, que les Égyptiens tiennent en esclavage, et je me suis souvenu de mon alliance.
6 “Sọ fún àwọn ará ilé Israẹli, ‘Èmi ni Olúwa, Èmi yóò sọ yín di òmìnira kúrò nínú àjàgà àwọn ará Ejibiti. Èmi yóò sì gbà yín sílẹ̀ kúrò ní oko ẹrú wọn. Èmi yóò dá a yín sílẹ̀ pẹ̀lú apá nínà (àwọn iṣẹ́ ìyanu) àti pẹ̀lú ìdájọ́ ńlá.
C'est pourquoi dis aux enfants d'Israël: « Je suis Yahvé, et je vous ferai sortir de dessous les fardeaux des Égyptiens, je vous délivrerai de leur servitude, je vous rachèterai à bras étendu et par de grands jugements.
7 Èmi yóò mú un yín bí ènìyàn mi, èmi yóò sì jẹ́ Ọlọ́run yín. Nígbà náà ni ẹ̀yin yóò mọ̀ pé, èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín, ẹni tí ó mú un yín jáde kúrò nínú àjàgà àwọn ará Ejibiti.
Je vous prendrai pour mon peuple. Je serai votre Dieu, et vous saurez que je suis Yahvé, votre Dieu, qui vous fait sortir de dessous les fardeaux des Égyptiens.
8 Èmi yóò mú un yín wá ilẹ̀ náà ti èmi ti búra pẹ̀lú ìgbọ́wọ́sókè láti fi fún Abrahamu. Isaaki àti Jakọbu. Èmi yóò fi fún un yín bí ohun ìní, Èmi ni Olúwa.’”
Je vous ferai entrer dans le pays que j'ai juré de donner à Abraham, à Isaac et à Jacob, et je vous le donnerai en héritage: je suis Yahvé.'"
9 Mose sì sọ èyí fún àwọn ará Israẹli, ṣùgbọ́n wọn kò fi etí sílẹ̀ sí Mose nítorí ọkàn wọn tó rẹ̀wẹ̀sì àti nítorí ìgbèkùn búburú bí ohun tí ó ti kọ́ sọ kó wọn sí ní oko ẹrú wọn.
Moïse en parla aux enfants d'Israël, mais ils n'écoutèrent pas Moïse, à cause de l'angoisse de l'esprit et de la cruelle servitude.
10 Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Mose.
Yahvé parla à Moïse et dit:
11 “Lọ, sọ fún Farao ọba Ejibiti pé kí ó jẹ́ kí àwọn ará Israẹli lọ kúrò ní orílẹ̀-èdè rẹ̀.”
« Va, parle à Pharaon, roi d'Égypte, pour qu'il laisse sortir les enfants d'Israël de son pays. »
12 Ṣùgbọ́n Mose sọ fún Olúwa pé, “Nígbà ti àwọn ará Israẹli tó jẹ́ ènìyàn mi kó fetí sí ọ̀rọ̀ mi, báwo ni Farao yóò ṣe fetí sí ọ̀rọ̀ mi, nígbà ti mo jẹ́ akólòlò?”
Moïse parla devant Yahvé, et dit: « Voici, les enfants d'Israël ne m'ont pas écouté. Comment Pharaon m'écoutera-t-il, alors que j'ai des lèvres incirconcises? »
13 Olúwa bá ìran Mose àti Aaroni sọ̀rọ̀ nípa àwọn ará Israẹli àti Farao ọba Ejibiti, ó pàṣẹ fún wọn pé kí wọn kó àwọn Israẹli jáde kúrò ni ilẹ̀ Ejibiti.
Yahvé parla à Moïse et à Aaron, et leur donna l'ordre de faire sortir du pays d'Égypte les enfants d'Israël et Pharaon, roi d'Égypte.
14 Wọ̀nyí ni olórí ìran wọn: àwọn ọmọ Reubeni àkọ́bí Israẹli ni: Hanoku, Pallu, Hesroni àti Karmi. Àwọn wọ̀nyí ni ìdílé Reubeni.
Voici les chefs des maisons de leurs pères. Fils de Ruben, premier-né d'Israël: Hanoch, Pallu, Hetsron et Carmi. Ce sont là les familles de Ruben.
15 Àwọn ọmọ Simeoni ni: Jemueli, Jamini, Ohadi, Jakini, Sohari àti Saulu ọmọ obìnrin Kenaani. Àwọn wọ̀nyí ni ìran Simeoni.
Fils de Siméon: Jemuel, Jamin, Ohad, Jachin, Zohar et Saül, fils d'une Cananéenne: ce sont là les familles de Siméon.
16 Ìwọ̀nyí ni orúkọ àwọn ọmọ Lefi gẹ́gẹ́ bí àkọsílẹ̀ wọn: Gerṣoni, Kohati àti Merari. Lefi lo ẹ̀tàdínlógóje ọdún láyé.
Voici les noms des fils de Lévi, selon leurs générations: Guerschon, Kehath et Merari. Les années de la vie de Lévi furent de cent trente-sept ans.
17 Àwọn ọmọ Gerṣoni ni ìran wọn ni: Libni àti Ṣimei.
Fils de Guerschon: Libni et Schimeï, selon leurs familles.
18 Àwọn ọmọ Kohati ni: Amramu, Isari, Hebroni àti Usieli. Kohati lo ẹ̀tàléláádóje ọdún láyé.
Fils de Kehath: Amram, Jitsehar, Hébron et Uzziel. Les années de la vie de Kehath furent de cent trente-trois ans.
19 Àwọn ọmọ Merari ni: Mahili àti Muṣi. Ìwọ̀nyí ni ìran Lefi gẹ́gẹ́ bí àkọsílẹ̀ wọn.
Fils de Merari: Mahli et Mushi. Ce sont là les familles des Lévites, selon leurs générations.
20 Amramu sì fẹ́ Jokebedi arábìnrin baba rẹ̀ ní ìyàwó. Jokebedi sì bí Aaroni àti Mose fún un. Amramu lo ẹ̀tàdínlógóje ọdún láyé.
Amram prit pour femme Jochebed, la sœur de son père, et elle lui enfanta Aaron et Moïse. Les années de la vie d'Amram furent de cent trente-sept ans.
21 Àwọn ọmọ Isari ni: Kora, Nefegi àti Sikri.
Fils de Jitsehar: Koré, Néphég, et Zicri.
22 Àwọn ọmọ Usieli ni: Miṣaeli, Elsafani àti Sitiri.
Fils d'Uzziel: Mishaël, Elzaphan et Sithri.
23 Aaroni fẹ́ Eliṣeba ọmọbìnrin Amminadabu tí í ṣe arábìnrin Nahiṣoni, ó sì bí Nadabu, Abihu, Eleasari àti Itamari.
Aaron prit pour femme Elischéba, fille d'Amminadab, sœur de Nachshon; elle lui enfanta Nadab et Abihu, Eléazar et Ithamar.
24 Àwọn ọmọ Kora ni: Asiri, Elkana àti Abiasafu. Ìwọ̀nyí ni ìran Kora.
Fils de Koré: Assir, Elkana et Abiasaph; ce sont là les familles des Koréens.
25 Eleasari ọmọ Aaroni fẹ́ ọ̀kan lára àwọn ọmọbìnrin Putieli ní ìyàwó, ó sì bí Finehasi fún un. Ìwọ̀nyí ni olórí àwọn Lefi ni ìdílé ìdílé.
Le fils d'Eléazar Aaron prit pour femme une des filles de Putiel, qui lui enfanta Phinées. Ce sont là les chefs des maisons paternelles des Lévites, selon leurs familles.
26 Aaroni àti Mose yìí kan náà ni Olúwa sọ fún pé, “Ẹ kó àwọn ará Israẹli jáde kúrò ni ilẹ̀ Ejibiti ní ìsọ̀rí ìsọ̀rí.”
Ce sont ces Aaron et Moïse à qui Yahvé a dit: « Fais sortir du pays d'Égypte les enfants d'Israël, selon leurs armées. »
27 Àwọn ni ó bá Farao ọba Ejibiti sọ̀rọ̀ nípa kíkó àwọn ará Israẹli jáde kúrò ni Ejibiti, àní Mose àti Aaroni yìí kan náà ni.
Ce sont eux qui ont parlé à Pharaon, roi d'Égypte, pour faire sortir d'Égypte les enfants d'Israël. Ce sont ces Moïse et Aaron.
28 Nígbà tí Olúwa bá Mose sọ̀rọ̀ ni Ejibiti,
Le jour où Yahvé parla à Moïse au pays d'Égypte,
29 Olúwa sì sọ fún Mose pé, “Èmi ni Olúwa. Sọ ohun gbogbo ti mo ti sọ fún ọ fún Farao ọba Ejibiti.”
Yahvé dit à Moïse: « Je suis Yahvé. Dis à Pharaon, roi d'Égypte, tout ce que je te dirai. »
30 Ṣùgbọ́n Mose sì wí ní iwájú Olúwa pé, “Níwọ́n ìgbà ti mo jẹ́ akólòlò, ọ̀nà dà ti Farao yóò ṣe fi etí sí mi?”
Moïse dit devant Yahvé: « Voici, je suis d'une bouche incirconcise, et comment Pharaon m'écouterait-il? »

< Exodus 6 >