< Exodus 5 >

1 Lẹ́yìn náà ni Mose àti Aaroni tọ Farao lọ, wọ́n sì wí pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa, Ọlọ́run Israẹli sọ, ‘Jẹ́ kí àwọn ènìyàn mi kí ó lọ, kí wọn kí ó lè ṣe àjọ mi ní ijù.’”
Un pēc tam Mozus un Ārons gāja un sacīja uz Faraonu: tā saka Tas Kungs, Israēla Dievs: atlaid manus ļaudis, ka tie man svētkus tur tuksnesī.
2 Farao dáhùn wí pé, “Ta ni Olúwa, tí èmi yóò fi gbọ́rọ̀ sí i lẹ́nu, tí èmi yóò fi jẹ́ kí Israẹli ó lọ? Èmi kò mọ Olúwa, èmi kò sì ní jẹ́ kí Israẹli ó lọ.”
Bet Faraons sacīja: kas tas tāds Kungs, kā balsij man būs klausīt un Israēli atlaist? Es To Kungu nepazīstu, un Israēli arī neatlaidīšu.
3 Lẹ́yìn náà ni wọ́n wí pé, “Ọlọ́run àwọn Heberu tí pàdé wa. Ní ìsinsin yìí, jẹ́ kí a lọ ní ìrìn ọjọ́ mẹ́ta sínú aginjù láti rú ẹbọ sí Olúwa Ọlọ́run wa, kí Ó má ba á fi àjàkálẹ̀-ààrùn tàbí idà bá wa jà.”
Tad tie sacīja: tas Ebreju Dievs mūs ir sastapis, lai mēs ejam treju dienu gājumu tuksnesī, upurēt Tam Kungam, savam Dievam, lai Viņš pār mums nenāk ar mēri vai ar zobenu.
4 Ṣùgbọ́n ọba Ejibiti sọ wí pé, “Mose àti Aaroni, èéṣe ti ẹ̀yin fi mú àwọn ènìyàn kúrò lẹ́nu iṣẹ́ wọn? Ẹ padà sẹ́nu iṣẹ́ yín.”
Tad Ēģiptes ķēniņš uz tiem sacīja: jūs, Mozus un Ārons, - kam jūs tos ļaudis atturat no viņu darbiem? Ejat pie savas kalpošanas!
5 Nígbà náà ni Farao sọ pé, “Ẹ wò ó àwọn ènìyàn náà ti pọ̀ sí ì nílẹ̀ yìí ní ìsinsin yìí, ẹ̀yin sì ń dá wọn dúró láti máa bá iṣẹ́ lọ.”
Vēl Faraons sacīja: redzi, ļaužu tai zemē tā jau daudz, un jūs tos vēl gribat atturēt no viņu kalpošanas?
6 Ní ọjọ́ yìí kan náà ni Farao pàṣẹ fún àwọn akóniṣiṣẹ́ àti àwọn ti ń ṣe alábojútó iṣẹ́ lórí àwọn ènìyàn.
Un Faraons tai dienā ļaužu uzraugiem un virsniekiem pavēlēja un sacīja:
7 “Ẹ̀yin kò ní láti pèsè koríko gbígbẹ fún bíríkì sísun mọ́ fún àwọn ènìyàn wọ̀nyí; ẹ jẹ́ kí wọn máa wá koríko gbígbẹ fún ara wọn.
Jums turpmāk nebūs tiem ļaudīm dot salmus pie ķieģeļu taisīšanas, kā vakar un aizvakar; tiem pašiem būs iet un sev salmus meklēt.
8 Ṣùgbọ́n ẹ jẹ́ kí wọn ó ṣe iye bíríkì kan náà bí ì ti àtẹ̀yìnwá, kí ẹ má ṣe dín iye rẹ̀ kú. Ọ̀lẹ ni wọ́n, ìwà ọ̀lẹ yìí náà ló mú wọn pariwo pé, ‘Ẹ jẹ́ kí a lọ, kí a sì rú ẹbọ sí Ọlọ́run wa.’
Un to ķieģeļu pulku, ko tie citkārt taisījuši, jums tiem tā pat būs uzlikt, jums no tiem neko nebūs atraut; jo tie ir bez darba, tādēļ tie brēc un saka: iesim, upurēsim savam Dievam!
9 Ẹ mú iṣẹ́ náà le fún wọn, kí wọn bá a le è tẹramọ́ iṣẹ́ wọn, ẹ má fi ààyè gba irọ́ wọn.”
Lai tiem vīriem tā kalpošana top grūtāka, ka tiem ir darbs, un tie negriežās pie blēņām.
10 Ní ìgbà náà ni àwọn akóniṣiṣẹ́ àti àwọn tí ń ṣe alábojútó iṣẹ́ jáde tọ̀ wọ́n lọ láti sọ fún àwọn ènìyàn náà pé, “Èyí ni ohun tí Farao sọ, ‘Èmi kò ní fún un yín ni koríko gbígbẹ mọ́.
Tad tie ļaužu uzraugi un virsnieki izgāja un runāja uz tiem ļaudīm sacīdami: Tā saka Faraons: es jums vairs nedošu salmus.
11 Ẹ lọ wá koríko gbígbẹ ni ibi tí ẹ bá ti lè rí i, ṣùgbọ́n iṣẹ́ yín kí yóò dínkù.’”
Ejat paši, dabūjiet sev salmus kur dabūdami, bet no jūsu darba nekas netaps atlaists.
12 Gbogbo wọn sí fọ́n káàkiri ni ilẹ̀ Ejibiti láti sa ìdì koríko tí wọn yóò lò bí ì koríko gbígbẹ fún sísun bíríkì.
Tad tie ļaudis izklīda pa visu Ēģiptes zemi, ka tie rugājus sakrātu salmu vietā.
13 Àwọn akóniṣiṣẹ́ sì ń ni wọ́n lára, wọ́n wí pé, “Ẹ parí iṣẹ́ tí ẹ ni láti ṣe fún ọjọ́ kan bí ìgbà ti a ń fún un yin ní koríko gbígbẹ.”
Un tie uzraugi tos spieda, sacīdami: Pabeidziet savu dienas darbu it tāpat, kā kad jums salmi bija.
14 Àwọn alábojútó iṣẹ́ tí àwọn akóniṣiṣẹ́ Farao yàn lára ọmọ Israẹli ni wọn ń lù, tí wọn sì ń béèrè lọ́wọ́ wọn pé, “Èéṣe tí ẹ̀yin kò ṣe iye bíríkì ti ẹ̀yin ń ṣe ní àná ní òní bí i tí àtẹ̀yìnwá?”
Un Israēla bērnu uzraugi, ko Faraona virsnieki pār tiem bija iecēluši, tapa sisti, un uz tiem sacīja: kāpēc jūs neesat pabeiguši savu nospriesto darbu pie ķieģeļu dedzināšanas kā papriekš, ne vakar, ne šodien?
15 Nígbà náà ni àwọn alábojútó iṣẹ́ tí a yàn lára àwọn ọmọ Israẹli tọ Farao lọ láti lọ bẹ̀bẹ̀ pé, “Èéṣe tí ìwọ fi ọwọ́ líle mú àwa ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ báyìí?
Tad Israēla bērnu uzraugi gāja un brēca uz Faraonu un sacīja: kāpēc tu saviem kalpiem tā dari?
16 Wọn kò fún àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ ni koríko gbígbẹ, síbẹ̀ wọn sọ fún wa pé, ‘Ẹ ṣe bíríkì!’ Wọ́n na àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ, ṣùgbọ́n ẹ̀bi náà wá láti ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn rẹ.”
Taviem kalpiem salmus nedod, un mums saka: taisāt ķieģeļus; un redzi, tavi kalpi top sisti, un tā ir tavas tautas vaina.
17 Farao sí dáhùn wí pé, “Ọ̀lẹ ni yín, ọ̀lẹ! Èyí ni ó mú kí ẹ̀yin máa sọ ní ìgbà gbogbo pé, ‘Ẹ jẹ́ kí a lọ, kí a sì rú ẹbọ sí Olúwa.’
Tad Faraons sacīja: jūs esat sliņķi, sliņķi jūs esat, tāpēc jūs sakāt, iesim, upurēsim Tam Kungam.
18 Nísinsin yìí ẹ padà lọ sí ẹnu iṣẹ́ yín, a kò ní fún un yín ni koríko gbígbẹ, síbẹ̀ ẹ gbọdọ̀ ṣe iye bíríkì tí ó yẹ kí ẹ ṣe.”
Tad nu ejat pie darba, salmus jums nedos, bet ķieģeļu skaits jums jātaisa.
19 Àwọn ọmọ Israẹli tí ó jẹ́ alábojútó iṣẹ́ mọ̀ dájú wí pé àwọn ti wà nínú wàhálà ńlá ní ìgbà tí a sọ fún wọn pé, “Ẹ kò ní láti dín iye bíríkì tí ẹ ń ṣe ni ojoojúmọ́ kù.”
Tad Israēla bērnu uzraugi redzēja, ka viņi postā, tāpēc ka sacīja: jums nebūs atraut no nospriestā dienas darba ķieģeļiem.
20 Ní ìgbà tí wọ́n kúrò ni ọ̀dọ̀ Farao wọ́n rí Mose àti Aaroni tí ó dúró láti pàdé wọn.
Un tie sastapa Mozu un Āronu, kas tur stāvēja tos sagaidīt, kad tie no Faraona izgāja,
21 Wọn sì wí pé, “Kí Olúwa kí ó wò yín, kí ó sì ṣe ìdájọ́! Ẹ̀yin ti mú wa dàbí òórùn búburú fún Farao àti àwọn òṣìṣẹ́ rẹ̀, ẹ sì ti fún wọn ni idà láti fi pa wá.”
Un sacīja uz tiem: lai Tas Kungs jūs redz un soda, tāpēc ka jūs mūsu smaržu esat smirdošu darījuši pie Faraona un pie viņa kalpiem, viņiem rokā dodami zobenu, mūs nokaut.
22 Mose padà tọ Olúwa lọ, ó sì wí pé, “Olúwa, èéṣe tí ìwọ fi mú ìyọnu wá sí orí àwọn ènìyàn wọ̀nyí? Ṣe torí èyí ni ìwọ fi rán mi?
Tad Mozus atgriezās pie Tā Kunga un sacīja: Kungs, kāpēc Tu šiem ļaudīm esi darījis ļaunu? Kāpēc tad Tu mani esi sūtījis?
23 Láti ìgbà ti mo ti tọ Farao lọ láti bá a sọ̀rọ̀ ni orúkọ rẹ ni ó ti mú ìyọnu wá sí orí àwọn ènìyàn wọ̀nyí, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kò sì gba àwọn ènìyàn rẹ sílẹ̀ rárá.”
Jo kamēr es esmu gājis pie Faraona, runāt Tavā vārdā, viņš tiem ļaudīm dara ļaunu, un Tu Savus ļaudis glābt neesi glābis.

< Exodus 5 >