< Exodus 5 >
1 Lẹ́yìn náà ni Mose àti Aaroni tọ Farao lọ, wọ́n sì wí pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa, Ọlọ́run Israẹli sọ, ‘Jẹ́ kí àwọn ènìyàn mi kí ó lọ, kí wọn kí ó lè ṣe àjọ mi ní ijù.’”
Thuutha-inĩ Musa na Harũni nĩmathiire kũrĩ Firaũni, makĩmwĩra atĩrĩ, “Jehova, o we Ngai wa Isiraeli, oigĩte ũũ: ‘Reke andũ akwa mathiĩ, nĩgeetha makagĩe na gĩathĩ gĩakwa werũ-inĩ.’”
2 Farao dáhùn wí pé, “Ta ni Olúwa, tí èmi yóò fi gbọ́rọ̀ sí i lẹ́nu, tí èmi yóò fi jẹ́ kí Israẹli ó lọ? Èmi kò mọ Olúwa, èmi kò sì ní jẹ́ kí Israẹli ó lọ.”
Nake Firaũni akĩmooria atĩrĩ, “Jehova nĩwe ũ, atĩ ndĩmwathĩkĩre na ndekererie andũ a Isiraeli mathiĩ? Niĩ ndiũĩ Jehova na ndikũrekereria andũ a Isiraeli mathiĩ.”
3 Lẹ́yìn náà ni wọ́n wí pé, “Ọlọ́run àwọn Heberu tí pàdé wa. Ní ìsinsin yìí, jẹ́ kí a lọ ní ìrìn ọjọ́ mẹ́ta sínú aginjù láti rú ẹbọ sí Olúwa Ọlọ́run wa, kí Ó má ba á fi àjàkálẹ̀-ààrùn tàbí idà bá wa jà.”
Ningĩ makĩmwĩra atĩrĩ, “Ngai wa Ahibirania nĩatwarĩirie. Nĩ ũndũ ũcio twĩtĩkĩrie tũthiĩ rũgendo rwa mĩthenya ĩtatũ werũ-inĩ tũkarutĩre Jehova Ngai witũ magongona, kwaga ũguo no atũrehithĩrie mĩthiro kana atũniine na rũhiũ rwa njora.”
4 Ṣùgbọ́n ọba Ejibiti sọ wí pé, “Mose àti Aaroni, èéṣe ti ẹ̀yin fi mú àwọn ènìyàn kúrò lẹ́nu iṣẹ́ wọn? Ẹ padà sẹ́nu iṣẹ́ yín.”
No mũthamaki wa bũrũri wa Misiri akĩmooria atĩrĩ, “Musa na Harũni, nĩ kĩĩ kĩratũma mũrute andũ wĩra-inĩ wao? Cookai wĩra-inĩ wanyu!”
5 Nígbà náà ni Farao sọ pé, “Ẹ wò ó àwọn ènìyàn náà ti pọ̀ sí ì nílẹ̀ yìí ní ìsinsin yìí, ẹ̀yin sì ń dá wọn dúró láti máa bá iṣẹ́ lọ.”
Nake Firaũni akiuga atĩrĩ, “Ta rorai, andũ a bũrũri rĩu nĩmaingĩhĩte, na inyuĩ nĩmũragiria marute wĩra.”
6 Ní ọjọ́ yìí kan náà ni Farao pàṣẹ fún àwọn akóniṣiṣẹ́ àti àwọn ti ń ṣe alábojútó iṣẹ́ lórí àwọn ènìyàn.
Mũthenya o ũcio Firaũni agĩatha arũgamĩrĩri a ngombo o na nyabaara cia andũ, akĩmeera atĩrĩ,
7 “Ẹ̀yin kò ní láti pèsè koríko gbígbẹ fún bíríkì sísun mọ́ fún àwọn ènìyàn wọ̀nyí; ẹ jẹ́ kí wọn máa wá koríko gbígbẹ fún ara wọn.
“Mũtigacooke kũhe andũ a Isiraeli nyeki ya gũthondeka maturubarĩ; nĩmathiĩ magecarĩrie nyeki o ene.
8 Ṣùgbọ́n ẹ jẹ́ kí wọn ó ṣe iye bíríkì kan náà bí ì ti àtẹ̀yìnwá, kí ẹ má ṣe dín iye rẹ̀ kú. Ọ̀lẹ ni wọ́n, ìwà ọ̀lẹ yìí náà ló mú wọn pariwo pé, ‘Ẹ jẹ́ kí a lọ, kí a sì rú ẹbọ sí Ọlọ́run wa.’
No mũmeere atĩ no nginya mathondeke maturubarĩ mũigana o ta wa mbere; mũtikamanyiihĩrie gĩthimo. Nĩ igũũta; nĩkĩo mararĩra makoiga atĩrĩ, ‘Nĩtũrekwo tũthiĩ tũkarutĩre Ngai witũ igongona.’
9 Ẹ mú iṣẹ́ náà le fún wọn, kí wọn bá a le è tẹramọ́ iṣẹ́ wọn, ẹ má fi ààyè gba irọ́ wọn.”
Maritũhĩriei wĩra nĩgeetha makoragwo makĩruta wĩra hĩndĩ ciothe, na mũtige gũthikĩrĩria ũhoro wa maheeni.”
10 Ní ìgbà náà ni àwọn akóniṣiṣẹ́ àti àwọn tí ń ṣe alábojútó iṣẹ́ jáde tọ̀ wọ́n lọ láti sọ fún àwọn ènìyàn náà pé, “Èyí ni ohun tí Farao sọ, ‘Èmi kò ní fún un yín ni koríko gbígbẹ mọ́.
Nao arũgamĩrĩri a ngombo na nyabaara cia andũ magĩthiĩ makĩĩra andũ atĩrĩ, “Firaũni ekuuga ũũ: ‘Ndigũcooka kũmũhe nyeki rĩngĩ.
11 Ẹ lọ wá koríko gbígbẹ ni ibi tí ẹ bá ti lè rí i, ṣùgbọ́n iṣẹ́ yín kí yóò dínkù.’”
Thiĩi mũgecarĩrie nyeki yanyu kũrĩa guothe mũrĩmĩona, no wĩra wanyu ndũkũnyihanyiihio o na hanini.’”
12 Gbogbo wọn sí fọ́n káàkiri ni ilẹ̀ Ejibiti láti sa ìdì koríko tí wọn yóò lò bí ì koríko gbígbẹ fún sísun bíríkì.
Nĩ ũndũ ũcio andũ makĩhurunjũkĩra bũrũri wa Misiri guothe kũngania makoni ma ngano mamatũmĩre ta nyeki.
13 Àwọn akóniṣiṣẹ́ sì ń ni wọ́n lára, wọ́n wí pé, “Ẹ parí iṣẹ́ tí ẹ ni láti ṣe fún ọjọ́ kan bí ìgbà ti a ń fún un yin ní koríko gbígbẹ.”
Arũgamĩrĩri a ngombo makĩmahinyĩrĩria mũno, makameeraga atĩrĩ, “Rĩĩkiai wĩra ũrĩa mwagĩrĩirwo wa o mũthenya, o ta ũrĩa mwekaga rĩrĩa mwaheagwo nyeki.”
14 Àwọn alábojútó iṣẹ́ tí àwọn akóniṣiṣẹ́ Farao yàn lára ọmọ Israẹli ni wọn ń lù, tí wọn sì ń béèrè lọ́wọ́ wọn pé, “Èéṣe tí ẹ̀yin kò ṣe iye bíríkì ti ẹ̀yin ń ṣe ní àná ní òní bí i tí àtẹ̀yìnwá?”
Nao andũ a Isiraeli arĩa maarĩ nyabaara arĩa maathuurĩtwo nĩ anene a ngombo a Firaũni magakĩhũũragwo, makoorio atĩrĩ, “Nĩ kĩĩ kĩragiririe mũhingie mũigana wa maturubarĩ ma ira kana ma ũmũthĩ, ta ũrĩa mũrekaga mbere?”
15 Nígbà náà ni àwọn alábojútó iṣẹ́ tí a yàn lára àwọn ọmọ Israẹli tọ Farao lọ láti lọ bẹ̀bẹ̀ pé, “Èéṣe tí ìwọ fi ọwọ́ líle mú àwa ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ báyìí?
Nao andũ a Isiraeli arĩa maarĩ nyabaara magĩthiĩ kũrĩ Firaũni kũmũthaitha, makĩmũũria atĩrĩ: “Nĩ kĩĩ gĩtũmĩte wĩke ndungata ciaku maũndũ maya?
16 Wọn kò fún àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ ni koríko gbígbẹ, síbẹ̀ wọn sọ fún wa pé, ‘Ẹ ṣe bíríkì!’ Wọ́n na àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ, ṣùgbọ́n ẹ̀bi náà wá láti ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn rẹ.”
Ndungata ciaku itiraheo nyeki, na no tũrerwo, ‘Thondekai maturubarĩ!’ Ndungata ciaku nĩirahũũrwo, no andũ aku nĩo marĩ na mahĩtia.”
17 Farao sí dáhùn wí pé, “Ọ̀lẹ ni yín, ọ̀lẹ! Èyí ni ó mú kí ẹ̀yin máa sọ ní ìgbà gbogbo pé, ‘Ẹ jẹ́ kí a lọ, kí a sì rú ẹbọ sí Olúwa.’
Nake Firaũni agĩcookia atĩrĩ, “Igũũta ici! Inyuĩ mũrĩ igũũta! Nĩkĩo mũraikara mũkiugaga atĩrĩ, ‘Nĩtũrekwo tũkarutĩre Jehova igongona.’
18 Nísinsin yìí ẹ padà lọ sí ẹnu iṣẹ́ yín, a kò ní fún un yín ni koríko gbígbẹ, síbẹ̀ ẹ gbọdọ̀ ṣe iye bíríkì tí ó yẹ kí ẹ ṣe.”
Cookai wĩra-inĩ. Mũtikũheo nyeki, na no nginya mũthondeke mũigana wa maturubarĩ marĩa mwagĩrĩirwo.”
19 Àwọn ọmọ Israẹli tí ó jẹ́ alábojútó iṣẹ́ mọ̀ dájú wí pé àwọn ti wà nínú wàhálà ńlá ní ìgbà tí a sọ fún wọn pé, “Ẹ kò ní láti dín iye bíríkì tí ẹ ń ṣe ni ojoojúmọ́ kù.”
Nao andũ a Isiraeli arĩa maarĩ nyabaara makĩmenya atĩ maarĩ thĩĩna-inĩ rĩrĩa meerirwo atĩrĩ, “Mũtikũnyiihĩrio mũigana wa maturubarĩ marĩa mwagĩrĩirwo gũthondeka o mũthenya.”
20 Ní ìgbà tí wọ́n kúrò ni ọ̀dọ̀ Farao wọ́n rí Mose àti Aaroni tí ó dúró láti pàdé wọn.
Rĩrĩa moimire harĩ Firaũni-rĩ, magĩkora Musa na Harũni arĩa maametereire,
21 Wọn sì wí pé, “Kí Olúwa kí ó wò yín, kí ó sì ṣe ìdájọ́! Ẹ̀yin ti mú wa dàbí òórùn búburú fún Farao àti àwọn òṣìṣẹ́ rẹ̀, ẹ sì ti fún wọn ni idà láti fi pa wá.”
nao anyabara acio makĩmeera atĩrĩ, “Jehova aromuona na amũtuĩre ciira! Mũtũmĩte tũtuĩke kĩndũ kĩnungu kũrĩ Firaũni na anene ake, na mũkamane rũhiũ rwa njora moko-inĩ mao matũũrage.”
22 Mose padà tọ Olúwa lọ, ó sì wí pé, “Olúwa, èéṣe tí ìwọ fi mú ìyọnu wá sí orí àwọn ènìyàn wọ̀nyí? Ṣe torí èyí ni ìwọ fi rán mi?
Musa agĩcooka kũrĩ, Jehova akĩmũũria atĩrĩ, “Mwathani, nĩ kĩĩ gĩtũmĩte ũrehithĩrie andũ aya thĩĩna? Gĩkĩ nĩkĩo gĩatũmire ũndũme?
23 Láti ìgbà ti mo ti tọ Farao lọ láti bá a sọ̀rọ̀ ni orúkọ rẹ ni ó ti mú ìyọnu wá sí orí àwọn ènìyàn wọ̀nyí, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kò sì gba àwọn ènìyàn rẹ sílẹ̀ rárá.”
Kuuma rĩrĩa ndaathiire kũrĩ Firaũni kũmwarĩria thĩinĩ wa rĩĩtwa rĩaku, nĩareheire andũ aya thĩĩna, nawe ũkaaga gũteithũra andũ aku o na hanini.”