< Exodus 40 >

1 Olúwa sì wí fún Mose pé,
And the Lord spoke unto Moses, saying,
2 “Ní ọjọ́ kìn-ín-ní, oṣù kìn-ín-ní ni kí ó gbé àgọ́ náà, àgọ́ àjọ náà ró.
On the first day of the first month shalt thou set up the tabernacle of the tent of the congregation.
3 Gbé àpótí ẹ̀rí sí inú rẹ̀, kí ó sì bo àpótí náà pẹ̀lú aṣọ títa.
And thou shalt put therein the ark of the testimony, and separate the ark with the vail.
4 Gbé tábìlì náà wọ ilé, kí o sì to àwọn ohun tí ó jẹ́ tirẹ̀ lé e lórí. Nígbà náà gbé ọ̀pá fìtílà wọlé, kí o sì to àwọn fìtílà rẹ̀.
And thou shalt bring in the table, and arrange the order of the showbread upon it; and thou shalt bring in the candlestick, and light the lamps thereof.
5 Gbé pẹpẹ wúrà ti tùràrí sí iwájú àpótí ẹ̀rí, kí o sì fi aṣọ títa ẹnu-ọ̀nà sí ara àgọ́ náà.
And thou shalt set the altar of gold for the incense before the ark of the testimony; and thou shalt put up the hanging at the door to the tabernacle.
6 “Gbé pẹpẹ ẹbọ sísun sí iwájú ẹnu-ọ̀nà àgọ́ náà, àgọ́ àjọ;
And thou shalt set the altar of burnt-offering before the door of the tabernacle of the tent of the congregation.
7 gbé agbada sí àárín àgọ́ àjọ àti pẹpẹ, kí o sì fi omi sí inú rẹ̀.
And thou shalt set the laver between the tabernacle of the congregation and the altar, and thou shalt put water therein.
8 Gbé àgbàlá ró yìí ka, kí ó sì fi aṣọ títa sí ẹnu-ọ̀nà àgbàlá náà.
And thou shalt set up the court round about, and put up the hanging at the gate of the court.
9 “Mú òróró ìtasórí, kí ó sì ta á sára àgọ́ náà àti ohun gbogbo tí ó wà nínú rẹ̀, yà pẹpẹ sí mímọ́ àti gbogbo ọ̀ṣọ́ rẹ̀, yóò sì jẹ́ mímọ́.
And thou shalt take the anointing oil, and anoint the tabernacle, and all that is therein; and thou shalt hallow it, with all its vessels, and it shall be holy.
10 Ta òróró sára pẹpẹ ẹbọ sísun àti gbogbo ohun èlò rẹ̀, ya pẹpẹ náà sí mímọ́, yóò sì jẹ́ mímọ́ jùlọ.
And thou shalt anoint the altar of burnt-offering, and all its vessels; and thou shalt sanctify the altar, and the altar shall be most holy.
11 Ta òróró sára agbada náà àti ẹsẹ̀ rẹ, kí o sì yà wọ́n sí mímọ́.
And thou shalt anoint the laver with its foot, and sanctify it.
12 “Mú Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀ wá sí ẹnu-ọ̀nà àgọ́ àjọ, kí o sì wẹ̀ wọ́n pẹ̀lú omi.
And thou shalt bring near Aaron and his sons unto the door of the tabernacle of the congregation, and wash them with water.
13 Nígbà náà wọ Aaroni ní aṣọ mímọ́, ta òróró sí i ní orí, kí o sì yà á sí mímọ́, nítorí kí ó lè máa sìn mi bí àlùfáà.
And thou shalt clothe Aaron with the holy garments; and thou shalt anoint him, and sanctify him, that he may be a priest unto me.
14 Mú àwọn ọmọ rẹ̀ kí o sì fi aṣọ àwọ̀tẹ́lẹ̀ wọ̀ wọ́n.
And his sons shalt thou bring near, and clothe them with coats:
15 Ta òróró sí wọn ní orí gẹ́gẹ́ bí o ti ta òróró sí baba wọn ní orí, nítorí kì wọn lè máa sìn mi bí àlùfáà. Ìtasórí wọn yóò jẹ́ iṣẹ́ àlùfáà ti yóò máa lò fún gbogbo ìrandíran tó ń bọ̀.”
And thou shalt anoint them, as thou hast anointed their father, that they may be priests unto me; and this shall be, that their anointing shall be unto them for an everlasting priesthood throughout their generations.
16 Mose ṣe ohun gbogbo gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún un.
And Moses did so; all, just as the Lord had commanded him, so did he.
17 Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n gbé àgọ́ náà ró ní ọjọ́ kìn-ín-ní oṣù kìn-ín-ní ní ọdún kejì.
And it came to pass in the first month in the second year, on the first of the month, that the tabernacle was reared up.
18 Nígbà tí Mose gbé àgọ́ náà ró ó fi ihò ìtẹ̀bọ̀ sí ààyè rẹ̀, ó to pákó rẹ̀, ó fi ọ̀pá rẹ̀ bọ̀ ọ́, ó sì gbé àwọn òpó rẹ̀ ró.
And Moses reared up the tabernacle, and placed its sockets, and set up its boards, and put in its bars, and reared up its pillars.
19 Ó na aṣọ àgọ́ náà sórí àgọ́, ó sì fi ìbòrí bo orí àgọ́ náà, bí Olúwa ṣe pàṣẹ fún Mose.
And he spread the tent over the tabernacle, and put the covering of the tent over it above; as the Lord had commanded Moses.
20 Ó mu ẹ̀rí, ó sì fi sínú àpótí, ó so àwọn òpó mọ́ àpótí náà, ó sì fi àánú bo orí rẹ.
And he took and put the testimony into the ark, and placed the staves on the ark; and he put the mercy-seat upon the ark above.
21 Ó sì gbé àpótí náà wá sínú àgọ́; ó sì sọ aṣọ títa, ó sì ta á bo àpótí ẹ̀rí, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose.
And he brought the ark into the tabernacle, and set up the vail of the separation, and made therewith a separation for the ark of the testimony; as the Lord had commanded Moses.
22 Mose gbé tábìlì sínú àgọ́ àjọ sí ìhà àríwá àgọ́ náà lẹ́yìn aṣọ títa,
And he put the table in the tabernacle of the congregation, upon the side of the tabernacle, northward, without the vail.
23 ó sì to àkàrà sórí rẹ̀ níwájú Olúwa, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose.
And he arranged upon it the order of bread before the Lord; as the Lord had commanded Moses.
24 Ó gbé ọ̀pá fìtílà sínú àgọ́ àjọ ní òdìkejì tábìlì ní ìhà gúúsù àgọ́ náà.
And he placed the candlestick in the tabernacle of the congregation, opposite the table, on the side of the tabernacle, southward.
25 Ó sì tan àwọn fìtílà náà níwájú Olúwa, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose.
And he lighted the lamps before the Lord; as the Lord had commanded Moses.
26 Mose gbé pẹpẹ wúrà sínú àgọ́ àjọ níwájú aṣọ títa
And he placed the golden altar in the tabernacle of the congregation before the vail.
27 ó sì jó tùràrí dídùn lórí rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose.
And he burnt thereon the incense of spices; as the Lord had commanded Moses.
28 Ó sì ta aṣọ títa sí ẹnu-ọ̀nà àgọ́ náà.
And he put up the hanging at the door to the tabernacle.
29 Ó gbé pẹpẹ ẹbọ sísun sí ẹ̀gbẹ́ ẹnu-ọ̀nà àgọ́ àjọ, ó sì rú ẹbọ sísun àti ẹbọ oúnjẹ, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose.
And the altar of burnt-offering he placed by the door of the tabernacle of the tent of the congregation; and he offered upon it the burnt-offering and the meat-offering; as the Lord had commanded Moses.
30 Ó gbé agbada sí àárín àgọ́ àjọ àti pẹpẹ, ó sì pọn omi sínú rẹ̀ fún wíwẹ̀,
And he set the laver between the tabernacle of the congregation and the altar, and put water there, for washing.
31 Mose, Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀ lò ó láti fi wẹ ọwọ́ àti ẹsẹ̀ wọn.
And Moses and Aaron and his sons washed therefrom their hands and their feet.
32 Wọ́n máa ń wẹ̀ nígbàkígbà tí wọ́n bá wọ àgọ́ àjọ tàbí tí wọ́n bá súnmọ́ pẹpẹ, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose.
When they went in unto the tabernacle of the congregation, and when they came near unto the altar, they washed themselves; as the Lord had commanded Moses.
33 Mose sì gbé àgbàlá tí ó yí àgọ́ náà kà ró àti pẹpẹ, ó sì ta aṣọ títa ti ẹnu-ọ̀nà sí àgbàlá náà. Bẹ́ẹ̀ ni Mose ṣe parí iṣẹ́ náà.
And he reared up the court round about the tabernacle and the altar, and put up the hanging of the gate of the court; and so did Moses finish the work.
34 Nígbà náà ni àwọsánmọ̀ bo àgọ́ àjọ, ògo Olúwa bo àgọ́ náà.
And the cloud covered the tent of the congregation, and the glory of the Lord filled the tabernacle.
35 Mose kò sì lè wọ inú àgọ́ àjọ, nítorí àwọsánmọ̀ wà ní orí àgọ́, ògo Olúwa sì ti kún inú àgọ́ náà.
And Moses was not able to enter into the tent of the congregation; because the cloud abode thereon, and the glory of the Lord filled the tabernacle.
36 Ní gbogbo ìrìnàjò àwọn ọmọ Israẹli nígbàkígbà tí a bá ti fa ìkùùkuu àwọsánmọ̀ náà sókè kúrò lórí àgọ́, wọ́n máa ń jáde lọ;
And when the cloud was taken up from over the tabernacle, the children of Israel were wont to go onward in all their journeyings.
37 ṣùgbọ́n tí àwọsánmọ̀ kò bá gòkè wọn kò ní jáde títí di ọjọ́ tí ó bá gòkè.
But if the cloud was not taken up, then they journeyed not till the day that is was taken up.
38 Nítorí náà àwọsánmọ̀ Olúwa wà lórí àgọ́ ní ọ̀sán, iná sì wà nínú àwọsánmọ̀ ní alẹ́, ní ojú gbogbo ilé Israẹli ní gbogbo ìrìnàjò wọn.
For the cloud of the Lord was upon the tabernacle by day, and a fire was by night on it, before the eyes of all the house of Israel, throughout all their journeyings.

< Exodus 40 >