< Exodus 4 >

1 Mose dáhùn ó sì wí pé, “Ṣùgbọ́n bí wọn kò bá gbà mí gbọ́ ń kọ́? Tàbí tí wọn kò fi etí sílẹ̀ láti gbọ́ ọ̀rọ̀ ẹnu mi, tí wọn sì wí pé, ‘Olúwa kò farahàn ọ́’?”
Musa jawab berip: — Mana, ular manga ixǝnmǝy turup, sɵzümgǝ ⱪulaⱪ salmaydu, bǝlki: «Pǝrwǝrdigar sanga kɵrünmidi», deyixi mumkin, dedi.
2 Ní ìgbà náà ni Olúwa sọ fún un pé, “Kí ni ó wà ní ọwọ́ rẹ n nì?” Ó sì dáhùn pé, “Ọ̀pá ni.”
Pǝrwǝrdigar uningƣa: — Ⱪolungdiki bu nemǝ? — dǝp soridi. U: — Bu bir ⱨasa, dǝp jawab bǝrdi.
3 Olúwa sì sọ pé, “Sọ ọ̀pá náà sílẹ̀.” Mose sì sọ ọ̀pá náà sílẹ̀, lọ́gán ni ọ̀pá náà di ejò, ó sì sá fún un.
U: — Uni yǝrgǝ taxla, dedi. Uni yǝrgǝ taxliwidi, u bir yilanƣa aylandi; Musa uning aldidin ⱪaqti.
4 Nígbà náà ni Olúwa wá sọ fún un pé, “Na ọwọ́ rẹ, kí o sì mú un ni ìrù.” Mose sì na ọwọ́ rẹ̀, ó sì mu ejò náà, ejò náà sì padà di ọ̀pá tí ó wà ni ọwọ́ rẹ̀.
Andin Pǝrwǝrdigar Musaƣa: — Ⱪolungni uzitip, uni ⱪuyruⱪidin tut, dewidi, u ⱪolini uzitip, uni tutti. U yǝnǝ uning ⱪolida ⱨasiƣa aylandi.
5 Olúwa sì wí pé, “Èyí rí bẹ́ẹ̀ kí wọn bá à le è gbàgbọ́ pé, Olúwa Ọlọ́run àwọn baba wọn, Ọlọ́run Abrahamu, Ọlọ́run Isaaki, àti Ọlọ́run Jakọbu; tí farahàn ọ́.”
[Pǝrwǝrdigar yǝnǝ]: — Buning bilǝn ular ata-bowilirining Hudasi, yǝni Ibraⱨimning Hudasi, Isⱨaⱪning Hudasi wǝ Yaⱪupning Hudasi bolƣan Pǝrwǝrdigarning sanga kɵrünginigǝ ixinidu, — dedi.
6 Ní ìgbà náà ni Olúwa wí pé, “Ti ọwọ́ rẹ bọ inú aṣọ ní igbá àyà rẹ̀.” Mose sì ti ọwọ́ rẹ̀ bọ inú aṣọ ní igbá àyà rẹ̀, ní ìgbà ti ó sì yọ ọ́ jáde, ọwọ́ rẹ̀ ti dẹ́tẹ̀, ó sì ti funfun bí ẹ̀gbọ̀n òwú.
Pǝrwǝrdigar uningƣa yǝnǝ: — Ⱪolungni ⱪoynungƣa salƣin, dewidi, u ⱪolini ⱪoyniƣa selip qiⱪiriwidi, mana, ⱪoli pesǝ-mahaw kesiligǝ giriptar bolup ⱪardǝk aⱪirip kǝtti.
7 Ó sì wí pé, “Nísinsin yìí, fi ọwọ́ náà padà sí abẹ́ aṣọ ní igbá àyà rẹ.” Mose sì ṣe bẹ́ẹ̀, ọwọ́ rẹ̀ sì padà bọ́ sípò bí àwọn ẹ̀yà ara rẹ̀ tókù.
Andin uningƣa: — Ⱪolungni yǝnǝ ⱪoynungƣa salƣin, dewidi, ⱪolini ⱪoyniƣa saldi. Uni yǝnǝ ⱪoynidin qiⱪiriwidi, mana, ɵz ǝksigǝ kelip ǝtlirining baxⱪa yǝrliridǝk boldi.
8 Ní ìgbà náà ni Olúwa wí pé, “Bí wọn kò bá gbà ọ́ gbọ́ tàbí kọ ibi ara sí iṣẹ́ ìyanu àkọ́kọ́, wọ́n le è ti ipasẹ̀ iṣẹ́ ìyanu kejì gbàgbọ́.
Pǝrwǝrdigar yǝnǝ: — Xundaⱪ boliduki, ǝgǝr ular sanga ixǝnmǝy, aldinⱪi mɵjizilik alamǝtkǝ kɵngülximisǝ, ular ikkinqi mɵjizilik alamǝtkǝ ixinidu.
9 Ṣùgbọ́n bí wọn kò bá gba àmì méjèèjì wọ̀nyí gbọ́, tí wọn kò sì fetí sí ọ̀rọ̀ rẹ, bu omi díẹ̀ láti inú odò Naili kí o si dà á sí orí ìyàngbẹ ilẹ̀, omi tí ìwọ bù láti inú odò yìí yóò sì di ẹ̀jẹ̀.”
Ⱨalbuki, ular bu ikki mɵjizigǝ yǝnila ixǝnmisǝ wǝ ya sɵzünggǝ ⱪulaⱪ salmisa, undaⱪta sǝn [Nil] dǝryasining süyidin elip, ⱪuruⱪ yǝrgǝ tɵkkin. Xuning bilǝn sǝn dǝryadin alƣan su ⱪuruⱪ yǝr üstidǝ ⱪanƣa aylinidu, dedi.
10 Mose sì sọ fún Olúwa pé, “Èmi jẹ́ akólòlò, èmi kì í ṣe ẹni tó lè sọ̀rọ̀ já gaara láti ìgbà àtijọ́ wá tàbí láti ìgbà ti o ti ń bá ìránṣẹ́ rẹ sọ̀rọ̀, mo jẹ́ ẹni ti ahọ́n rẹ̀ lọ́, tí ó sì ń lọ́ra àti sọ̀rọ̀.”
Andin Musa Pǝrwǝrdigarƣa: — Əy Igǝm, mǝn ǝslidinla gǝpkǝ usta ǝmǝstim, sǝn ⱪulungƣa sɵz ⱪilƣandin keyinmu yǝnila xundaⱪ; qünki mǝn aƣzim kalwa wǝ tilim eƣir adǝmmǝn, — dedi.
11 Olúwa sì sọ fún un pé, “Ta ni ó fún ènìyàn ni ẹnu? Ta ni ó mú un ya odi tàbí adití? Ta ni ó mú un ríran, tàbí mú un fọ́jú? Ǹjẹ́ kì í ṣe èmi Olúwa?
Pǝrwǝrdigar uningƣa: — Kim insanƣa eƣiz bǝrgǝn? Kim adǝmni gaqa yaki gas, kɵrgüqi yaki kor ⱪilƣan? Xundaⱪ ⱪilƣuqi Mǝn Pǝrwǝrdigar ǝmǝsmu?
12 Lọ nísinsin yìí, Èmi yóò ràn ọ́ lọ́wọ́ láti sọ̀rọ̀. Èmi yóò sì kọ́ ọ ni ohun ti ìwọ yóò sọ.”
Əmdi sǝn barƣin, Mǝn Ɵzüm sening aƣzing bilǝn billǝ bolimǝn, nemǝ sɵzlǝydiƣiningni sanga ɵgitip turimǝn, — dedi.
13 Mose dáhùn ó wí pé, “Olúwa jọ̀wọ́ rán ẹlòmíràn láti lọ ṣe iṣẹ́ yìí.”
Lekin u: — Əy Igǝm! Sǝndin ɵtünüp ⱪalay, Sǝn [bu ixⱪa] haliƣan [baxⱪa] birsini ǝwǝtip, xuning ⱪoli bilǝn ⱪilƣin! — dedi.
14 Ìbínú Olúwa ru sókè sí Mose, ó sì sọ pé, “Aaroni ará Lefi arákùnrin rẹ ń kọ́? Mo mọ̀ pé ó lè sọ̀rọ̀ já gaara, ó ti wà ní ọ̀nà rẹ̀ báyìí láti pàdé e rẹ. Inú rẹ̀ yóò sì dùn ti ó bá rí ọ.
Buni anglap Pǝrwǝrdigarning ƣǝzipi Musaƣa tutixip: — Lawiylardin bolƣan akang Ⱨarun bar ǝmǝsmu? Uning gǝpni obdan ⱪilalaydiƣinini bilimǝn. Mana, u ǝmdi sening aldingƣa qiⱪixⱪa alliⱪaqan yolƣa qiⱪti; u seni kɵrsǝ, kɵngli tolimu hux bolidu.
15 Ìwọ yóò sọ̀rọ̀ fún un, ìwọ yóò sì fi ọ̀rọ̀ sí i lẹ́nu, èmi yóò ràn yín lọ́wọ́ láti sọ̀rọ̀. Èmi yóò kọ́ ọ yín ni ohun ti ẹ ó ṣe.
Əmdi dǝydiƣan gǝplǝrni uningƣa eyt; Mǝn Ɵzüm sening aƣzing bilǝn billǝ wǝ uning aƣzi bilǝn billǝ bolimǝn, nemǝ ⱪilix kerǝklikinglarni silǝrgǝ ɵgitimǝn.
16 Òun yóò bá ọ sọ̀rọ̀ sí àwọn ènìyàn, yóò sì dàbí i pé ẹnu un rẹ ni a gbà sọ ọ̀rọ̀ náà, ìwọ yóò sì dàbí Ọlọ́run ní iwájú rẹ̀.
Ⱨarun sening ornungda hǝlⱪⱪǝ sɵzlǝydu; xundaⱪ boliduki, u sanga eƣiz bolidu, sǝn uningƣa Hudadǝk bolisǝn.
17 Ṣùgbọ́n mú ọ̀pá yìí ni ọwọ́ rẹ kí ìwọ bá à lè fi ṣe àwọn iṣẹ́ àmì ìyanu pẹ̀lú rẹ̀.”
Bu ⱨasini ⱪolungƣa elip, uning bilǝn xu mɵjizilik alamǝtlǝrni kɵrsitisǝn, — dedi.
18 Mose padà sí ọ̀dọ̀ Jetro baba ìyàwó rẹ̀, ó sì sọ fún un pé, “Jọ̀wọ́ jẹ́ kí n padà tọ àwọn ènìyàn mi lọ ni ilẹ̀ Ejibiti láti wò bóyá wọ́n ṣì wà láààyè síbẹ̀.” Jetro sì dáhùn, ó wí pé, “Máa lọ ni àlàáfíà.”
Xuning bilǝn Musa ⱪeynatisi Yǝtroning ⱪexiƣa yenip berip, uningƣa: — Manga ijazǝt bǝrgǝyla, Misirdiki ⱪerindaxlirimning ⱪexiƣa baray, ular ⱨayatmu, ǝmǝsmu kɵrüp kelǝy, dedi. Yǝtro Musaƣa: — Aman-esǝn berip kǝlgin, — dedi.
19 Nísinsin yìí, Olúwa ti sọ fún Mose ni ilẹ̀ Midiani pé, “Máa padà lọ sí Ejibiti, nítorí àwọn ti ó fẹ́ pa ọ ti kú.”
Musa tehi Midiyandiki waⱪtida, Pǝrwǝrdigar uningƣa yǝnǝ: — Misirƣa yenip barƣin! Qünki sening jeningni istigǝn kixilǝr ɵlüp kǝtti, — dedi.
20 Mose mú ìyàwó rẹ̀ àti àwọn ọmọ rẹ̀, ó kó wọn lé orí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, ó sì bẹ̀rẹ̀ ìrìnàjò rẹ̀ padà sí Ejibiti. Ó sì mú ọ̀pá Ọlọ́run sí ọwọ́ rẹ̀.
Xuning bilǝn Musa ayali wǝ oƣullirini elip, ularni bir exǝkkǝ mindürüp, Misir zeminiƣa berixⱪa yolƣa qiⱪti. Mangƣanda Musa Hudaning ⱨasisini alƣaq kǝtti.
21 Olúwa sì sọ fún Mose pé, “Ní ìgbà tí ìwọ bá padà sí Ejibiti rí i pé ìwọ ṣe iṣẹ́ ìyanu ni iwájú Farao. Èmi ti fún ọ lágbára láti ṣe é. Èmi yóò sì sé àyà rẹ̀ le, òun kì yóò jẹ́ kí àwọn ènìyàn náà kí ó lọ.
Pǝrwǝrdigar Musaƣa: — Misirƣa yenip barƣiningda sǝn agaⱨ bol, Mǝn ⱪolungƣa tapxurƣan barliⱪ karamǝtlǝrni Pirǝwnning aldida kɵrsǝtkin. Lekin Mǝn uning kɵnglini hǝlⱪni ⱪoyup bǝrmigüdǝk ⱪattiⱪ ⱪilimǝn.
22 Lẹ́yìn náà, kí o sọ fún Farao pé, ‘Èyí ni Olúwa sọ: Israẹli ní àkọ́bí ọmọ mi ọkùnrin,
Sǝn Pirǝwngǝ: — «Pǝrwǝrdigar mundaⱪ dǝydu: — Israil Mening oƣlum, Mening tunji oƣlum bolidu.
23 mo sọ fún ọ, “Jẹ́ kí ọmọ mi lọ, ki òun kí ó lè máa sìn mí.” Ṣùgbọ́n ìwọ kọ̀ láti jẹ́ kí ó lọ; nítorí náà, èmi yóò pa àkọ́bí ọmọ rẹ ọkùnrin.’”
Xuning üqün Mǝn sanga: Oƣlumni Ɵzümgǝ ibadǝt ⱪilixⱪa ⱪoyup bǝr, dedim. Uningƣa yol ⱪoyuxni rǝt ⱪilidiƣan bolsang, sening tunji oƣlungni ɵltürimǝn» — degin, — dedi.
24 Ní ọ̀nà ìrìnàjò rẹ, ni ibi tí wọ́n gbé sùn ní ilé èrò ní alẹ́, Olúwa pàdé Mose, ó sì fẹ́ láti pa á.
Əmma Musa sǝpǝr ⱪilip bir ⱪonalƣuƣa kǝlgǝndǝ, Pǝrwǝrdigar uningƣa uqrap, uni ɵltürüwǝtmǝkqi boldi.
25 Ṣùgbọ́n Sippora mú ọ̀bẹ òkúta mímú, ó sì kọ ọmọ rẹ̀ ní ilà abẹ́, ó sì fi awọ rẹ̀ kan ẹsẹ̀ Mose. Sippora sì wí pé, “Ọkọ ẹlẹ́jẹ̀ ni ìwọ jẹ́ sí mi.”
Xuning bilǝn Zipporaⱨ bir qaⱪmaⱪ texini elip, oƣlining hǝtnilikini kesip, uni erining ayiƣiƣa taxlap: — Sǝn dǝrwǝⱪǝ aldimda ⱪan tɵkǝr ǝr ikǝnsǝn! — dedi.
26 Nítorí náà Olúwa yọ̀ǹda rẹ láti ìgbà tí ó ti wí pé, “Ẹlẹ́jẹ̀ ni ìwọ í ṣe.” Èyí tó túmọ̀ sí ìkọlà abẹ́.
Xuning bilǝn Pǝrwǝrdigar uni ⱪoyup bǝrdi (bu qaƣda Zipporaⱨ uningƣa: «Sǝn dǝrwǝⱪǝ aldimda ⱪan tɵkǝr bir ǝr ikǝnsǝn!» — dedi. Bu sɵzini u hǝtnǝ tüpǝylidin eytti).
27 Olúwa sì sọ fún Aaroni pé, “Lọ sínú aginjù láti lọ pàdé Mose.” Ní ìgbà náà ni ó lọ pàdé Mose ní orí òkè Ọlọ́run, ó sì fi ẹnu kò ó ní ẹnu.
Pǝrwǝrdigar Ⱨarunƣa: — Sǝn qɵl-bayawanƣa berip, Musa bilǝn kɵrüxkin, dewidi, u berip Hudaning teƣida uning bilǝn uqrixip, uni sɵydi.
28 Ní ìgbà náà ni Mose sì sọ ohun gbogbo tí Ọlọ́run ti rán fún Aaroni àti nípa gbogbo iṣẹ́ ìyanu tí Olúwa ti pàṣẹ fún un láti ṣe ní iwájú Farao.
Musa ɵzini ǝwǝtkǝn Pǝrwǝrdigarning ⱨǝmmǝ sɵzliri bilǝn ⱪilixⱪa buyruƣan barliⱪ mɵjizilik alamǝtlǝrni Ⱨarunƣa dǝp bǝrdi.
29 Mose àti Aaroni pe gbogbo àwọn àgbàgbà Israẹli jọ.
Andin Musa bilǝn Ⱨarun berip, Israillarning barliⱪ aⱪsaⱪallirini yiƣdi.
30 Aaroni sọ ohun gbogbo tí Olúwa sọ fún Mose fún wọn, ó sì ṣe iṣẹ́ àmì náà ní ojú àwọn ènìyàn náà.
Ⱨarun Pǝrwǝrdigarning Musaƣa eytⱪan ⱨǝmmǝ sɵzlirini bayan ⱪildi wǝ hǝlⱪning kɵz aldida xu mɵjizilik alamǝtlǝrni kɵrsǝtti.
31 Wọ́n sì gbàgbọ́. Nígbà tí wọ́n gbọ́ pé Olúwa ti bẹ àwọn ọmọ Israẹli wò àti pé Olúwa ti gbọ́ nípa ìpọ́njú wọn, wọ́n tẹríba, wọ́n sì sìn ín. Ó sì ṣe àwọn iṣẹ́ àmì náà níwájú àwọn ènìyàn náà.
Buni kɵrüp, hǝlⱪ ixǝndi; Pǝrwǝrdigarning Israillarni yoⱪlap, ular uqriƣan harliⱪlarni kɵrgǝnlikini angliƣan ⱨaman, baxlirini egip sǝjdǝ ⱪilixti.

< Exodus 4 >