< Exodus 4 >

1 Mose dáhùn ó sì wí pé, “Ṣùgbọ́n bí wọn kò bá gbà mí gbọ́ ń kọ́? Tàbí tí wọn kò fi etí sílẹ̀ láti gbọ́ ọ̀rọ̀ ẹnu mi, tí wọn sì wí pé, ‘Olúwa kò farahàn ọ́’?”
Mojzes je odgovoril in rekel: »Toda, glej, ne bodo mi verjeli niti prisluhnili mojemu glasu, kajti rekli bodo: › Gospod se ti ni prikazal.‹«
2 Ní ìgbà náà ni Olúwa sọ fún un pé, “Kí ni ó wà ní ọwọ́ rẹ n nì?” Ó sì dáhùn pé, “Ọ̀pá ni.”
Gospod mu je rekel: »Kaj je to v tvoji roki?« Rekel je: »Palica.«
3 Olúwa sì sọ pé, “Sọ ọ̀pá náà sílẹ̀.” Mose sì sọ ọ̀pá náà sílẹ̀, lọ́gán ni ọ̀pá náà di ejò, ó sì sá fún un.
Rekel je: »Vrzi jo na tla.« Vrgel jo je na tla in ta je postala kača in Mojzes je pobegnil pred njo.
4 Nígbà náà ni Olúwa wá sọ fún un pé, “Na ọwọ́ rẹ, kí o sì mú un ni ìrù.” Mose sì na ọwọ́ rẹ̀, ó sì mu ejò náà, ejò náà sì padà di ọ̀pá tí ó wà ni ọwọ́ rẹ̀.
Gospod je rekel Mojzesu: »Iztegni svojo roko in jo primi za rep.« Iztegnil je svojo roko in jo ujel in v njegovi roki je postala palica.
5 Olúwa sì wí pé, “Èyí rí bẹ́ẹ̀ kí wọn bá à le è gbàgbọ́ pé, Olúwa Ọlọ́run àwọn baba wọn, Ọlọ́run Abrahamu, Ọlọ́run Isaaki, àti Ọlọ́run Jakọbu; tí farahàn ọ́.”
»Da bodo oni lahko verjeli, da se ti je prikazal Gospod, Bog njihovih očetov, Bog Abrahama, Bog Izaka in Bog Jakoba.«
6 Ní ìgbà náà ni Olúwa wí pé, “Ti ọwọ́ rẹ bọ inú aṣọ ní igbá àyà rẹ̀.” Mose sì ti ọwọ́ rẹ̀ bọ inú aṣọ ní igbá àyà rẹ̀, ní ìgbà ti ó sì yọ ọ́ jáde, ọwọ́ rẹ̀ ti dẹ́tẹ̀, ó sì ti funfun bí ẹ̀gbọ̀n òwú.
Gospod mu je nadalje rekel: »Sedaj daj svojo roko v svoje naročje.« Svojo roko je položil v svoje naročje, ko pa jo je izvlekel, glej, je bila njegova roka gobava kakor sneg.
7 Ó sì wí pé, “Nísinsin yìí, fi ọwọ́ náà padà sí abẹ́ aṣọ ní igbá àyà rẹ.” Mose sì ṣe bẹ́ẹ̀, ọwọ́ rẹ̀ sì padà bọ́ sípò bí àwọn ẹ̀yà ara rẹ̀ tókù.
Rekel je: »Svojo roko ponovno daj v svoje naročje.« In ponovno je svojo roko položil v svoje naročje in izvlekel jo je iz svojega naročja in glej, ponovno je bila spremenjena kakor drugo njegovo meso.
8 Ní ìgbà náà ni Olúwa wí pé, “Bí wọn kò bá gbà ọ́ gbọ́ tàbí kọ ibi ara sí iṣẹ́ ìyanu àkọ́kọ́, wọ́n le è ti ipasẹ̀ iṣẹ́ ìyanu kejì gbàgbọ́.
»Zgodilo se bo, če ti ne bodo verjeli niti prisluhnili glasu prvega znamenja, da bodo verjeli glasu zadnjega znamenja.
9 Ṣùgbọ́n bí wọn kò bá gba àmì méjèèjì wọ̀nyí gbọ́, tí wọn kò sì fetí sí ọ̀rọ̀ rẹ, bu omi díẹ̀ láti inú odò Naili kí o si dà á sí orí ìyàngbẹ ilẹ̀, omi tí ìwọ bù láti inú odò yìí yóò sì di ẹ̀jẹ̀.”
Zgodilo se bo, če ne bodo verjeli tudi tema dvema znamenjema niti prisluhnili tvojemu glasu, da boš iz reke zajel vodo in jo izlil na suho zemljo in voda, ki jo zajameš iz reke, bo na suhih tleh postala kri.«
10 Mose sì sọ fún Olúwa pé, “Èmi jẹ́ akólòlò, èmi kì í ṣe ẹni tó lè sọ̀rọ̀ já gaara láti ìgbà àtijọ́ wá tàbí láti ìgbà ti o ti ń bá ìránṣẹ́ rẹ sọ̀rọ̀, mo jẹ́ ẹni ti ahọ́n rẹ̀ lọ́, tí ó sì ń lọ́ra àti sọ̀rọ̀.”
Mojzes je Gospodu rekel: »Oh moj Gospod, jaz nisem zgovoren, niti poprej niti odkar si spregovoril svojemu služabniku, temveč sem počasen za govorjenje in počasnega jezika.«
11 Olúwa sì sọ fún un pé, “Ta ni ó fún ènìyàn ni ẹnu? Ta ni ó mú un ya odi tàbí adití? Ta ni ó mú un ríran, tàbí mú un fọ́jú? Ǹjẹ́ kì í ṣe èmi Olúwa?
Gospod mu je rekel: »Kdo je naredil človekova usta? Ali kdo naredi nemega ali gluhega ali da vidi ali slepega? Ali ne jaz, Gospod?
12 Lọ nísinsin yìí, Èmi yóò ràn ọ́ lọ́wọ́ láti sọ̀rọ̀. Èmi yóò sì kọ́ ọ ni ohun ti ìwọ yóò sọ.”
Sedaj torej pojdi in jaz bom s tvojimi usti in te učil kaj boš govoril.«
13 Mose dáhùn ó wí pé, “Olúwa jọ̀wọ́ rán ẹlòmíràn láti lọ ṣe iṣẹ́ yìí.”
Rekel je: »Oh moj Gospod, pošlji, prosim te, po roki tistega, ki ga ti hočeš poslati.«
14 Ìbínú Olúwa ru sókè sí Mose, ó sì sọ pé, “Aaroni ará Lefi arákùnrin rẹ ń kọ́? Mo mọ̀ pé ó lè sọ̀rọ̀ já gaara, ó ti wà ní ọ̀nà rẹ̀ báyìí láti pàdé e rẹ. Inú rẹ̀ yóò sì dùn ti ó bá rí ọ.
Gospodova jeza je bila vžgana zoper Mojzesa in rekel je: » Mar ni Lévijevec Aron tvoj brat? Vem, da lahko dobro govori. In tudi, glej, prihaja, da te sreča in ko te zagleda, bo v svojem srcu vesel.
15 Ìwọ yóò sọ̀rọ̀ fún un, ìwọ yóò sì fi ọ̀rọ̀ sí i lẹ́nu, èmi yóò ràn yín lọ́wọ́ láti sọ̀rọ̀. Èmi yóò kọ́ ọ yín ni ohun ti ẹ ó ṣe.
Ti mu boš govoril in v njegova usta polagal besede in jaz bom s tvojimi usti in z njegovimi usti in vaju učil, kaj bosta storila.
16 Òun yóò bá ọ sọ̀rọ̀ sí àwọn ènìyàn, yóò sì dàbí i pé ẹnu un rẹ ni a gbà sọ ọ̀rọ̀ náà, ìwọ yóò sì dàbí Ọlọ́run ní iwájú rẹ̀.
On bo tvoj govornik ljudstvu in on bo, celó on bo tebi namesto ust in ti boš njemu namesto Boga.
17 Ṣùgbọ́n mú ọ̀pá yìí ni ọwọ́ rẹ kí ìwọ bá à lè fi ṣe àwọn iṣẹ́ àmì ìyanu pẹ̀lú rẹ̀.”
In v svojo roko boš vzel to palico, s katero boš delal znamenja.«
18 Mose padà sí ọ̀dọ̀ Jetro baba ìyàwó rẹ̀, ó sì sọ fún un pé, “Jọ̀wọ́ jẹ́ kí n padà tọ àwọn ènìyàn mi lọ ni ilẹ̀ Ejibiti láti wò bóyá wọ́n ṣì wà láààyè síbẹ̀.” Jetro sì dáhùn, ó wí pé, “Máa lọ ni àlàáfíà.”
Mojzes je odšel, se vrnil k svojemu tastu Jitru in mu rekel: »Pusti me iti, prosim te in se vrniti k mojim bratom, ki so v Egiptu in videti ali so še živi.« Jitro je Mojzesu rekel: »Pojdi v miru.«
19 Nísinsin yìí, Olúwa ti sọ fún Mose ni ilẹ̀ Midiani pé, “Máa padà lọ sí Ejibiti, nítorí àwọn ti ó fẹ́ pa ọ ti kú.”
Gospod je v Midjánu rekel Mojzesu: »Pojdi, vrni se v Egipt, kajti vsi ljudje, ki so ti stregli po življenju, so mrtvi.«
20 Mose mú ìyàwó rẹ̀ àti àwọn ọmọ rẹ̀, ó kó wọn lé orí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, ó sì bẹ̀rẹ̀ ìrìnàjò rẹ̀ padà sí Ejibiti. Ó sì mú ọ̀pá Ọlọ́run sí ọwọ́ rẹ̀.
Mojzes je vzel svojo ženo in svoja sinova in jih posadil na osla in se vrnil v egiptovsko deželo in Mojzes je v svojo roko vzel Božjo palico.
21 Olúwa sì sọ fún Mose pé, “Ní ìgbà tí ìwọ bá padà sí Ejibiti rí i pé ìwọ ṣe iṣẹ́ ìyanu ni iwájú Farao. Èmi ti fún ọ lágbára láti ṣe é. Èmi yóò sì sé àyà rẹ̀ le, òun kì yóò jẹ́ kí àwọn ènìyàn náà kí ó lọ.
Gospod je rekel Mojzesu: »Ko greš, da se vrneš v Egipt, glej, da boš pred faraonom storil vse te čudeže, ki sem jih položil v tvojo roko, toda jaz bom zakrknil njegovo srce, da ljudstvu ne bo dovolil oditi.
22 Lẹ́yìn náà, kí o sọ fún Farao pé, ‘Èyí ni Olúwa sọ: Israẹli ní àkọ́bí ọmọ mi ọkùnrin,
Faraonu boš rekel: ›Tako govori Gospod, Izrael je moj sin, celo moj prvorojenec‹
23 mo sọ fún ọ, “Jẹ́ kí ọmọ mi lọ, ki òun kí ó lè máa sìn mí.” Ṣùgbọ́n ìwọ kọ̀ láti jẹ́ kí ó lọ; nítorí náà, èmi yóò pa àkọ́bí ọmọ rẹ ọkùnrin.’”
in jaz ti pravim: ›dovoli mojemu sinu oditi, da mi bo lahko služil. Če pa mu boš odklonil oditi, glej, bom ubil tvojega sina, celó tvojega prvorojenca.‹«
24 Ní ọ̀nà ìrìnàjò rẹ, ni ibi tí wọ́n gbé sùn ní ilé èrò ní alẹ́, Olúwa pàdé Mose, ó sì fẹ́ láti pa á.
Pripetilo se je po poti v gostišče, da ga je srečal Gospod in si prizadeval, da ga ubije.
25 Ṣùgbọ́n Sippora mú ọ̀bẹ òkúta mímú, ó sì kọ ọmọ rẹ̀ ní ilà abẹ́, ó sì fi awọ rẹ̀ kan ẹsẹ̀ Mose. Sippora sì wí pé, “Ọkọ ẹlẹ́jẹ̀ ni ìwọ jẹ́ sí mi.”
Tedaj je Cipóra vzela oster kamen in odrezala prednjo kožico svojega sina in jo vrgla k njegovim stopalom ter rekla: »Zagotovo si mi krvav soprog.«
26 Nítorí náà Olúwa yọ̀ǹda rẹ láti ìgbà tí ó ti wí pé, “Ẹlẹ́jẹ̀ ni ìwọ í ṣe.” Èyí tó túmọ̀ sí ìkọlà abẹ́.
Tako ga je pustil oditi. Potem je rekla: »Krvav soprog si zaradi obreze.«
27 Olúwa sì sọ fún Aaroni pé, “Lọ sínú aginjù láti lọ pàdé Mose.” Ní ìgbà náà ni ó lọ pàdé Mose ní orí òkè Ọlọ́run, ó sì fi ẹnu kò ó ní ẹnu.
Gospod je rekel Aronu: »Pojdi v divjino, da srečaš Mojzesa.« Ta je odšel in ga srečal na gori Boga ter ga poljubil.
28 Ní ìgbà náà ni Mose sì sọ ohun gbogbo tí Ọlọ́run ti rán fún Aaroni àti nípa gbogbo iṣẹ́ ìyanu tí Olúwa ti pàṣẹ fún un láti ṣe ní iwájú Farao.
Mojzes je povedal Aronu vse besede Gospoda, ki ga je poslal in vsa znamenja, ki mu jih je zapovedal.
29 Mose àti Aaroni pe gbogbo àwọn àgbàgbà Israẹli jọ.
Mojzes in Aron sta odšla ter zbrala skupaj vse starešine Izraelovih otrok
30 Aaroni sọ ohun gbogbo tí Olúwa sọ fún Mose fún wọn, ó sì ṣe iṣẹ́ àmì náà ní ojú àwọn ènìyàn náà.
in Aron je govoril vse besede, ki jih je Gospod govoril Mojzesu in v očeh ljudstva storil znamenja.
31 Wọ́n sì gbàgbọ́. Nígbà tí wọ́n gbọ́ pé Olúwa ti bẹ àwọn ọmọ Israẹli wò àti pé Olúwa ti gbọ́ nípa ìpọ́njú wọn, wọ́n tẹríba, wọ́n sì sìn ín. Ó sì ṣe àwọn iṣẹ́ àmì náà níwájú àwọn ènìyàn náà.
Ljudje so verovali in ko so slišali, da je Gospod obiskal Izraelove otroke in da je pogledal na njihovo stisko, potem so sklonili svoje glave in oboževali.

< Exodus 4 >