< Exodus 4 >
1 Mose dáhùn ó sì wí pé, “Ṣùgbọ́n bí wọn kò bá gbà mí gbọ́ ń kọ́? Tàbí tí wọn kò fi etí sílẹ̀ láti gbọ́ ọ̀rọ̀ ẹnu mi, tí wọn sì wí pé, ‘Olúwa kò farahàn ọ́’?”
Potem Mojżesz odpowiedział: Lecz oni mi nie uwierzą i nie usłuchają mego głosu, bo powiedzą: PAN ci się nie ukazał.
2 Ní ìgbà náà ni Olúwa sọ fún un pé, “Kí ni ó wà ní ọwọ́ rẹ n nì?” Ó sì dáhùn pé, “Ọ̀pá ni.”
PAN zapytał go: Co masz w swojej ręce? Odpowiedział: Laskę.
3 Olúwa sì sọ pé, “Sọ ọ̀pá náà sílẹ̀.” Mose sì sọ ọ̀pá náà sílẹ̀, lọ́gán ni ọ̀pá náà di ejò, ó sì sá fún un.
I rozkazał: Rzuć ją na ziemię. Rzucił ją więc na ziemię i zamieniła się w węża; i Mojżesz przed nim uciekał.
4 Nígbà náà ni Olúwa wá sọ fún un pé, “Na ọwọ́ rẹ, kí o sì mú un ni ìrù.” Mose sì na ọwọ́ rẹ̀, ó sì mu ejò náà, ejò náà sì padà di ọ̀pá tí ó wà ni ọwọ́ rẹ̀.
Następnie PAN powiedział do Mojżesza: Wyciągnij rękę i chwyć go za ogon. Wyciągnął więc rękę i chwycił go, i ten zamienił się w laskę w jego ręce.
5 Olúwa sì wí pé, “Èyí rí bẹ́ẹ̀ kí wọn bá à le è gbàgbọ́ pé, Olúwa Ọlọ́run àwọn baba wọn, Ọlọ́run Abrahamu, Ọlọ́run Isaaki, àti Ọlọ́run Jakọbu; tí farahàn ọ́.”
[Uczyń tak], aby uwierzyli, że ukazał ci się PAN, Bóg ich ojców, Bóg Abrahama, Bóg Izaaka i Bóg Jakuba.
6 Ní ìgbà náà ni Olúwa wí pé, “Ti ọwọ́ rẹ bọ inú aṣọ ní igbá àyà rẹ̀.” Mose sì ti ọwọ́ rẹ̀ bọ inú aṣọ ní igbá àyà rẹ̀, ní ìgbà ti ó sì yọ ọ́ jáde, ọwọ́ rẹ̀ ti dẹ́tẹ̀, ó sì ti funfun bí ẹ̀gbọ̀n òwú.
PAN powiedział mu jeszcze: Włóż teraz rękę w zanadrze. Włożył więc rękę w zanadrze, a gdy ją wyjął, była pokryta trądem jak śniegiem.
7 Ó sì wí pé, “Nísinsin yìí, fi ọwọ́ náà padà sí abẹ́ aṣọ ní igbá àyà rẹ.” Mose sì ṣe bẹ́ẹ̀, ọwọ́ rẹ̀ sì padà bọ́ sípò bí àwọn ẹ̀yà ara rẹ̀ tókù.
I powiedział: Włóż ponownie rękę w zanadrze. I włożył znowu rękę w zanadrze, [a gdy] ją wyjął, stała się znowu jak [reszta] jego ciała.
8 Ní ìgbà náà ni Olúwa wí pé, “Bí wọn kò bá gbà ọ́ gbọ́ tàbí kọ ibi ara sí iṣẹ́ ìyanu àkọ́kọ́, wọ́n le è ti ipasẹ̀ iṣẹ́ ìyanu kejì gbàgbọ́.
Jeśli więc ci nie uwierzą i nie usłuchają głosu pierwszego znaku, to uwierzą głosowi drugiego znaku.
9 Ṣùgbọ́n bí wọn kò bá gba àmì méjèèjì wọ̀nyí gbọ́, tí wọn kò sì fetí sí ọ̀rọ̀ rẹ, bu omi díẹ̀ láti inú odò Naili kí o si dà á sí orí ìyàngbẹ ilẹ̀, omi tí ìwọ bù láti inú odò yìí yóò sì di ẹ̀jẹ̀.”
A jeśli nie uwierzą obu tym znakom i nie usłuchają twego głosu, to weźmiesz wody z rzeki i wylejesz [ją] na ziemię. Wtedy ta woda, którą weźmiesz z rzeki, zamieni się na ziemi w krew.
10 Mose sì sọ fún Olúwa pé, “Èmi jẹ́ akólòlò, èmi kì í ṣe ẹni tó lè sọ̀rọ̀ já gaara láti ìgbà àtijọ́ wá tàbí láti ìgbà ti o ti ń bá ìránṣẹ́ rẹ sọ̀rọ̀, mo jẹ́ ẹni ti ahọ́n rẹ̀ lọ́, tí ó sì ń lọ́ra àti sọ̀rọ̀.”
Mojżesz powiedział do PANA: Proszę, Panie, nie jestem wymowny – ani przedtem, ani odkąd przemówiłeś do twego sługi, bo mam powolną mowę i ociężały język.
11 Olúwa sì sọ fún un pé, “Ta ni ó fún ènìyàn ni ẹnu? Ta ni ó mú un ya odi tàbí adití? Ta ni ó mú un ríran, tàbí mú un fọ́jú? Ǹjẹ́ kì í ṣe èmi Olúwa?
PAN mu odpowiedział: Któż uczynił usta człowieka? Albo kto czyni niemego lub głuchego, widzącego lub ślepego? Czyż nie ja, PAN?
12 Lọ nísinsin yìí, Èmi yóò ràn ọ́ lọ́wọ́ láti sọ̀rọ̀. Èmi yóò sì kọ́ ọ ni ohun ti ìwọ yóò sọ.”
Teraz więc idź, a ja będę przy twoich ustach i pouczę cię, co masz mówić.
13 Mose dáhùn ó wí pé, “Olúwa jọ̀wọ́ rán ẹlòmíràn láti lọ ṣe iṣẹ́ yìí.”
[Mojżesz] powiedział: Proszę, Panie, poślij tego, kogo masz posłać.
14 Ìbínú Olúwa ru sókè sí Mose, ó sì sọ pé, “Aaroni ará Lefi arákùnrin rẹ ń kọ́? Mo mọ̀ pé ó lè sọ̀rọ̀ já gaara, ó ti wà ní ọ̀nà rẹ̀ báyìí láti pàdé e rẹ. Inú rẹ̀ yóò sì dùn ti ó bá rí ọ.
Wtedy zapalił się gniew PANA na Mojżesza i powiedział: Czyż Aaron, Lewita, nie jest twoim bratem? Wiem, że on potrafi dobrze mówić. Oto on wyjdzie ci na spotkanie, a gdy cię zobaczy, uraduje się w swoim sercu.
15 Ìwọ yóò sọ̀rọ̀ fún un, ìwọ yóò sì fi ọ̀rọ̀ sí i lẹ́nu, èmi yóò ràn yín lọ́wọ́ láti sọ̀rọ̀. Èmi yóò kọ́ ọ yín ni ohun ti ẹ ó ṣe.
Ty będziesz mówił do niego i włożysz słowa w jego usta. A ja będę przy twoich ustach i przy jego ustach i pouczę was, co macie czynić.
16 Òun yóò bá ọ sọ̀rọ̀ sí àwọn ènìyàn, yóò sì dàbí i pé ẹnu un rẹ ni a gbà sọ ọ̀rọ̀ náà, ìwọ yóò sì dàbí Ọlọ́run ní iwájú rẹ̀.
On będzie mówił za ciebie do ludu. On będzie dla ciebie jakby ustami, a ty dla niego będziesz jakby Bogiem.
17 Ṣùgbọ́n mú ọ̀pá yìí ni ọwọ́ rẹ kí ìwọ bá à lè fi ṣe àwọn iṣẹ́ àmì ìyanu pẹ̀lú rẹ̀.”
I weź w rękę tę laskę, którą będziesz czynił znaki.
18 Mose padà sí ọ̀dọ̀ Jetro baba ìyàwó rẹ̀, ó sì sọ fún un pé, “Jọ̀wọ́ jẹ́ kí n padà tọ àwọn ènìyàn mi lọ ni ilẹ̀ Ejibiti láti wò bóyá wọ́n ṣì wà láààyè síbẹ̀.” Jetro sì dáhùn, ó wí pé, “Máa lọ ni àlàáfíà.”
Odszedł więc Mojżesz i wrócił do swego teścia Jetra, i powiedział do niego: Pozwól mi wrócić do moich braci, którzy [są] w Egipcie, aby zobaczyć, czy jeszcze żyją. Jetro odpowiedział Mojżeszowi: Idź w pokoju.
19 Nísinsin yìí, Olúwa ti sọ fún Mose ni ilẹ̀ Midiani pé, “Máa padà lọ sí Ejibiti, nítorí àwọn ti ó fẹ́ pa ọ ti kú.”
PAN rzekł do Mojżesza [w ziemi] Midian: Idź, wróć do Egiptu, bo pomarli wszyscy, którzy czyhali na twoje życie.
20 Mose mú ìyàwó rẹ̀ àti àwọn ọmọ rẹ̀, ó kó wọn lé orí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, ó sì bẹ̀rẹ̀ ìrìnàjò rẹ̀ padà sí Ejibiti. Ó sì mú ọ̀pá Ọlọ́run sí ọwọ́ rẹ̀.
Mojżesz więc wziął swoją żonę i swoich synów, wsadził ich na osła i wyruszył do ziemi Egiptu. Wziął też Mojżesz laskę Boga do ręki.
21 Olúwa sì sọ fún Mose pé, “Ní ìgbà tí ìwọ bá padà sí Ejibiti rí i pé ìwọ ṣe iṣẹ́ ìyanu ni iwájú Farao. Èmi ti fún ọ lágbára láti ṣe é. Èmi yóò sì sé àyà rẹ̀ le, òun kì yóò jẹ́ kí àwọn ènìyàn náà kí ó lọ.
PAN powiedział do Mojżesza: Gdy pójdziesz i wrócisz do Egiptu, dopilnuj, [abyś] wszystkich cudów, które dałem ci do ręki, dokonał przed faraonem. A ja zatwardzę jego serce, tak że nie wypuści ludu.
22 Lẹ́yìn náà, kí o sọ fún Farao pé, ‘Èyí ni Olúwa sọ: Israẹli ní àkọ́bí ọmọ mi ọkùnrin,
I powiesz do faraona: Tak mówi PAN: Izrael [jest] moim synem, moim pierworodnym.
23 mo sọ fún ọ, “Jẹ́ kí ọmọ mi lọ, ki òun kí ó lè máa sìn mí.” Ṣùgbọ́n ìwọ kọ̀ láti jẹ́ kí ó lọ; nítorí náà, èmi yóò pa àkọ́bí ọmọ rẹ ọkùnrin.’”
Mówię ci: Wypuść mego syna, aby mi służył. [Jeśli] będziesz się wzbraniał wypuścić go, zabiję twojego syna, twego pierworodnego.
24 Ní ọ̀nà ìrìnàjò rẹ, ni ibi tí wọ́n gbé sùn ní ilé èrò ní alẹ́, Olúwa pàdé Mose, ó sì fẹ́ láti pa á.
A w czasie drogi, w gospodzie, PAN zastąpił drogę [Mojżeszowi] i chciał go zabić.
25 Ṣùgbọ́n Sippora mú ọ̀bẹ òkúta mímú, ó sì kọ ọmọ rẹ̀ ní ilà abẹ́, ó sì fi awọ rẹ̀ kan ẹsẹ̀ Mose. Sippora sì wí pé, “Ọkọ ẹlẹ́jẹ̀ ni ìwọ jẹ́ sí mi.”
Wtedy Sefora wzięła [ostry] kamień, odcięła napletek swego syna i rzuciła do jego stóp, i powiedziała: Naprawdę jesteś dla mnie oblubieńcem krwi.
26 Nítorí náà Olúwa yọ̀ǹda rẹ láti ìgbà tí ó ti wí pé, “Ẹlẹ́jẹ̀ ni ìwọ í ṣe.” Èyí tó túmọ̀ sí ìkọlà abẹ́.
I [PAN] odstąpił od niego. Wtedy nazwała go oblubieńcem krwi z powodu obrzezania.
27 Olúwa sì sọ fún Aaroni pé, “Lọ sínú aginjù láti lọ pàdé Mose.” Ní ìgbà náà ni ó lọ pàdé Mose ní orí òkè Ọlọ́run, ó sì fi ẹnu kò ó ní ẹnu.
A do Aarona PAN powiedział: Wyjdź naprzeciw Mojżeszowi na pustynię. Wyszedł więc i spotkał go na górze Boga, i pocałował go.
28 Ní ìgbà náà ni Mose sì sọ ohun gbogbo tí Ọlọ́run ti rán fún Aaroni àti nípa gbogbo iṣẹ́ ìyanu tí Olúwa ti pàṣẹ fún un láti ṣe ní iwájú Farao.
Wtedy Mojżesz powtórzył Aaronowi wszystkie słowa PANA, który go posłał, i wszystkie znaki, które nakazał mu [uczynić].
29 Mose àti Aaroni pe gbogbo àwọn àgbàgbà Israẹli jọ.
Mojżesz i Aaron poszli więc i zebrali wszystkich starszych synów Izraela.
30 Aaroni sọ ohun gbogbo tí Olúwa sọ fún Mose fún wọn, ó sì ṣe iṣẹ́ àmì náà ní ojú àwọn ènìyàn náà.
I Aaron powiedział wszystkie słowa, które PAN mówił do Mojżesza, a [Mojżesz] czynił znaki na oczach ludu.
31 Wọ́n sì gbàgbọ́. Nígbà tí wọ́n gbọ́ pé Olúwa ti bẹ àwọn ọmọ Israẹli wò àti pé Olúwa ti gbọ́ nípa ìpọ́njú wọn, wọ́n tẹríba, wọ́n sì sìn ín. Ó sì ṣe àwọn iṣẹ́ àmì náà níwájú àwọn ènìyàn náà.
I lud uwierzył. I gdy usłyszeli, że PAN nawiedził synów Izraela i że wejrzał na ich utrapienie, pochylili się i oddali pokłon.