< Exodus 4 >

1 Mose dáhùn ó sì wí pé, “Ṣùgbọ́n bí wọn kò bá gbà mí gbọ́ ń kọ́? Tàbí tí wọn kò fi etí sílẹ̀ láti gbọ́ ọ̀rọ̀ ẹnu mi, tí wọn sì wí pé, ‘Olúwa kò farahàn ọ́’?”
تصدیق نخواهند کرد، و سخن مرانخواهند شنید، بلکه خواهند گفت یهوه بر توظاهر نشده است.»۱
2 Ní ìgbà náà ni Olúwa sọ fún un pé, “Kí ni ó wà ní ọwọ́ rẹ n nì?” Ó sì dáhùn pé, “Ọ̀pá ni.”
پس خداوند به وی گفت: «آن چیست در دست تو؟» گفت: «عصا.»۲
3 Olúwa sì sọ pé, “Sọ ọ̀pá náà sílẹ̀.” Mose sì sọ ọ̀pá náà sílẹ̀, lọ́gán ni ọ̀pá náà di ejò, ó sì sá fún un.
گفت: «آن را بر زمین بینداز.» و چون آن را به زمین انداخت، ماری گردید و موسی از نزدش گریخت.۳
4 Nígbà náà ni Olúwa wá sọ fún un pé, “Na ọwọ́ rẹ, kí o sì mú un ni ìrù.” Mose sì na ọwọ́ rẹ̀, ó sì mu ejò náà, ejò náà sì padà di ọ̀pá tí ó wà ni ọwọ́ rẹ̀.
پس خداوند به موسی گفت: «دست خود رادراز کن و دمش را بگیر.» پس دست خود را درازکرده، آن را بگرفت، که در دستش عصا شد.۴
5 Olúwa sì wí pé, “Èyí rí bẹ́ẹ̀ kí wọn bá à le è gbàgbọ́ pé, Olúwa Ọlọ́run àwọn baba wọn, Ọlọ́run Abrahamu, Ọlọ́run Isaaki, àti Ọlọ́run Jakọbu; tí farahàn ọ́.”
«تاآنکه باور کنند که یهوه خدای پدران ایشان، خدای ابراهیم، خدای اسحاق، و خدای یعقوب، به تو ظاهر شد.»۵
6 Ní ìgbà náà ni Olúwa wí pé, “Ti ọwọ́ rẹ bọ inú aṣọ ní igbá àyà rẹ̀.” Mose sì ti ọwọ́ rẹ̀ bọ inú aṣọ ní igbá àyà rẹ̀, ní ìgbà ti ó sì yọ ọ́ jáde, ọwọ́ rẹ̀ ti dẹ́tẹ̀, ó sì ti funfun bí ẹ̀gbọ̀n òwú.
و خداوند دیگرباره وی راگفت: «دست خود را در گریبان خود بگذار.» چون دست به گریبان خود برد، و آن را بیرون آورد، اینک دست او مثل برف مبروص شد.۶
7 Ó sì wí pé, “Nísinsin yìí, fi ọwọ́ náà padà sí abẹ́ aṣọ ní igbá àyà rẹ.” Mose sì ṣe bẹ́ẹ̀, ọwọ́ rẹ̀ sì padà bọ́ sípò bí àwọn ẹ̀yà ara rẹ̀ tókù.
پس گفت: «دست خود را باز به گریبان خود بگذار.» چون دست به گریبان خود باز برد، و آن را بیرون آورد، اینک مثل سایر بدنش باز آمده بود.۷
8 Ní ìgbà náà ni Olúwa wí pé, “Bí wọn kò bá gbà ọ́ gbọ́ tàbí kọ ibi ara sí iṣẹ́ ìyanu àkọ́kọ́, wọ́n le è ti ipasẹ̀ iṣẹ́ ìyanu kejì gbàgbọ́.
«وواقع خواهد شد که اگر تو را تصدیق نکنند، وآواز آیت نخستین را نشنوند، همانا آواز آیت دوم را باور خواهند کرد.۸
9 Ṣùgbọ́n bí wọn kò bá gba àmì méjèèjì wọ̀nyí gbọ́, tí wọn kò sì fetí sí ọ̀rọ̀ rẹ, bu omi díẹ̀ láti inú odò Naili kí o si dà á sí orí ìyàngbẹ ilẹ̀, omi tí ìwọ bù láti inú odò yìí yóò sì di ẹ̀jẹ̀.”
و هر گاه این دو آیت راباور نکردند و سخن تو را نشنیدند، آنگاه از آب نهر گرفته، به خشکی بریز، و آبی که از نهر گرفتی بر روی خشکی به خون مبدل خواهد شد.»۹
10 Mose sì sọ fún Olúwa pé, “Èmi jẹ́ akólòlò, èmi kì í ṣe ẹni tó lè sọ̀rọ̀ já gaara láti ìgbà àtijọ́ wá tàbí láti ìgbà ti o ti ń bá ìránṣẹ́ rẹ sọ̀rọ̀, mo jẹ́ ẹni ti ahọ́n rẹ̀ lọ́, tí ó sì ń lọ́ra àti sọ̀rọ̀.”
پس موسی به خداوند گفت: «ای خداوند، من مردی فصیح نیستم، نه در سابق و نه از وقتی که به بنده خود سخن گفتی، بلکه بطی الکلام و کندزبان.»۱۰
11 Olúwa sì sọ fún un pé, “Ta ni ó fún ènìyàn ni ẹnu? Ta ni ó mú un ya odi tàbí adití? Ta ni ó mú un ríran, tàbí mú un fọ́jú? Ǹjẹ́ kì í ṣe èmi Olúwa?
خداوند گفت: «کیست که زبان به انسان داد، و گنگ و کر و بینا و نابینا را که آفرید؟ آیا نه من که یهوه هستم؟۱۱
12 Lọ nísinsin yìí, Èmi yóò ràn ọ́ lọ́wọ́ láti sọ̀rọ̀. Èmi yóò sì kọ́ ọ ni ohun ti ìwọ yóò sọ.”
پس الان برو و من با زبانت خواهم بود، و هر‌چه باید بگویی تو را خواهم آموخت.»۱۲
13 Mose dáhùn ó wí pé, “Olúwa jọ̀wọ́ rán ẹlòmíràn láti lọ ṣe iṣẹ́ yìí.”
گفت: «استدعا دارم‌ای خداوند که بفرستی به‌دست هر‌که می‌فرستی.»۱۳
14 Ìbínú Olúwa ru sókè sí Mose, ó sì sọ pé, “Aaroni ará Lefi arákùnrin rẹ ń kọ́? Mo mọ̀ pé ó lè sọ̀rọ̀ já gaara, ó ti wà ní ọ̀nà rẹ̀ báyìí láti pàdé e rẹ. Inú rẹ̀ yóò sì dùn ti ó bá rí ọ.
آنگاه خشم خداوند بر موسی مشتعل شدو گفت: «آیا برادرت، هارون لاوی را نمی دانم که او فصیح الکلام است؟ و اینک او نیز به استقبال توبیرون می‌آید، و چون تو را ببیند، در دل خود شادخواهد گردید.۱۴
15 Ìwọ yóò sọ̀rọ̀ fún un, ìwọ yóò sì fi ọ̀rọ̀ sí i lẹ́nu, èmi yóò ràn yín lọ́wọ́ láti sọ̀rọ̀. Èmi yóò kọ́ ọ yín ni ohun ti ẹ ó ṣe.
و بدو سخن خواهی گفت وکلام را به زبان وی القا خواهی کرد، و من با زبان توو با زبان او خواهم بود، و آنچه باید بکنید شما راخواهم آموخت.۱۵
16 Òun yóò bá ọ sọ̀rọ̀ sí àwọn ènìyàn, yóò sì dàbí i pé ẹnu un rẹ ni a gbà sọ ọ̀rọ̀ náà, ìwọ yóò sì dàbí Ọlọ́run ní iwájú rẹ̀.
و او برای تو به قوم سخن خواهد گفت، و او مر تو را به‌جای زبان خواهدبود، و تو او را به‌جای خدا خواهی بود.۱۶
17 Ṣùgbọ́n mú ọ̀pá yìí ni ọwọ́ rẹ kí ìwọ bá à lè fi ṣe àwọn iṣẹ́ àmì ìyanu pẹ̀lú rẹ̀.”
و این عصا را به‌دست خود بگیر که به آن آیات را ظاهر سازی.»۱۷
18 Mose padà sí ọ̀dọ̀ Jetro baba ìyàwó rẹ̀, ó sì sọ fún un pé, “Jọ̀wọ́ jẹ́ kí n padà tọ àwọn ènìyàn mi lọ ni ilẹ̀ Ejibiti láti wò bóyá wọ́n ṣì wà láààyè síbẹ̀.” Jetro sì dáhùn, ó wí pé, “Máa lọ ni àlàáfíà.”
پس موسی روانه شده، نزد پدر زن خود، یترون، برگشت و به وی گفت: «بروم و نزد برادران خود که در مصرند برگردم، و ببینم که تا کنون زنده‌اند.» یترون به موسی گفت: «به سلامتی برو.»۱۸
19 Nísinsin yìí, Olúwa ti sọ fún Mose ni ilẹ̀ Midiani pé, “Máa padà lọ sí Ejibiti, nítorí àwọn ti ó fẹ́ pa ọ ti kú.”
و خداوند در مدیان به موسی گفت: «روانه شده به مصر برگرد، زیرا آنانی که در قصد جان توبودند، مرده‌اند.»۱۹
20 Mose mú ìyàwó rẹ̀ àti àwọn ọmọ rẹ̀, ó kó wọn lé orí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, ó sì bẹ̀rẹ̀ ìrìnàjò rẹ̀ padà sí Ejibiti. Ó sì mú ọ̀pá Ọlọ́run sí ọwọ́ rẹ̀.
پس موسی زن خویش وپسران خود را برداشته، ایشان را بر الاغ سوارکرده، به زمین مصر مراجعت نمود، و موسی عصای خدا را به‌دست خود گرفت.۲۰
21 Olúwa sì sọ fún Mose pé, “Ní ìgbà tí ìwọ bá padà sí Ejibiti rí i pé ìwọ ṣe iṣẹ́ ìyanu ni iwájú Farao. Èmi ti fún ọ lágbára láti ṣe é. Èmi yóò sì sé àyà rẹ̀ le, òun kì yóò jẹ́ kí àwọn ènìyàn náà kí ó lọ.
و خداوندبه موسی گفت: «چون روانه شده، به مصرمراجعت کردی، آگاه باش که همه علاماتی را که به‌دستت سپرده‌ام به حضور فرعون ظاهر سازی، و من دل او را سخت خواهم ساخت تا قوم را رهانکند.۲۱
22 Lẹ́yìn náà, kí o sọ fún Farao pé, ‘Èyí ni Olúwa sọ: Israẹli ní àkọ́bí ọmọ mi ọkùnrin,
و به فرعون بگو خداوند چنین می‌گوید: اسرائیل، پسر من و نخست زاده من است،۲۲
23 mo sọ fún ọ, “Jẹ́ kí ọmọ mi lọ, ki òun kí ó lè máa sìn mí.” Ṣùgbọ́n ìwọ kọ̀ láti jẹ́ kí ó lọ; nítorí náà, èmi yóò pa àkọ́bí ọmọ rẹ ọkùnrin.’”
و به تو می‌گویم پسرم را رها کن تا مرا عبادت نماید، واگر از رها کردنش ابا نمایی، همانا پسر تو، یعنی نخست زاده تو را می‌کشم.»۲۳
24 Ní ọ̀nà ìrìnàjò rẹ, ni ibi tí wọ́n gbé sùn ní ilé èrò ní alẹ́, Olúwa pàdé Mose, ó sì fẹ́ láti pa á.
و واقع شد در بین راه که خداوند در منزل بدو برخورده، قصد قتل وی نمود.۲۴
25 Ṣùgbọ́n Sippora mú ọ̀bẹ òkúta mímú, ó sì kọ ọmọ rẹ̀ ní ilà abẹ́, ó sì fi awọ rẹ̀ kan ẹsẹ̀ Mose. Sippora sì wí pé, “Ọkọ ẹlẹ́jẹ̀ ni ìwọ jẹ́ sí mi.”
آنگاه صفوره سنگی تیز گرفته، غلفه پسر خود را ختنه کرد و نزد پای وی انداخته، گفت: «تو مرا شوهرخون هستی.»۲۵
26 Nítorí náà Olúwa yọ̀ǹda rẹ láti ìgbà tí ó ti wí pé, “Ẹlẹ́jẹ̀ ni ìwọ í ṣe.” Èyí tó túmọ̀ sí ìkọlà abẹ́.
پس او وی را رها کرد، آنگاه (صفوره ) گفت: «شوهر خون هستی، » به‌سبب ختنه.۲۶
27 Olúwa sì sọ fún Aaroni pé, “Lọ sínú aginjù láti lọ pàdé Mose.” Ní ìgbà náà ni ó lọ pàdé Mose ní orí òkè Ọlọ́run, ó sì fi ẹnu kò ó ní ẹnu.
و خداوند به هارون گفت: «به سوی صحرا به استقبال موسی برو.» پس روانه شد و او را در جبل الله ملاقات کرده، او را بوسید.۲۷
28 Ní ìgbà náà ni Mose sì sọ ohun gbogbo tí Ọlọ́run ti rán fún Aaroni àti nípa gbogbo iṣẹ́ ìyanu tí Olúwa ti pàṣẹ fún un láti ṣe ní iwájú Farao.
وموسی از جمیع کلمات خداوند که او را فرستاده بود، و از همه آیاتی که به وی امر فرموده بود، هارون را خبر داد.۲۸
29 Mose àti Aaroni pe gbogbo àwọn àgbàgbà Israẹli jọ.
پس موسی و هارون رفته، کل مشایخ بنی‌اسرائیل را جمع کردند.۲۹
30 Aaroni sọ ohun gbogbo tí Olúwa sọ fún Mose fún wọn, ó sì ṣe iṣẹ́ àmì náà ní ojú àwọn ènìyàn náà.
وهارون همه سخنانی را که خداوند به موسی فرموده بود، باز‌گفت، و آیات را به نظر قوم ظاهرساخت.۳۰
31 Wọ́n sì gbàgbọ́. Nígbà tí wọ́n gbọ́ pé Olúwa ti bẹ àwọn ọmọ Israẹli wò àti pé Olúwa ti gbọ́ nípa ìpọ́njú wọn, wọ́n tẹríba, wọ́n sì sìn ín. Ó sì ṣe àwọn iṣẹ́ àmì náà níwájú àwọn ènìyàn náà.
و قوم ایمان آوردند. و چون شنیدندکه خداوند از بنی‌اسرائیل تفقد نموده، و به مصیبت ایشان نظر انداخته است، به روی درافتاده، سجده کردند.۳۱

< Exodus 4 >