< Exodus 4 >

1 Mose dáhùn ó sì wí pé, “Ṣùgbọ́n bí wọn kò bá gbà mí gbọ́ ń kọ́? Tàbí tí wọn kò fi etí sílẹ̀ láti gbọ́ ọ̀rọ̀ ẹnu mi, tí wọn sì wí pé, ‘Olúwa kò farahàn ọ́’?”
Musa akĩmũcookeria atĩrĩ, “Ĩ mangĩrega kũnjĩtĩkia kana kũnjigua, na manjĩĩre atĩrĩ, ‘Jehova ndakuumĩrĩire?’”
2 Ní ìgbà náà ni Olúwa sọ fún un pé, “Kí ni ó wà ní ọwọ́ rẹ n nì?” Ó sì dáhùn pé, “Ọ̀pá ni.”
Nake Jehova akĩmũũria atĩrĩ, “Nĩ kĩĩ kĩu ũrĩ nakĩo guoko?” Nake agĩcookia atĩrĩ, “Nĩ rũthanju.”
3 Olúwa sì sọ pé, “Sọ ọ̀pá náà sílẹ̀.” Mose sì sọ ọ̀pá náà sílẹ̀, lọ́gán ni ọ̀pá náà di ejò, ó sì sá fún un.
Jehova akĩmwĩra atĩrĩ, “Rũikie thĩ.” Musa akĩrũikia thĩ, naruo rũgĩtuĩka nyoka, nake akĩmĩũrĩra.
4 Nígbà náà ni Olúwa wá sọ fún un pé, “Na ọwọ́ rẹ, kí o sì mú un ni ìrù.” Mose sì na ọwọ́ rẹ̀, ó sì mu ejò náà, ejò náà sì padà di ọ̀pá tí ó wà ni ọwọ́ rẹ̀.
Nake Jehova akĩmwĩra atĩrĩ, “Tambũrũkia guoko ũmĩnyiite mũtingʼoe.” Nĩ ũndũ ũcio Musa agĩtambũrũkia guoko akĩmĩnyiita, nayo ĩkĩgarũrũka, ĩgĩtuĩka rũthanju guoko-inĩ gwake.
5 Olúwa sì wí pé, “Èyí rí bẹ́ẹ̀ kí wọn bá à le è gbàgbọ́ pé, Olúwa Ọlọ́run àwọn baba wọn, Ọlọ́run Abrahamu, Ọlọ́run Isaaki, àti Ọlọ́run Jakọbu; tí farahàn ọ́.”
Nake Jehova akiuga atĩrĩ, “Ũndũ ũyũ nĩguo wa gũtũma metĩkie atĩ Jehova, o we Ngai wa maithe mao Ngai wa Iburahĩmu, na Ngai wa Isaaka, na Ngai wa Jakubu nĩakuumĩrĩire.”
6 Ní ìgbà náà ni Olúwa wí pé, “Ti ọwọ́ rẹ bọ inú aṣọ ní igbá àyà rẹ̀.” Mose sì ti ọwọ́ rẹ̀ bọ inú aṣọ ní igbá àyà rẹ̀, ní ìgbà ti ó sì yọ ọ́ jáde, ọwọ́ rẹ̀ ti dẹ́tẹ̀, ó sì ti funfun bí ẹ̀gbọ̀n òwú.
Ningĩ Jehova akiuga atĩrĩ, “Ikia guoko nguo-inĩ yaku.” Nĩ ũndũ ũcio Musa agĩikia guoko nguo-inĩ yake, na rĩrĩa aakũrutire kwarĩ na mangũ, gũkeerũha ta ira.
7 Ó sì wí pé, “Nísinsin yìí, fi ọwọ́ náà padà sí abẹ́ aṣọ ní igbá àyà rẹ.” Mose sì ṣe bẹ́ẹ̀, ọwọ́ rẹ̀ sì padà bọ́ sípò bí àwọn ẹ̀yà ara rẹ̀ tókù.
Jehova agĩcooka akĩmwĩra atĩrĩ, “Cookia guoko nguo-inĩ yaku.” Nĩ ũndũ ũcio Musa agĩcookia guoko nguo-inĩ, na rĩrĩa aakũrutire kwagarũrũkĩte gũkahaanana na mwĩrĩ ũcio ũngĩ wake.
8 Ní ìgbà náà ni Olúwa wí pé, “Bí wọn kò bá gbà ọ́ gbọ́ tàbí kọ ibi ara sí iṣẹ́ ìyanu àkọ́kọ́, wọ́n le è ti ipasẹ̀ iṣẹ́ ìyanu kejì gbàgbọ́.
Ningĩ Jehova akiuga atĩrĩ, “Mangĩaga gũgwĩtĩkia na kũrũmbũiya kĩama kĩa mbere, no gũkorwo nĩmagetĩkia gĩa keerĩ.
9 Ṣùgbọ́n bí wọn kò bá gba àmì méjèèjì wọ̀nyí gbọ́, tí wọn kò sì fetí sí ọ̀rọ̀ rẹ, bu omi díẹ̀ láti inú odò Naili kí o si dà á sí orí ìyàngbẹ ilẹ̀, omi tí ìwọ bù láti inú odò yìí yóò sì di ẹ̀jẹ̀.”
No mangĩaga gwĩtĩkia ciama ici cierĩ kana mage gũkũigua-rĩ, ũgaataha maaĩ kuuma Rũũĩ rwa Nili na ũmaite thĩ. Maaĩ macio ũgaataha kuuma rũũĩ nĩmagatuĩka thakame maitwo thĩ.”
10 Mose sì sọ fún Olúwa pé, “Èmi jẹ́ akólòlò, èmi kì í ṣe ẹni tó lè sọ̀rọ̀ já gaara láti ìgbà àtijọ́ wá tàbí láti ìgbà ti o ti ń bá ìránṣẹ́ rẹ sọ̀rọ̀, mo jẹ́ ẹni ti ahọ́n rẹ̀ lọ́, tí ó sì ń lọ́ra àti sọ̀rọ̀.”
Musa akĩĩra Jehova atĩrĩ, “Wee, Mwathani, nĩũũĩ niĩ ndirĩ ndatuĩka mũndũ mwaria wega, kuuma o tene o na kuuma wambĩrĩria kwaria na niĩ ndungata yaku. Niĩ ndirĩ mĩtũkĩ ya mĩario, na ndĩ rũrĩmĩ rũritũ.”
11 Olúwa sì sọ fún un pé, “Ta ni ó fún ènìyàn ni ẹnu? Ta ni ó mú un ya odi tàbí adití? Ta ni ó mú un ríran, tàbí mú un fọ́jú? Ǹjẹ́ kì í ṣe èmi Olúwa?
Jehova akĩmwĩra atĩrĩ, “Nũũ waheire mũndũ kanua? Nũũ ũtũmaga mũndũ aage kũigua kana aremwo nĩ kwaria? Nũũ ũtũmaga mũndũ one kana atuĩke mũtumumu? Githĩ ti niĩ, Jehova?
12 Lọ nísinsin yìí, Èmi yóò ràn ọ́ lọ́wọ́ láti sọ̀rọ̀. Èmi yóò sì kọ́ ọ ni ohun ti ìwọ yóò sọ.”
Na rĩrĩ, thiĩ; nĩngakũhotithia kwaria na ngũrute ũrĩa ũkoiga.”
13 Mose dáhùn ó wí pé, “Olúwa jọ̀wọ́ rán ẹlòmíràn láti lọ ṣe iṣẹ́ yìí.”
No Musa akiuga atĩrĩ, “Mwathani, ndagũthaitha tũma mũndũ ũngĩ akaarie.”
14 Ìbínú Olúwa ru sókè sí Mose, ó sì sọ pé, “Aaroni ará Lefi arákùnrin rẹ ń kọ́? Mo mọ̀ pé ó lè sọ̀rọ̀ já gaara, ó ti wà ní ọ̀nà rẹ̀ báyìí láti pàdé e rẹ. Inú rẹ̀ yóò sì dùn ti ó bá rí ọ.
Namo marakara ma Jehova makĩrĩrĩmbũkĩra Musa, akĩmũũria atĩrĩ, “Ĩ mũrũ wa nyũkwa Harũni, ũrĩa Mũlawii-rĩ, ndangĩaria? Nĩnjũũĩ no aarie wega. Arĩ njĩra-inĩ agĩũka gũgũtũnga, na nĩegũkena akuona.
15 Ìwọ yóò sọ̀rọ̀ fún un, ìwọ yóò sì fi ọ̀rọ̀ sí i lẹ́nu, èmi yóò ràn yín lọ́wọ́ láti sọ̀rọ̀. Èmi yóò kọ́ ọ yín ni ohun ti ẹ ó ṣe.
Ũrĩmwaragĩria na ũkamwĩra ũrĩa ekuuga, na nĩngamũhotithia inyuĩ eerĩ kwaria, na ndĩmũrute ũrĩa mũgeeka.
16 Òun yóò bá ọ sọ̀rọ̀ sí àwọn ènìyàn, yóò sì dàbí i pé ẹnu un rẹ ni a gbà sọ ọ̀rọ̀ náà, ìwọ yóò sì dàbí Ọlọ́run ní iwájú rẹ̀.
Nĩakaarĩria andũ handũ haku, na agaatuĩka taarĩ we kanua gaku, nawe ũtuĩke ta ũrĩ Ngai harĩ we.
17 Ṣùgbọ́n mú ọ̀pá yìí ni ọwọ́ rẹ kí ìwọ bá à lè fi ṣe àwọn iṣẹ́ àmì ìyanu pẹ̀lú rẹ̀.”
No oya rũthanju rũrũ nĩguo ũhotage kũringa ciama naruo.”
18 Mose padà sí ọ̀dọ̀ Jetro baba ìyàwó rẹ̀, ó sì sọ fún un pé, “Jọ̀wọ́ jẹ́ kí n padà tọ àwọn ènìyàn mi lọ ni ilẹ̀ Ejibiti láti wò bóyá wọ́n ṣì wà láààyè síbẹ̀.” Jetro sì dáhùn, ó wí pé, “Máa lọ ni àlàáfíà.”
Nake Musa agĩcooka kwa Jethero mũthoni-we, akĩmwĩra atĩrĩ, “Njĩtĩkĩria njooke bũrũri wa Misiri kũrĩ andũ aitũ, ngarore kana nĩ kũrĩ matũire muoyo.” Jethero akiuga atĩrĩ, “Thiĩ, ndakũhoera thayũ.”
19 Nísinsin yìí, Olúwa ti sọ fún Mose ni ilẹ̀ Midiani pé, “Máa padà lọ sí Ejibiti, nítorí àwọn ti ó fẹ́ pa ọ ti kú.”
Na rĩrĩ, Jehova nĩarĩirie Musa arĩ o kũu Midiani, akĩmwĩra atĩrĩ, “Cooka bũrũri wa Misiri, nĩgũkorwo andũ othe arĩa meendaga gũkũũraga nĩmakuĩte.”
20 Mose mú ìyàwó rẹ̀ àti àwọn ọmọ rẹ̀, ó kó wọn lé orí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, ó sì bẹ̀rẹ̀ ìrìnàjò rẹ̀ padà sí Ejibiti. Ó sì mú ọ̀pá Ọlọ́run sí ọwọ́ rẹ̀.
Nĩ ũndũ ũcio Musa akĩoya mũtumia wake na ariũ ake, akĩmahaicia ndigiri na makĩambĩrĩria rũgendo rwa gũcooka bũrũri wa Misiri. Nake akĩoya rũthanju rwa Ngai akĩrũnyiita na guoko.
21 Olúwa sì sọ fún Mose pé, “Ní ìgbà tí ìwọ bá padà sí Ejibiti rí i pé ìwọ ṣe iṣẹ́ ìyanu ni iwájú Farao. Èmi ti fún ọ lágbára láti ṣe é. Èmi yóò sì sé àyà rẹ̀ le, òun kì yóò jẹ́ kí àwọn ènìyàn náà kí ó lọ.
Jehova akĩĩra Musa atĩrĩ, “Wacooka bũrũri wa Misiri-rĩ, tigĩrĩra nĩ weka morirũ mothe marĩa ngũhotithĩtie gwĩka mbere ya Firaũni. No nĩngomia ngoro yake nĩgeetha ndagetĩkĩrie andũ mathiĩ.
22 Lẹ́yìn náà, kí o sọ fún Farao pé, ‘Èyí ni Olúwa sọ: Israẹli ní àkọ́bí ọmọ mi ọkùnrin,
Ningĩ wĩre Firaũni atĩrĩ, ‘Ũũ nĩguo Jehova ekuuga: Isiraeli nĩwe mũriũ wakwa wa irigithathi,
23 mo sọ fún ọ, “Jẹ́ kí ọmọ mi lọ, ki òun kí ó lè máa sìn mí.” Ṣùgbọ́n ìwọ kọ̀ láti jẹ́ kí ó lọ; nítorí náà, èmi yóò pa àkọ́bí ọmọ rẹ ọkùnrin.’”
na nĩndakwĩrire atĩrĩ, “Reke mũriũ wakwa athiĩ akaahooe.” No nĩwaregire kũmwĩtĩkĩria athiĩ; nĩ ũndũ ũcio nĩngooraga mũriũ waku wa irigithathi.’”
24 Ní ọ̀nà ìrìnàjò rẹ, ni ibi tí wọ́n gbé sùn ní ilé èrò ní alẹ́, Olúwa pàdé Mose, ó sì fẹ́ láti pa á.
Marĩ handũ harĩa mararĩrĩire marĩ rũgendo-inĩ-rĩ, Jehova akiumĩrĩra Musa, na aarĩ hakuhĩ kũmũũraga.
25 Ṣùgbọ́n Sippora mú ọ̀bẹ òkúta mímú, ó sì kọ ọmọ rẹ̀ ní ilà abẹ́, ó sì fi awọ rẹ̀ kan ẹsẹ̀ Mose. Sippora sì wí pé, “Ọkọ ẹlẹ́jẹ̀ ni ìwọ jẹ́ sí mi.”
No Zipora akĩoya kahiga kaarĩ kogĩ ta kahiũ, akĩruithia mũriũ, na akĩhutithia gĩkonde kĩu nyarĩrĩ cia Musa. Agĩcooka akĩmwĩra atĩrĩ, “Ti-itherũ ũrĩ mũthuuri wakwa wa thakame.”
26 Nítorí náà Olúwa yọ̀ǹda rẹ láti ìgbà tí ó ti wí pé, “Ẹlẹ́jẹ̀ ni ìwọ í ṣe.” Èyí tó túmọ̀ sí ìkọlà abẹ́.
Nĩ ũndũ ũcio Jehova agĩtigana nake. (Hĩndĩ ĩyo mũtumia ũcio wake oigire “ũrĩ mũthuuri wakwa wa thakame” aaragia ũhoro wa irua.)
27 Olúwa sì sọ fún Aaroni pé, “Lọ sínú aginjù láti lọ pàdé Mose.” Ní ìgbà náà ni ó lọ pàdé Mose ní orí òkè Ọlọ́run, ó sì fi ẹnu kò ó ní ẹnu.
Nake Jehova akĩĩra Harũni atĩrĩ, “Thiĩ werũ-inĩ ũgathaagane Musa.” Nĩ ũndũ ũcio Harũni agĩtũnga Musa kĩrĩma-inĩ kĩa Ngai, akĩmũhĩmbĩria.
28 Ní ìgbà náà ni Mose sì sọ ohun gbogbo tí Ọlọ́run ti rán fún Aaroni àti nípa gbogbo iṣẹ́ ìyanu tí Olúwa ti pàṣẹ fún un láti ṣe ní iwájú Farao.
Nake Musa akĩĩra Harũni ũrĩa wothe Jehova amũtũmĩte akoige, o na ningĩ ũhoro wa ciama ciothe iria aamwathĩte aringe.
29 Mose àti Aaroni pe gbogbo àwọn àgbàgbà Israẹli jọ.
Musa na Harũni magĩcookanĩrĩria athuuri a Isiraeli othe,
30 Aaroni sọ ohun gbogbo tí Olúwa sọ fún Mose fún wọn, ó sì ṣe iṣẹ́ àmì náà ní ojú àwọn ènìyàn náà.
nake Harũni akĩmeera ũrĩa wothe Jehova eerĩte Musa. O na ningĩ Musa akĩringa ciama mbere yao;
31 Wọ́n sì gbàgbọ́. Nígbà tí wọ́n gbọ́ pé Olúwa ti bẹ àwọn ọmọ Israẹli wò àti pé Olúwa ti gbọ́ nípa ìpọ́njú wọn, wọ́n tẹríba, wọ́n sì sìn ín. Ó sì ṣe àwọn iṣẹ́ àmì náà níwájú àwọn ènìyàn náà.
nao magĩĩtĩkia. Na rĩrĩa maiguire atĩ Jehova nĩameciirĩtie na akona mĩnyamaro yao-rĩ, makĩinamĩrĩra, magĩthathaiya.

< Exodus 4 >