< Exodus 4 >

1 Mose dáhùn ó sì wí pé, “Ṣùgbọ́n bí wọn kò bá gbà mí gbọ́ ń kọ́? Tàbí tí wọn kò fi etí sílẹ̀ láti gbọ́ ọ̀rọ̀ ẹnu mi, tí wọn sì wí pé, ‘Olúwa kò farahàn ọ́’?”
Alors Moïse répondit et dit: Mais voici, ils ne me croiront pas et n'écouteront point ma voix, car ils diront: L'Éternel ne t'est point apparu.
2 Ní ìgbà náà ni Olúwa sọ fún un pé, “Kí ni ó wà ní ọwọ́ rẹ n nì?” Ó sì dáhùn pé, “Ọ̀pá ni.”
Et l'Éternel lui dit: Qu'as-tu dans la main? Et il répondit: Un bâton.
3 Olúwa sì sọ pé, “Sọ ọ̀pá náà sílẹ̀.” Mose sì sọ ọ̀pá náà sílẹ̀, lọ́gán ni ọ̀pá náà di ejò, ó sì sá fún un.
Et Il dit: Jette-le par terre. Et il le jeta par terre, et le bâton devint serpent, et Moïse s'enfuit à son aspect.
4 Nígbà náà ni Olúwa wá sọ fún un pé, “Na ọwọ́ rẹ, kí o sì mú un ni ìrù.” Mose sì na ọwọ́ rẹ̀, ó sì mu ejò náà, ejò náà sì padà di ọ̀pá tí ó wà ni ọwọ́ rẹ̀.
Et l'Éternel dit à Moïse: Étends la main et saisis-le par la queue. Et il étendit la main et le saisit, et le serpent redevint bâton dans sa main.
5 Olúwa sì wí pé, “Èyí rí bẹ́ẹ̀ kí wọn bá à le è gbàgbọ́ pé, Olúwa Ọlọ́run àwọn baba wọn, Ọlọ́run Abrahamu, Ọlọ́run Isaaki, àti Ọlọ́run Jakọbu; tí farahàn ọ́.”
« C'est afin qu'ils croient que l'Éternel, Dieu de leurs pères, t'est apparu, le Dieu d'Abraham, le Dieu d'Isaac et le Dieu de Jacob. »
6 Ní ìgbà náà ni Olúwa wí pé, “Ti ọwọ́ rẹ bọ inú aṣọ ní igbá àyà rẹ̀.” Mose sì ti ọwọ́ rẹ̀ bọ inú aṣọ ní igbá àyà rẹ̀, ní ìgbà ti ó sì yọ ọ́ jáde, ọwọ́ rẹ̀ ti dẹ́tẹ̀, ó sì ti funfun bí ẹ̀gbọ̀n òwú.
Et l'Éternel lui dit encore: Ramène donc ta main dans ton sein. Et il ramena sa main dans son sein, puis il l'en retira et voilà que sa main était couverte d'une lèpre pareille à la neige.
7 Ó sì wí pé, “Nísinsin yìí, fi ọwọ́ náà padà sí abẹ́ aṣọ ní igbá àyà rẹ.” Mose sì ṣe bẹ́ẹ̀, ọwọ́ rẹ̀ sì padà bọ́ sípò bí àwọn ẹ̀yà ara rẹ̀ tókù.
Et Il dit: Ramène ta main dans ton sein. Et il ramena sa main dans son sein, puis il l'en retira, et voilà qu'elle était redevenue pareille à sa chair.
8 Ní ìgbà náà ni Olúwa wí pé, “Bí wọn kò bá gbà ọ́ gbọ́ tàbí kọ ibi ara sí iṣẹ́ ìyanu àkọ́kọ́, wọ́n le è ti ipasẹ̀ iṣẹ́ ìyanu kejì gbàgbọ́.
« Que s'ils ne te croient pas et n'écoutent pas le langage du premier signe, ils croiront au langage du second signe.
9 Ṣùgbọ́n bí wọn kò bá gba àmì méjèèjì wọ̀nyí gbọ́, tí wọn kò sì fetí sí ọ̀rọ̀ rẹ, bu omi díẹ̀ láti inú odò Naili kí o si dà á sí orí ìyàngbẹ ilẹ̀, omi tí ìwọ bù láti inú odò yìí yóò sì di ẹ̀jẹ̀.”
Que s'ils ne se rendent pas même à ces deux signes, et n'écoutent pas ta voix, prends de l'eau du Nil, et répands-la sur la terre sèche; l'eau que tu auras prise dans le fleuve, deviendra sang sur la terre sèche. »
10 Mose sì sọ fún Olúwa pé, “Èmi jẹ́ akólòlò, èmi kì í ṣe ẹni tó lè sọ̀rọ̀ já gaara láti ìgbà àtijọ́ wá tàbí láti ìgbà ti o ti ń bá ìránṣẹ́ rẹ sọ̀rọ̀, mo jẹ́ ẹni ti ahọ́n rẹ̀ lọ́, tí ó sì ń lọ́ra àti sọ̀rọ̀.”
Et Moïse dit à l'Éternel: Je t'en conjure, Seigneur! Ni d'hier ni d'avant-hier je ne fus un homme disert, pas même depuis que tu parles à ton serviteur, car j'ai la bouche pesante et la langue pesante.
11 Olúwa sì sọ fún un pé, “Ta ni ó fún ènìyàn ni ẹnu? Ta ni ó mú un ya odi tàbí adití? Ta ni ó mú un ríran, tàbí mú un fọ́jú? Ǹjẹ́ kì í ṣe èmi Olúwa?
Et l'Éternel lui dit: Qui a formé à l'homme une bouche, ou qui rend muet ou sourd, voyant ou aveugle? n'est-ce pas moi l'Éternel?
12 Lọ nísinsin yìí, Èmi yóò ràn ọ́ lọ́wọ́ láti sọ̀rọ̀. Èmi yóò sì kọ́ ọ ni ohun ti ìwọ yóò sọ.”
Ainsi va, et moi-même je serai en aide à ta bouche, et je t'enseignerai ce que tu auras à dire.
13 Mose dáhùn ó wí pé, “Olúwa jọ̀wọ́ rán ẹlòmíràn láti lọ ṣe iṣẹ́ yìí.”
Et il dit: Je t'en conjure, Seigneur! oh! envoie qui il te plaira d'envoyer.
14 Ìbínú Olúwa ru sókè sí Mose, ó sì sọ pé, “Aaroni ará Lefi arákùnrin rẹ ń kọ́? Mo mọ̀ pé ó lè sọ̀rọ̀ já gaara, ó ti wà ní ọ̀nà rẹ̀ báyìí láti pàdé e rẹ. Inú rẹ̀ yóò sì dùn ti ó bá rí ọ.
Alors la colère de l'Éternel s'enflamma contre Moïse, et Il dit: N'as-tu pas pour frère Aaron, le Lévite? je sais qu'il est capable de parler, et même le voici qui vient au-devant de toi, et te voyant il se réjouira dans son cœur.
15 Ìwọ yóò sọ̀rọ̀ fún un, ìwọ yóò sì fi ọ̀rọ̀ sí i lẹ́nu, èmi yóò ràn yín lọ́wọ́ láti sọ̀rọ̀. Èmi yóò kọ́ ọ yín ni ohun ti ẹ ó ṣe.
Et tu lui parleras, et tu lui mettras les paroles dans la bouche, et je serai en aide à ta bouche et à sa bouche, et je vous montrerai ce que vous aurez à faire.
16 Òun yóò bá ọ sọ̀rọ̀ sí àwọn ènìyàn, yóò sì dàbí i pé ẹnu un rẹ ni a gbà sọ ọ̀rọ̀ náà, ìwọ yóò sì dàbí Ọlọ́run ní iwájú rẹ̀.
Et il parlera pour toi au peuple et il sera une bouche pour toi et tu seras Dieu pour lui.
17 Ṣùgbọ́n mú ọ̀pá yìí ni ọwọ́ rẹ kí ìwọ bá à lè fi ṣe àwọn iṣẹ́ àmì ìyanu pẹ̀lú rẹ̀.”
Et prends dans ta main ce bâton-là avec lequel tu opéreras les signes.
18 Mose padà sí ọ̀dọ̀ Jetro baba ìyàwó rẹ̀, ó sì sọ fún un pé, “Jọ̀wọ́ jẹ́ kí n padà tọ àwọn ènìyàn mi lọ ni ilẹ̀ Ejibiti láti wò bóyá wọ́n ṣì wà láààyè síbẹ̀.” Jetro sì dáhùn, ó wí pé, “Máa lọ ni àlàáfíà.”
Alors Moïse s'en alla et revint chez son beau-père Jéthro, et lui dit: Laisse-moi partir et rejoindre mes frères qui sont en Egypte, afin que je voie s'ils sont encore en vie. Et Jéthro dit à Moïse: Va en paix!
19 Nísinsin yìí, Olúwa ti sọ fún Mose ni ilẹ̀ Midiani pé, “Máa padà lọ sí Ejibiti, nítorí àwọn ti ó fẹ́ pa ọ ti kú.”
Et l'Éternel dit à Moïse en Madian: Va, retourne en Egypte, car tous les hommes qui en voulaient à ta vie sont morts.
20 Mose mú ìyàwó rẹ̀ àti àwọn ọmọ rẹ̀, ó kó wọn lé orí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, ó sì bẹ̀rẹ̀ ìrìnàjò rẹ̀ padà sí Ejibiti. Ó sì mú ọ̀pá Ọlọ́run sí ọwọ́ rẹ̀.
Alors Moïse prit sa femme et ses fils et leur donna des ânes pour monture et revint au pays d'Egypte. Et Moïse prit, le bâton de Dieu dans sa main.
21 Olúwa sì sọ fún Mose pé, “Ní ìgbà tí ìwọ bá padà sí Ejibiti rí i pé ìwọ ṣe iṣẹ́ ìyanu ni iwájú Farao. Èmi ti fún ọ lágbára láti ṣe é. Èmi yóò sì sé àyà rẹ̀ le, òun kì yóò jẹ́ kí àwọn ènìyàn náà kí ó lọ.
Et l'Éternel dit à Moïse: En cheminant pour retourner en Egypte, considère tous les miracles que j'ai mis en ton pouvoir, et tu les opéreras devant Pharaon; mais moi, j'endurcirai son cœur, en sorte qu'il ne laissera point aller le peuple.
22 Lẹ́yìn náà, kí o sọ fún Farao pé, ‘Èyí ni Olúwa sọ: Israẹli ní àkọ́bí ọmọ mi ọkùnrin,
Et tu diras à Pharaon: Ainsi parle l'Éternel: Israël est mon fils premier-né,
23 mo sọ fún ọ, “Jẹ́ kí ọmọ mi lọ, ki òun kí ó lè máa sìn mí.” Ṣùgbọ́n ìwọ kọ̀ láti jẹ́ kí ó lọ; nítorí náà, èmi yóò pa àkọ́bí ọmọ rẹ ọkùnrin.’”
et je te dis: Laisse aller mon fils me servir; et si tu refuses de le laisser aller, voici, je ferai mourir ton fils premier-né.
24 Ní ọ̀nà ìrìnàjò rẹ, ni ibi tí wọ́n gbé sùn ní ilé èrò ní alẹ́, Olúwa pàdé Mose, ó sì fẹ́ láti pa á.
Et il arriva pendant le voyage, dans l'hôtellerie, que l'Éternel se trouva devant lui, et Il voulait le faire mourir.
25 Ṣùgbọ́n Sippora mú ọ̀bẹ òkúta mímú, ó sì kọ ọmọ rẹ̀ ní ilà abẹ́, ó sì fi awọ rẹ̀ kan ẹsẹ̀ Mose. Sippora sì wí pé, “Ọkọ ẹlẹ́jẹ̀ ni ìwọ jẹ́ sí mi.”
Alors Tsippora prit un caillou et trancha le prépuce de son fils, et le jeta à ses pieds, en disant: Tu es pour moi un époux sanguinaire.
26 Nítorí náà Olúwa yọ̀ǹda rẹ láti ìgbà tí ó ti wí pé, “Ẹlẹ́jẹ̀ ni ìwọ í ṣe.” Èyí tó túmọ̀ sí ìkọlà abẹ́.
Et Il cessa de le prendre à partie. C'est alors qu'elle dit: Tu es un époux sanguinaire eu égard à la circoncision.
27 Olúwa sì sọ fún Aaroni pé, “Lọ sínú aginjù láti lọ pàdé Mose.” Ní ìgbà náà ni ó lọ pàdé Mose ní orí òkè Ọlọ́run, ó sì fi ẹnu kò ó ní ẹnu.
Et l'Éternel dit à Aaron: Va à la rencontre de Moïse dans le désert. Et il partit et le rencontra sur la montagne de Dieu, et il l'embrassa.
28 Ní ìgbà náà ni Mose sì sọ ohun gbogbo tí Ọlọ́run ti rán fún Aaroni àti nípa gbogbo iṣẹ́ ìyanu tí Olúwa ti pàṣẹ fún un láti ṣe ní iwájú Farao.
Alors Moïse rapporta à Aaron toutes les paroles de l'Éternel qui l'envoyait et tous les signes dont Il lui avait donné l'ordre.
29 Mose àti Aaroni pe gbogbo àwọn àgbàgbà Israẹli jọ.
Puis Moïse se mit en route avec Aaron; et ils assemblèrent tous les Anciens des enfants d'Israël.
30 Aaroni sọ ohun gbogbo tí Olúwa sọ fún Mose fún wọn, ó sì ṣe iṣẹ́ àmì náà ní ojú àwọn ènìyàn náà.
Et Aaron leur transmit toutes les paroles que l'Éternel avait dites à Moïse; et il opéra les signes devant le peuple.
31 Wọ́n sì gbàgbọ́. Nígbà tí wọ́n gbọ́ pé Olúwa ti bẹ àwọn ọmọ Israẹli wò àti pé Olúwa ti gbọ́ nípa ìpọ́njú wọn, wọ́n tẹríba, wọ́n sì sìn ín. Ó sì ṣe àwọn iṣẹ́ àmì náà níwájú àwọn ènìyàn náà.
Et le peuple crut, et quand ils apprirent que l'Éternel avait souci des enfants d'Israël, et qu'il considérait leur misère, ils se prosternèrent et adorèrent.

< Exodus 4 >