< Exodus 4 >

1 Mose dáhùn ó sì wí pé, “Ṣùgbọ́n bí wọn kò bá gbà mí gbọ́ ń kọ́? Tàbí tí wọn kò fi etí sílẹ̀ láti gbọ́ ọ̀rọ̀ ẹnu mi, tí wọn sì wí pé, ‘Olúwa kò farahàn ọ́’?”
Moïse répondit: « Mais voici qu'ils ne me croiront pas et n'écouteront pas ma voix, car ils diront: « Yahvé ne t'est pas apparu »".
2 Ní ìgbà náà ni Olúwa sọ fún un pé, “Kí ni ó wà ní ọwọ́ rẹ n nì?” Ó sì dáhùn pé, “Ọ̀pá ni.”
Yahvé lui dit: « Qu'est-ce que tu as dans la main? » Il a dit: « Une baguette. »
3 Olúwa sì sọ pé, “Sọ ọ̀pá náà sílẹ̀.” Mose sì sọ ọ̀pá náà sílẹ̀, lọ́gán ni ọ̀pá náà di ejò, ó sì sá fún un.
Il a dit: « Jette-la par terre. » Il la jeta par terre, et elle devint un serpent; Moïse s'en enfuit.
4 Nígbà náà ni Olúwa wá sọ fún un pé, “Na ọwọ́ rẹ, kí o sì mú un ni ìrù.” Mose sì na ọwọ́ rẹ̀, ó sì mu ejò náà, ejò náà sì padà di ọ̀pá tí ó wà ni ọwọ́ rẹ̀.
Yahvé dit à Moïse: « Étends ta main, et prends-le par la queue. » Il étendit la main et la saisit, et elle devint une verge dans sa main.
5 Olúwa sì wí pé, “Èyí rí bẹ́ẹ̀ kí wọn bá à le è gbàgbọ́ pé, Olúwa Ọlọ́run àwọn baba wọn, Ọlọ́run Abrahamu, Ọlọ́run Isaaki, àti Ọlọ́run Jakọbu; tí farahàn ọ́.”
« C'est afin qu'ils croient que Yahvé, le Dieu de leurs pères, le Dieu d'Abraham, le Dieu d'Isaac et le Dieu de Jacob, t'est apparu ».
6 Ní ìgbà náà ni Olúwa wí pé, “Ti ọwọ́ rẹ bọ inú aṣọ ní igbá àyà rẹ̀.” Mose sì ti ọwọ́ rẹ̀ bọ inú aṣọ ní igbá àyà rẹ̀, ní ìgbà ti ó sì yọ ọ́ jáde, ọwọ́ rẹ̀ ti dẹ́tẹ̀, ó sì ti funfun bí ẹ̀gbọ̀n òwú.
Yahvé lui dit encore: « Mets maintenant ta main dans ton manteau. » Il mit sa main dans son manteau, et quand il la retira, voici que sa main était lépreuse, blanche comme la neige.
7 Ó sì wí pé, “Nísinsin yìí, fi ọwọ́ náà padà sí abẹ́ aṣọ ní igbá àyà rẹ.” Mose sì ṣe bẹ́ẹ̀, ọwọ́ rẹ̀ sì padà bọ́ sípò bí àwọn ẹ̀yà ara rẹ̀ tókù.
Il dit: « Remets ta main dans ton manteau. » Il remit sa main dans son manteau, et quand il la retira de son manteau, voici qu'elle était redevenue comme son autre chair.
8 Ní ìgbà náà ni Olúwa wí pé, “Bí wọn kò bá gbà ọ́ gbọ́ tàbí kọ ibi ara sí iṣẹ́ ìyanu àkọ́kọ́, wọ́n le è ti ipasẹ̀ iṣẹ́ ìyanu kejì gbàgbọ́.
S'ils ne te croient pas et n'écoutent pas la voix du premier signe, ils croiront la voix du second signe.
9 Ṣùgbọ́n bí wọn kò bá gba àmì méjèèjì wọ̀nyí gbọ́, tí wọn kò sì fetí sí ọ̀rọ̀ rẹ, bu omi díẹ̀ láti inú odò Naili kí o si dà á sí orí ìyàngbẹ ilẹ̀, omi tí ìwọ bù láti inú odò yìí yóò sì di ẹ̀jẹ̀.”
S'ils ne croient pas à ces deux signes et n'écoutent pas ta voix, tu prendras de l'eau du fleuve et tu la répandras sur la terre ferme. L'eau que tu prendras du fleuve deviendra du sang sur la terre ferme. »
10 Mose sì sọ fún Olúwa pé, “Èmi jẹ́ akólòlò, èmi kì í ṣe ẹni tó lè sọ̀rọ̀ já gaara láti ìgbà àtijọ́ wá tàbí láti ìgbà ti o ti ń bá ìránṣẹ́ rẹ sọ̀rọ̀, mo jẹ́ ẹni ti ahọ́n rẹ̀ lọ́, tí ó sì ń lọ́ra àti sọ̀rọ̀.”
Moïse dit à Yahvé: « Seigneur, je ne suis pas éloquent, ni avant, ni depuis que tu parles à ton serviteur; car je suis lent à parler et j'ai la langue lente. »
11 Olúwa sì sọ fún un pé, “Ta ni ó fún ènìyàn ni ẹnu? Ta ni ó mú un ya odi tàbí adití? Ta ni ó mú un ríran, tàbí mú un fọ́jú? Ǹjẹ́ kì í ṣe èmi Olúwa?
Yahvé lui dit: « Qui a fait la bouche de l'homme? Ou qui rend muet, ou sourd, ou voyant, ou aveugle? N'est-ce pas moi, Yahvé?
12 Lọ nísinsin yìí, Èmi yóò ràn ọ́ lọ́wọ́ láti sọ̀rọ̀. Èmi yóò sì kọ́ ọ ni ohun ti ìwọ yóò sọ.”
Va donc maintenant, et je serai avec ta bouche, et je t'enseignerai ce que tu dois dire. »
13 Mose dáhùn ó wí pé, “Olúwa jọ̀wọ́ rán ẹlòmíràn láti lọ ṣe iṣẹ́ yìí.”
Moïse dit: « Oh, Seigneur, envoie quelqu'un d'autre. »
14 Ìbínú Olúwa ru sókè sí Mose, ó sì sọ pé, “Aaroni ará Lefi arákùnrin rẹ ń kọ́? Mo mọ̀ pé ó lè sọ̀rọ̀ já gaara, ó ti wà ní ọ̀nà rẹ̀ báyìí láti pàdé e rẹ. Inú rẹ̀ yóò sì dùn ti ó bá rí ọ.
La colère de Yahvé s'enflamma contre Moïse, et il dit: « Et Aaron, ton frère, le Lévite? Je sais qu'il sait bien parler. Et voici qu'il sort à ta rencontre. Quand il te verra, il se réjouira dans son cœur.
15 Ìwọ yóò sọ̀rọ̀ fún un, ìwọ yóò sì fi ọ̀rọ̀ sí i lẹ́nu, èmi yóò ràn yín lọ́wọ́ láti sọ̀rọ̀. Èmi yóò kọ́ ọ yín ni ohun ti ẹ ó ṣe.
Tu lui parleras, et tu mettras les paroles dans sa bouche. Je serai avec ta bouche et avec sa bouche, et je t'enseignerai ce que tu dois faire.
16 Òun yóò bá ọ sọ̀rọ̀ sí àwọn ènìyàn, yóò sì dàbí i pé ẹnu un rẹ ni a gbà sọ ọ̀rọ̀ náà, ìwọ yóò sì dàbí Ọlọ́run ní iwájú rẹ̀.
Il sera ton porte-parole auprès du peuple. Il sera pour toi une bouche, et tu seras pour lui comme Dieu.
17 Ṣùgbọ́n mú ọ̀pá yìí ni ọwọ́ rẹ kí ìwọ bá à lè fi ṣe àwọn iṣẹ́ àmì ìyanu pẹ̀lú rẹ̀.”
Tu prendras dans ta main cette verge, avec laquelle tu feras les signes. »
18 Mose padà sí ọ̀dọ̀ Jetro baba ìyàwó rẹ̀, ó sì sọ fún un pé, “Jọ̀wọ́ jẹ́ kí n padà tọ àwọn ènìyàn mi lọ ni ilẹ̀ Ejibiti láti wò bóyá wọ́n ṣì wà láààyè síbẹ̀.” Jetro sì dáhùn, ó wí pé, “Máa lọ ni àlàáfíà.”
Moïse s'en alla et retourna chez Jéthro, son beau-père, et lui dit: « Laisse-moi, je t'en prie, retourner auprès de mes frères qui sont en Égypte, et voir s'ils sont encore en vie. » Jéthro a dit à Moïse: « Va en paix. »
19 Nísinsin yìí, Olúwa ti sọ fún Mose ni ilẹ̀ Midiani pé, “Máa padà lọ sí Ejibiti, nítorí àwọn ti ó fẹ́ pa ọ ti kú.”
Yahvé dit à Moïse en Madian: « Va, retourne en Égypte, car tous les hommes qui en voulaient à ta vie sont morts. »
20 Mose mú ìyàwó rẹ̀ àti àwọn ọmọ rẹ̀, ó kó wọn lé orí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, ó sì bẹ̀rẹ̀ ìrìnàjò rẹ̀ padà sí Ejibiti. Ó sì mú ọ̀pá Ọlọ́run sí ọwọ́ rẹ̀.
Moïse prit sa femme et ses fils, les fit monter sur un âne, et il retourna au pays d'Égypte. Moïse prit dans sa main la verge de Dieu.
21 Olúwa sì sọ fún Mose pé, “Ní ìgbà tí ìwọ bá padà sí Ejibiti rí i pé ìwọ ṣe iṣẹ́ ìyanu ni iwájú Farao. Èmi ti fún ọ lágbára láti ṣe é. Èmi yóò sì sé àyà rẹ̀ le, òun kì yóò jẹ́ kí àwọn ènìyàn náà kí ó lọ.
Yahvé dit à Moïse: « Quand tu retourneras en Égypte, tu feras devant Pharaon tous les prodiges que j'ai mis en ta main, mais j'endurcirai son cœur et il ne laissera pas aller le peuple.
22 Lẹ́yìn náà, kí o sọ fún Farao pé, ‘Èyí ni Olúwa sọ: Israẹli ní àkọ́bí ọmọ mi ọkùnrin,
Tu diras à Pharaon: « Yahvé dit: Israël est mon fils, mon premier-né,
23 mo sọ fún ọ, “Jẹ́ kí ọmọ mi lọ, ki òun kí ó lè máa sìn mí.” Ṣùgbọ́n ìwọ kọ̀ láti jẹ́ kí ó lọ; nítorí náà, èmi yóò pa àkọ́bí ọmọ rẹ ọkùnrin.’”
et je t'ai dit: « Laisse aller mon fils, pour qu'il me serve », et tu as refusé de le laisser aller. Voici que je vais tuer ton fils premier-né. »
24 Ní ọ̀nà ìrìnàjò rẹ, ni ibi tí wọ́n gbé sùn ní ilé èrò ní alẹ́, Olúwa pàdé Mose, ó sì fẹ́ láti pa á.
En chemin, dans un lieu d'hébergement, Yahvé rencontra Moïse et voulut le tuer.
25 Ṣùgbọ́n Sippora mú ọ̀bẹ òkúta mímú, ó sì kọ ọmọ rẹ̀ ní ilà abẹ́, ó sì fi awọ rẹ̀ kan ẹsẹ̀ Mose. Sippora sì wí pé, “Ọkọ ẹlẹ́jẹ̀ ni ìwọ jẹ́ sí mi.”
Alors Zippora prit un silex, coupa le prépuce de son fils et le jeta à ses pieds; et elle dit: « Certainement, tu es pour moi un époux de sang. »
26 Nítorí náà Olúwa yọ̀ǹda rẹ láti ìgbà tí ó ti wí pé, “Ẹlẹ́jẹ̀ ni ìwọ í ṣe.” Èyí tó túmọ̀ sí ìkọlà abẹ́.
Il le laissa donc tranquille. Alors elle dit: « Tu es un époux de sang », à cause de la circoncision.
27 Olúwa sì sọ fún Aaroni pé, “Lọ sínú aginjù láti lọ pàdé Mose.” Ní ìgbà náà ni ó lọ pàdé Mose ní orí òkè Ọlọ́run, ó sì fi ẹnu kò ó ní ẹnu.
Yahvé dit à Aaron: « Va dans le désert à la rencontre de Moïse. » Il alla à sa rencontre sur la montagne de Dieu, et le baisa.
28 Ní ìgbà náà ni Mose sì sọ ohun gbogbo tí Ọlọ́run ti rán fún Aaroni àti nípa gbogbo iṣẹ́ ìyanu tí Olúwa ti pàṣẹ fún un láti ṣe ní iwájú Farao.
Moïse rapporta à Aaron toutes les paroles de Yahvé par lesquelles il l'avait envoyé, et tous les signes par lesquels il l'avait instruit.
29 Mose àti Aaroni pe gbogbo àwọn àgbàgbà Israẹli jọ.
Moïse et Aaron allèrent rassembler tous les anciens des enfants d'Israël.
30 Aaroni sọ ohun gbogbo tí Olúwa sọ fún Mose fún wọn, ó sì ṣe iṣẹ́ àmì náà ní ojú àwọn ènìyàn náà.
Aaron prononça toutes les paroles que Yahvé avait dites à Moïse, et il fit les signes aux yeux du peuple.
31 Wọ́n sì gbàgbọ́. Nígbà tí wọ́n gbọ́ pé Olúwa ti bẹ àwọn ọmọ Israẹli wò àti pé Olúwa ti gbọ́ nípa ìpọ́njú wọn, wọ́n tẹríba, wọ́n sì sìn ín. Ó sì ṣe àwọn iṣẹ́ àmì náà níwájú àwọn ènìyàn náà.
Le peuple crut, et quand il apprit que Yahvé avait visité les enfants d'Israël et qu'il avait vu leur détresse, il se prosterna et se prosterna.

< Exodus 4 >